< Micah 3 >

1 Nígbà náà, ni mo wí pé, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin olórí Jakọbu, ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli. Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò ha ni í gba òdodo bí.
و گفتم: ای روسای یعقوب و‌ای داوران خاندان اسرائیل بشنوید! آیا بر شما نیست که انصاف را بدانید؟۱
2 Ẹ̀yin tí ó kórìíra ìre, tí ẹ sì fẹ́ràn ibi; ẹ̀yin tí ẹ fa awọ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi ya kúrò lára wọn àti ẹran-ara wọn kúrò ní egungun wọn;
آنانی که از نیکویی نفرت دارند و بر بدی مایل می‌باشند و پوست را از تن مردم و گوشت را از استخوانهای ایشان می‌کنند،۲
3 àwọn tí ó jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi, wọn sì bọ́ awọ ara wọn kúrò lára wọn. Wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́; wọn sì gé e sí wẹ́wẹ́ bí ẹran inú ìkòkò, bí ẹran inú agbada?”
و کسانی که گوشت قوم مرا می‌خورند و پوست ایشان را از تن ایشان می‌کنند و استخوانهای ایشان را خرد کرده، آنها را گویا در دیگ و مثل گوشت در پاتیل می‌ریزند.۳
4 Nígbà náà ni wọn yóò kígbe sí Olúwa, ṣùgbọ́n òun kì yóò dá wọn lóhùn. Ní àkókò náà ni òun yóò fi ojú rẹ̀ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, nítorí ibi tí wọ́n ti ṣe.
آنگاه نزد خداونداستغاثه خواهند نمود و ایشان را اجابت نخواهدنمود بلکه روی خود را در آنزمان از ایشان خواهد پوشانید چونکه مرتکب اعمال زشت شده‌اند.۴
5 Báyìí ni Olúwa wí, “Ní ti àwọn Wòlíì tí ń ṣi àwọn ènìyàn mi lọ́nà, tí ẹnìkan bá fún wọn ní oúnjẹ, wọn yóò kéde àlàáfíà; ṣùgbọ́n tí kò bá fi nǹkan sí wọn ní ẹnu, wọn yóò múra ogun sí i.
خداوند درباره انبیایی که قوم مرا گمراه می‌کنند و به دندانهای خود می‌گزند و سلامتی راندا می‌کنند و اگر کسی چیزی به دهان ایشان نگذارد با او تدارک جنگ می‌بینند، چنین می‌گوید:۵
6 Nítorí náà òru yóò wá sórí yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì rí ìran kankan, òkùnkùn yóò sì kùn fún yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì lè sọtẹ́lẹ̀. Oòrùn yóò sì wọ lórí àwọn wòlíì ọjọ́ yóò sì ṣókùnkùn lórí wọn.
از این جهت برای شما شب خواهدبود که رویا نبینید و ظلمت برای شما خواهد بود که فالگیری ننمایید. آفتاب بر انبیاء غروب خواهد کرد و روز بر ایشان تاریک خواهد شد.۶
7 Ojú yóò sì ti àwọn wòlíì àwọn alásọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú yóò sì gba ìtìjú. Gbogbo wọn ni yóò bo ojú wọn, nítorí kò sí ìdáhùn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
وراییان خجل و فالگیران رسوا شده، جمیع ایشان لبهای خود را خواهند پوشانید چونکه از جانب خدا جواب نخواهد بود.۷
8 Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi kún fún agbára pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, láti sọ ìré-òfin-kọjá Jakọbu fún un, àti láti sọ ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli fún un.
و لیکن من از قوت روح خداوند و از انصاف و توانایی مملو شده‌ام تایعقوب را از عصیان او و اسرائیل را از گناهش خبر دهم.۸
9 Gbọ́ ẹ̀yin olórí ilé Jakọbu, àti ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli, tí ó kórìíra òdodo tí ó sì yí òtítọ́ padà;
‌ای روسای خاندان یعقوب و‌ای داوران خاندان اسرائیل این را بشنوید! شما که ازانصاف نفرت دارید و تمامی راستی را منحرف می‌سازید.۹
10 tí ó kọ́ Sioni pẹ̀lú ìtàjẹ̀ sílẹ̀, àti Jerusalẹmu pẹ̀lú ìwà búburú.
و صهیون را به خون و اورشلیم را به ظلم بنا می‌نمایید.۱۰
11 Àwọn olórí rẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀, àwọn àlùfáà rẹ̀ sì ń kọ́ni nítorí owó ọ̀yà àwọn wòlíì rẹ̀ pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ nítorí owó. Síbẹ̀, wọn gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, wọ́n sì wí pé, “Nítòótọ́, Olúwa wà pẹ̀lú wa! Ibi kan kì yóò bá wa.”
روسای ایشان برای رشوه داوری می‌نمایند و کاهنان ایشان برای اجرت تعلیم می‌دهند و انبیای ایشان برای نقره فال می‌گیرند و بر خداوند توکل نموده، می‌گویند: آیاخداوند در میان ما نیست پس بلا به ما نخواهدرسید.۱۱
12 Nítorí náà, nítorí tiyín, ni a ó ṣe ro Sioni bí oko, Jerusalẹmu yóò sì di ebè àti òkè tẹmpili bí i ibi gíga igbó.
بنابراین صهیون به‌سبب شما مثل مزرعه شیار خواهد شد و اورشلیم به توده های سنگ و کوه خانه به بلندیهای جنگل مبدل خواهد گردید.۱۲

< Micah 3 >