< Matthew 27 >
1 Ní òwúrọ̀, gbogbo àwọn olórí àlùfáà àti àwọn àgbàgbà Júù tún padà láti gbìmọ̀ bí wọn yóò ti ṣe pa Jesu.
De grand matin, tous les principaux sacrificateurs et les anciens du peuple tinrent conseil pour faire exécuter Jésus.
2 Lẹ́yìn èyí, wọ́n fi ẹ̀wọ̀n dè é, wọ́n sì jọ̀wọ́ rẹ̀ fún Pilatu tí i ṣe gómìnà.
Après l'avoir lié, ils remmenèrent et le livrèrent à Ponce-Pilate, qui était gouverneur.
3 Nígbà tí Judasi, ẹni tí ó fi í hàn, rí i wí pé a ti dá a lẹ́bi ikú, ó yí ọkàn rẹ̀ padà, ó sì káàánú nípa ohun tí ó ṣe. Ó sì mú ọgbọ̀n owó fàdákà tí ó gba náà wá fún àwọn olórí àlùfáà àti àwọn àgbàgbà Júù.
Alors Judas, qui l'avait livré, voyant que Jésus était condamné, se repentit, et alla rendre les trente pièces d'argent aux principaux sacrificateurs et aux anciens,
4 Ó wí pé, “Mo ti ṣẹ̀ nítorí tí mo ti ta ẹ̀jẹ̀ aláìlẹ́ṣẹ̀ sílẹ̀.” Wọ́n dá a lóhùn pẹ̀lú ìbínú pé, “Èyí kò kàn wá! Wàhálà tìrẹ ni!”
disant: «J'ai péché en livrant le sang innocent.» Mais ils lui dirent: «Que nous importe? cela te regarde.»
5 Nígbà náà ni Judasi da owó náà sílẹ̀ nínú tẹmpili. Ó jáde, ó sì lọ pokùnso.
Là-dessus, Judas jeta les pièces d'argent dans le temple, se retira, et alla se pendre.
6 Àwọn olórí àlùfáà sì mú owó náà. Wọ́n wí pé, “Àwa kò lè fi owó yìí sínú owó ìkójọpọ̀. Ní ìwọ̀n ìgbà tí ó lòdì sí òfin wa nítorí pé owó ẹ̀jẹ̀ ni.”
Les principaux sacrificateurs, ayant ramassé l'argent, dirent: «Il n'est pas permis de le mettre dans le trésor, puisque c'est le prix du sang; »
7 Wọ́n sì gbìmọ̀, wọ́n sì fi ra ilẹ̀ amọ̀kòkò, láti máa sin òkú àwọn àjèjì nínú rẹ̀.
et, après en avoir délibéré, ils achetèrent avec cet argent le champ du Potier pour la sépulture des étrangers.
8 Ìdí nìyìí tí à ń pe ibi ìsìnkú náà ní “Ilẹ̀ Ẹ̀jẹ̀” títí di òní.
C'est pourquoi ce champ est appelé encore aujourd'hui le Champ du Sang.
9 Èyí sì jẹ́ ìmúṣẹ èyí tí a ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu wòlíì Jeremiah wí pé, “Wọ́n sì mú ọgbọ̀n owó fàdákà tí àwọn ènìyàn Israẹli díye lé e.
Alors s'accomplit ce qui avait été dit par le prophète Jérémie: «Et ils ont reçu les trente pièces d’argent, prix de celui qui avait été mis à prix et qu’ils avaient taxé de la part des enfants d'Israël,
10 Wọ́n sì fi ra ilẹ̀ kan lọ́wọ́ àwọn amọ̀kòkò gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ.”
et ils les ont données pour le champ du Potier comme le Seigneur me l’avait commandé.»
11 Nígbà náà ni Jesu dúró níwájú baálẹ̀ láti gba ìdájọ́. Baálẹ̀ sì béèrè pé, “Ṣe ìwọ ni ọba àwọn Júù?” Jesu dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, nítorí tí ìwọ wí i.”
