< Matthew 8 >
1 Nígbà tí ó ti orí òkè sọ̀kalẹ̀, ọ̀pọ̀ ènìyàn ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
kambo Yecu yirau do doweri nubbo ducce bwancinenten.
2 Sì wò ó, adẹ́tẹ̀ kan wà, ó wá ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀ ó wí pé, “Olúwa, bí ìwọ bá fẹ́, ìwọ lè sọ mi di mímọ́.”
La nii ki wale kung diro kibi kwan ki no mwi ciu tiri mwatin yilam kimo wucak.
3 Jesu sì nà ọwọ́ rẹ̀, ó fi bà á, ó wí pé, “Mo fẹ́, ìwọ di mímọ́.” Lójúkan náà, ẹ̀tẹ̀ rẹ̀ sì mọ́!
La Yecu tar kang ceko kico ri ki “miki cui”. La yilam wuccak, la dang jang dang jang cii yilam wucak ki wale ceu nen.
4 Jesu sì wí fún pé, “Wò ó, má ṣe sọ fún ẹnìkan. Ṣùgbọ́n máa ba ọ̀nà rẹ̀ lọ, fi ara rẹ̀ hàn fún àlùfáà, kí o sì san ẹ̀bùn tí Mose pàṣẹ ní ẹ̀rí fún wọn.”
Yecu yico “yire nii ka nge diker” tame nureu ya nung dormwero nii wabenin na mwi ne lumacere ko werful muca ko tokeu. wo buka kanger ce ko.
5 Nígbà tí Jesu sì wọ̀ Kapernaumu, balógun ọ̀rún kan tọ̀ ọ́ wá, ó bẹ̀bẹ̀ fún ìrànlọ́wọ́.
kambo ci yilau ti kafanahum meri, nii dur nob kweneo bou cinen ken coti.
6 O sì wí pé, “Olúwa, ọmọ ọ̀dọ̀ mi dùbúlẹ̀ ààrùn ẹ̀gbà ni ilé, tòun ti ìrora ńlá.”
La ki Te luwe bwe canga dam lo kilen di la nuwa dotange ti kambo ken.
7 Jesu sì wí fún un pé, “Èmi ń bọ̀ wá mú un láradá.”
Di la Yecu yi c o “Matin bou nami twam co”
8 Balógun ọ̀rún náà dáhùn, ó wí pé, “Olúwa, èmi kò yẹ ní ẹni tí ìwọ ń wọ̀ abẹ́ òrùlé rẹ̀, ṣùgbọ́n sọ kìkì ọ̀rọ̀ kan, a ó sì mú ọmọ ọ̀dọ̀ mi láradá.
Nii dur nob kweneb bo ciya co ki “Teluwe mi labo wo mwi bou to lo miyeu. Tok kaker dila bwe canga ni atin twam.
9 Ẹni tí ó wà lábẹ́ àṣẹ sá ni èmi, èmi sí ní ọmọ-ogun lẹ́yìn mi. Bí mo wí fún ẹni kan pé, ‘Lọ,’ a sì lọ, àti fún ẹni kejì pé, ‘Wá,’ a sì wá, àti fún ọmọ ọ̀dọ̀ mi pé, ‘Ṣe èyí,’ a sì ṣe é.”
wori no mo ken min nii ciyo dur biwan keret, tag ri min wiki nob kwenebo min dur dor cere. Miki yi w miki ya ri ci yaken, ki kanage 'bou ri ci bow kange ki canga mi, ma wuro dila cimam.
10 Nígbà tí Jesu gbọ́ èyí ẹnu yà á, ó sì wí fún àwọn tí ó ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, èmi kò rí ẹnìkan ni Israẹli tó ní ìgbàgbọ́ ńlá bí irú èyí.
Kamo Yecu nuwa weri, cin nyi mangi la cin yi biro bwang cinnen ten tiyeu, “bilenker mi yi kom ti mi fiya bo kange win wo ki bilenker nawo mor Iciraila.”
11 Mo sì wí fún yín, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni yóò ti ìhà ìlà-oòrùn àti ìhà ìwọ̀-oòrùn wá, wọ́n á sì bá Abrahamu àti Isaaki àti Jakọbu jẹun ní ìjọba ọ̀run.
Min yi kom, kila atin bou twaar kange me la ciyan ca wari kange Ibrahim, Icaku kange Yakubu mor Liyar kwamar.
