< Micah 2 >

1 Ègbé ni fún àwọn tí ń gbèrò àìṣedéédéé tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ibi lórí ibùsùn wọn! Nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́, wọn yóò gbé e jáde nítorí ó wà ní agbára wọn láti ṣe é.
Malheur à ceux qui pensent à faire outrage, qui forgent le mal sur leurs lits, et qui l'exécutent dès le point du jour, parce qu'ils ont le pouvoir en main.
2 Wọ́n sì ń ṣe ojúkòkòrò oko, wọ́n sì fi agbára wọn gbà wọ́n, àti àwọn ilé, wọ́n sì gbà wọ́n. Wọ́n sì ni ènìyàn àti ilẹ̀ rẹ̀ lára àní ènìyàn àti ohun ìní rẹ̀.
S'ils convoitent des possessions, ils les ont aussitôt ravies, et [s'ils convoitent] des maisons, ils les ont aussitôt prises; ainsi ils oppriment l'homme et sa maison, l'homme, dis-je, et son héritage.
3 Nítorí náà, Olúwa wí pé: “Èmi ń gbèrò ibi sí àwọn ìdílé wọ̀nyí, nínú èyí tí wọn kì yóò le è gba ara wọn là. Ìwọ kì yóò sì lè máa rìn ní ìgbéraga mọ́, nítorí yóò jẹ́ àkókò ibi.
C'est pourquoi ainsi a dit l'Eternel: Voici, je pense contre cette famille-ci un mal duquel vous ne pourrez point vous mettre à couvert, et vous ne marcherez point à tête levée; car ce temps [est] mauvais.
4 Ní ọjọ́ náà ni ẹnìkan yóò pa òwe kan sí yín; wọn yóò sì pohùnréré ẹkún kíkorò pé: ‘Ní kíkó a ti kó wọn tán; Olúwa ti pín ohun ìní àwọn ènìyàn mi; Ó ti mú un kúrò lọ́dọ̀ mi! Ó fi oko wa lé àwọn ọlọ̀tẹ̀ lọ́wọ́.’”
En ce temps-là on fera de vous un proverbe lugubre, et l'on gémira d'un gémissement lamentable, en disant: Nous sommes entièrement détruits, il a changé la portion de mon peuple; comment nous l'aurait-il ôtée? partage-t-il nos champs, pour nous les faire rendre?
5 Nítorí náà, ìwọ kò ní ní ẹnìkankan tí yóò ta okùn nínú ìjọ Olúwa, tí yóò pín ilẹ̀ nípa ìbò.
C'est pourquoi il n'y aura personne pour toi qui jette le cordeau pour ton lot dans la congrégation de l'Eternel.
6 “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀,” ni àwọn wòlíì wọn wí. “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀ nípa nǹkan wọ̀nyí; kí ìtìjú má ṣe le bá wa.”
[On dit]: Ne prophétisez point, ils prophétiseront, [mais] ils ne prophétiseront point pour ceux-ci; l'ignominie ne tournera point en arrière.
7 Ṣé kí á sọ ọ́, ìwọ ilé Jakọbu: “Ǹjẹ́ ẹ̀mí Olúwa ha ń bínú bí? Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ ha nìwọ̀nyí?” “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ mi kò ha ń ṣe rere fún ẹni tí ń rìn déédé bí?
Or toi qui es appelée Maison de Jacob, l'Esprit de l'Eternel est-il amoindri? Sont-ce là ses actes? Mes paroles ne sont-elles pas bonnes pour celui qui marche droitement?
8 Láìpẹ́ àwọn ènìyàn mi dìde bí ọ̀tá sí mi. Ìwọ bọ́ aṣọ ọlọ́rọ̀ kúrò lára àwọn tí ń kọjá lọ ní àìléwu, bí àwọn ẹni tí ó padà bọ̀ láti ojú ogun.
Mais celui qui était hier mon peuple, s'élève à la manière d'un ennemi, pour rencontrer un manteau; vous dépouillez le vêtement magnifique à ceux qui passent en assurance, étant de retour de la guerre.
9 Ẹ̀yin sì lé obìnrin àwọn ènìyàn mi kúrò nínú ilé ayọ̀ wọn, ẹ̀yin sì ti gba ògo mi, kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ wọn láéláé.
Vous mettez les femmes de mon peuple hors des maisons où elles prenaient plaisir; vous ôtez pour jamais ma gloire de dessus leurs petits enfants.
10 Ẹ dìde, kí ẹ sì máa lọ! Nítorí èyí kì í ṣe ibi ìsinmi yín, nítorí tí a ti sọ ọ́ di àìmọ́ yóò pa yín run, àní ìparun kíkorò.
Levez-vous, et marchez, car [ce pays] ne [vous est] plus [un lieu de] repos; parce qu'il est souillé, il [vous] détruira, même d'une prompte destruction.
11 Tí òpùrọ́ àti ẹlẹ́tàn bá wà tí wọ́n sì wí pé, ‘Èmi yóò sọtẹ́lẹ̀ fún ọ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wáìnì àti ọtí líle,’ òun ni yóò tilẹ̀ ṣe wòlíì àwọn ènìyàn wọ̀nyí!
S'il y a quelque homme qui marche selon le vent, et qui mente faussement, [en disant]; Je te prophétiserai du vin et de la cervoise; ce sera le Prophète de ce peuple.
12 “Èmi yóò kó gbogbo yín jọ, ìwọ Jakọbu; Èmi yóò gbá ìyókù Israẹli jọ. Èmi yóò kó wọn jọ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú agbo ẹran, gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nínú agbo wọn, ibẹ̀ yóò sì pariwo nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.
[Mais] je t'assemblerai tout entier, ô Jacob! et je ramasserai entièrement le reste d'Israël, et le mettrai tout ensemble comme les brebis de Botsra, comme un troupeau au milieu de son étable; il y aura un grand bruit pour la foule des hommes.
13 Ẹni tí ó ń fọ ọ̀nà yóò lọ sókè níwájú wọn; wọn yóò fọ láti ẹnu ibodè, wọn yóò sì jáde lọ. Àwọn ọba wọn yóò sì kọjá lọ níwájú wọn, Olúwa ni yóò sì ṣe olórí wọn.”
Le briseur montera devant eux, on brisera, et on passera outre, et eux sortiront par la porte; et leur Roi passera devant eux, et l'Eternel sera à leur tête.

< Micah 2 >