< Micah 2 >
1 Ègbé ni fún àwọn tí ń gbèrò àìṣedéédéé tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ibi lórí ibùsùn wọn! Nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́, wọn yóò gbé e jáde nítorí ó wà ní agbára wọn láti ṣe é.
Oh azok kik jogtalanságot gondolnak ki és rosszat cselekesznek fekvőhelyeiken; a reggel virradtakor megcselekszik, mert van rá mód a kezükben.
2 Wọ́n sì ń ṣe ojúkòkòrò oko, wọ́n sì fi agbára wọn gbà wọ́n, àti àwọn ilé, wọ́n sì gbà wọ́n. Wọ́n sì ni ènìyàn àti ilẹ̀ rẹ̀ lára àní ènìyàn àti ohun ìní rẹ̀.
Megkívánnak mezőket és elrabolják, házakat, és elveszik; kifosztják a férfit és házát, embert és birtokát.
3 Nítorí náà, Olúwa wí pé: “Èmi ń gbèrò ibi sí àwọn ìdílé wọ̀nyí, nínú èyí tí wọn kì yóò le è gba ara wọn là. Ìwọ kì yóò sì lè máa rìn ní ìgbéraga mọ́, nítorí yóò jẹ́ àkókò ibi.
Azért így szól az Örökkévaló: Íme én kigondolok a nemzetség ellen veszedelmet, a honnan nem mozdíthatjátok el a nyakatokat, és nem járhattok magasan, mert gonosz idő az.
4 Ní ọjọ́ náà ni ẹnìkan yóò pa òwe kan sí yín; wọn yóò sì pohùnréré ẹkún kíkorò pé: ‘Ní kíkó a ti kó wọn tán; Olúwa ti pín ohun ìní àwọn ènìyàn mi; Ó ti mú un kúrò lọ́dọ̀ mi! Ó fi oko wa lé àwọn ọlọ̀tẹ̀ lọ́wọ́.’”
Ama napon példázatot hangoztatnak rólatok: és jajgatnak jajgató jajgatással, mondván: Pusztítva pusztíttattunk el, népemnek osztályrészét másnak adja – mint mozdít el engem! – a hódítónak, ki mezőnket felosztja.
5 Nítorí náà, ìwọ kò ní ní ẹnìkankan tí yóò ta okùn nínú ìjọ Olúwa, tí yóò pín ilẹ̀ nípa ìbò.
Azért nem lesz neked, ki mérőkötelet vet a sors útján az Örökkévalónak gyülekezetében!
6 “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀,” ni àwọn wòlíì wọn wí. “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀ nípa nǹkan wọ̀nyí; kí ìtìjú má ṣe le bá wa.”
Ne szónokoljatok! – szónokolják; ne szónokoljanak ezeknek, nem szűnik meg a gyalázkodás!
7 Ṣé kí á sọ ọ́, ìwọ ilé Jakọbu: “Ǹjẹ́ ẹ̀mí Olúwa ha ń bínú bí? Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ ha nìwọ̀nyí?” “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ mi kò ha ń ṣe rere fún ẹni tí ń rìn déédé bí?
Mily mondás, oh Jákób háza, vajon kifogyott-e az Örökkévaló türeleme, avagy ilyenek-e az ő cselekedetei? Nemde jót tesznek szavaim az egyenesen járóval.
8 Láìpẹ́ àwọn ènìyàn mi dìde bí ọ̀tá sí mi. Ìwọ bọ́ aṣọ ọlọ́rọ̀ kúrò lára àwọn tí ń kọjá lọ ní àìléwu, bí àwọn ẹni tí ó padà bọ̀ láti ojú ogun.
De népem ellenében ellenségül támadnak: felül a ruhán lehúzzátok a köpenyt azokról, kik bizton vonulnak, harczból visszatérve.
9 Ẹ̀yin sì lé obìnrin àwọn ènìyàn mi kúrò nínú ilé ayọ̀ wọn, ẹ̀yin sì ti gba ògo mi, kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ wọn láéláé.
Népemnek asszonyait kiűzitek gyönyörködésük házából, kisdedeikről leszeditek az én ékességemet mindétig!
10 Ẹ dìde, kí ẹ sì máa lọ! Nítorí èyí kì í ṣe ibi ìsinmi yín, nítorí tí a ti sọ ọ́ di àìmọ́ yóò pa yín run, àní ìparun kíkorò.
Keljetek föl s menjetek, mert nem ez a nyugalom, a rontó tisztátalanság, az iszonyú romlás miatt.
11 Tí òpùrọ́ àti ẹlẹ́tàn bá wà tí wọ́n sì wí pé, ‘Èmi yóò sọtẹ́lẹ̀ fún ọ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wáìnì àti ọtí líle,’ òun ni yóò tilẹ̀ ṣe wòlíì àwọn ènìyàn wọ̀nyí!
Ha valaki, ki széllel és hamissággal jár, azt hazudja szónokolok neked borról és részegítő italról, az lenne a népnek szónokklója.
12 “Èmi yóò kó gbogbo yín jọ, ìwọ Jakọbu; Èmi yóò gbá ìyókù Israẹli jọ. Èmi yóò kó wọn jọ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú agbo ẹran, gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nínú agbo wọn, ibẹ̀ yóò sì pariwo nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.
Gyűjtve gyűjtelek, Jákób, egészen, összehozva összehozom Izraél maradékát, egyaránt ollyá teszem, mint az akol juhait, mint nyáj a legelőjén, zajongni fognak embertől.
13 Ẹni tí ó ń fọ ọ̀nà yóò lọ sókè níwájú wọn; wọn yóò fọ láti ẹnu ibodè, wọn yóò sì jáde lọ. Àwọn ọba wọn yóò sì kọjá lọ níwájú wọn, Olúwa ni yóò sì ṣe olórí wọn.”
Haladt az úttörő előttük, áttörnek és elvonulnak, a kapun mentek ki; előttük vonult királyuk, az Örökkévaló élükön!