12 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ìjọba ni a ó sọ sínú òkùnkùn lóde, níbẹ̀ ni ẹkún àti ìpayínkeke yóò gbé wà.”
Yilo bibei liyareu atin cor ke mor kumta cilero kiring kiring fiye cika wiyek kange kika nuneg?
13 Nítorí náà Jesu sì wí fún balógun ọ̀run náà pé, “Máa lọ ilé, ohun tí ìwọ gbàgbọ́ ti rí bẹ́ẹ̀.” A sì mú ọmọ ọ̀dọ̀ náà láradá ní wákàtí kan náà.
Yecu yi dur nor kwenebo, “ya nawo mwi le bilenkeu, la a mamwen nyo dila cnagau twam ki kwama don-dong (Yila mwenyo).
14 Nígbà tí Jesu sì dé ilé Peteru, ìyá ìyàwó Peteru dùbúlẹ̀ àìsàn ibà.
kambo Yecu bow mor lo Bitruce ri cin to fer Bitruce nawi yeu dam da nuwa luma ki kwi bwi.
15 Ṣùgbọ́n nígbà tí Jesu fi ọwọ́ kan ọwọ́ rẹ̀, ibà náà fi í sílẹ̀, lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ ó sì dìde ó ń ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
Yecu tai kang cekori la kwirom bwim bo dubom co. Dila cin kweni cin ter maka cinen carito.
16 Nígbà tí ó di àṣálẹ́, ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ó ní ẹ̀mí èṣù ni a mú wá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ lé àwọn ẹ̀mí èṣù náà jáde. A sì mú gbogbo àwọn ọlọ́kùnrùn láradá.
Kambo meu dome ri nubo bow Yecu ki nubo kila wo ki kelkelitini yeu. Ciin cikangum yuwa tangbe tinito ki ker yila cin twam wiyak biro nuwabo lumau.
17 Kí èyí tí a ti sọ láti ẹnu wòlíì Isaiah lè ṣẹ pé, “Òun tìkára rẹ̀ gbà àìlera wa, ó sì ń ru ààrùn wa.”
Ki nure wo la diim digero toku nyi kaya nii tomange, tokti ki “co ciki bwico yem bwii nuwa ka luma beko ri yila cin tum twirak beko”.
18 Nígbà tí Jesu rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn tó yí i ká, ó pàṣẹ pé kí wọ́n rékọjá sí òdìkejì adágún.
L kambo Yecu to mwerkako duce ken tangum ceri cin neci nyal naci yabken kong wimak ko Galili.
19 Olùkọ́ òfin kan sì tọ̀ ọ́ wá, ó wí fún un pé, “Olùkọ́, èmi ó má tọ̀ ọ́ lẹ́yìn níbikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”
La ni mulankak bow cinen di to ki ki, “nii meraanka, matin bwang mwentn {Bwen no mwiki yang fye mwi yakenti wiyeu gwam feri}”.
20 Jesu dá lóhùn pé, “Àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ ní ihò, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ni ìtẹ́; ṣùgbọ́n Ọmọ Ènìyàn kò ní ibi tí yóò fi orí rẹ̀ lé.”
Yecu yi co ki” wiki buwak cek, kange bilibetinim wo dii kwamau wiki lo cece dila bi bwe nii fire mani ki fiye wo ci yom dor tiye.”
21 Ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ mìíràn sì wí fún un pé, “Olúwa, kọ́kọ́ jẹ́ kí èmi kí ó kọ́ lọ sìnkú baba mi ná.”
kange mor nub bwang kab cebo yico, “Teluwe dob ye bwiri nan ya nami fwerum teni”.
22 Ṣùgbọ́n Jesu wí fún un pé, “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn, sì jẹ́ kí àwọn òkú kí ó máa sin òkú ara wọn.”
Di la Yecu yi co ki “Bwangmenten na dob nubo bwiyamen na fwerum bar cero.
23 Nígbà náà ni ó bọ́ sínú ọkọ̀ ojú omi, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tẹ̀lé e.
Kambo Yecu dogen tukom bwatiyeri, nob bwangka cebo bwang ci nen ten more ce.
24 Ní àìròtẹ́lẹ̀, ìjì líle dìde lórí Òkun tó bẹ́ẹ̀ tí rírú omi fi bò ọkọ̀ náà mọ́lẹ̀; ṣùgbọ́n Jesu ń sùn.
La yuwako durko kwenu mor wima, tokum bwantiyebo cimon ki yuwa mwengeb. La yecu dam dum.