Cependant Jésus comparut devant le gouverneur, qui l’interrogea, disant: «C'est toi, qui es le roi des Juifs?» — «Tu le dis, » lui répondit Jésus.
12 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn àgbàgbà Júù fi gbogbo ẹ̀sùn wọn kàn án, Jesu kò dáhùn kan.
Quand les principaux sacrificateurs et les anciens l'accusaient, il ne répondait rien.
13 Nígbà náà ni Pilatu, béèrè lọ́wọ́ Jesu pé, “Àbí ìwọ kò gbọ́ ẹ̀rí tí wọn ń wí nípa rẹ ni?”
Alors Pilate lui dit: «N'entends-tu pas de combien de crimes ils te chargent?»
14 Jesu kò sì tún dáhùn kan. Èyí sì ya baálẹ̀ lẹ́nu.
Et Jésus ne répondit pas même sur un seul point, ce qui étonna fort le gouverneur.
15 Ó jẹ́ àṣà gómìnà láti dá ọ̀kan nínú àwọn ẹlẹ́wọ̀n Júù sílẹ̀ lọ́dọọdún, ní àsìkò àjọ̀dún ìrékọjá. Ẹnikẹ́ni tí àwọn ènìyàn bá ti fẹ́ ni.
C'était la coutume, à chaque fête, que le gouverneur relâchât un prisonnier, celui que le peuple voulait.
16 Ní àsìkò náà ọ̀daràn paraku kan wà nínú ẹ̀wọ̀n tí à ń pè Jesu Baraba.
Or, on détenait alors un prisonnier fameux, nommé Barrabas.
17 Bí ọ̀pọ̀ ènìyàn ti péjọ síwájú ilé Pilatu lówúrọ̀ ọjọ́ náà, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ta ni ẹ̀yin ń fẹ́ kí n dá sílẹ̀ fún yín, Baraba tàbí Jesu, ẹni tí ń jẹ́ Kristi?”
Pilate, ayant fait assembler la multitude, lui dit: «Lequel voulez-vous que je vous relâche? Barrabas, ou Jésus, qu'on appelle Christ?»
18 Òun ti mọ̀ pé nítorí ìlara ni wọn fi fà á lé òun lọ́wọ́.
Car il savait que c'était par envie que les sénateurs l'avaient livré.
19 Bí Pilatu sì ti ṣe jókòó lórí ìtẹ́ ìdájọ́ rẹ̀, ìyàwó rẹ̀ ránṣẹ́ sí i pé, “Má ṣe ní ohun kankan ṣe pẹ̀lú ọkùnrin aláìṣẹ̀ náà. Nítorí mo jìyà ohun púpọ̀ lójú àlá mi lónìí nítorí rẹ̀.”
D'ailleurs, pendant qu'il siégeait sur son tribunal, sa femme lui avait fait dire: «Ne te mêle pas de l'affaire de ce juste, car j'ai eu, aujourd'hui, des rêves affreux à cause de lui.»
20 Ṣùgbọ́n àwọn olórí àlùfáà àti àwọn àgbàgbà Júù rọ àwọn ènìyàn, láti béèrè kí a dá Baraba sílẹ̀, kí a sì béèrè ikú fún Jesu.
Mais les principaux sacrificateurs et les anciens persuadèrent au peuple de demander Barrabas, et de faire périr Jésus.
21 Nígbà tí Pilatu sì tún béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èwo nínú àwọn méjèèjì yìí ni ẹ̀ ń fẹ́ kí n dá sílẹ̀ fún yín?” Àwọn ènìyàn sì kígbe padà pé, “Baraba!”
Le gouverneur, prenant la parole, leur dit: «Lequel des deux voulez-vous que je vous relâche?» — Barrabas, » dirent-ils.
22 Pilatu béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe sí Jesu ẹni ti a ń pè ní Kristi?” Gbogbo wọn sì tún kígbe pé, “Kàn án mọ́ àgbélébùú!”
