< Micah 1 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.
Et la parole de Dieu vint à Michée, fils de Morasthi, aux jours de Joatham, Achaz et Ézéchias, rois de Juda, sur les choses qu'il vit concernant Samarie et Jérusalem.
2 Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn, fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, kí Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.
Écoutez, peuples, ces paroles; que toute la terre soit attentive, et tous ceux qu'elle contient. Et le Seigneur Maître sera parmi nous comme un témoignage, le Seigneur du haut de Sa maison sainte.
3 Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀; yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
Car voilà que le Seigneur sortira du lieu où Il réside, et Il descendra, et Il marchera sur les hauteurs de la terre.
4 Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀, àwọn àfonífojì yóò sì pínyà, bí idà níwájú iná, bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
Et sous Lui les montagnes seront émues, et les vallées fondront comme la cire devant le feu, et comme les eaux d'une cataracte.
5 Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí, àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli. Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu? Ǹjẹ́ Samaria ha kọ? Kí ni àwọn ibi gíga Juda? Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?
Et tout cela arrivera à cause de l'impiété de Jacob et des péchés de la maison d'Israël. Quelle est l'impiété de Jacob? n'est-ce pas Samarie? Quel est le péché de Juda? n'est-ce pas Jérusalem?
6 “Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá, bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà. Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì. Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
Je rendrai Samarie comme la cabane d'un garde de vergers dans les champs, comme un plant de vigne; et J'arracherai ses pierres pour les jeter dans le ravin, et Je mettrai à découvert ses fondations.
7 Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run. Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà, gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”
Et toutes ses statues tomberont; et tous ses salaires qu'elle a reçus seront livrés aux flammes; et J'anéantirai toutes ses idoles; car elle a amassé des salaires de prostitution; et de ces salaires de prostitution elle s'est enrichie.
8 Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún, èmi yóò sì pohùnréré ẹkún: èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò. Èmi yóò ké bí akátá, èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
À cause de cela, elle se frappera la poitrine et se lamentera; elle ira nue et déchaussée; ses lamentations seront comme les sifflements du dragon, et ses plaintes comme celles des filles des Sirènes.
9 Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán; ó sì ti wá sí Juda. Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi, àní sí Jerusalẹmu.
Car la plaie l'accable; sa plaie s'est étendue jusqu'en Juda, et touche aux portes de Mon peuple, à Jérusalem.
10 Ẹ má ṣe sọ ní Gati ẹ má ṣe sọkún rárá. Ní ilẹ̀ Beti-Ofra mo yí ara mi nínú eruku.
Ô vous, gens de Geth, ne vous glorifiez pas; vous, gens d'Énacim, n'édifiez pas avec les ruines du temple par dérision; mais répandez de la poussière sur vos têtes par dérision de vous-mêmes!
11 Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú, ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri. Àwọn tí ó ń gbé ni Saanani kì yóò sì jáde wá. Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀; a ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
La populeuse Sennaar, qui habite en joie ses villes, n'en est point sortie pour pleurer une maison voisine; elle entendra votre plainte douloureuse.
12 Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre, ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
Qui a commencé à faire du bien à celle qui habitait dans la douleur? Car les maux sont aussi descendus, par le Seigneur, jusqu'aux portes de Jérusalem,
13 Ìwọ olùgbé Lakiṣi, dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára. Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀ sí àwọn ọmọbìnrin Sioni, nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
avec le tumulte des chars et des cavaliers. Celle qui demeure en Lachis est pour le fille de Sion le principe de son péché; car en toi se sont trouvés les impiétés d'Israël.
14 Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún Moreṣeti Gati. Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
À cause de cela, le Seigneur enverra des vengeurs jusqu'aux héritages de Geth, et jusqu'aux maisons vaines qui ont été vanités pour les rois d'Israël.
15 Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa. Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli yóò sì wá sí Adullamu.
Et ils emmèneront tes héritiers, ô toi qui demeures en Lachis! L'héritage de gloire de la fille d'Israël ne subsistera pas au delà d'Odollam.
16 Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára, sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún, nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.
Rase-toi, coupe ta chevelure à cause de tes enfants, qui font tes délices; dilate ton veuvage comme un aigle; car on les a emmenés en captivité hors de toi.