< Matthew 24 >
1 Bí Jesu ti ń kúrò ni tẹmpili, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n fẹ́ fi ẹwà tẹmpili náà hàn án.
Nake Jesũ akiuma hekarũ, na rĩrĩa aathiiaga arutwo ake magĩũka kũrĩ we nĩguo mamuonie mĩako ya hekarũ.
2 Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin kò ha rí gbogbo nǹkan wọ̀nyí? Lóòótọ́ ni mo wí fún yín gbogbo ilé yìí ni a yóò wó lulẹ̀, kò ní sí òkúta kan tí a ó fi sílẹ̀ lórí òmíràn, tí a kì yóò wó lulẹ̀.”
Akĩmooria atĩrĩ, “Nĩmũkuona indo ici ciothe? Ngũmwĩra atĩrĩ na ma, gũtirĩ ihiga o na rĩmwe rĩa maya rĩgaakorwo rĩrĩ igũrũ wa rĩrĩa rĩngĩ; mothe nĩmakamomorwo.”
3 Bí ó ti jókòó ní orí òkè Olifi, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn tọ̀ ọ́ wá ní ìkọ̀kọ̀, wọ́n wí pé, “Sọ fún wa nígbà wo ni èyí yóò ṣẹlẹ̀? Kí ni yóò jẹ́ àmì ìpadà wá rẹ, àti ti òpin ayé?” (aiōn )
Na rĩrĩa Jesũ aikarĩte thĩ Kĩrĩma-inĩ kĩa Mĩtamaiyũ-rĩ, arutwo ake magĩũka harĩ we hatarĩ andũ angĩ, makĩmũũria atĩrĩ, “Ta twĩre, maũndũ macio mageekĩka rĩ, na kĩmenyithia gĩa gũcooka gwaku na kĩa mũthia wa mahinda maya nĩ kĩrĩkũ?” (aiōn )
4 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tàn yín jẹ.
Nake Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Mwĩmenyagĩrĩrei mũtikanaheenio nĩ mũndũ o na ũrĩkũ.
5 Nítorí ọ̀pọ̀ yóò wá ní orúkọ mi tí wọn yóò máa pe ara wọn ní Kristi náà. Wọn yóò ṣi ọ̀pọ̀lọpọ̀ lọ́nà.
Nĩgũkorwo andũ aingĩ nĩmagooka na rĩĩtwa rĩakwa, makiugaga atĩrĩ, ‘Niĩ nĩ niĩ Kristũ,’ na nĩ makaheenia andũ aingĩ.
6 Ẹ ó máa gbọ́ ìró ogun àti ìdágìrì ogun, kí ẹ̀yin má ṣe jáyà nítorí nǹkan wọ̀nyí kò lè ṣe kí ó ma ṣẹlẹ̀, ṣùgbọ́n òpin kì í ṣe àkókò náà.
Nĩmũkaigua ũhoro wa mbaara, na mũhuhu ũkoniĩ mbaara, no inyuĩ mũtikanamake. Maũndũ ta macio no nginya mageekĩka, no ithirĩro ti rĩkinyu.
7 Orílẹ̀-èdè yóò dìde sí orílẹ̀-èdè, àti ìjọba sí ìjọba. Ìyàn àti ilẹ̀ mímì yóò wà ní ibi púpọ̀.
Rũrĩrĩ nĩrũgookĩrĩra rũrĩa rũngĩ, na ũthamaki ũũkĩrĩre ũrĩa ũngĩ. Nĩgũkaagĩa ngʼaragu na ithingithia kũndũ na kũndũ.
8 Ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan wọ̀nyí sì jẹ́ ìbẹ̀rẹ̀ ìpọ́njú tí ó ń bọ̀.
Maũndũ macio mothe nĩ kĩambĩrĩria kĩa ruo ta rwa mũndũ-wa-nja akĩrũmwo agĩe mwana.
9 “Nígbà náà ni a ó sì dá a yín lóró. A ó pa yín, a ó sì kórìíra yín ni gbogbo orílẹ̀-èdè, nítorí pé ẹ̀yin jẹ́ tèmi.
“Ningĩ nĩmũkaneanwo mũnyariirwo na mũũragwo, na mũmenwo nĩ ndũrĩrĩ ciothe nĩ ũndũ wakwa.