Pilate reprit: «Que ferai-je donc de Jésus, qu'on appelle Christ?» Ils dirent tous: «Qu'il soit crucifié!»
23 Pilatu sì béèrè pé, “Nítorí kí ni? Kí ló ṣe tí ó burú?” Wọ́n kígbe sókè pé, “Kàn án mọ́ àgbélébùú! Kàn án mọ́ àgbélébùú!”
— «Quel mal a-t-il donc fait?» dit le gouverneur. Mais ils crièrent encore plus fort: «Qu'il soit crucifié!»
24 Nígbà tí Pilatu sì rí i pé òun kò tún rí nǹkan kan ṣe mọ́, àti wí pé rògbòdìyàn ti ń bẹ̀rẹ̀, ó béèrè omi, ó sì wẹ ọwọ́ rẹ̀ níwájú ọ̀pọ̀ ènìyàn, ó wí pé, “Ọrùn mí mọ́ nípa ẹ̀jẹ̀ ọkùnrin yìí. Ẹ̀yin fúnra yín, ẹ bojútó o!”
Pilate voyant que son insistance ne servait à rien, mais que le tumulte allait croissant, prit de l'eau, se lava les mains à la vue du peuple, et dit: «Je suis innocent du sang de ce juste: cela vous regarde.»
25 Gbogbo àgbájọ náà sì ké pé, “Kí ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wà lórí wa, àti ní orí àwọn ọmọ wa!”
Et tout le peuple répondit: «Que son sang soit sur nous et sur nos enfants!»
26 Nígbà náà ni Pilatu dá Baraba sílẹ̀ fún wọn. Lẹ́yìn tí òun ti na Jesu tán, ó fi í lé wọn lọ́wọ́ láti mú un lọ kàn mọ́ àgbélébùú.
Alors il leur relâcha Barrabas; et, après avoir fait flageller Jésus, il le livra pour être crucifié.
27 Nígbà náà ni àwọn ọmọ-ogun gómìnà mú Jesu lọ sí gbọ̀ngàn ìdájọ́ wọ́n sì kó gbogbo ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tì í.
Alors les soldats du gouverneur emmenèrent Jésus dans le prétoire et assemblèrent autour de lui toute la cohorte.
28 Wọ́n tú Jesu sì ìhòhò, wọ́n sì wọ̀ ọ́ ní aṣọ òdòdó,
Ils le dépouillèrent de ses vêtements et l'affublèrent d'un manteau écarlate;
29 wọ́n sì hun adé ẹ̀gún. Wọ́n sì fi dé e lórí. Wọ́n sì fi ọ̀pá sí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀pá ọba. Wọ́n sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, wọ́n fi í ṣe ẹlẹ́yà pé, “Kábíyèsí, ọba àwọn Júù!”
puis, ils tressèrent une couronne d'épines, qu'ils lui mirent sur la tête; ils lui mirent aussi un roseau dans la main droite. Ils se prosternaient devant lui, et lui disaient par dérision: «Salut, roi des Juifs.»
30 Wọ́n sì tu itọ́ sí i lójú àti ara, wọ́n gba ọ̀pá wọ́n sì nà án lórí.
Puis, ils crachaient sur lui, et, prenant le roseau, ils le frappaient sur la tête.
31 Nígbà tí wọ́n fi ṣẹ̀sín tán, wọ́n bọ́ aṣọ ara rẹ̀. Wọ́n tún fi aṣọ tirẹ̀ wọ̀ ọ́. Wọ́n sì mú un jáde láti kàn án mọ́ àgbélébùú.
Quand ils l'eurent ainsi bafoué, ils lui ôtèrent le manteau, lui remirent ses vêtements, et l'emmenèrent pour le crucifier.
32 Bí wọ́n sì ti ń jáde, wọ́n rí ọkùnrin kan ará Kirene tí à ń pè ní Simoni. Wọ́n sì mú ọkùnrin náà ní túláàsì láti ru àgbélébùú Jesu.
En sortant de la ville, ils trouvèrent un homme de Cyrène, nommé Simon, qu'ils mirent en réquisition pour porter la croix de Jésus.
