< Matthew 3 >

1 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Johanu onítẹ̀bọmi wá, ó ń wàásù ní aginjù Judea.
ཏདཱནོཾ ཡོཧྣྣཱམཱ མཛྫཡིཏཱ ཡིཧཱུདཱིཡདེཤསྱ པྲཱནྟརམ྄ ཨུཔསྠཱཡ པྲཙཱརཡན྄ ཀཐཡཱམཱས,
2 Ó ń wí pé, “Ẹ ronúpìwàdà, nítorí ìjọba ọ̀run kù sí dẹ̀dẹ̀.”
མནཱཾསི པརཱཝརྟྟཡཏ, སྭརྒཱིཡརཱཛཏྭཾ སམཱིཔམཱགཏམ྄།
3 Èyí ni ẹni náà ti wòlíì Isaiah sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ pé, “Ohùn ẹni ti ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ẹ ṣe ojú ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́.’”
པརམེཤསྱ པནྠཱནཾ པརིཥྐུརུཏ སཪྻྭཏཿ། ཏསྱ རཱཛཔཐཱཾཤྩཻཝ སམཱིཀུརུཏ སཪྻྭཐཱ། ཨིཏྱེཏཏ྄ པྲཱནྟརེ ཝཱཀྱཾ ཝདཏཿ ཀསྱཙིད྄ རཝཿ༎
4 Aṣọ Johanu náà sì jẹ́ ti irun ìbákasẹ, ó sì di àmùrè awọ sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Eṣú àti oyin ìgàn sì ni oúnjẹ rẹ̀.
ཨེཏདྭཙནཾ ཡིཤཡིཡབྷཝིཥྱདྭཱདིནཱ ཡོཧནམུདྡིཤྱ བྷཱཥིཏམ྄། ཡོཧནོ ཝསནཾ མཧཱངྒརོམཛཾ ཏསྱ ཀཊཽ ཙརྨྨཀཊིབནྡྷནཾ; ས ཙ ཤཱུཀཀཱིཊཱན྄ མདྷུ ཙ བྷུཀྟཝཱན྄།
5 Àwọn ènìyàn jáde lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ láti Jerusalẹmu àti gbogbo Judea àti àwọn ènìyàn láti gbogbo ìhà Jordani.
ཏདཱནཱིཾ ཡིརཱུཤཱལམྣགརནིཝཱསིནཿ སཪྻྭེ ཡིཧཱུདིདེཤཱིཡཱ ཡརྡྡནྟཊིནྱཱ ཨུབྷཡཏཊསྠཱཤྩ མཱནཝཱ བཧིརཱགཏྱ ཏསྱ སམཱིཔེ
6 Wọ́n ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn, a sì ń bamitiisi wọn ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní odò Jordani.
སྭཱིཡཾ སྭཱིཡཾ དུརིཏམ྄ ཨངྒཱིཀྲྀཏྱ ཏསྱཱཾ ཡརྡྡནི ཏེན མཛྫིཏཱ བབྷཱུཝུཿ།
7 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó rí ọ̀pọ̀ àwọn Farisi àti Sadusi tí wọ́n ń wá ṣe ìtẹ̀bọmi, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ọmọ paramọ́lẹ̀! Ta ni ó kìlọ̀ fún yín pé kí ẹ́ sá kúrò nínú ìbínú tí ń bọ̀?
ཨཔརཾ བཧཱུན྄ ཕིརཱུཤིནཿ སིདཱུཀིནཤྩ མནུཛཱན྄ མཾཀྟུཾ སྭསམཱིཔམ྄ ཨཱགཙྪྟོ ཝིལོཀྱ ས ཏཱན྄ ཨབྷིདདྷཽ, རེ རེ བྷུཛགཝཾཤཱ ཨཱགཱམཱིནཿ ཀོཔཱཏ྄ པལཱཡིཏུཾ ཡུཥྨཱན྄ ཀཤྩེཏིཏཝཱན྄?
8 Ẹ so èso tí ó yẹ fún ìrònúpìwàdà.
མནཿཔརཱཝརྟྟནསྱ སམུཙིཏཾ ཕལཾ ཕལཏ།
9 Kí ẹ má sì ṣe rò nínú ara yin pé, ‘Àwa ní Abrahamu ní baba.’ Èmi wí fún yín, Ọlọ́run lè mu àwọn ọmọ jáde láti inú àwọn òkúta wọ̀nyí wá fún Abrahamu.
ཀིནྟྭསྨཱཀཾ ཏཱཏ ཨིབྲཱཧཱིམ྄ ཨསྟཱིཏི སྭེཥུ མནཿསུ ཙཱིནྟཡནྟོ མཱ ཝྱཱཧརཏ། ཡཏོ ཡུཥྨཱན྄ ཨཧཾ ཝདཱམི, ཨཱིཤྭར ཨེཏེབྷྱཿ པཱཥཱཎེབྷྱ ཨིབྲཱཧཱིམཿ སནྟཱནཱན྄ ཨུཏྤཱདཡིཏུཾ ཤཀྣོཏི།
10 Nísinsin yìí, a ti fi àáké lè gbòǹgbò igi, àti pé gbogbo igi tí kò bá so èso rere ni a óò ge lulẹ̀ ti a ó sì wọ jù sínú iná.
