< Matthew 24 >

1 Bí Jesu ti ń kúrò ni tẹmpili, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n fẹ́ fi ẹwà tẹmpili náà hàn án.
اَنَنْتَرَں یِیشُ رْیَدا مَنْدِرادْ بَہِ رْگَچّھَتِ، تَدانِیں شِشْیاسْتَں مَنْدِرَنِرْمّانَں دَرْشَیِتُماگَتاح۔
2 Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin kò ha rí gbogbo nǹkan wọ̀nyí? Lóòótọ́ ni mo wí fún yín gbogbo ilé yìí ni a yóò wó lulẹ̀, kò ní sí òkúta kan tí a ó fi sílẹ̀ lórí òmíràn, tí a kì yóò wó lulẹ̀.”
تَتو یِیشُسْتانُواچَ، یُویَں کِمیتانِ نَ پَشْیَتھَ؟ یُشْمانَہَں سَتْیَں وَدامِ، ایتَنِّچَیَنَسْیَ پاشانَیکَمَپْیَنْیَپاشانےپَرِ نَ سْتھاسْیَتِ سَرْوّانِ بھُومِساتْ کارِشْیَنْتے۔
3 Bí ó ti jókòó ní orí òkè Olifi, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn tọ̀ ọ́ wá ní ìkọ̀kọ̀, wọ́n wí pé, “Sọ fún wa nígbà wo ni èyí yóò ṣẹlẹ̀? Kí ni yóò jẹ́ àmì ìpadà wá rẹ, àti ti òpin ayé?” (aiōn g165)
اَنَنْتَرَں تَسْمِنْ جَیتُنَپَرْوَّتوپَرِ سَمُپَوِشْٹے شِشْیاسْتَسْیَ سَمِیپَماگَتْیَ گُپْتَں پَپْرَچّھُح، ایتا گھَٹَناح کَدا بھَوِشْیَنْتِ؟ بھَوَتَ آگَمَنَسْیَ یُگانْتَسْیَ چَ کِں لَکْشْمَ؟ تَدَسْمانْ وَدَتُ۔ (aiōn g165)
4 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tàn yín jẹ.
تَدانِیں یِیشُسْتانَووچَتْ، اَوَدھَدْوَّں، کوپِ یُشْمانْ نَ بھْرَمَییتْ۔
5 Nítorí ọ̀pọ̀ yóò wá ní orúkọ mi tí wọn yóò máa pe ara wọn ní Kristi náà. Wọn yóò ṣi ọ̀pọ̀lọpọ̀ lọ́nà.
بَہَوو مَمَ نامَ گرِہْلَنْتَ آگَمِشْیَنْتِ، کھْرِیشْٹوہَمیویتِ واچَں وَدَنْتو بَہُونْ بھْرَمَیِشْیَنْتِ۔
6 Ẹ ó máa gbọ́ ìró ogun àti ìdágìrì ogun, kí ẹ̀yin má ṣe jáyà nítorí nǹkan wọ̀nyí kò lè ṣe kí ó ma ṣẹlẹ̀, ṣùgbọ́n òpin kì í ṣe àkókò náà.
یُویَنْچَ سَںگْرامَسْیَ رَنَسْیَ چاڈَمْبَرَں شْروشْیَتھَ، اَوَدھَدْوَّں تینَ چَنْچَلا ما بھَوَتَ، ایتانْیَوَشْیَں گھَٹِشْیَنْتے، کِنْتُ تَدا یُگانْتو نَہِ۔
7 Orílẹ̀-èdè yóò dìde sí orílẹ̀-èdè, àti ìjọba sí ìjọba. Ìyàn àti ilẹ̀ mímì yóò wà ní ibi púpọ̀.
اَپَرَں دیشَسْیَ وِپَکْشو دیشو راجْیَسْیَ وِپَکْشو راجْیَں بھَوِشْیَتِ، سْتھانے سْتھانے چَ دُرْبھِکْشَں مَہامارِی بھُوکَمْپَشْچَ بھَوِشْیَنْتِ،
8 Ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan wọ̀nyí sì jẹ́ ìbẹ̀rẹ̀ ìpọ́njú tí ó ń bọ̀.