10 Àti pé, ọ̀pọ̀ nínú yín yóò kọsẹ̀, ẹ̀yin yóò ṣòfófó ara yín, ẹ̀yin yóò kórìíra ara yín pẹ̀lú,
Hĩndĩ ĩyo-rĩ, andũ aingĩ nĩmagatiganĩria wĩtĩkio na makunyananĩre mũndũ na ũrĩa ũngĩ, na mamenane.
11 ọ̀pọ̀ àwọn èké wòlíì yóò farahàn, wọn yóò tan ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn jẹ.
Na anabii aingĩ a maheeni nĩmakoimĩra na nĩmakaheenia andũ aingĩ.
12 Ẹ̀ṣẹ̀ yóò wà níbi gbogbo, yóò sì sọ ìfẹ́ ọ̀pọ̀ di tútù,
Na tondũ waganu nĩũkaingĩha mũno-rĩ, wendani wa andũ aingĩ nĩũkanyiiha,
13 ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá forítì í dópin ni a ó gbàlà.
no ũrĩa ũgaakirĩrĩria nginya hĩndĩ ya ithirĩro-rĩ, ũcio nĩakahonoka.
14 A ó sì wàásù ìyìnrere nípa ìjọba náà yìí ní gbogbo ayé ká, láti ṣe ẹ̀rí fún gbogbo orílẹ̀-èdè, nígbà náà ni òpin yóò dé.
Naguo Ũhoro-ũyũ-Mwega wa ũthamaki nĩũkahunjio thĩ yothe ũtuĩke ũira kũrĩ ndũrĩrĩ ciothe, na thuutha ũcio ithirĩro rĩkinye.
15 “Nítorí náà, nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìríra ‘ìsọdahoro, tí a ti ẹnu wòlíì Daniẹli sọ,’ tí ó bá dúró ní ibi mímọ́ (ẹnikẹ́ni tí ó bá kà á kí ó yé e),
“Nĩ ũndũ ũcio rĩrĩa mũkoona ‘kĩndũ kĩrĩa kĩrĩ thaahu na gĩa kũrehe ihooru’ kĩrũgamĩte Handũ-harĩa-Hatheru, o kĩrĩa kĩarĩtio na kanua ka mũnabii Danieli (ũrĩa ũrathoma nĩamenye ũhoro ũcio),
16 nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ni Judea sálọ sí orí òkè.
hĩndĩ ĩyo arĩa marĩ Judea nĩmorĩre irĩma-inĩ.
17 Kí ẹni tí ó wà lórí ilé rẹ̀ má ṣe sọ̀kalẹ̀ wá mú ohunkóhun jáde nínú ilé rẹ̀.
Mũndũ ũrĩa ũrĩ nyũmba yake igũrũ ndakaharũrũke atĩ akarute kĩndũ kuuma nyũmba yake.
18 Kí àwọn tí ó sì wà lóko má ṣe darí wá sí ilé láti mú àwọn aṣọ wọn.
Nake ũrĩa wĩ mũgũnda ndagacooke mũciĩ kũgĩĩra nguo ciake.
19 Ṣùgbọ́n àánú ṣe mí fún àwọn obìnrin ti ó lóyún, àti fún àwọn tí ó ń fún ọmọ loyan ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì!
Kaĩ atumia arĩa magaakorwo na nda na arĩa magaakorwo makĩongithia hĩndĩ ĩyo nĩmagakorwo na thĩĩna-ĩ!
20 Ẹ sì máa gbàdúrà kí sísá yín má ṣe jẹ́ ìgbà òtútù, tàbí ọjọ́ ìsinmi.
Hooyai nĩguo gwĩthara kwanyu gũtikanakorwo kũrĩ hĩndĩ ya heho kana mũthenya wa Thabatũ.
21 Nítorí ìpọ́njú ńlá yóò wà, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ láti ìgbà ìbẹ̀rẹ̀ ọjọ́ ayé wá títí di ìsinsin yìí irú rẹ̀ kì yóò sì ṣí.
Nĩgũkorwo hĩndĩ ĩyo nĩgũkagĩa na mĩnyamaro mĩnene, ĩtarĩ yoneka kuuma kĩambĩrĩria gĩa thĩ nginya rĩu, na ĩtakooneka rĩngĩ.
22 “Lóòótọ́, àfi bí a ké ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì kúrú, gbogbo ẹ̀dá alààyè yóò ṣègbé. Ṣùgbọ́n nítorí ti àwọn àyànfẹ́ ni a ó fi ké ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì kúrú.
