< Micah 2 >

1 Ègbé ni fún àwọn tí ń gbèrò àìṣedéédéé tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ibi lórí ibùsùn wọn! Nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́, wọn yóò gbé e jáde nítorí ó wà ní agbára wọn láti ṣe é.
Vai celor ce plănuiesc nelegiuire și fac răutate pe paturile lor! Când dimineața se luminează, ei o împlinesc, fiindcă este în puterea mâinii lor.
2 Wọ́n sì ń ṣe ojúkòkòrò oko, wọ́n sì fi agbára wọn gbà wọ́n, àti àwọn ilé, wọ́n sì gbà wọ́n. Wọ́n sì ni ènìyàn àti ilẹ̀ rẹ̀ lára àní ènìyàn àti ohun ìní rẹ̀.
Și ei poftesc câmpii și le iau prin violență; și case, și le iau; astfel ei oprimă pe om și casa lui, chiar pe om și moștenirea lui.
3 Nítorí náà, Olúwa wí pé: “Èmi ń gbèrò ibi sí àwọn ìdílé wọ̀nyí, nínú èyí tí wọn kì yóò le è gba ara wọn là. Ìwọ kì yóò sì lè máa rìn ní ìgbéraga mọ́, nítorí yóò jẹ́ àkókò ibi.
De aceea astfel spune DOMNUL: Iată, împotriva acestei familii, eu plănuiesc un rău, de la care nu vă veți feri gâturile, nici nu veți merge trufași, căci timpul acesta este rău.
4 Ní ọjọ́ náà ni ẹnìkan yóò pa òwe kan sí yín; wọn yóò sì pohùnréré ẹkún kíkorò pé: ‘Ní kíkó a ti kó wọn tán; Olúwa ti pín ohun ìní àwọn ènìyàn mi; Ó ti mú un kúrò lọ́dọ̀ mi! Ó fi oko wa lé àwọn ọlọ̀tẹ̀ lọ́wọ́.’”
În acea zi, cineva va ridica o parabolă împotriva ta și va plânge cu plângere jalnică și va spune: Noi suntem prădați în întregime, el a schimbat partea de moștenire a poporului meu, cum a luat-o el de la mine! Întorcându-se, el ne-a împărțit câmpiile.
5 Nítorí náà, ìwọ kò ní ní ẹnìkankan tí yóò ta okùn nínú ìjọ Olúwa, tí yóò pín ilẹ̀ nípa ìbò.
De aceea tu nu vei avea pe nimeni în adunarea DOMNULUI care să arunce o funie de măsurat prin sorț.
6 “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀,” ni àwọn wòlíì wọn wí. “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀ nípa nǹkan wọ̀nyí; kí ìtìjú má ṣe le bá wa.”
Nu profețiți, spuneți-le celor ce profețesc: ei nu le vor profeți, ca să nu le fie rușine.
7 Ṣé kí á sọ ọ́, ìwọ ilé Jakọbu: “Ǹjẹ́ ẹ̀mí Olúwa ha ń bínú bí? Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ ha nìwọ̀nyí?” “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ mi kò ha ń ṣe rere fún ẹni tí ń rìn déédé bí?
Tu, cea numită casa lui Iacob, este duhul DOMNULUI strâmtorat? Sunt acestea lucrările lui? Nu fac bine cuvintele mele celui ce umblă cu integritate?
8 Láìpẹ́ àwọn ènìyàn mi dìde bí ọ̀tá sí mi. Ìwọ bọ́ aṣọ ọlọ́rọ̀ kúrò lára àwọn tí ń kọjá lọ ní àìléwu, bí àwọn ẹni tí ó padà bọ̀ láti ojú ogun.
Chiar de curând poporul meu s-a ridicat ca un dușman: voi smulgeți roba cu tot cu cămașă de la cei ce trec în siguranță, ca și oameni care se întorc de la război.
9 Ẹ̀yin sì lé obìnrin àwọn ènìyàn mi kúrò nínú ilé ayọ̀ wọn, ẹ̀yin sì ti gba ògo mi, kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ wọn láéláé.
Ați aruncat afară din casele lor plăcute pe femeile poporului meu; ați luat pentru totdeauna gloria mea de la copiii lor.
10 Ẹ dìde, kí ẹ sì máa lọ! Nítorí èyí kì í ṣe ibi ìsinmi yín, nítorí tí a ti sọ ọ́ di àìmọ́ yóò pa yín run, àní ìparun kíkorò.
Ridicați-vă și îndepărtați-vă; fiindcă aceasta nu este odihna voastră: fiindcă este întinată, vă va nimici, chiar cu o nimicire grozavă.
11 Tí òpùrọ́ àti ẹlẹ́tàn bá wà tí wọ́n sì wí pé, ‘Èmi yóò sọtẹ́lẹ̀ fún ọ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wáìnì àti ọtí líle,’ òun ni yóò tilẹ̀ ṣe wòlíì àwọn ènìyàn wọ̀nyí!
Dacă un om, umblând în duh și în falsitate, minte, spunând: Eu vă voi profeți despre vin și băutură tare; el va fi profetul acestui popor.
12 “Èmi yóò kó gbogbo yín jọ, ìwọ Jakọbu; Èmi yóò gbá ìyókù Israẹli jọ. Èmi yóò kó wọn jọ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú agbo ẹran, gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nínú agbo wọn, ibẹ̀ yóò sì pariwo nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.
Eu îi voi aduna negreșit pe toți ai tăi, Iacobe; eu voi strânge negreșit rămășița lui Israel; eu îi voi pune împreună ca oile lui Boțra, ca turma în mijlocul staulului ei, ei vor face zgomot mare din cauza mulțimii oamenilor.
13 Ẹni tí ó ń fọ ọ̀nà yóò lọ sókè níwájú wọn; wọn yóò fọ láti ẹnu ibodè, wọn yóò sì jáde lọ. Àwọn ọba wọn yóò sì kọjá lọ níwájú wọn, Olúwa ni yóò sì ṣe olórí wọn.”
Cel care zdrobește a venit înaintea lor; au fost zdrobiți și au trecut prin poartă și au ieșit pe ea; și împăratul lor va trece înaintea lor și DOMNUL în fruntea lor.

< Micah 2 >