< Micah 3 >

1 Nígbà náà, ni mo wí pé, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin olórí Jakọbu, ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli. Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò ha ni í gba òdodo bí.
Ningĩ ngiuga atĩrĩ, “Ta iguai, inyuĩ atongoria a Jakubu, o inyuĩ aathani a nyũmba ya Isiraeli. Githĩ mũtiagĩrĩirwo nĩkũmenya ũhoro wa gũtuanĩra ciira na kĩhooto.
2 Ẹ̀yin tí ó kórìíra ìre, tí ẹ sì fẹ́ràn ibi; ẹ̀yin tí ẹ fa awọ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi ya kúrò lára wọn àti ẹran-ara wọn kúrò ní egungun wọn;
No inyuĩ mũthũire maũndũ mega no mũkenda marĩa mooru; inyuĩ mũnũraga andũ akwa ikonde, na mũgathoora nyama mahĩndĩ-inĩ mao.
3 àwọn tí ó jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi, wọn sì bọ́ awọ ara wọn kúrò lára wọn. Wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́; wọn sì gé e sí wẹ́wẹ́ bí ẹran inú ìkòkò, bí ẹran inú agbada?”
Inyuĩ mũrĩĩaga nyama cia mĩĩrĩ ya andũ akwa, mũkamonũra ikonde na mũkoinanga mahĩndĩ mao tũcunjĩ; O inyuĩ mũmatinangagia ta nyama cia gũkarangwo na rũgĩo, o na ta nyama cia gũtherũkio na nyũngũ.”
4 Nígbà náà ni wọn yóò kígbe sí Olúwa, ṣùgbọ́n òun kì yóò dá wọn lóhùn. Ní àkókò náà ni òun yóò fi ojú rẹ̀ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, nítorí ibi tí wọ́n ti ṣe.
Hĩndĩ ĩyo magaakaĩra Jehova, nowe ndakamacookeria. Hĩndĩ ĩyo nĩakahitha ũthiũ wake kuuma kũrĩ o, tondũ wa ũũru ũrĩa mekĩte.
5 Báyìí ni Olúwa wí, “Ní ti àwọn Wòlíì tí ń ṣi àwọn ènìyàn mi lọ́nà, tí ẹnìkan bá fún wọn ní oúnjẹ, wọn yóò kéde àlàáfíà; ṣùgbọ́n tí kò bá fi nǹkan sí wọn ní ẹnu, wọn yóò múra ogun sí i.
Jehova ekuuga atĩrĩ, “Ha ũhoro wa anabii acio mahĩtithagia andũ akwa, mũndũ aamahe irio, maanagĩrĩra makiugaga ‘thayũ,’ no angĩmaima irio, makahaarĩria mbaara ya kũmũũkĩrĩra.
6 Nítorí náà òru yóò wá sórí yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì rí ìran kankan, òkùnkùn yóò sì kùn fún yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì lè sọtẹ́lẹ̀. Oòrùn yóò sì wọ lórí àwọn wòlíì ọjọ́ yóò sì ṣókùnkùn lórí wọn.
Tondũ ũcio, ũtukũ nĩũkamũhubanĩria, mwage kuona cioneki, mũhubanĩrio nĩ nduma mwage ũguũrio. Riũa nĩrĩgathũĩra anabii, naguo mũthenya ũmatuĩkĩre nduma.
7 Ojú yóò sì ti àwọn wòlíì àwọn alásọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú yóò sì gba ìtìjú. Gbogbo wọn ni yóò bo ojú wọn, nítorí kò sí ìdáhùn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
Ooni-maũndũ nĩmagaconoka, nao aragũri maconorithio. Othe nĩmakahumbĩra mothiũ mao, tondũ gũtirĩ ũhoro magaacookerio nĩ Ngai.”
8 Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi kún fún agbára pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, láti sọ ìré-òfin-kọjá Jakọbu fún un, àti láti sọ ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli fún un.
No hakwa-rĩ, niĩ njiyũrĩtwo nĩ hinya, na ngaiyũrwo nĩ Roho wa Jehova, o na ngaiyũrwo nĩ kĩhooto na ũhoti, nĩguo nyumbũrĩre Jakubu ũremi wake, na nyumbũrĩre Isiraeli mehia make.
9 Gbọ́ ẹ̀yin olórí ilé Jakọbu, àti ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli, tí ó kórìíra òdodo tí ó sì yí òtítọ́ padà;
Ta thikĩrĩriai, inyuĩ atongoria a nyũmba ya Jakubu, o inyuĩ aathani a nyũmba ya Isiraeli, inyuĩ mũmenaga kĩhooto, na mũkoogomia maũndũ marĩa ma ma;
10 tí ó kọ́ Sioni pẹ̀lú ìtàjẹ̀ sílẹ̀, àti Jerusalẹmu pẹ̀lú ìwà búburú.
inyuĩ mwakaga Zayuni na ũiti wa thakame, na mũgaaka Jerusalemu na waganu.
11 Àwọn olórí rẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀, àwọn àlùfáà rẹ̀ sì ń kọ́ni nítorí owó ọ̀yà àwọn wòlíì rẹ̀ pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ nítorí owó. Síbẹ̀, wọn gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, wọ́n sì wí pé, “Nítòótọ́, Olúwa wà pẹ̀lú wa! Ibi kan kì yóò bá wa.”
Atongoria akuo matuaga ciira maahakwo, athĩnjĩri-Ngai akuo marutanaga maarĩhwo, na anabii akuo marathaga mohoro maheo mbeeca. No rĩrĩ, megiritanagia na Jehova makoiga atĩrĩ, “Githĩ Jehova ndakĩrĩ gatagatĩ-inĩ gaitũ? Gũtirĩ ũũru ũngĩtũkora.”
12 Nítorí náà, nítorí tiyín, ni a ó ṣe ro Sioni bí oko, Jerusalẹmu yóò sì di ebè àti òkè tẹmpili bí i ibi gíga igbó.
Nĩ tondũ wanyu-rĩ, Zayuni gũgaaciimbwo ta mũgũnda, Jerusalemu gũtuĩke hĩba ya mahiga, nakĩo kĩrĩma kĩrĩa gĩakĩtwo hekarũ gĩtuĩke kĩhumbu kĩmereirwo nĩ ihinga.

< Micah 3 >