ایتانِ دُحکھوپَکْرَماح۔
9 “Nígbà náà ni a ó sì dá a yín lóró. A ó pa yín, a ó sì kórìíra yín ni gbogbo orílẹ̀-èdè, nítorí pé ẹ̀yin jẹ́ tèmi.
تَدانِیں لوکا دُحکھَں بھوجَیِتُں یُشْمانْ پَرَکَریشُ سَمَرْپَیِشْیَنْتِ ہَنِشْیَنْتِ چَ، تَتھا مَمَ نامَکارَنادْ یُویَں سَرْوَّدیشِییَمَنُجاناں سَمِیپے گھرِنارْہا بھَوِشْیَتھَ۔
10 Àti pé, ọ̀pọ̀ nínú yín yóò kọsẹ̀, ẹ̀yin yóò ṣòfófó ara yín, ẹ̀yin yóò kórìíra ara yín pẹ̀lú,
بَہُشُ وِگھْنَں پْراپْتَوَتْسُ پَرَسْپَرَمْ رِتِییاں کرِتَوَتْسُ چَ ایکوپَرَں پَرَکَریشُ سَمَرْپَیِشْیَتِ۔
11 ọ̀pọ̀ àwọn èké wòlíì yóò farahàn, wọn yóò tan ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn jẹ.
تَتھا بَہَوو مرِشابھَوِشْیَدْوادِنَ اُپَسْتھایَ بَہُونْ بھْرَمَیِشْیَنْتِ۔
12 Ẹ̀ṣẹ̀ yóò wà níbi gbogbo, yóò sì sọ ìfẹ́ ọ̀pọ̀ di tútù,
دُشْکَرْمَّناں باہُلْیانْچَ بَہُوناں پْریمَ شِیتَلَں بھَوِشْیَتِ۔
13 ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá forítì í dópin ni a ó gbàlà.
کِنْتُ یَح کَشْچِتْ شیشَں یاوَدْ دھَیرْیَّماشْرَیَتے، سَایوَ پَرِتْرایِشْیَتے۔
14 A ó sì wàásù ìyìnrere nípa ìjọba náà yìí ní gbogbo ayé ká, láti ṣe ẹ̀rí fún gbogbo orílẹ̀-èdè, nígbà náà ni òpin yóò dé.
اَپَرَں سَرْوَّدیشِییَلوکانْ پْرَتِماکْشِی بھَوِتُں راجَسْیَ شُبھَسَماچارَح سَرْوَّجَگَتِ پْرَچارِشْیَتے، ایتادرِشِ سَتِ یُگانْتَ اُپَسْتھاسْیَتِ۔
15 “Nítorí náà, nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìríra ‘ìsọdahoro, tí a ti ẹnu wòlíì Daniẹli sọ,’ tí ó bá dúró ní ibi mímọ́ (ẹnikẹ́ni tí ó bá kà á kí ó yé e),
اَتو یَتْ سَرْوَّناشَکرِدْگھرِنارْہَں وَسْتُ دانِییلْبھَوِشْیَدْوَدِنا پْروکْتَں تَدْ یَدا پُنْیَسْتھانے سْتھاپِتَں دْرَکْشْیَتھَ، (یَح پَٹھَتِ، سَ بُدھْیَتاں)
16 nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ni Judea sálọ sí orí òkè.
تَدانِیں یے یِہُودِییَدیشے تِشْٹھَنْتِ، تے پَرْوَّتیشُ پَلایَنْتاں۔
17 Kí ẹni tí ó wà lórí ilé rẹ̀ má ṣe sọ̀kalẹ̀ wá mú ohunkóhun jáde nínú ilé rẹ̀.
یَح کَشْچِدْ گرِہَپرِشْٹھے تِشْٹھَتِ، سَ گرِہاتْ کِمَپِ وَسْتْوانیتُمْ اَدھے ناوَروہیتْ۔
18 Kí àwọn tí ó sì wà lóko má ṣe darí wá sí ilé láti mú àwọn aṣọ wọn.
یَشْچَ کْشیتْرے تِشْٹھَتِ، سوپِ وَسْتْرَمانیتُں پَراورِتْیَ نَ یایاتْ۔
19 Ṣùgbọ́n àánú ṣe mí fún àwọn obìnrin ti ó lóyún, àti fún àwọn tí ó ń fún ọmọ loyan ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì!