33 Wọ́n sì jáde lọ sí àdúgbò kan tí à ń pè ní Gọlgọta (èyí tí í ṣe “Ibi Agbárí”).
Quand ils furent arrivés à la place appelée Golgotha, c’est-à-dire, la place du Crâne,
34 Níbẹ̀ ni wọn ti fún un ni ọtí wáìnì tí ó ní egbòogi nínú láti mu. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó tọ́ ọ wò, ó kọ̀ láti mu ún.
ils lui présentèrent du vin mêlé de fiel, et Jésus, l'ayant goûté, ne le voulut point boire.
35 Lẹ́yìn tí wọ́n sì ti kàn án mọ́ àgbélébùú, wọ́n dìbò láti pín aṣọ rẹ̀ láàrín ara wọn.
Après qu'ils l'eurent crucifié, ils se partagèrent ses vêtements en les tirant au sort,
36 Nígbà náà ni wọ́n jókòó yí i ká. Wọ́n ń ṣọ́ ọ níbẹ̀.
puis ils s'assirent pour le garder.
37 Ní òkè orí rẹ̀, wọ́n kọ ohun kan tí ó kà báyìí pé: “Èyí ni Jesu, Ọba àwọn Júù.” síbẹ̀.
Ils placèrent au-dessus de sa tête cet écriteau indiquant le sujet de sa condamnation: «Jésus, Roi des Juifs.»
38 Wọ́n kan àwọn olè méjì pẹ̀lú rẹ̀ ní òwúrọ̀ náà. Ọ̀kan ní ọwọ́ ọ̀tún, àti èkejì ní ọwọ́ òsì rẹ̀.
On crucifia avec lui deux brigands, l'un à sa droite, l'autre à sa gauche.
39 Àwọn tí ń kọjá lọ sì ń bú u. Wọ́n sì ń mi orí wọn pé:
Et les passants l'insultaient en branlant la tête,
40 “Ìwọ tí yóò wó tẹmpili, ìwọ tí yóò sì tún un mọ ní ọjọ́ kẹta. Bí ó bá jẹ́ pé Ọmọ Ọlọ́run ni ìwọ, sọ̀kalẹ̀ láti orí igi àgbélébùú, kí ó sì gba ara rẹ là!”
et en disant: «Toi, qui détruis le temple, et qui le rebâtis en trois jours, sauve-toi toi-même. Si tu es Fils de Dieu, descends de ta croix.»
41 Bákan náà àwọn olórí àlùfáà pẹ̀lú àwọn akọ̀wé òfin àti àwọn àgbàgbà Júù sì fi í ṣe ẹlẹ́yà.
Les principaux sacrificateurs aussi le poursuivaient de leurs sarcasmes, ainsi que les scribes et les anciens, et disaient:
42 Wọ́n kẹ́gàn rẹ̀ pé, “Ó gba àwọn ẹlòmíràn là, kò sí lè gba ara rẹ̀. Ìwọ ọba àwọn Israẹli? Sọ̀kalẹ̀ láti orí àgbélébùú nísinsin yìí, àwa yóò sì gbà ọ́ gbọ́.
«Il en a sauvé d'autres, et il ne peut se sauver lui-même! Il est le roi d'Israël! Qu'il descende maintenant de la croix, et nous croirons en lui.
43 Ó gba Ọlọ́run gbọ́, jẹ́ kí Ọlọ́run gbà á là ní ìsinsin yìí tí òun bá fẹ́ ẹ. Ǹjẹ́ òun kò wí pé, èmi ni Ọmọ Ọlọ́run?”
Il s'est confié en Dieu; que Dieu le délivre maintenant, s'il l'aime; car il a dit: «Je suis Fils de Dieu.»
44 Bákan náà, àwọn olè tí a kàn mọ́ àgbélébùú pẹ̀lú rẹ̀ fi í ṣe ẹlẹ́yà.
Et les brigands qui étaient crucifiés avec lui, l'insultaient de la même manière.
