< Micah 2 >

1 Ègbé ni fún àwọn tí ń gbèrò àìṣedéédéé tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ibi lórí ibùsùn wọn! Nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́, wọn yóò gbé e jáde nítorí ó wà ní agbára wọn láti ṣe é.
Asi pay dagiti agpanggep iti kinadakes, dagiti adda iti pagiddaanda nga agpangpanggep nga agaramid iti dakes. Aramidenda dagitoy iti agsapa gapu ta addaanda iti pannakabael.
2 Wọ́n sì ń ṣe ojúkòkòrò oko, wọ́n sì fi agbára wọn gbà wọ́n, àti àwọn ilé, wọ́n sì gbà wọ́n. Wọ́n sì ni ènìyàn àti ilẹ̀ rẹ̀ lára àní ènìyàn àti ohun ìní rẹ̀.
Tarigagayanda dagiti talon ket agawenda dagitoy; tarigagayanda dagiti balay ket alaenda dagitoy. Irurumenda ti tao ken ti balayna, ti tao ken ti tawidna.
3 Nítorí náà, Olúwa wí pé: “Èmi ń gbèrò ibi sí àwọn ìdílé wọ̀nyí, nínú èyí tí wọn kì yóò le è gba ara wọn là. Ìwọ kì yóò sì lè máa rìn ní ìgbéraga mọ́, nítorí yóò jẹ́ àkókò ibi.
Ngarud, kastoy ti kuna ni Yahweh: “Kitaem, mangiyegak iti didigra iti daytoy a puli, ket saankayonto a makalisi. Saankayonton a magna a sipapalangguad, ta dakesto dayta a tiempo.
4 Ní ọjọ́ náà ni ẹnìkan yóò pa òwe kan sí yín; wọn yóò sì pohùnréré ẹkún kíkorò pé: ‘Ní kíkó a ti kó wọn tán; Olúwa ti pín ohun ìní àwọn ènìyàn mi; Ó ti mú un kúrò lọ́dọ̀ mi! Ó fi oko wa lé àwọn ọlọ̀tẹ̀ lọ́wọ́.’”
Iti dayta nga aldaw, agkantanto dagiti kabusoryo iti maipapan kadakayo, ket agdung-awkayonto nga addaan panagasug. Kantaendanto, 'Dakami nga Israelita, nadadaelkamin a naminpinsan; binaliwanen ni Yahweh ti territoryo dagiti tattaok. Alaenna kadi met daytoy kaniak? Imbunongna dagiti talonmi kadagiti mangliliput!”'
5 Nítorí náà, ìwọ kò ní ní ẹnìkankan tí yóò ta okùn nínú ìjọ Olúwa, tí yóò pín ilẹ̀ nípa ìbò.
Ngarud, dakayo a nababaknang, awanto ti kaputotanyo nga umawat iti daga a kas bingayna iti pannakaibunong ti daga iti gimong ni Yahweh.
6 “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀,” ni àwọn wòlíì wọn wí. “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀ nípa nǹkan wọ̀nyí; kí ìtìjú má ṣe le bá wa.”
“Saanka nga agipadto,” kunada. “Masapul a saanda nga ipadtoda dagitoy a banbanag; saan nga umay ti pannakaibabain.”
7 Ṣé kí á sọ ọ́, ìwọ ilé Jakọbu: “Ǹjẹ́ ẹ̀mí Olúwa ha ń bínú bí? Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ ha nìwọ̀nyí?” “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ mi kò ha ń ṣe rere fún ẹni tí ń rìn déédé bí?
Rumbeng kadi a kastoy ti kunayo, O balay ni Jacob, “Makaunget kadi ti espiritu ni Yahweh? Pudno kadi a dagitoy ti aramidna?” Saan kadi a nasayaat dagiti sasaok iti siasinoman nga agar-aramid iti nalinteg?
8 Láìpẹ́ àwọn ènìyàn mi dìde bí ọ̀tá sí mi. Ìwọ bọ́ aṣọ ọlọ́rọ̀ kúrò lára àwọn tí ń kọjá lọ ní àìléwu, bí àwọn ẹni tí ó padà bọ̀ láti ojú ogun.
Iti nabiit pay, bimmusor dagiti tattaok a kasla maysa a kabusor. Ussobenyo ti kagay, ti kawes dagiti aglabas a mangpanpanunot a natalgeddan, a kas dagiti soldado a naggapu iti gubat nga iti pagarupda ket natalgeddan.
9 Ẹ̀yin sì lé obìnrin àwọn ènìyàn mi kúrò nínú ilé ayọ̀ wọn, ẹ̀yin sì ti gba ògo mi, kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ wọn láéláé.
Pinapanawyo dagiti babbai a tattaok kadagiti napintas a balayda; innalayo ti bendisionko kadagiti annakda iti agnanayon.
10 Ẹ dìde, kí ẹ sì máa lọ! Nítorí èyí kì í ṣe ibi ìsinmi yín, nítorí tí a ti sọ ọ́ di àìmọ́ yóò pa yín run, àní ìparun kíkorò.
Tumakderkayo ket pumanawkayo, ta saan a daytoy ti lugar a mabalinyo a pagyanan, gapu iti kinarugitna; naan-anay a nadadael daytoy.
11 Tí òpùrọ́ àti ẹlẹ́tàn bá wà tí wọ́n sì wí pé, ‘Èmi yóò sọtẹ́lẹ̀ fún ọ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wáìnì àti ọtí líle,’ òun ni yóò tilẹ̀ ṣe wòlíì àwọn ènìyàn wọ̀nyí!
No adda umay kadakayo nga addaan iti espiritu iti kinamanaginkukuna ken kinaulbod ket kunana, “Agipadtoak kadakayo maipapan iti arak ken naingel a mainum,” ket isuna ti kayatyo nga agbalin a profetayo.
12 “Èmi yóò kó gbogbo yín jọ, ìwọ Jakọbu; Èmi yóò gbá ìyókù Israẹli jọ. Èmi yóò kó wọn jọ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú agbo ẹran, gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nínú agbo wọn, ibẹ̀ yóò sì pariwo nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.
Siguradoek nga ummongenkayonto amin, O Jacob. Siguradoek nga ummongekto dagiti nabatbati iti Israel. Pagtitiponekto ida a kasla karnero iti koral, a kas iti arban iti tengnga ti pagarabanda. Addanto ti napigsa nga ariwawa gapu iti adu a tattao.
13 Ẹni tí ó ń fọ ọ̀nà yóò lọ sókè níwájú wọn; wọn yóò fọ láti ẹnu ibodè, wọn yóò sì jáde lọ. Àwọn ọba wọn yóò sì kọjá lọ níwájú wọn, Olúwa ni yóò sì ṣe olórí wọn.”
Addanto ti mangilukat iti dalanda nga isu iti umuna kadakuada. Luktanda ti ruangan ket rimmuarda; lumabasto ti arida iti sangoananda. Ni Yahweh ti mangidaulonto kadakuada.

< Micah 2 >