تَدانِیں گَرْبھِنِیسْتَنْیَپایَیِتْرِیناں دُرْگَتِ رْبھَوِشْیَتِ۔
20 Ẹ sì máa gbàdúrà kí sísá yín má ṣe jẹ́ ìgbà òtútù, tàbí ọjọ́ ìsinmi.
اَتو یَشْماکَں پَلایَنَں شِیتَکالے وِشْرامَوارے وا یَنَّ بھَویتْ، تَدَرْتھَں پْرارْتھَیَدھْوَمْ۔
21 Nítorí ìpọ́njú ńlá yóò wà, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ láti ìgbà ìbẹ̀rẹ̀ ọjọ́ ayé wá títí di ìsinsin yìí irú rẹ̀ kì yóò sì ṣí.
آ جَگَدارَمْبھادْ ایتَتْکالَپَرْیَّنَنْتَں یادرِشَح کَداپِ نابھَوَتْ نَ چَ بھَوِشْیَتِ تادرِشو مَہاکْلیشَسْتَدانِیمْ اُپَسْتھاسْیَتِ۔
22 “Lóòótọ́, àfi bí a ké ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì kúrú, gbogbo ẹ̀dá alààyè yóò ṣègbé. Ṣùgbọ́n nítorí ti àwọn àyànfẹ́ ni a ó fi ké ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì kúrú.
تَسْیَ کْلیشَسْیَ سَمَیو یَدِ ہْسْوو نَ کْرِییتَ، تَرْہِ کَسْیاپِ پْرانِنو رَکْشَنَں بھَوِتُں نَ شَکْنُیاتْ، کِنْتُ مَنونِیتَمَنُجاناں کرِتے سَ کالو ہْسْوِیکَرِشْیَتے۔
23 Nígbà náà, bí ẹnikẹ́ni bá sọ fún yín pé, ‘Wo Kristi náà,’ tàbí pé ó ti farahàn níhìn-ín tàbí lọ́hùn ún, ẹ má ṣe gbà á gbọ́.
اَپَرَنْچَ پَشْیَتَ، کھْرِیشْٹوتْرَ وِدْیَتے، وا تَتْرَ وِدْیَتے، تَدانِیں یَدِی کَشْچِدْ یُشْمانَ اِتِ واکْیَں وَدَتِ، تَتھاپِ تَتْ نَ پْرَتِیتْ۔
24 Nítorí àwọn èké Kristi àti àwọn èké wòlíì yóò dìde. Wọn yóò sì ṣe ọ̀pọ̀ iṣẹ́ àmì àti ìyanu. Bí ó bá lè ṣe é ṣe wọn yóò tan àwọn àyànfẹ́ Ọlọ́run pàápàá jẹ.
یَتو بھاکْتَکھْرِیشْٹا بھاکْتَبھَوِشْیَدْوادِنَشْچَ اُپَسْتھایَ یانِ مَہَنْتِ لَکْشْمانِ چِتْرَکَرْمّانِ چَ پْرَکاشَیِشْیَنْتِ، تَے رْیَدِ سَمْبھَویتْ تَرْہِ مَنونِیتَمانَوا اَپِ بھْرامِشْیَنْتے۔
25 Wò ó, mo ti kìlọ̀ fún yín tẹ́lẹ̀.
پَشْیَتَ، گھَٹَناتَح پُورْوَّں یُشْمانْ وارْتّامْ اَوادِشَمْ۔
26 “Nítorí náà, bí ẹnìkan bá sọ fún yín pé, ‘Olùgbàlà ti dé,’ àti pé, ‘Ó wà ní aginjù,’ ẹ má ṣe wàhálà láti lọ wò ó, tàbí tí wọ́n bá ní, ó ń fi ara pamọ́ sí iyàrá,” ẹ má ṣe gbà wọn gbọ́.
