< Micah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.
Parole de Dieu qui fut adressée, du temps de Jotham, Achaz, Ezéchias, rois de Juda, à Michée de Moréchet, lequel prophétisa au sujet de Samarie et de Jérusalem:
2 Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn, fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, kí Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.
"Ecoutez, peuples, écoutez tous! Prête ton attention, ô terre, toi et ce que tu renfermes! Que le Seigneur Dieu serve de témoin contre vous, le Seigneur du fond de sa sainte résidence!
3 Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀; yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
Oui, voici l’Eternel qui sort de sa demeure, qui descend et foule les hauteurs de la terre.
4 Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀, àwọn àfonífojì yóò sì pínyà, bí idà níwájú iná, bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
Sous ses pas, les montagnes se liquéfient, lés vallées se crevassent: ainsi la cire fond sous l’action du feu et les eaux se précipitent sur une pente.
5 Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí, àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli. Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu? Ǹjẹ́ Samaria ha kọ? Kí ni àwọn ibi gíga Juda? Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?
Tout cela à cause de l’infidélité de Jacob et des prévarications de la maison d’Israël. A qui imputer l’infidélité de Jacob? N’Est-ce point à Samarie? A qui les hauts-lieux de Juda? N’Est-ce point à Jérusalem?
6 “Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá, bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà. Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì. Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
Aussi ferai-je de Samarie un champ de décombres, un terrain de plantation pour des vignes. Je lancerai ses pierres dans la vallée et mettrai à nu ses fondations.
7 Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run. Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà, gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”
Toutes ses images sculptées seront fracassées, ses présents d’amour consumés par le feu; toutes ses statues, je les réduirai en ruines; car les ayant amassées avec le salaire de la prostitution, elle les verra s’en aller en salaire de prostitution.
8 Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún, èmi yóò sì pohùnréré ẹkún: èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò. Èmi yóò ké bí akátá, èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
C’Est pour cela que je veux donner cours à mes plaintes, à mes lamentations, circuler pieds-nus et sans vêtements, poussant des hurlements lugubres comme les chacals et des cris plaintifs comme les autruches.
9 Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán; ó sì ti wá sí Juda. Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi, àní sí Jerusalẹmu.
Car cuisants sont les maux qui l’ont frappée, ils atteignent même Juda, s’étendent jusqu’à la porte de mon peuple, jusqu’à Jérusalem.
10 Ẹ má ṣe sọ ní Gati ẹ má ṣe sọkún rárá. Ní ilẹ̀ Beti-Ofra mo yí ara mi nínú eruku.
Ne le racontez pas à Gath! Evitez de pousser des sanglots! Dans les maisons de Afra, roulez-vous dans la poussière!
11 Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú, ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri. Àwọn tí ó ń gbé ni Saanani kì yóò sì jáde wá. Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀; a ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
Suivez votre chemin, habitants de Chafir, dans une nudité honteuse! Les habitants de Caanân, eux, n’osent pas sortir; le deuil de Bethaêcel vous ôte l’envie d’y séjourner.
12 Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre, ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
Les habitants de Maroth tremblent pour leur bien-être, puisque déjà, de par l’Eternel, le malheur a fondu sur les portes de Jérusalem.
13 Ìwọ olùgbé Lakiṣi, dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára. Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀ sí àwọn ọmọbìnrin Sioni, nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
Attachez les chars aux coursiers, habitants de Lakhich! Tu fus une source de péché pour la fille de Sion, car c’est bien chez toi que se trouvent les crimes d’Israël.
14 Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún Moreṣeti Gati. Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
C’Est pourquoi tu diras adieu à Moréchet-Gath; les maisons d’Akhzib sont une déception pour les rois d’Israël.
15 Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa. Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli yóò sì wá sí Adullamu.
Une fois de plus, habitants de Marêcha, j’amènerai un conquérant contre toi; jusqu’à Adoullam parvient l’élite d’Israël.
16 Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára, sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún, nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.
Coupe-toi les cheveux, rase-toi à cause des enfants qui sont tes délices. Rends ta calvitie large comme les ailes de l’aigle, puisqu’ils te quittent pour aller en exil.

< Micah 1 >