45 Láti wákàtí kẹfà ni òkùnkùn fi ṣú bo gbogbo ilẹ̀ títí dé wákàtí kẹsànán ọjọ́.
Depuis la sixième beure jusqu’à la neuvième, des ténèbres se répandirent sur toute la terre.
46 Níwọ̀n wákàtí kẹsànán ní Jesu sì kígbe ní ohùn rara wí pé, “Eli, Eli, lama sabakitani” (ní èdè Heberu). Ìtumọ̀ èyí tí í ṣe, “Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí sílẹ̀?”
Vers la neuvième heure, Jésus cria d'une voix forte: «Eli, Eli, lama sabactani» c'est-à-dire, mon Dieu, mon Dieu, pourquoi m'as-tu abandonné?
47 Ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò yé díẹ̀ nínú àwọn ẹni tí ń wòran, nígbà tí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, wọ́n wí pé ọkùnrin yìí ń pe Elijah.
Quelques-uns des assistants, l'ayant entendu, dirent: «Voilà qu'il appelle Elie; »
48 Lẹ́sẹ̀kan náà, ọ̀kan nínú wọn sáré, ó mú kànìnkànìn, ó tẹ̀ ẹ́ bọ inú ọtí kíkan. Ó fi lé orí ọ̀pá, ó gbé e sókè láti fi fún un mu.
et aussitôt l'un d'eux courut prendre une éponge, qu'il trempa dans du vinaigre, et, l'ayant ajustée à une tige, il lui donna à boire.
49 Ṣùgbọ́n àwọn ìyókù wí pé, “Ẹ fi í sílẹ̀. Ẹ jẹ́ kí a wò ó bóyá Elijah yóò sọ̀kalẹ̀ láti gbà á là.”
Mais les autres disaient: «Laisse, voyons si Élie viendra le sauver.»
50 Nígbà tí Jesu sì kígbe ní ohùn rara lẹ́ẹ̀kan sí i, ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀, ó sì kú.
Mais Jésus poussa de nouveau un grand cri et rendit l'esprit.
51 Lójúkan náà aṣọ ìkélé tẹmpili fàya, láti òkè dé ìsàlẹ̀. Ilẹ̀ sì mì tìtì. Àwọn àpáta sì sán.
A ce moment le voile du temple se déchira en deux, depuis le haut jusqu'en bas; la terre trembla; les rochers se fendirent;
52 Àwọn isà òkú sì ṣí sílẹ̀. Ọ̀pọ̀ òkú àwọn ẹni mímọ́ tí ó ti sùn sì tún jíǹde.
les sépulcres s'ouvrirent, et plusieurs saints, dont les corps y étaient couchés, ressuscitèrent,
53 Wọ́n jáde wá láti isà òkú lẹ́yìn àjíǹde Jesu, wọ́n sì lọ sí ìlú mímọ́. Níbẹ̀ ni wọ́n ti fi ara han ọ̀pọ̀ ènìyàn.
et, étant sortis de leurs sépulcres, ils vinrent après la résurrection de Jésus, dans la ville sainte, et apparurent à un grand nombre de personnes.
54 Nígbà tí balógun ọ̀run àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tí wọ́n ń sọ Jesu rí bí ilẹ̀ ṣe mì tìtì àti ohun tí ó ṣẹlẹ̀, ẹ̀rù bà wọn gidigidi, wọ́n wí pé, “Lóòótọ́ Ọmọ Ọlọ́run ní í ṣe!”
Le centurion et ceux qui étaient avec lui pour garder Jésus, voyant le tremblement de terre et ce qui venait de se passer, furent saisis d'une grande terreur, et dirent: «Assurément, cet homme était Fils de Dieu.»
55 Ọ̀pọ̀ obìnrin tí ó wá láti Galili pẹ̀lú Jesu láti tọ́jú rẹ̀ wọn ń wò ó láti òkèèrè.
