< Matthew 9 >
1 Jesu bọ́ sínú ọkọ̀, ó sì rékọjá odò lọ sí ìlú abínibí rẹ̀,
Jezus wsiadł więc do łodzi i odpłynął do swojego miasta, Kafarnaum.
2 àwọn ọkùnrin kan gbé arọ kan tọ̀ ọ́ wá lórí àkéte rẹ̀. Nígbà tí Jesu rí ìgbàgbọ́ wọn, ó wí fún arọ náà pé, “Ọmọ tújúká, a dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ́.”
Tam kilku mężczyzn przyniosło do Niego na noszach sparaliżowanego. Widząc ich wiarę, Jezus rzekł do chorego: —Bądź dobrej myśli, synu. Odpuszczam ci grzechy!
3 Nígbà yìí ni àwọn olùkọ́ òfin wí fún ara wọn pé, “Ọkùnrin yìí ń sọ̀rọ̀-òdì!”
„To jawne bluźnierstwo!”—z oburzeniem pomyślało sobie kilku przywódców religijnych.
4 Jesu sì mọ̀ èrò inú wọn, ó wí pé, “Nítorí kín ni ẹ̀yin ṣe ń ro búburú nínú yín?
Jezus, znając ich myśli, zapytał: —Dlaczego was to oburza?
5 Èwo ni ó rọrùn jù: láti wí pé, ‘A dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ,’ tàbí wí pé, ‘Dìde, kí o sì máa rìn?’
Co jest łatwiej powiedzieć: „Odpuszczam ci grzechy” czy: „Wstań i chodź!”?
6 Ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin kí ó lè mọ̀ pé Ọmọ Ènìyàn ní agbára ní ayé láti dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì ni.” Ó sì wí fún arọ náà pé, “Dìde, sì gbé àkéte rẹ, kí o sì máa lọ ilé rẹ.”
Udowodnię wam, że Ja, Syn Człowieczy, mogę odpuszczać grzechy. I zwrócił się do sparaliżowanego: —Jesteś uzdrowiony! Zabierz swoje nosze i idź do domu!
7 Ọkùnrin náà sì dìde, ó sì lọ ilé rẹ̀.
A chory wstał i odszedł do domu.
8 Nígbà tí ìjọ ènìyàn rí í ẹnu sì yà wọ́n, wọ́n yin Ọlọ́run lógo, ti ó fi irú agbára báyìí fún ènìyàn.
Po zebranych przeszedł dreszcz lęku. I wielbili Boga za to, że dał taką moc człowiekowi!
9 Bí Jesu sì ti ń rékọjá láti ibẹ̀ lọ, o rí ọkùnrin kan ti à ń pè ní Matiu, ó jókòó ní ibùdó àwọn agbowó òde, ó sì wí fún un pé, “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn,” Matiu sì dìde, ó ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
Odchodząc stamtąd, Jezus zobaczył niejakiego Mateusza, poborcę podatkowego, który właśnie tam pracował. —Chodź ze Mną—zwrócił się do niego. A on natychmiast wstał i poszedł z Jezusem.
10 Ó sì ṣe, bí Jesu tí jókòó ti ó ń jẹun nínú ilé Matiu, sì kíyèsi i, ọ̀pọ̀ àwọn agbowó òde àti ẹlẹ́ṣẹ̀ wá, wọ́n sì bá a jẹun pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
Później, gdy Jezus i Jego uczniowie byli u niego w domu, zebrało się wokół stołu wielu nieuczciwych poborców podatkowych i innych ludzi, uważanych za grzeszników.
11 Nígbà tí àwọn Farisi sì rí i, wọ́n wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Èéṣe tí olùkọ́ yín fi ń bá àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ jẹun pọ̀?”
Widząc to, faryzeusze mówili do uczniów: —Dlaczego wasz nauczyciel zadaje się z takimi ludźmi?
12 Ṣùgbọ́n nígbà tí Jesu gbọ́ èyí, ó wí fún wọn pé, “Àwọn tí ara wọ́n le kò wá oníṣègùn bí kò ṣe àwọn tí ara wọn kò dá.
Jezus usłyszał to i odpowiedział: —To chorzy potrzebują lekarza, a nie zdrowi!
13 Ṣùgbọ́n ẹ lọ kọ́ ohun ti èyí túmọ̀ sí: ‘Àánú ni èmi ń fẹ́, kì í ṣe ẹbọ,’ nítorí èmi kò wá láti pe àwọn olódodo, bí kò ṣe àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.”
Idźcie i zastanówcie się nad słowami Pisma: „Pragnę waszej miłości, a nie ofiar”. Nie przyszedłem wzywać do opamiętania się tych, którzy uważają się za dobrych, ale właśnie grzeszników.
