< Micah 3 >
1 Nígbà náà, ni mo wí pé, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin olórí Jakọbu, ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli. Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò ha ni í gba òdodo bí.
Et j’ai dit: Ecoutez, princes de Jacob, et chefs de la maison d’Israël: N’est-ce pas à vous de connaître ce qui est juste,
2 Ẹ̀yin tí ó kórìíra ìre, tí ẹ sì fẹ́ràn ibi; ẹ̀yin tí ẹ fa awọ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi ya kúrò lára wọn àti ẹran-ara wọn kúrò ní egungun wọn;
Vous qui avez en haine le bien et qui aimez le mal; vous qui enlevez violemment leur peau de dessus eux et leur chair de dessus leurs os?
3 àwọn tí ó jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi, wọn sì bọ́ awọ ara wọn kúrò lára wọn. Wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́; wọn sì gé e sí wẹ́wẹ́ bí ẹran inú ìkòkò, bí ẹran inú agbada?”
Qui ont mangé la chair de mon peuple, et ont arraché leur peau, brisé leurs os, et ils les ont coupés en morceaux comme pour les faire cuire dans une chaudière, et comme de la chair qu’on met dans une marmite.
4 Nígbà náà ni wọn yóò kígbe sí Olúwa, ṣùgbọ́n òun kì yóò dá wọn lóhùn. Ní àkókò náà ni òun yóò fi ojú rẹ̀ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, nítorí ibi tí wọ́n ti ṣe.
Alors ils crieront vers le Seigneur; mais il ne les exaucera pas; et il leur cachera sa face en ce temps-là, à cause de la malice de leurs inventions.
5 Báyìí ni Olúwa wí, “Ní ti àwọn Wòlíì tí ń ṣi àwọn ènìyàn mi lọ́nà, tí ẹnìkan bá fún wọn ní oúnjẹ, wọn yóò kéde àlàáfíà; ṣùgbọ́n tí kò bá fi nǹkan sí wọn ní ẹnu, wọn yóò múra ogun sí i.
Voici ce que dit le Seigneur contre les prophètes qui séduisent mon peuple; qui mordent avec leurs dents, et prêchent la paix; si quelqu’un ne leur met pas dans la bouche quelque chose, ils consacrent contre lui un combat.
6 Nítorí náà òru yóò wá sórí yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì rí ìran kankan, òkùnkùn yóò sì kùn fún yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì lè sọtẹ́lẹ̀. Oòrùn yóò sì wọ lórí àwọn wòlíì ọjọ́ yóò sì ṣókùnkùn lórí wọn.
À cause de cela, vous aurez pour vision une nuit, et des ténèbres pour révélation; et le soleil se couchera pour les prophètes, et le jour se couvrira de ténèbres pour eux.
7 Ojú yóò sì ti àwọn wòlíì àwọn alásọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú yóò sì gba ìtìjú. Gbogbo wọn ni yóò bo ojú wọn, nítorí kò sí ìdáhùn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
Et ceux qui voient des visions seront confondus, les devins seront confondus; et tous se voileront le visage, parce qu’il n’y a pas de réponse de Dieu.
8 Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi kún fún agbára pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, láti sọ ìré-òfin-kọjá Jakọbu fún un, àti láti sọ ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli fún un.
Mais cependant moi j’ai été rempli de la force de l’esprit du Seigneur, de sa justice et de sa vertu, afin que j’annonce à Jacob son crime et à Israël son pèche.
9 Gbọ́ ẹ̀yin olórí ilé Jakọbu, àti ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli, tí ó kórìíra òdodo tí ó sì yí òtítọ́ padà;
Ecoutez ceci, princes de la maison de Jacob, et juges de la maison d’Israël, vous qui abominez le jugement et pervertissez tout ce qui est juste;
10 tí ó kọ́ Sioni pẹ̀lú ìtàjẹ̀ sílẹ̀, àti Jerusalẹmu pẹ̀lú ìwà búburú.
Qui bâtissez Sion avec du sang, et Jérusalem avec l’iniquité.
11 Àwọn olórí rẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀, àwọn àlùfáà rẹ̀ sì ń kọ́ni nítorí owó ọ̀yà àwọn wòlíì rẹ̀ pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ nítorí owó. Síbẹ̀, wọn gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, wọ́n sì wí pé, “Nítòótọ́, Olúwa wà pẹ̀lú wa! Ibi kan kì yóò bá wa.”
Ses princes jugeaient pour des présents, et ses prêtres enseignaient pour un salaire, et ses prophètes prédisaient pour de l’argent; et ils se reposaient sur le Seigneur, disant: Est-ce que le Seigneur n’est pas au milieu de nous? Les maux ne viendront pas sur nous.
12 Nítorí náà, nítorí tiyín, ni a ó ṣe ro Sioni bí oko, Jerusalẹmu yóò sì di ebè àti òkè tẹmpili bí i ibi gíga igbó.
C’est pour cela qu’à cause de vous, Sion comme un champ sera labourée, et que Jérusalem sera comme un monceau de pierres, et la montagne du temple une haute forêt.