< Matthew 4 >

1 Nígbà náà ni Ẹ̀mí Mímọ́ darí Jesu sí ijù láti dán an wò láti ọwọ́ èṣù.
Tedy Jezus zawiedziony jest na puszczę od Ducha, aby był kuszony od dyjabła.
2 Lẹ́yìn tí Òun ti gbààwẹ̀ ní ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, ebi sì ń pa á.
A gdy pościł czterdzieści dni i czterdzieści nocy, potem łaknął.
3 Nígbà náà ni olùdánwò tọ̀ ọ́ wá, ó wí pé, “Bí ìwọ bá ṣe Ọmọ Ọlọ́run, pàṣẹ kí òkúta wọ̀nyí di àkàrà.”
I przystąpiwszy do niego kusiciel, rzekł: Jeźliś jest Syn Boży, rzecz, aby się te kamienie stały chlebem.
4 Ṣùgbọ́n Jesu dáhùn pé, “A ti kọ ìwé rẹ̀ pé: ‘Ènìyàn kì yóò wà láààyè nípa àkàrà nìkan, bí kò ṣe nípa gbogbo ọ̀rọ̀ ti ó ti ẹnu Ọlọ́run jáde wá.’”
A on odpowiadając rzekł: Napisano: Nie samym chlebem człowiek żyć będzie, ale każdem słowem pochodzącem przez usta Boże.
5 Lẹ́yìn èyí ni èṣù gbé e lọ sí ìlú mímọ́ náà; ó gbé e lé ibi ṣóńṣó tẹmpili.
Tedy go wziął dyjabeł do miasta świętego, i postawił go na ganku kościelnym,
6 Ó wí pé, “Bí ìwọ̀ bá jẹ́ Ọmọ Ọlọ́run, bẹ́ sílẹ̀ fún ara rẹ. A sá à ti kọ̀wé rẹ̀ pé, “‘Yóò pàṣẹ fún àwọn angẹli rẹ̀ nítorí tìrẹ wọn yóò sì gbé ọ sókè ni ọwọ́ wọn kí ìwọ kí ó má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gbún òkúta.’”
I rzekł mu: Jeźliś jest Syn Boży, spuść się na dół, albowiem napisano: Iż Aniołom swoim przykazał o tobie, i będą cię na rękach nosili, abyś snać nie obraził o kamień nogi swojej.
7 Jesu sì dalóhùn, “A sá à ti kọ ọ́ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ dán Olúwa Ọlọ́run rẹ wò.’”
Rzekł mu Jezus: Zasię napisano: Nie będziesz kusił Pana, Boga twego.
8 Lẹ́ẹ̀kan sí i, èṣù gbé e lọ sórí òkè gíga, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ ọba ayé àti gbogbo ògo wọn hàn án.
Wziął go zasię dyjabeł na górę bardzo wysoką, i pokazał mu wszystkie królestwa świata i sławę ich,
9 Ó sì wí fún un pé, “Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi yóò fi fún ọ, bí ìwọ bá foríbalẹ̀ tí o sì sìn mi.”
I rzekł mu: To wszystko dam tobie, jeźli upadłszy, pokłonisz mi się.
10 Jesu wí fún un pé, “Padà kúrò lẹ́yìn mi, Satani! Nítorí a ti kọ ọ́ pé, ‘Olúwa Ọlọ́run rẹ ni kí ìwọ kí ó fi orí balẹ̀ fún, òun nìkan ṣoṣo ni kí ìwọ máa sìn.’”
Tedy mu rzekł Jezus: Pójdź precz, szatanie! albowiem napisano: Panu Bogu twemu kłaniać się będziesz, i jemu samemu służyć będziesz.
11 Nígbà náà ni èṣù fi í sílẹ̀ lọ, àwọn angẹli sì tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì ṣe ìránṣẹ́ fún un.
Tedy go opuścił dyjabeł, a oto Aniołowie przystąpili i służyli mu.
12 Nígbà tí Jesu gbọ́ wí pé a ti fi Johanu sínú túbú ó padà sí Galili.
A gdy usłyszał Jezus, iż Jan był podany do więzienia, wrócił się do Galilei;
13 Ó kúrò ní Nasareti, ó sì lọ í gbé Kapernaumu, èyí tí ó wà létí Òkun Sebuluni àti Naftali.