14 Nígbà náà ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu tọ̀ ọ́ wá láti béèrè wí pé, “Èéṣe tí àwa àti àwọn Farisi fi ń gbààwẹ̀, ṣùgbọ́n tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ kò gbààwẹ̀?”
Pewnego razu przyszli do Jezusa uczniowie Jana Chrzciciela i zapytali Go: —My i faryzeusze, stosując się do religijnych zaleceń, często powstrzymujemy się od posiłków. Dlaczego Twoi uczniowie tego nie czynią?
15 Jesu sì dáhùn pé, “Àwọn ọmọ ilé ìyàwó ha le máa ṣọ̀fọ̀, nígbà tí ọkọ ìyàwó ń bẹ lọ́dọ̀ wọn? Ṣùgbọ́n ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí a ó gba ọkọ ìyàwó lọ́wọ́ wọn; nígbà náà ni wọn yóò gbààwẹ̀.
—Przecież goście na weselu, będąc z panem młodym, nie mogą się smucić!—odrzekł Jezus. —Ale nadejdzie czas, gdy zabiorą im pana młodego. Wtedy będą pościć.
16 “Kò sí ẹni tí ń fi ìrépé aṣọ tuntun lẹ ògbólógbòó ẹ̀wù; nítorí èyí tí a fi lẹ̀ ẹ́ yóò ya ní ojú lílẹ̀, aṣọ náà yóò sì ya púpọ̀ sì i ju ti ìṣáájú lọ.
Nikt nie używa nowego materiału do łatania starego ubrania, bo nowa łata się kurczy i jeszcze bardziej rozdziera ubranie.
17 Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí fi ọtí tuntun sínú ògbólógbòó ìgò-awọ; bí a bá ṣe bẹ́ẹ̀, ìgò-awọ yóò bẹ́, ọtí á sì tú jáde, ìgò-awọ á sì ṣègbé. Ṣùgbọ́n ọtí tuntun ni wọn í fi sínú ìgò-awọ tuntun àwọn méjèèjì a sì ṣe déédé.”
Nie wlewa się też świeżego wina do starych, stwardniałych bukłaków. Mogłyby przecież popękać, a wtedy i wino by się rozlało, i bukłaki zniszczyły. Świeże wino wlewa się do nowych, miękkich bukłaków. W ten sposób i jedno, i drugie się zachowuje.
18 Bí ó ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí fún wọn, kíyèsi i, ìjòyè kan tọ̀ ọ́ wá, ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀ wí pé, “Ọmọbìnrin mi kú nísinsin yìí, ṣùgbọ́n wá fi ọwọ́ rẹ̀ lé e, òun yóò sì yè.”
Gdy jeszcze o tym mówił, podszedł do Niego przełożony miejscowej synagogi. Pokłonił się i powiedział: —Przed chwilą zmarła moja córeczka. Ale jeśli przyjdziesz i dotkniesz jej, ożyje.
19 Jesu dìde ó sì bá a lọ àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
Jezus wstał i wraz z uczniami poszedł za przełożonym.
20 Sì kíyèsi i, obìnrin kan ti ó ní ìsun ẹ̀jẹ̀ ní ọdún méjìlá, ó wá lẹ́yìn rẹ̀, ó fi ọwọ́ kan ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀.
Tymczasem pewna kobieta, od dwunastu lat cierpiąca na krwotok, podeszła do Niego od tyłu i dotknęła Jego ubrania.
21 Nítorí ó wí nínú ara rẹ̀ pé, “Bí mo bá sá à le fi ọwọ́ kan ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀, ara mi yóò dá.”
Pomyślała bowiem: „Jeśli tylko dotknę Jego płaszcza, zostanę uzdrowiona”.
22 Nígbà tí Jesu sì yí ara rẹ̀ padà tí ó rí i, ó wí pé, “Ọmọbìnrin, tújúká, ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradà.” A sì mú obìnrin náà láradá ni wákàtí kan náà.
Jezus odwrócił się, dostrzegł ją i rzekł: —Bądź dobrej myśli, córko! Uwierzyłaś, więc zostałaś uzdrowiona! I w tej samej chwili kobieta odzyskała zdrowie.
23 Nígbà tí Jesu sí i dé ilé ìjòyè náà, ó bá àwọn afunfèrè àti ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ó ń pariwo.
Gdy przybył do domu przełożonego synagogi, zobaczył żałobników i lamentujący tłum.
24 Ó wí fún wọn pé, “Ẹ máa lọ; nítorí ọmọbìnrin náà kò kú, sísùn ni ó sùn.” Wọ́n sì fi i rín ẹ̀rín ẹlẹ́yà.
—Odejdźcie stąd—powiedział. —Dziewczynka nie umarła, tylko śpi. Ale oni śmiali się z Niego.
