< Micah 3 >

1 Nígbà náà, ni mo wí pé, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin olórí Jakọbu, ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli. Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò ha ni í gba òdodo bí.
J'ai dit, « S'il vous plaît, écoutez, têtes de Jacob, et les chefs de la maison d'Israël: N'est-ce pas à vous de connaître la justice?
2 Ẹ̀yin tí ó kórìíra ìre, tí ẹ sì fẹ́ràn ibi; ẹ̀yin tí ẹ fa awọ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi ya kúrò lára wọn àti ẹran-ara wọn kúrò ní egungun wọn;
Vous qui détestez le bien, et aimer le mal; qui s'arrachent la peau, et leur chair de leurs os;
3 àwọn tí ó jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi, wọn sì bọ́ awọ ara wọn kúrò lára wọn. Wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́; wọn sì gé e sí wẹ́wẹ́ bí ẹran inú ìkòkò, bí ẹran inú agbada?”
qui mangent aussi la chair de mon peuple, et peler leur peau, et briser leurs os, et les couper en morceaux, comme pour le pot, et comme viande dans le chaudron.
4 Nígbà náà ni wọn yóò kígbe sí Olúwa, ṣùgbọ́n òun kì yóò dá wọn lóhùn. Ní àkókò náà ni òun yóò fi ojú rẹ̀ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, nítorí ibi tí wọ́n ti ṣe.
Alors ils crieront à Yahvé, mais il ne leur répondra pas. Oui, il leur cachera son visage à ce moment-là, parce qu'ils ont rendu leurs actions mauvaises. »
5 Báyìí ni Olúwa wí, “Ní ti àwọn Wòlíì tí ń ṣi àwọn ènìyàn mi lọ́nà, tí ẹnìkan bá fún wọn ní oúnjẹ, wọn yóò kéde àlàáfíà; ṣùgbọ́n tí kò bá fi nǹkan sí wọn ní ẹnu, wọn yóò múra ogun sí i.
L'Éternel dit à propos des prophètes qui égarent mon peuple: ceux qui nourrissent leurs dents, ils proclament: « Paix! » et ceux qui ne nourrissent pas leurs bouches, ils lui préparent la guerre:
6 Nítorí náà òru yóò wá sórí yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì rí ìran kankan, òkùnkùn yóò sì kùn fún yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì lè sọtẹ́lẹ̀. Oòrùn yóò sì wọ lórí àwọn wòlíì ọjọ́ yóò sì ṣókùnkùn lórí wọn.
« C'est pourquoi la nuit est sur vous, sans vision, et il est sombre pour vous, pour que vous ne puissiez pas deviner; et le soleil se couchera sur les prophètes, et le jour sera noir sur eux.
7 Ojú yóò sì ti àwọn wòlíì àwọn alásọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú yóò sì gba ìtìjú. Gbogbo wọn ni yóò bo ojú wọn, nítorí kò sí ìdáhùn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
Les voyants seront déçus, et les devins confondus. Oui, ils doivent tous couvrir leurs lèvres, car il n'y a pas de réponse de Dieu. »
8 Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi kún fún agbára pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, láti sọ ìré-òfin-kọjá Jakọbu fún un, àti láti sọ ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli fún un.
Quant à moi, je suis rempli de puissance par l'Esprit de Yahvé, et du jugement, et de la puissance, pour déclarer à Jacob sa désobéissance, et à Israël son péché.
9 Gbọ́ ẹ̀yin olórí ilé Jakọbu, àti ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli, tí ó kórìíra òdodo tí ó sì yí òtítọ́ padà;
Écoutez ceci, vous, les chefs de la maison de Jacob, et les chefs de la maison d'Israël, qui abhorrent la justice, et pervertissent toute équité,
10 tí ó kọ́ Sioni pẹ̀lú ìtàjẹ̀ sílẹ̀, àti Jerusalẹmu pẹ̀lú ìwà búburú.
qui édifient Sion avec du sang, et Jérusalem avec l'iniquité.
11 Àwọn olórí rẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀, àwọn àlùfáà rẹ̀ sì ń kọ́ni nítorí owó ọ̀yà àwọn wòlíì rẹ̀ pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ nítorí owó. Síbẹ̀, wọn gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, wọ́n sì wí pé, “Nítòótọ́, Olúwa wà pẹ̀lú wa! Ibi kan kì yóò bá wa.”
Ses chefs jugent pour des pots-de-vin, et ses prêtres enseignent pour un prix, et ses prophètes disent la bonne aventure pour de l'argent; mais ils s'appuient sur Yahvé, et disent, « Yahvé n'est-il pas parmi nous? Aucun désastre ne viendra sur nous. »
12 Nítorí náà, nítorí tiyín, ni a ó ṣe ro Sioni bí oko, Jerusalẹmu yóò sì di ebè àti òkè tẹmpili bí i ibi gíga igbó.
C'est pourquoi Sion, à cause de toi, sera labourée comme un champ, et Jérusalem deviendront des tas de décombres, et la montagne du temple comme les hauts lieux d'une forêt.

< Micah 3 >