اَتَح پَشْیَتَ، سَ پْرانْتَرے وِدْیَتَ اِتِ واکْیے کینَچِتْ کَتھِتیپِ بَہِ رْما گَچّھَتَ، وا پَشْیَتَ، سونْتَحپُرے وِدْیَتے، ایتَدْواکْیَ اُکْتیپِ ما پْرَتِیتَ۔
27 Nítorí bí mọ̀nàmọ́ná ti ń tàn láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀-oòrùn, bẹ́ẹ̀ ni wíwá Ọmọ Ènìyàn yóò jẹ́.
یَتو یَتھا وِدْیُتْ پُورْوَّدِشو نِرْگَتْیَ پَشْچِمَدِشَں یاوَتْ پْرَکاشَتے، تَتھا مانُشَپُتْرَسْیاپْیاگَمَنَں بھَوِشْیَتِ۔
28 Nítorí ibikíbi tí òkú bá gbé wà, ibẹ̀ ni àwọn ẹyẹ igún ń kójọpọ̀ sí.
یَتْرَ شَوَسْتِشْٹھَتِ، تَتْریوَ گرِدھْرا مِلَنْتِ۔
29 “Lójúkan náà, lẹ́yìn ìpọ́njú ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, “‘ni oòrùn yóò ṣókùnkùn, òṣùpá kì yóò sì fi ìmọ́lẹ̀ rẹ hàn; àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run yóò já sílẹ̀, agbára ojú ọ̀run ni a ó mì tìtì.’
اَپَرَں تَسْیَ کْلیشَسَمَیَسْیاوْیَوَہِتَپَرَتْرَ سُورْیَّسْیَ تیجو لوپْسْیَتے، چَنْدْرَما جْیوسْناں نَ کَرِشْیَتِ، نَبھَسو نَکْشَتْرانِ پَتِشْیَنْتِ، گَگَنِییا گْرَہاشْچَ وِچَلِشْیَنْتِ۔
30 “Nígbà náà ni àmì Ọmọ Ènìyàn yóò sì fi ara hàn ní ọ̀run, nígbà náà ni gbogbo ẹ̀yà ayé yóò káàánú, wọn yóò sì rí Ọmọ Ènìyàn tí yóò máa ti ojú ọ̀run bọ̀ ti òun ti ògo àti agbára ńlá.
تَدانِیمْ آکاشَمَدھْیے مَنُجَسُتَسْیَ لَکْشْمَ دَرْشِشْیَتے، تَتو نِجَپَراکْرَمینَ مَہاتیجَسا چَ میگھارُوڈھَں مَنُجَسُتَں نَبھَساگَچّھَنْتَں وِلوکْیَ پرِتھِوْیاح سَرْوَّوَںشِییا وِلَپِشْیَنْتِ۔
31 Yóò sì rán àwọn angẹli rẹ̀ jáde pẹ̀lú ohùn ìpè ńlá, wọn yóò sì kó gbogbo àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ láti orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé àti ọ̀run jọ.
تَدانِیں سَ مَہاشَبْدایَمانَتُورْیّا وادَکانْ نِجَدُوتانْ پْرَہیشْیَتِ، تے وْیومْنَ ایکَسِیماتوپَرَسِیماں یاوَتْ چَتُرْدِشَسْتَسْیَ مَنونِیتَجَنانْ آنِییَ میلَیِشْیَنْتِ۔
32 “Nísinsin yìí, ẹ kọ́ òwe lára igi ọ̀pọ̀tọ́. Nígbà tí ẹ̀ka rẹ̀ bá ti ń yọ tuntun tí ó bá sì ń ru ewé, ẹ̀yin mọ̀ pé ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn súnmọ́ tòsí.
اُڈُمْبَرَپادَپَسْیَ درِشْٹانْتَں شِکْشَدھْوَں؛ یَدا تَسْیَ نَوِیناح شاکھا جایَنْتے، پَلَّوادِشْچَ نِرْگَچّھَتِ، تَدا نِداگھَکالَح سَوِدھو بھَوَتِیتِ یُویَں جانِیتھَ؛
33 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, nígbà tí ẹ̀yin bá sì rí i tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ń ṣẹlẹ̀, kí ẹ mọ̀ pé ìpadàbọ̀ mi dé tán lẹ́yìn ìlẹ̀kùn.