Na tiga matukũ macio makuhĩhirio-rĩ, gũtirĩ mũndũ ũngĩkaahonoka, no nĩ tondũ wa andũ arĩa aamũre, matukũ macio nĩmagakuhĩhio.
23 Nígbà náà, bí ẹnikẹ́ni bá sọ fún yín pé, ‘Wo Kristi náà,’ tàbí pé ó ti farahàn níhìn-ín tàbí lọ́hùn ún, ẹ má ṣe gbà á gbọ́.
Hĩndĩ ĩyo mũndũ o na ũrĩkũ angĩkamwĩra atĩrĩ, ‘Kristũ arĩ na haha!’ kana, ‘Arĩ harĩa!’ Mũtikanetĩkie ũhoro ũcio.
24 Nítorí àwọn èké Kristi àti àwọn èké wòlíì yóò dìde. Wọn yóò sì ṣe ọ̀pọ̀ iṣẹ́ àmì àti ìyanu. Bí ó bá lè ṣe é ṣe wọn yóò tan àwọn àyànfẹ́ Ọlọ́run pàápàá jẹ.
Nĩgũkorwo Kristũ a maheeni na anabii a maheeni nĩmakeyumĩria monanie morirũ manene na maringe ciama, nĩguo maheenie o na arĩa aamũre, korwo no kũhoteke.
25 Wò ó, mo ti kìlọ̀ fún yín tẹ́lẹ̀.
Na rĩrĩ, inyuĩ ndaamũmenyithia ũhoro ũcio mbere ya hĩndĩ ĩyo.
26 “Nítorí náà, bí ẹnìkan bá sọ fún yín pé, ‘Olùgbàlà ti dé,’ àti pé, ‘Ó wà ní aginjù,’ ẹ má ṣe wàhálà láti lọ wò ó, tàbí tí wọ́n bá ní, ó ń fi ara pamọ́ sí iyàrá,” ẹ má ṣe gbà wọn gbọ́.
“Nĩ ũndũ ũcio mũndũ o na ũrĩkũ angĩkamwĩra atĩrĩ, ‘Arĩ werũ-inĩ,’ mũtikanathiĩ kuo; kana angĩmwĩra, ‘Arĩ nyũmba thĩinĩ,’ mũtikanetĩkie ũhoro ũcio.
27 Nítorí bí mọ̀nàmọ́ná ti ń tàn láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀-oòrùn, bẹ́ẹ̀ ni wíwá Ọmọ Ènìyàn yóò jẹ́.
Nĩgũkorwo o ta ũrĩa rũheni ruumĩte irathĩro ruonekaga ithũĩro-rĩ, ũguo noguo gũũka kwa Mũrũ wa Mũndũ gũgaakorwo kũhaana.
28 Nítorí ibikíbi tí òkú bá gbé wà, ibẹ̀ ni àwọn ẹyẹ igún ń kójọpọ̀ sí.
Harĩa hothe harĩ kĩimba, hau nĩho nderi ciũnganaga.
29 “Lójúkan náà, lẹ́yìn ìpọ́njú ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, “‘ni oòrùn yóò ṣókùnkùn, òṣùpá kì yóò sì fi ìmọ́lẹ̀ rẹ hàn; àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run yóò já sílẹ̀, agbára ojú ọ̀run ni a ó mì tìtì.’
“Na rĩrĩ, o rĩmwe thuutha wa mĩnyamaro ya matukũ macio, “‘riũa nĩrĩkagĩa nduma, naguo mweri ũtige kwara; nacio njata nĩikaagũa kuuma igũrũ, namo maahinya ma igũrũ nĩmakenyenyio.’
30 “Nígbà náà ni àmì Ọmọ Ènìyàn yóò sì fi ara hàn ní ọ̀run, nígbà náà ni gbogbo ẹ̀yà ayé yóò káàánú, wọn yóò sì rí Ọmọ Ènìyàn tí yóò máa ti ojú ọ̀run bọ̀ ti òun ti ògo àti agbára ńlá.
“Hĩndĩ ĩyo kĩmenyithia kĩa Mũrũ wa Mũndũ nĩgĩkooneka kũu igũrũ, na ndũrĩrĩ ciothe cia thĩ nĩigacakaya. Nĩikoona Mũrũ wa Mũndũ agĩũka arĩ igũrũ rĩa matu, na arĩ na hinya na riiri mũingĩ.
