< Matthew 3 >

1 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Johanu onítẹ̀bọmi wá, ó ń wàásù ní aginjù Judea.
តទានោំ យោហ្ន្នាមា មជ្ជយិតា យិហូទីយទេឝស្យ ប្រាន្តរម៑ ឧបស្ថាយ ប្រចារយន៑ កថយាមាស,
2 Ó ń wí pé, “Ẹ ronúpìwàdà, nítorí ìjọba ọ̀run kù sí dẹ̀dẹ̀.”
មនាំសិ បរាវត៌្តយត, ស្វគ៌ីយរាជត្វំ សមីបមាគតម៑។
3 Èyí ni ẹni náà ti wòlíì Isaiah sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ pé, “Ohùn ẹni ti ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ẹ ṣe ojú ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́.’”
បរមេឝស្យ បន្ថានំ បរិឞ្កុរុត សវ៌្វតះ។ តស្យ រាជបថាំឝ្ចៃវ សមីកុរុត សវ៌្វថា។ ឥត្យេតត៑ ប្រាន្តរេ វាក្យំ វទតះ កស្យចិទ៑ រវះ៕
4 Aṣọ Johanu náà sì jẹ́ ti irun ìbákasẹ, ó sì di àmùrè awọ sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Eṣú àti oyin ìgàn sì ni oúnjẹ rẹ̀.
ឯតទ្វចនំ យិឝយិយភវិឞ្យទ្វាទិនា យោហនមុទ្ទិឝ្យ ភាឞិតម៑។ យោហនោ វសនំ មហាង្គរោមជំ តស្យ កដៅ ចម៌្មកដិពន្ធនំ; ស ច ឝូកកីដាន៑ មធុ ច ភុក្តវាន៑។
5 Àwọn ènìyàn jáde lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ láti Jerusalẹmu àti gbogbo Judea àti àwọn ènìyàn láti gbogbo ìhà Jordani.
តទានីំ យិរូឝាលម្នគរនិវាសិនះ សវ៌្វេ យិហូទិទេឝីយា យទ៌្ទន្តដិន្យា ឧភយតដស្ថាឝ្ច មានវា ពហិរាគត្យ តស្យ សមីបេ
6 Wọ́n ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn, a sì ń bamitiisi wọn ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní odò Jordani.
ស្វីយំ ស្វីយំ ទុរិតម៑ អង្គីក្ឫត្យ តស្យាំ យទ៌្ទនិ តេន មជ្ជិតា ពភូវុះ។
7 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó rí ọ̀pọ̀ àwọn Farisi àti Sadusi tí wọ́n ń wá ṣe ìtẹ̀bọmi, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ọmọ paramọ́lẹ̀! Ta ni ó kìlọ̀ fún yín pé kí ẹ́ sá kúrò nínú ìbínú tí ń bọ̀?
អបរំ ពហូន៑ ផិរូឝិនះ សិទូកិនឝ្ច មនុជាន៑ មំក្តុំ ស្វសមីបម៑ អាគច្ឆ្តោ វិលោក្យ ស តាន៑ អភិទធៅ, រេ រេ ភុជគវំឝា អាគាមីនះ កោបាត៑ បលាយិតុំ យុឞ្មាន៑ កឝ្ចេតិតវាន៑?
8 Ẹ so èso tí ó yẹ fún ìrònúpìwàdà.
មនះបរាវត៌្តនស្យ សមុចិតំ ផលំ ផលត។
9 Kí ẹ má sì ṣe rò nínú ara yin pé, ‘Àwa ní Abrahamu ní baba.’ Èmi wí fún yín, Ọlọ́run lè mu àwọn ọmọ jáde láti inú àwọn òkúta wọ̀nyí wá fún Abrahamu.
កិន្ត្វស្មាកំ តាត ឥព្រាហីម៑ អស្តីតិ ស្វេឞុ មនះសុ ចីន្តយន្តោ មា វ្យាហរត។ យតោ យុឞ្មាន៑ អហំ វទាមិ, ឦឝ្វរ ឯតេភ្យះ បាឞាណេភ្យ ឥព្រាហីមះ សន្តានាន៑ ឧត្បាទយិតុំ ឝក្នោតិ។
10 Nísinsin yìí, a ti fi àáké lè gbòǹgbò igi, àti pé gbogbo igi tí kò bá so èso rere ni a óò ge lulẹ̀ ti a ó sì wọ jù sínú iná.