ཨཔརཾ པཱདཔཱནཱཾ མཱུལེ ཀུཋཱར ཨིདཱནཱིམཔི ལགན྄ ཨཱསྟེ, ཏསྨཱད྄ ཡསྨིན྄ པཱདཔེ ཨུཏྟམཾ ཕལཾ ན བྷཝཏི, ས ཀྲྀཏྟོ མདྷྱེ྅གྣིཾ ནིཀྵེཔྶྱཏེ།
11 “Èmi fi omi bamitiisi yín fún ìrònúpìwàdà. Ṣùgbọ́n lẹ́yìn mi ẹnìkan tí ó pọ̀jù mí lọ ń bọ̀, bàtà ẹni tí èmi kò tó gbé. Òun ni yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ àti iná bamitiisi yín.
ཨཔརམ྄ ཨཧཾ མནཿཔརཱཝརྟྟནསཱུཙཀེན མཛྫནེན ཡུཥྨཱན྄ མཛྫཡཱམཱིཏི སཏྱཾ, ཀིནྟུ མམ པཤྩཱད྄ ཡ ཨཱགཙྪཏི, ས མཏྟོཔི མཧཱན྄, ཨཧཾ ཏདཱིཡོཔཱནཧཽ ཝོཌྷུམཔི ནཧི ཡོགྱོསྨི, ས ཡུཥྨཱན྄ ཝཧྣིརཱུཔེ པཝིཏྲ ཨཱཏྨནི སཾམཛྫཡིཥྱཏི།
12 Ẹni ti àmúga ìpakà rẹ̀ ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀, yóò gbá ilẹ̀ ìpakà rẹ̀, yóò kó alikama rẹ̀ sínú àká, ṣùgbọ́n ìyàngbò ni yóò fi iná àjóòkú sun.”
ཏསྱ ཀཱརེ སཱུརྤ ཨཱསྟེ, ས སྭཱིཡཤསྱཱནི སམྱཀ྄ པྲསྥོཊྱ ནིཛཱན྄ སཀལགོདྷཱུམཱན྄ སཾགྲྀཧྱ བྷཱཎྜཱགཱརེ སྠཱཔཡིཥྱཏི, ཀིཾནྟུ སཪྻྭཱཎི ཝུཥཱཎྱནིཪྻྭཱཎཝཧྣིནཱ དཱཧཡིཥྱཏི།
13 Nígbà náà ni Jesu ti Galili wá sí odò Jordani kí Johanu bá à lè ṣe ìtẹ̀bọmi fún un.
ཨནནྟརཾ ཡཱིཤུ ཪྻོཧནཱ མཛྫིཏོ བྷཝིཏུཾ གཱལཱིལྤྲདེཤཱད྄ ཡརྡྡནི ཏསྱ སམཱིཔམ྄ ཨཱཛགཱམ།
14 Ṣùgbọ́n Johanu kò fẹ́ ṣe ìtẹ̀bọmi fún un, ó wí pé, “Ìwọ ni ìbá bamitiisi fún mi, ìwọ sì tọ̀ mí wá?”
ཀིནྟུ ཡོཧན྄ ཏཾ ནིཥིདྷྱ བབྷཱཥེ, ཏྭཾ ཀིཾ མམ སམཱིཔམ྄ ཨཱགཙྪསི? ཝརཾ ཏྭཡཱ མཛྫནཾ མམ པྲཡོཛནམ྄ ཨཱསྟེ།
15 Jesu sì dáhùn pé, “Jọ̀wọ́ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ náà, nítorí bẹ́ẹ̀ ni ó yẹ fún wa láti mú gbogbo òdodo ṣẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni Johanu gbà, ó sì ṣe ìtẹ̀bọmi fún un.
ཏདཱནཱིཾ ཡཱིཤུཿ པྲཏྱཝོཙཏ྄; ཨཱིདཱནཱིམ྄ ཨནུམནྱསྭ, ཡཏ ཨིཏྠཾ སཪྻྭདྷརྨྨསཱདྷནམ྄ ཨསྨཱཀཾ ཀརྟྟཝྱཾ, ཏཏཿ སོ྅ནྭམནྱཏ།
16 Bí ó si tí ṣe ìtẹ̀bọmi fún Jesu tán, Ó jáde láti inú omi. Ní àkókò náà ọ̀run ṣí sílẹ̀ fún un, Ó sì rí Ẹ̀mí Ọlọ́run ń sọ̀kalẹ̀ bí àdàbà, ó sì bà lé e.
ཨནནྟརཾ ཡཱིཤུརམྨསི མཛྫིཏུཿ སན྄ ཏཏྐྵཎཱཏ྄ ཏོཡམདྷྱཱད྄ ཨུཏྠཱཡ ཛགཱམ, ཏདཱ ཛཱིམཱུཏདྭཱརེ མུཀྟེ ཛཱཏེ, ས ཨཱིཤྭརསྱཱཏྨཱནཾ ཀཔོཏཝད྄ ཨཝརུཧྱ སྭོཔཪྻྱཱགཙྪནྟཾ ཝཱིཀྵཱཉྩཀྲེ།
17 Ohùn kan láti ọ̀run wá sì wí pé, “Èyí sì ni àyànfẹ́ ọmọ mi, ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”
ཨཔརམ྄ ཨེཥ མམ པྲིཡཿ པུཏྲ ཨེཏསྨིནྣེཝ མམ མཧཱསནྟོཥ ཨེཏཱདྲྀཤཱི ཝྱོམཛཱ ཝཱག྄ བབྷཱུཝ།

< Matthew 3 >