< Micah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.
در دوران سلطنت یوتام و آحاز و حِزِقیا، پادشاهان یهودا، خداوند این پیام را دربارهٔ اورشلیم و سامره، به صورت رؤیا به میکاه مورشتی داد.
2 Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn, fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, kí Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.
ای تمام قومها بشنوید! ای همهٔ ساکنان زمین گوش دهید! خداوند از خانه مقدّس خود بر ضد شما شهادت می‌دهد.
3 Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀; yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
اینک خداوند تخت فرمانروایی خود را در آسمان ترک کرده و از فراز کوهها به زمین می‌آید.
4 Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀, àwọn àfonífojì yóò sì pínyà, bí idà níwájú iná, bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
کوهها در زیر پاهایش مثل موم آب می‌شوند و مانند سیل از بلندیها به دره سرازیر می‌گردند.
5 Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí, àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli. Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu? Ǹjẹ́ Samaria ha kọ? Kí ni àwọn ibi gíga Juda? Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?
تمام اینها به سبب گناهان مردم اسرائیل و یهودا اتفاق می‌افتد. بت‌پرستی و عِصیان سامره و اورشلیم را که پایتختهای اسرائیل و یهودا هستند، پر ساخته است.
6 “Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá, bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà. Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì. Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
خداوند می‌فرماید: «شهر سامره را به صورت توده‌ای از خاک درمی‌آورم؛ آن را چنان شخم می‌زنم که بتوان برای کشت انگور از آن استفاده کرد. حصار و قلعه‌های آن را خراب کرده، سنگهایش را به دره می‌ریزم تا بنیادش نمایان شود.
7 Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run. Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà, gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”
تمام بتهایش خرد خواهند شد و همۀ هدایای معبدش در آتش خواهند سوخت. من همۀ تمثالهایش را نابود خواهم کرد. او هدایایش را از فاحشگی به دست آورده است، پس آنها را از دست خواهد داد و آنها به فاحشه‌های دیگر داده خواهند شد.»
8 Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún, èmi yóò sì pohùnréré ẹkún: èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò. Èmi yóò ké bí akátá, èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
من گریه می‌کنم و ماتم می‌گیرم، مثل شغال زوزه می‌کشم و مانند جغد شیون می‌کنم. از غصه و سرافکندگی با پای برهنه و تن عریان راه می‌روم،
9 Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán; ó sì ti wá sí Juda. Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi, àní sí Jerusalẹmu.
چون زخم قوم من عمیقتر از آن است که شفا یابد. زیرا ویرانی به یهودا و حتی به دروازه‌های اورشلیم نیز رسیده است.
10 Ẹ má ṣe sọ ní Gati ẹ má ṣe sọkún rárá. Ní ilẹ̀ Beti-Ofra mo yí ara mi nínú eruku.
این را به شهر جت نگویید و نگذارید اهالی آنجا گریهٔ شما را بشنوند! ای ساکنان بیت‌عفره از شدت درد و شرمندگی در خاک بغلتید!
11 Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú, ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri. Àwọn tí ó ń gbé ni Saanani kì yóò sì jáde wá. Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀; a ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
مردم شافیر برهنه و سرافکنده به اسارت برده می‌شوند. اهالی صعنان جرأت نمی‌کنند از خانه‌هایشان بیرون بیایند. وقتی صدای ماتم مردم بیت‌ایصل را بشنوید، بدانید که در آنجا پناهگاهی نیست.
12 Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre, ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
ساکنان ماروت از فرط انتظار بیمار شده‌اند، چون بلا از جانب خداوند بر ضد اورشلیم نازل شده است.
13 Ìwọ olùgbé Lakiṣi, dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára. Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀ sí àwọn ọmọbìnrin Sioni, nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
ای مردم لاکیش بشتابید! بر سریعترین ارابه‌های خود سوار شده، فرار کنید، چون شما اولین شهر یهودا بودید که گناه بت‌پرستی اسرائیل را دنبال کردید و برای سایر شهرها سرمشق شدید.
14 Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún Moreṣeti Gati. Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
ای مردم یهودا، هدایای خداحافظی به شهر مورِشِت جَت بفرستید، زیرا امیدی برای نجات آن نیست. شهر اکزیب پادشاهان اسرائیل را فریفته است.
15 Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa. Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli yóò sì wá sí Adullamu.
ای مردم مریشه، دشمنانتان بر شما مسلط خواهند شد و بزرگان اسرائیل به غار عدولام پناه خواهند برد.
16 Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára, sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún, nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.
برای فرزندان خود ماتم کنید، چون آنها را از آغوشتان خواهند ربود و دیگر هرگز آنها را نخواهید دید. سرهایتان را بتراشید و خود را مانند کرکس کچل سازید، زیرا فرزندان عزیزتان را به سرزمینهای دور دست به اسارت خواهند برد.

< Micah 1 >