تَدْوَدْ ایتا گھَٹَنا درِشْٹْوا سَ سَمَیو دْوارَ اُپاسْتھادْ اِتِ جانِیتَ۔
34 Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ìran yìí kì yóò kọjá títí tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ.
یُشْمانَہَں تَتھْیَں وَدامِ، اِدانِینْتَنَجَناناں گَمَناتْ پُورْوَّمیوَ تانِ سَرْوّانِ گھَٹِشْیَنْتے۔
35 Ọ̀run àti ayé yóò rékọjá, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi kì yóò rékọjá.
نَبھومیدِنْیو رْلُپْتَیورَپِ مَمَ واکْ کَداپِ نَ لوپْسْیَتے۔
36 “Ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan ti ó mọ ọjọ́ àti wákàtí tí òpin náà yóò dé, àwọn angẹli ọ̀run pàápàá kò mọ̀ ọ́n. Àní, ọmọ kò mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe Baba mi nìkan ṣoṣo ló mọ̀ ọ́n.
اَپَرَں مَمَ تاتَں وِنا مانُشَح سْوَرْگَسْتھو دُوتو وا کوپِ تَدِّنَں تَدَّنْڈَنْچَ نَ جْناپَیَتِ۔
37 Bí ó ṣe rí ní ìgbà ayé Noa, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wíwá Ọmọ Ènìyàn yóò sì rí.
اَپَرَں نوہے وِدْیَمانے یادرِشَمَبھَوَتْ تادرِشَں مَنُجَسُتَسْیاگَمَنَکالیپِ بھَوِشْیَتِ۔
38 Nítorí bí àwọn ọjọ́ náà ti wà ṣáájú ìkún omi, tí wọ́n ń jẹ́ tí wọ́n ń mu, tí wọ́n ń gbéyàwó, tí wọ́n sì ń fa ìyàwó fún ni, títí tí ó fi di ọjọ́ tí Noa fi bọ́ sínú ọkọ̀.
پھَلَتو جَلاپْلاوَناتْ پُورْوَّں یَدِّنَں یاوَتْ نوہَح پوتَں ناروہَتْ، تاوَتْکالَں یَتھا مَنُشْیا بھوجَنے پانے وِوَہَنے وِواہَنے چَ پْرَورِتّا آسَنْ؛
39 Ènìyàn kò gbàgbọ́ nípa ohun tí o ṣẹlẹ̀ títí tí ìkún omi fi dé nítòótọ́, tí ó sì kó wọn lọ. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wíwá Ọmọ Ènìyàn.
اَپَرَمْ آپْلاوِتویَماگَتْیَ یاوَتْ سَکَلَمَنُجانْ پْلاوَیِتْوا نانَیَتْ، تاوَتْ تے یَتھا نَ وِداماسُح، تَتھا مَنُجَسُتاگَمَنیپِ بھَوِشْیَتِ۔
40 Àwọn ọkùnrin méjì yóò máa ṣiṣẹ́ nínú oko, a o mú ẹnìkan, a ó sì fi ẹni kejì sílẹ̀.
تَدا کْشیتْرَسْتھِتَیورْدْوَیوریکو دھارِشْیَتے، اَپَرَسْتْیاجِشْیَتے۔
41 Àwọn obìnrin méjì yóò jùmọ̀ máa lọ ọlọ pọ̀, a yóò mú ọ̀kan, a ó fi ẹni kejì sílẹ̀.
تَتھا پیشَنْیا پِںشَتْیورُبھَیو رْیوشِتوریکا دھارِشْیَتےپَرا تْیاجِشْیَتے۔
42 “Nítorí náà, ẹ múra sílẹ̀, nítorí ẹ kò mọ ọjọ́ tí Olúwa yín yóò dé.