Il y avait là plusieurs femmes qui regardaient de loin; elles avaient accompagné Jésus depuis la Galilée, pour le servir;
56 Nínú àwọn obìnrin ti ó wà níbẹ̀ ni Maria Magdalene, àti Maria ìyá Jakọbu àti Josẹfu, àti ìyá àwọn ọmọ Sebede méjèèjì wà níbẹ̀ pẹ̀lú.
c’étaient entre autres Marie Madeleine, Marie, mère de Jacques et de Joses, et la mère des fils de Zébédée.
57 Nígbà tí alẹ́ sì lẹ́, ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan láti Arimatea, tí à ń pè ní Josẹfu, ọ̀kan nínú àwọn tí ó jẹ́ ọmọ-ẹ̀yìn Jesu,
Sur le soir, il vint un homme riche d'Arimathée, nommé Joseph, qui était lui-même disciple de Jésus.
58 lọ sọ́dọ̀ Pilatu, ó sì tọrọ òkú Jesu. Pilatu sì pàṣẹ kí a gbé é fún un.
Cet homme s'était rendu auprès de Pilate, pour lui demander le corps de Jésus, et Pilate avait ordonné qu'on le lui remît.
59 Josẹfu sì gbé òkú náà. Ó fi aṣọ funfun mímọ́ dì í.
Joseph prit le corps, l'enveloppa d'un linceul blanc,
60 Ó sì tẹ́ ẹ sínú ibojì òkúta tí ó gbẹ́ nínú àpáta fúnra rẹ̀. Ó sì yí òkúta ńlá dí ẹnu-ọ̀nà ibojì náà, ó sì lọ.
et le déposa dans un sépulcre neuf, qu'il avait fait tailler dans le roc pour lui-même; puis il roula une grosse pierre à l'entrée du sépulcre, et s'en alla.
61 Maria Magdalene àti Maria kejì wà níbẹ̀, wọn jókòó òdìkejì ibojì náà.
Marie Madeleine et l'autre Marie étaient là, assises en face du tombeau.
62 Lọ́jọ́ kejì tí ó tẹ̀lé ọjọ́ ìpalẹ̀mọ́ àwọn olórí àlùfáà àti àwọn Farisi lọ sọ́dọ̀ Pilatu.
Le lendemain, c’est-à-dire, le jour qui suivait la préparation, les principaux sacrificateurs et les pharisiens se rendirent ensemble auprès de Pilate,
63 Wọ́n sọ fún un pé, “Alàgbà àwa rántí pé ẹlẹ́tàn n nì wí nígbà tí ó wà láyé pé, ‘Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta èmi yóò tún jí dìde.’
et lui dirent: «Seigneur, nous nous sommes rappelés que, lorsqu'il vivait encore, cet imposteur a dit: «Après trois jours je ressusciterai»,
64 Nítorí náà, pàṣẹ kí a ti ibojì rẹ̀ gbọningbọnin títí ọjọ́ kẹta, kí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ má ṣe wá jí gbé lọ, wọn a sì bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún gbogbo ènìyàn pé, ‘Òun ti jíǹde,’ bí èyí bá ní láti ṣẹlẹ̀, yóò burú fún wa púpọ̀ ju ti àkọ́kọ́ lọ.”
donne donc l'ordre qu'on s'assure du tombeau jusqu'au troisième jour, de peur que ses disciples ne viennent dérober le corps, et ne disent au peuple: «Il est ressuscité des morts; » cette dernière imposture serait pire que la première».
65 Pilatu sì pàṣẹ pé, “Ẹ lo àwọn olùṣọ́ yín kí wọn dáàbò bo ibojì náà bí ẹ bá ti fẹ́.”
Pilate leur dit: Une garde est à vos ordres; allez, assurez-vous du tombeau comme vous l'entendrez.
66 Nítorí náà wọ́n lọ. Wọ́n sì ṣé òkúta ibojì náà dáradára. Wọ́n sì fi àwọn olùṣọ́ sí ibẹ̀ láti dáàbò bò ó.
Ils allèrent s'assurer du tombeau à l'aide de la garde, après avoir scellé la pierre.