31 Yóò sì rán àwọn angẹli rẹ̀ jáde pẹ̀lú ohùn ìpè ńlá, wọn yóò sì kó gbogbo àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ láti orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé àti ọ̀run jọ.
Nake nĩagatũma araika ake na mũgambo mũnene wa karumbeta, nao nĩmakoongania arĩa ake aamũre moimĩte mĩena ĩna ĩrĩa yumaga rũhuho, kuuma gĩturi kĩmwe kĩa igũrũ nginya kĩrĩa kĩngĩ.
32 “Nísinsin yìí, ẹ kọ́ òwe lára igi ọ̀pọ̀tọ́. Nígbà tí ẹ̀ka rẹ̀ bá ti ń yọ tuntun tí ó bá sì ń ru ewé, ẹ̀yin mọ̀ pé ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn súnmọ́ tòsí.
“Na rĩrĩ, mwĩrutei na mũkũyũ: Rĩrĩa honge ciaguo ciarĩkia gũthundũka na ciaruta mathangũ-rĩ, nĩmũmenyaga atĩ hĩndĩ ya riũa ĩrĩ hakuhĩ.
33 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, nígbà tí ẹ̀yin bá sì rí i tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ń ṣẹlẹ̀, kí ẹ mọ̀ pé ìpadàbọ̀ mi dé tán lẹ́yìn ìlẹ̀kùn.
Ũguo noguo rĩrĩa mũkoona maũndũ macio mothe, mũkaamenya atĩ ihinda rĩrĩ hakuhĩ, rĩrĩ o ta mũrango-inĩ.
34 Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ìran yìí kì yóò kọjá títí tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ.
Ngũmwĩra atĩrĩ na ma, rũciaro rũrũ rũtigaathira nginya maũndũ macio mothe mahinge.
35 Ọ̀run àti ayé yóò rékọjá, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi kì yóò rékọjá.
Igũrũ na thĩ nĩigathira, no ciugo ciakwa itigathira.
36 “Ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan ti ó mọ ọjọ́ àti wákàtí tí òpin náà yóò dé, àwọn angẹli ọ̀run pàápàá kò mọ̀ ọ́n. Àní, ọmọ kò mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe Baba mi nìkan ṣoṣo ló mọ̀ ọ́n.
“Gũtirĩ mũndũ ũũĩ ũhoro wa mũthenya ũcio kana ithaa rĩu, o na araika a igũrũ matiũĩ, o na Mũriũ ndooĩ, tiga no Ithe wiki.
37 Bí ó ṣe rí ní ìgbà ayé Noa, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wíwá Ọmọ Ènìyàn yóò sì rí.
O ta ũrĩa gwatariĩ matukũ-inĩ ma Nuhu, noguo gũkahaana hĩndĩ ya gũũka kwa Mũrũ wa Mũndũ.
38 Nítorí bí àwọn ọjọ́ náà ti wà ṣáájú ìkún omi, tí wọ́n ń jẹ́ tí wọ́n ń mu, tí wọ́n ń gbéyàwó, tí wọ́n sì ń fa ìyàwó fún ni, títí tí ó fi di ọjọ́ tí Noa fi bọ́ sínú ọkọ̀.
Nĩgũkorwo o ta ũrĩa gwatariĩ matukũ marĩa maarĩ mbere ya kĩguũ, andũ nĩmarĩĩaga na makanyua, na nĩmahikanagia na makahika, o nginya mũthenya ũrĩa Nuhu aatoonyire thabina;
39 Ènìyàn kò gbàgbọ́ nípa ohun tí o ṣẹlẹ̀ títí tí ìkún omi fi dé nítòótọ́, tí ó sì kó wọn lọ. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wíwá Ọmọ Ènìyàn.
nao matiamenyire nginya rĩrĩa kĩguũ gĩokire, gĩkĩmaniina othe. Ũguo noguo gũkahaana hĩndĩ ya gũũka kwa Mũrũ wa Mũndũ.
40 Àwọn ọkùnrin méjì yóò máa ṣiṣẹ́ nínú oko, a o mú ẹnìkan, a ó sì fi ẹni kejì sílẹ̀.
Hĩndĩ ĩyo arũme eerĩ magaakorwo marĩ mũgũnda; ũmwe nĩakoywo na ũrĩa ũngĩ atigwo.