អបរំ បាទបានាំ មូលេ កុឋារ ឥទានីមបិ លគន៑ អាស្តេ, តស្មាទ៑ យស្មិន៑ បាទបេ ឧត្តមំ ផលំ ន ភវតិ, ស ក្ឫត្តោ មធ្យេៜគ្និំ និក្ឞេប្ស្យតេ។
11 “Èmi fi omi bamitiisi yín fún ìrònúpìwàdà. Ṣùgbọ́n lẹ́yìn mi ẹnìkan tí ó pọ̀jù mí lọ ń bọ̀, bàtà ẹni tí èmi kò tó gbé. Òun ni yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ àti iná bamitiisi yín.
អបរម៑ អហំ មនះបរាវត៌្តនសូចកេន មជ្ជនេន យុឞ្មាន៑ មជ្ជយាមីតិ សត្យំ, កិន្តុ មម បឝ្ចាទ៑ យ អាគច្ឆតិ, ស មត្តោបិ មហាន៑, អហំ តទីយោបានហៅ វោឍុមបិ នហិ យោគ្យោស្មិ, ស យុឞ្មាន៑ វហ្និរូបេ បវិត្រ អាត្មនិ សំមជ្ជយិឞ្យតិ។
12 Ẹni ti àmúga ìpakà rẹ̀ ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀, yóò gbá ilẹ̀ ìpakà rẹ̀, yóò kó alikama rẹ̀ sínú àká, ṣùgbọ́n ìyàngbò ni yóò fi iná àjóòkú sun.”
តស្យ ការេ សូប៌ អាស្តេ, ស ស្វីយឝស្យានិ សម្យក៑ ប្រស្ផោដ្យ និជាន៑ សកលគោធូមាន៑ សំគ្ឫហ្យ ភាណ្ឌាគារេ ស្ថាបយិឞ្យតិ, កិំន្តុ សវ៌្វាណិ វុឞាណ្យនិវ៌្វាណវហ្និនា ទាហយិឞ្យតិ។
13 Nígbà náà ni Jesu ti Galili wá sí odò Jordani kí Johanu bá à lè ṣe ìtẹ̀bọmi fún un.
អនន្តរំ យីឝុ រ្យោហនា មជ្ជិតោ ភវិតុំ គាលីល្ប្រទេឝាទ៑ យទ៌្ទនិ តស្យ សមីបម៑ អាជគាម។
14 Ṣùgbọ́n Johanu kò fẹ́ ṣe ìtẹ̀bọmi fún un, ó wí pé, “Ìwọ ni ìbá bamitiisi fún mi, ìwọ sì tọ̀ mí wá?”
កិន្តុ យោហន៑ តំ និឞិធ្យ ពភាឞេ, ត្វំ កិំ មម សមីបម៑ អាគច្ឆសិ? វរំ ត្វយា មជ្ជនំ មម ប្រយោជនម៑ អាស្តេ។
15 Jesu sì dáhùn pé, “Jọ̀wọ́ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ náà, nítorí bẹ́ẹ̀ ni ó yẹ fún wa láti mú gbogbo òdodo ṣẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni Johanu gbà, ó sì ṣe ìtẹ̀bọmi fún un.
តទានីំ យីឝុះ ប្រត្យវោចត៑; ឦទានីម៑ អនុមន្យស្វ, យត ឥត្ថំ សវ៌្វធម៌្មសាធនម៑ អស្មាកំ កត៌្តវ្យំ, តតះ សោៜន្វមន្យត។
16 Bí ó si tí ṣe ìtẹ̀bọmi fún Jesu tán, Ó jáde láti inú omi. Ní àkókò náà ọ̀run ṣí sílẹ̀ fún un, Ó sì rí Ẹ̀mí Ọlọ́run ń sọ̀kalẹ̀ bí àdàbà, ó sì bà lé e.
អនន្តរំ យីឝុរម្មសិ មជ្ជិតុះ សន៑ តត្ក្ឞណាត៑ តោយមធ្យាទ៑ ឧត្ថាយ ជគាម, តទា ជីមូតទ្វារេ មុក្តេ ជាតេ, ស ឦឝ្វរស្យាត្មានំ កបោតវទ៑ អវរុហ្យ ស្វោបយ៌្យាគច្ឆន្តំ វីក្ឞាញ្ចក្រេ។
17 Ohùn kan láti ọ̀run wá sì wí pé, “Èyí sì ni àyànfẹ́ ọmọ mi, ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”
អបរម៑ ឯឞ មម ប្រិយះ បុត្រ ឯតស្មិន្នេវ មម មហាសន្តោឞ ឯតាទ្ឫឝី វ្យោមជា វាគ៑ ពភូវ។

< Matthew 3 >