25 Ṣùgbọ́n nígbà tí a ti àwọn ènìyàn jáde, ó wọ ilé, ó sì fà ọmọbìnrin náà ní ọwọ́ sókè; bẹ́ẹ̀ ni ọmọbìnrin náà sì dìde.
W końcu jednak wyproszono tłum. Jezus wszedł do środka, wziął dziewczynkę za rękę, a ona natychmiast wstała!
26 Òkìkí èyí sì kàn ká gbogbo ilẹ̀ náà.
Wieść o tym obiegła całą okolicę.
27 Nígbà tí Jesu sì jáde níbẹ̀, àwọn ọkùnrin afọ́jú méjì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, wọ́n ń kígbe sókè wí pé, “Ṣàánú fún wa, ìwọ ọmọ Dafidi.”
Jezus właśnie stamtąd odchodził, gdy zjawili się dwaj niewidomi, którzy wołali za Nim: —Potomku króla Dawida, zmiłuj się nad nami!
28 Nígbà tí ó sì wọ̀ ilé, àwọn afọ́jú náà tọ̀ ọ́ wá, Jesu bi wọ́n pé, “Ẹ̀yin gbàgbọ́ pé mo le ṣe èyí?” Wọn sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa, ìwọ lè ṣe é.”
Szli tak za Nim aż do domu, gdzie się zatrzymał. Wtedy podeszli bliżej, a On ich zapytał: —Wierzycie, że mogę to zrobić? —Tak, Panie!—odpowiedzieli.
29 Ó sì fi ọwọ́ bà wọ́n ní ojú, ó wí pé, “Kí ó rí fún yín gẹ́gẹ́ bí ìgbàgbọ́ yín.”
—Niech będzie tak, jak wierzycie—powiedział Jezus i dotknął ich oczu.
30 Ojú wọn sì là; Jesu sì kìlọ̀ fún wọn gidigidi, wí pé, “Kíyèsi i, kí ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan kí ó mọ̀ nípa èyí.”
I nagle przejrzeli! Wówczas On surowo im nakazał: —Nikomu o tym nie mówcie.
31 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n lọ, wọ́n ròyìn rẹ̀ yí gbogbo ìlú náà ká.
Ale oni odeszli i zaraz wszędzie o tym opowiedzieli.
32 Bí wọ́n tí ń jáde lọ, wò ó wọ́n mú ọkùnrin odi kan tí ó ní ẹ̀mí èṣù tọ Jesu wá.
W tym właśnie czasie przyprowadzono do Jezusa kolejnego człowieka—niemowę zniewolonego przez demona.
33 Nígbà tí a lé ẹ̀mí èṣù náà jáde, ọkùnrin tí ó ya odi sì fọhùn. Ẹnu sì ya àwọn ènìyàn, wọ́n wí pé, “A kò rí irú èyí rí ní Israẹli.”
Po wypędzeniu demona, człowiek ten zaczął mówić. A tłumy nie mogły wyjść z podziwu: —Coś takiego nigdy się nie zdarzyło w całym Izraelu!
34 Ṣùgbọ́n àwọn Farisi wí pé, “Agbára olórí àwọn ẹ̀mí èṣù ni ó fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde.”
—Wypędza demony, bo władca demonów Mu w tym pomaga—twierdzili natomiast faryzeusze.
35 Jesu sì rìn yí gbogbo ìlú ńlá àti ìletò ká, ó ń kọ́ni nínú Sinagọgu wọn, ó sì ń wàásù ìyìnrere ìjọba ọrun, ó sì ń ṣe ìwòsàn ààrùn àti gbogbo àìsàn ní ara àwọn ènìyàn.
A Jezus odwiedzał wszystkie okoliczne miasta i wioski. Nauczał w synagogach, głosił dobrą nowinę o królestwie i uzdrawiał z każdej choroby i słabości.
36 Nígbà tí ó rí ọ̀pọ̀ ènìyàn, àánú wọn ṣe é, nítorí àárẹ̀ mú wọn, wọn kò sì rí ìrànlọ́wọ́, bí àwọn àgùntàn tí kò ní olùṣọ́.
Gdy patrzył na otaczające Go tłumy, ogarniała Go litość. Ludzie byli bowiem udręczeni i zagubieni jak owce bez pasterza.
37 Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Lóòótọ́ ni ìkórè pọ̀ ṣùgbọ́n àwọn alágbàṣe kò tó nǹkan.
—Żniwo jest wielkie—mówił uczniom—a tak mało pracujących!
38 Nítorí náà, ẹ gbàdúrà sí Olúwa ìkórè kí ó rán àwọn alágbàṣe sínú ìkórè rẹ̀.”
Proście więc gospodarza, aby posłał więcej pracowników na żniwa.