A opuściwszy Nazaret, przyszedł, i mieszkał w Kapernaum, które jest nad morzem w granicach Zabulonowych i Neftalimowych;
14 Kí èyí tí a ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu wòlíì Isaiah lè ṣẹ pé,
Aby się wypełniło, co powiedziano przez Izajasza proroka, mówiącego:
15 “Ìwọ Sebuluni àti ilẹ̀ Naftali ọ̀nà tó lọ sí Òkun, ní ọ̀nà Jordani, Galili ti àwọn kèfèrí.
Ziemia Zabulonowa i ziemia Neftalimowa przy drodze morskiej za Jordanem, Galilea poganów;
16 Àwọn ènìyàn tí ń gbé ni òkùnkùn tí ri ìmọ́lẹ̀ ńlá, àti àwọn tó ń gbé nínú ilẹ̀ òjijì ikú ni ìmọ́lẹ̀ tan fún.”
Lud, który siedział w ciemności, widział światłość wielką, a siedzącym w krainie i w cieniu śmierci weszła im światłość.
17 Láti ìgbà náà lọ ni Jesu ti bẹ̀rẹ̀ sí wàásù: “Ẹ ronúpìwàdà, nítorí tí ìjọba ọ̀run kù sí dẹ̀dẹ̀.”
Od onego czasu począł Jezus kazać i mówić: Pokutujcie, albowiem się przybliżyło królestwo niebieskie.
18 Bí Jesu ti ń rìn létí Òkun Galili, ó rí àwọn arákùnrin méjì, Simoni, ti à ń pè ní Peteru, àti Anderu arákùnrin rẹ̀. Wọ́n ń sọ àwọ̀n wọn sínú Òkun nítorí apẹja ni wọ́n.
A gdy Jezus chodził nad morzem Galilejskiem, ujrzał dwóch braci: Szymona, którego zowią Piotrem, i Andrzeja, brata jego, którzy zapuszczali sieć w morze; albowiem byli rybitwy.
19 Jesu wí fún wọn pé, “Ẹ wá, ẹ máa tọ̀ mí lẹ́yìn èmi yóò sì sọ yín di apẹja ènìyàn.”
I rzekł im: Pójdźcie za mną, a uczynię was rybitwami ludzi.
20 Lójúkan náà, wọ́n fi àwọ̀n wọn sílẹ̀, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
A oni zaraz opuściwszy sieci, szli za nim.
21 Bí ó sì ti kúrò ní ibẹ̀, ò rí àwọn arákùnrin méjì mìíràn, Jakọbu ọmọ Sebede àti Johanu, arákùnrin rẹ̀. Wọ́n wà nínú ọkọ̀ ojú omi pẹ̀lú Sebede baba wọn, wọ́n ń di àwọ̀n wọn, Jesu sì pè àwọn náà pẹ̀lú.
A postąpiwszy stamtąd, ujrzał drugich dwóch braci, Jakóba, syna Zebedeuszowego, i Jana, brata jego, w łodzi z Zebedeuszem, ojcem ich, poprawiających sieci swoje, i wezwał ich.
22 Lójúkan náà, wọ́n fi ọkọ̀ ojú omi àti baba wọn sílẹ̀, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
A oni wnetże opuściwszy łódź i ojca swego, poszli za nim.
23 Jesu sì rin káàkiri gbogbo Galili, ó ń kọ́ni ní Sinagọgu, ó ń wàásù ìyìnrere ti ìjọba ọ̀run, ó sì ń ṣe ìwòsàn ààrùn gbogbo àti àìsàn láàrín gbogbo ènìyàn.
I obchodził Jezus wszystkę Galileją, ucząc w bóżnicach ich, i każąc Ewangieliją królestwa, a uzdrawiając wszelką chorobę i wszelką niemoc między ludem.
24 Òkìkí rẹ̀ sì kàn yí gbogbo Siria ká; wọ́n sì gbé àwọn aláìsàn tí ó ní onírúurú ààrùn, àwọn tí ó ní ìnira ẹ̀mí èṣù, àti àwọn ti o ní wárápá àti àwọn tí ó ní ẹ̀gbà; ó sì wò wọ́n sàn.
I rozeszła się wieść o nim po wszystkiej Syryi; i przywodzono do niego wszystkie źle się mające, a rozmaitemi chorobami i mękami zdjęte, także i opętane, i lunatyki i powietrzem ruszone; i uzdrawiał je.
25 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn láti Galili, Dekapoli, Jerusalẹmu, Judea, àti láti òkè odò Jordani sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
A szedł za nim lud wielki z Galilei, z dziesięciu miast, i z Jeruzalemu, i z Judzkiej ziemi, i zza Jordanu.

< Matthew 4 >