< Micah 2 >

1 Ègbé ni fún àwọn tí ń gbèrò àìṣedéédéé tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ibi lórí ibùsùn wọn! Nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́, wọn yóò gbé e jáde nítorí ó wà ní agbára wọn láti ṣe é.
Biada tym, którzy wymyślają nieprawość i knują zło na swoich łożach, a o świcie wykonują je, bo jest to w ich mocy.
2 Wọ́n sì ń ṣe ojúkòkòrò oko, wọ́n sì fi agbára wọn gbà wọ́n, àti àwọn ilé, wọ́n sì gbà wọ́n. Wọ́n sì ni ènìyàn àti ilẹ̀ rẹ̀ lára àní ènìyàn àti ohun ìní rẹ̀.
Pożądają pól i wydzierają je; także domów i je zabierają. W ten sposób gnębią człowieka i jego dom, człowieka i jego dziedzictwo.
3 Nítorí náà, Olúwa wí pé: “Èmi ń gbèrò ibi sí àwọn ìdílé wọ̀nyí, nínú èyí tí wọn kì yóò le è gba ara wọn là. Ìwọ kì yóò sì lè máa rìn ní ìgbéraga mọ́, nítorí yóò jẹ́ àkókò ibi.
Dlatego tak mówi PAN: Oto obmyślam dla tego rodu nieszczęście, z którego nie będziecie mogli wyciągnąć swoich szyj ani nie będziecie chodzić zuchwale. [Będzie] to bowiem czas nieszczęścia.
4 Ní ọjọ́ náà ni ẹnìkan yóò pa òwe kan sí yín; wọn yóò sì pohùnréré ẹkún kíkorò pé: ‘Ní kíkó a ti kó wọn tán; Olúwa ti pín ohun ìní àwọn ènìyàn mi; Ó ti mú un kúrò lọ́dọ̀ mi! Ó fi oko wa lé àwọn ọlọ̀tẹ̀ lọ́wọ́.’”
W tym dniu powstanie o was przypowieść i podniosą [nad wami] żałosny lament, mówiąc: Jesteśmy doszczętnie spustoszeni. Odmienił dział mego ludu, [jakże] mi go odjął! Gdy wziął nasze pole, rozdzielił [je].
5 Nítorí náà, ìwọ kò ní ní ẹnìkankan tí yóò ta okùn nínú ìjọ Olúwa, tí yóò pín ilẹ̀ nípa ìbò.
Dlatego nie będziesz miał nikogo, kto rzuciłby sznurem na los w zgromadzeniu PANA.
6 “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀,” ni àwọn wòlíì wọn wí. “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀ nípa nǹkan wọ̀nyí; kí ìtìjú má ṣe le bá wa.”
Mówią: Nie prorokujcie, niech nam [inni] prorokują. Nie prorokują bowiem tak, jak ci. Żaden z nich nie przestaje mówić obraźliwie.
7 Ṣé kí á sọ ọ́, ìwọ ilé Jakọbu: “Ǹjẹ́ ẹ̀mí Olúwa ha ń bínú bí? Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ ha nìwọ̀nyí?” “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ mi kò ha ń ṣe rere fún ẹni tí ń rìn déédé bí?
O ty, [ludu, który] słyniesz domem Jakuba! Czy Duch PANA jest ograniczony? Czy takie [są] jego dzieła? Czy moje słowa nie są dobre [dla tego], który postępuje w sposób prawy?
8 Láìpẹ́ àwọn ènìyàn mi dìde bí ọ̀tá sí mi. Ìwọ bọ́ aṣọ ọlọ́rọ̀ kúrò lára àwọn tí ń kọjá lọ ní àìléwu, bí àwọn ẹni tí ó padà bọ̀ láti ojú ogun.
Wczoraj był moim ludem, [a dziś] jak wróg powstaje. Zdzieracie płaszcz wraz z szatą z tych, którzy przechodzą bezpiecznie, jakby wracali z wojny.
9 Ẹ̀yin sì lé obìnrin àwọn ènìyàn mi kúrò nínú ilé ayọ̀ wọn, ẹ̀yin sì ti gba ògo mi, kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ wọn láéláé.
Kobiety mego ludu wyganiacie z ich przytulnych domów; ich dzieciom odebraliście moją chwałę na zawsze.
10 Ẹ dìde, kí ẹ sì máa lọ! Nítorí èyí kì í ṣe ibi ìsinmi yín, nítorí tí a ti sọ ọ́ di àìmọ́ yóò pa yín run, àní ìparun kíkorò.
Wstańcie i odejdźcie, bo tu nie ma odpoczynku. Z powodu nieczystości zniszczy was, i to zniszczeniem srogim.
11 Tí òpùrọ́ àti ẹlẹ́tàn bá wà tí wọ́n sì wí pé, ‘Èmi yóò sọtẹ́lẹ̀ fún ọ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wáìnì àti ọtí líle,’ òun ni yóò tilẹ̀ ṣe wòlíì àwọn ènìyàn wọ̀nyí!
Gdy ktoś podaje się za proroka i kłamie, [mówiąc]: Będę prorokował o winie i o mocnym napoju, to taki staje się prorokiem tego ludu.
12 “Èmi yóò kó gbogbo yín jọ, ìwọ Jakọbu; Èmi yóò gbá ìyókù Israẹli jọ. Èmi yóò kó wọn jọ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú agbo ẹran, gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nínú agbo wọn, ibẹ̀ yóò sì pariwo nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.
Na pewno zgromadzę ciebie całego, Jakubie, na pewno zgromadzę resztkę Izraela. Zbiorę ich razem jak owce Bozra, jak trzodę w środku owczarni, i będzie bardzo głośno z powodu [mnóstwa] ludzi.
13 Ẹni tí ó ń fọ ọ̀nà yóò lọ sókè níwájú wọn; wọn yóò fọ láti ẹnu ibodè, wọn yóò sì jáde lọ. Àwọn ọba wọn yóò sì kọjá lọ níwájú wọn, Olúwa ni yóò sì ṣe olórí wọn.”
Zstąpi przed nimi ten, który będzie przełamywać. Przełamali się, przeszli przez bramę i wyszli przez nią. Ich król pójdzie przed nimi, a PAN na ich czele.

< Micah 2 >