41 Àwọn obìnrin méjì yóò jùmọ̀ máa lọ ọlọ pọ̀, a yóò mú ọ̀kan, a ó fi ẹni kejì sílẹ̀.
Andũ-a-nja eerĩ magaakorwo magĩthĩa hamwe; ũmwe nĩakoywo na ũrĩa ũngĩ atigwo.
42 “Nítorí náà, ẹ múra sílẹ̀, nítorí ẹ kò mọ ọjọ́ tí Olúwa yín yóò dé.
“Nĩ ũndũ ũcio, ikaragai mwĩiguĩte, tondũ mũtiũĩ mũthenya ũrĩa Mwathani wanyu agooka.
43 Ṣùgbọ́n, kí ẹ mọ èyí pé, baálé ilé ìbá mọ wákàtí náà tí olè yóò wá, ìbá máa ṣọ́nà, òun kì bá ti jẹ́ kí a já wọ ilé rẹ̀.
No menyai atĩrĩ, korwo mwene nyũmba nĩamenyete thaa cia ũtukũ iria mũici angĩũka, angĩaikarire eiguĩte, nyũmba yake ĩtuuo.
44 Nítorí náà, ẹ gbọdọ̀ wà ní ìmúrasílẹ̀, nítorí ní wákàtí àìròtẹ́lẹ̀ ni dídé Ọmọ Ènìyàn yóò jẹ́.
Nĩ ũndũ ũcio o na inyuĩ no nginya mũikarage mwĩhaarĩirie, tondũ Mũrũ wa Mũndũ agooka ithaa rĩrĩa mũtamwĩrĩgĩrĩire.
45 “Ǹjẹ́ olóòtítọ́ àti ọlọ́gbọ́n ọmọ ọ̀dọ̀ wo ni olúwa rẹ̀ lè fi ṣe olùbojútó ilé rẹ̀ láti bọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ lójoojúmọ́?
“Ningĩ-rĩ, ndungata ya kwĩhokeka na njũgĩ nĩĩrĩkũ, ĩrĩa mwathi wayo angĩĩhokera kũroraga ndungata iria ingĩ cia nyũmba yake, na ĩciheage irio ihinda rĩrĩa rĩagĩrĩire?
46 Alábùkún fún ni ọmọ ọ̀dọ̀ ti olúwa rẹ̀ dé tí ó sì bá a lórí iṣẹ́ ṣíṣe.
Kaĩ nĩũgaakorwo ũrĩ ũndũ mwega harĩ ndungata ĩyo, rĩrĩa mwathi wayo agooka akore ĩgĩĩka o ũguo-ĩ!
47 Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, èmi yóò sì fi irú ẹni bẹ́ẹ̀ ṣe alákòóso gbogbo ohun tí mo ní.
Ngũmwĩra atĩrĩ na ma, nĩakamĩĩhokera indo ciake ciothe.
48 Ṣùgbọ́n bí ọmọ ọ̀dọ̀ náà bá jẹ́ ènìyàn búburú náà bá wí ní ọkàn rẹ̀ pé, ‘Olúwa mi kì yóò tètè dé.’
No rĩrĩ, ndungata ĩyo ĩngĩkorwo nĩ njaganu, na ĩĩre na ngoro atĩrĩ, ‘Mwathi wakwa nĩegũikara ihinda iraaya atacookete,’
49 Tí ó sì bẹ̀rẹ̀ si í fi ìyà jẹ́ àwọn ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, tí ó ń jẹ, tí ó sì ń mu àmupara.
na ĩkĩambĩrĩrie kũhũũra ndungata iria ingĩ, na kũrĩa na kũnyua hamwe na arĩĩu.
50 Nígbà náà ni olúwa ọmọ ọ̀dọ̀ yóò wá ní ọjọ́ àti wákàtí tí kò retí.
Mwathi wa ndungata ĩyo agooka mũthenya ũrĩa ĩtamwĩrĩgĩrĩire, na ithaa rĩrĩa ĩtooĩ.
51 Yóò sì jẹ ẹ́ ní ìyà gidigidi, yóò sì rán an sí ibùgbé àwọn àgàbàgebè, níbẹ̀ ni ẹkún àti ìpayínkeke yóò wà.
Nake nĩakamĩherithia mũno, na amĩikie hamwe na andũ arĩa hinga, kũrĩa gũgaakorwo na kĩrĩro na kũhagarania magego.