< Micah 3 >
1 Nígbà náà, ni mo wí pé, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin olórí Jakọbu, ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli. Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò ha ni í gba òdodo bí.
I powiedziałem: Słuchajcie, naczelnicy Jakuba i wodzowie domu Izraela! Czy wy nie powinniście znać sądu?
2 Ẹ̀yin tí ó kórìíra ìre, tí ẹ sì fẹ́ràn ibi; ẹ̀yin tí ẹ fa awọ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi ya kúrò lára wọn àti ẹran-ara wọn kúrò ní egungun wọn;
Wy, którzy nienawidzicie dobra, a kochacie zło, którzy zdzieracie z ludu skórę i ciało z jego kości;
3 àwọn tí ó jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi, wọn sì bọ́ awọ ara wọn kúrò lára wọn. Wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́; wọn sì gé e sí wẹ́wẹ́ bí ẹran inú ìkòkò, bí ẹran inú agbada?”
[Którzy] jecie ciało mojego ludu, skórę z niego zdzieracie, jego kości łamiecie i kroicie je na kawałki jak do garnca i jak mięso do kotła.
4 Nígbà náà ni wọn yóò kígbe sí Olúwa, ṣùgbọ́n òun kì yóò dá wọn lóhùn. Ní àkókò náà ni òun yóò fi ojú rẹ̀ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, nítorí ibi tí wọ́n ti ṣe.
Wtedy będą wołać do PANA, a nie wysłucha ich, lecz zakryje swoje oblicze przed nimi w tym czasie, gdyż oni popełniali złe czyny.
5 Báyìí ni Olúwa wí, “Ní ti àwọn Wòlíì tí ń ṣi àwọn ènìyàn mi lọ́nà, tí ẹnìkan bá fún wọn ní oúnjẹ, wọn yóò kéde àlàáfíà; ṣùgbọ́n tí kò bá fi nǹkan sí wọn ní ẹnu, wọn yóò múra ogun sí i.
Tak mówi PAN o tych prorokach, którzy w błąd wprowadzą mój lud, którzy gryzą swoimi zębami i głoszą pokój, a temu, który nic im nie włoży do ust, wypowiadają wojnę.
6 Nítorí náà òru yóò wá sórí yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì rí ìran kankan, òkùnkùn yóò sì kùn fún yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì lè sọtẹ́lẹ̀. Oòrùn yóò sì wọ lórí àwọn wòlíì ọjọ́ yóò sì ṣókùnkùn lórí wọn.
Dlatego wasze widzenie zamienia się w noc, a wasza wróżba – w ciemność; słońce zajdzie nad prorokami i dzień się zaćmi nad nimi.
7 Ojú yóò sì ti àwọn wòlíì àwọn alásọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú yóò sì gba ìtìjú. Gbogbo wọn ni yóò bo ojú wọn, nítorí kò sí ìdáhùn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
Wtedy widzący będą się wstydzić i wróżbiarze się zarumienią. Oni wszyscy zakryją swoje wargi, bo nie będzie żadnej odpowiedzi od Boga.
8 Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi kún fún agbára pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, láti sọ ìré-òfin-kọjá Jakọbu fún un, àti láti sọ ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli fún un.
Ale ja jestem napełniony mocą Ducha PANA oraz sądu i siły, aby oznajmić Jakubowi jego występki i Izraelowi jego grzech.
9 Gbọ́ ẹ̀yin olórí ilé Jakọbu, àti ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli, tí ó kórìíra òdodo tí ó sì yí òtítọ́ padà;
Słuchajcie tego, naczelnicy domu Jakuba i wodzowie domu Izraela, którzy brzydzicie się sądem i wypaczacie wszystko, co sprawiedliwe.
10 tí ó kọ́ Sioni pẹ̀lú ìtàjẹ̀ sílẹ̀, àti Jerusalẹmu pẹ̀lú ìwà búburú.
Każdy buduje Syjon krwią, a Jerozolimę nieprawością.
11 Àwọn olórí rẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀, àwọn àlùfáà rẹ̀ sì ń kọ́ni nítorí owó ọ̀yà àwọn wòlíì rẹ̀ pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ nítorí owó. Síbẹ̀, wọn gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, wọ́n sì wí pé, “Nítòótọ́, Olúwa wà pẹ̀lú wa! Ibi kan kì yóò bá wa.”
Jej naczelnicy sądzą za dary, jego kapłani uczą za zapłatę i jego prorocy prorokują za pieniądze. Polegają [jednak] na PANU, mówiąc: Czy PAN nie jest wśród nas? Nie spotka nas nic złego.
12 Nítorí náà, nítorí tiyín, ni a ó ṣe ro Sioni bí oko, Jerusalẹmu yóò sì di ebè àti òkè tẹmpili bí i ibi gíga igbó.
Dlatego Syjon stanie się dla was [jak] zaorane pole, Jerozolima zamieni się w kupę gruzu, a góra domu – w zalesione wzgórze.