25 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọn jí i, wọ́n wí pe, “Olúwa, gbà wá! Àwa yóò rì!”
Nob bwang kab ceko bow cinen di yunco tokti ki “Cer nyo Teluwe, yan bwiya rangum.
26 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin onígbàgbọ́ kékeré. Èéṣe ti ẹ̀yin fi ń bẹ̀rù?” Nígbà náà ní ó dìde dúró, ó sì bá ìjì àti rírú Òkun náà wí, gbogbo rẹ̀ sì parọ́rọ́.
Yecu yi ci “Ye bwi kom cua tai tiye, kom wo ki bilenkere biduwaru?” Di la cin kweni la werang yuwako knge wimau. la cinge dur tam.
27 Ṣùgbọ́n ẹnu yà àwọn ọkùnrin náà, wọ́n sì béèrè pé, “Irú ènìyàn wo ni èyí? Kódà ìjì líle àti rírú omi Òkun gbọ́ tirẹ̀?”
Nubo nyimangi la ciki “nage nii ko wini wuro, wo ki yuwa ce kange wima nuwa co tiye?”.
28 Nígbà ti ó sì dé apá kejì ní ilẹ̀ àwọn ara Gadara, àwọn ọkùnrin méjì ẹlẹ́mìí èṣù ti inú ibojì wá pàdé rẹ̀. Wọn rorò gidigidi tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò le kọjá ní ọ̀nà ibẹ̀.
Kambo Yecu bow dinge wineu kange mor biten gadara nubo yob wo ki ninga tininyeu wab kam co. ciki ceru mor tuwe, la ci bwi kabo wo nob yameb mani cu nure wiyeu.
29 Wọ́n kígbe lóhùn rara wí pé, “Kí ní ṣe tàwa tìrẹ, Ìwọ Ọmọ Ọlọ́run? Ìwọ ha wá láti dá wa lóró ṣáájú ọjọ́ tí a yàn náà?”
La cin kwa kiyakye ki dir cin yi ki “ye yo nen kange nye, bibwe kwama? mwi bo fo namwi nenyo dotange nanyumde kwama nye lauwa?”
30 Agbo ẹlẹ́dẹ̀ ńlá tí ń jẹ ń bẹ ní ọ̀nà jíjìn díẹ̀ sí wọn.
La nyere tini duce ca canak ti fiye co, kwitangbo ducce kange fiye ci niyeu.
31 Àwọn ẹ̀mí èṣù náà bẹ̀ Jesu wí pé, “Bí ìwọ bá lé wa jáde, jẹ́ kí àwa kí ó lọ sínú agbo ẹlẹ́dẹ̀ yìí.”
Ninga tini tii kinito Yecu nin ciki “No mwi coknyori, tungen nwo mor nyere tini.
32 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa lọ!” Nígbà tí wọn sì jáde, wọn lọ sínú agbo ẹlẹ́dẹ̀ náà; sì wò ó, gbogbo agbo ẹlẹ́dẹ̀ náà sì rọ́ gììrì sọ̀kalẹ̀ bèbè odò bọ́ sínú Òkun, wọ́n sì ṣègbé nínú omi.
Yecu yi ci “ko ya” la ninga tininu ceru yila dogen mor bentilen nyeretini, la bentilen nyeretiniu yirarangu kulor dugleroni di corge mor wima cin bwirangum mor mwege.
33 Àwọn ẹni tí ń ṣọ wọn sì sá, wọ́n sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n lọ sí ìlú, wọ́n ròyìn ohun gbogbo, àti ohun tí a ṣe fún àwọn ẹlẹ́mìí èṣù.
Nubo to nyere tiyeu cin cua cin cu dila cin yaken mor cinar lor la cin yici digero bwiyeu wiyak. diger fiya nubowo ki ninga tiyeu.
34 Nígbà náà ni gbogbo ará ìlú náà sì jáde wá í pàdé Jesu. Nígbà tí wọ́n sì rí i, wọ́n bẹ̀ ẹ́, kí ó lọ kúrò ní agbègbè wọn.
La cinartoro wiyak ceru naci wabkan Yecu. kambo ci to ceuri cin kinong co ca dubom cunga ceko.