یُشْماکَں پْرَبھُح کَسْمِنْ دَنْڈَ آگَمِشْیَتِ، تَدْ یُشْمابھِ رْناوَگَمْیَتے، تَسْماتْ جاگْرَتَح سَنْتَسْتِشْٹھَتَ۔
43 Ṣùgbọ́n, kí ẹ mọ èyí pé, baálé ilé ìbá mọ wákàtí náà tí olè yóò wá, ìbá máa ṣọ́nà, òun kì bá ti jẹ́ kí a já wọ ilé rẹ̀.
کُتْرَ یامے سْتینَ آگَمِشْیَتِیتِ چیدْ گرِہَسْتھو جْناتُمْ اَشَکْشْیَتْ، تَرْہِ جاگَرِتْوا تَں سَنْدھِں کَرْتِّتُمْ اَوارَیِشْیَتْ تَدْ جانِیتَ۔
44 Nítorí náà, ẹ gbọdọ̀ wà ní ìmúrasílẹ̀, nítorí ní wákàtí àìròtẹ́lẹ̀ ni dídé Ọmọ Ènìyàn yóò jẹ́.
یُشْمابھِرَوَدھِییَتاں، یَتو یُشْمابھِ رْیَتْرَ نَ بُدھْیَتے، تَتْرَیوَ دَنْڈے مَنُجَسُتَ آیاسْیَتِ۔
45 “Ǹjẹ́ olóòtítọ́ àti ọlọ́gbọ́n ọmọ ọ̀dọ̀ wo ni olúwa rẹ̀ lè fi ṣe olùbojútó ilé rẹ̀ láti bọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ lójoojúmọ́?
پْرَبھُ رْنِجَپَرِوارانْ یَتھاکالَں بھوجَیِتُں یَں داسَمْ اَدھْیَکْشِیکرِتْیَ سْتھاپَیَتِ، تادرِشو وِشْواسْیو دھِیمانْ داسَح کَح؟
46 Alábùkún fún ni ọmọ ọ̀dọ̀ ti olúwa rẹ̀ dé tí ó sì bá a lórí iṣẹ́ ṣíṣe.
پْرَبھُراگَتْیَ یَں داسَں تَتھاچَرَنْتَں وِیکْشَتے، سَایوَ دھَنْیَح۔
47 Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, èmi yóò sì fi irú ẹni bẹ́ẹ̀ ṣe alákòóso gbogbo ohun tí mo ní.
یُشْمانَہَں سَتْیَں وَدامِ، سَ تَں نِجَسَرْوَّسْوَسْیادھِپَں کَرِشْیَتِ۔
48 Ṣùgbọ́n bí ọmọ ọ̀dọ̀ náà bá jẹ́ ènìyàn búburú náà bá wí ní ọkàn rẹ̀ pé, ‘Olúwa mi kì yóò tètè dé.’
کِنْتُ پْرَبھُراگَنْتُں وِلَمْبَتَ اِتِ مَنَسِ چِنْتَیِتْوا یو دُشْٹو داسو
49 Tí ó sì bẹ̀rẹ̀ si í fi ìyà jẹ́ àwọn ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, tí ó ń jẹ, tí ó sì ń mu àmupara.
پَرَداسانْ پْرَہَرْتُّں مَتّاناں سَنْگے بھوکْتُں پاتُنْچَ پْرَوَرْتَّتے،
50 Nígbà náà ni olúwa ọmọ ọ̀dọ̀ yóò wá ní ọjọ́ àti wákàtí tí kò retí.
سَ داسو یَدا ناپیکْشَتے، یَنْچَ دَنْڈَں نَ جاناتِ، تَتْکالَایوَ تَتْپْرَبھُرُپَسْتھاسْیَتِ۔
51 Yóò sì jẹ ẹ́ ní ìyà gidigidi, yóò sì rán an sí ibùgbé àwọn àgàbàgebè, níbẹ̀ ni ẹkún àti ìpayínkeke yóò wà.
تَدا تَں دَنْڈَیِتْوا یَتْرَ سْتھانے رودَنَں دَنْتَگھَرْشَنَنْچاساتے، تَتْرَ کَپَٹِبھِح ساکَں تَدَّشاں نِرُوپَیِشْیَتِ۔

< Matthew 24 >