< Matthew 23 >
1 Nígbà náà ni Jesu wí fún ọ̀pọ̀ ènìyàn àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé,
Atunci Isus a vorbit mulțimilor și ucenicilor Săi,
2 “Àwọn olùkọ́ òfin àti àwọn Farisi jókòó ní ipò Mose,
și a zis: “Cărturarii și fariseii stau pe scaunul lui Moise.
3 nítorí náà, ẹ gbọdọ̀ gbọ́ tiwọn, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí wọ́n bá sọ fún yín. Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ohun tí wọ́n ṣe, nítorí àwọn pàápàá kì í ṣe ohun tí wọn kọ́ yín láti ṣe.
Așadar, tot ce vă spun ei să observați, observați și faceți, dar nu faceți faptele lor; căci ei spun și nu fac.
4 Wọ́n á di ẹrù wúwo tí ó sì ṣòro láti rù, wọ́n a sì gbé e le àwọn ènìyàn léjìká, ṣùgbọ́n àwọn tìkára wọn kò jẹ́ fi ìka wọn kan an.
Căci ei leagă poveri grele, greu de purtat, și le pun pe umerii oamenilor, dar ei înșiși nu vor să ridice un deget pentru a-i ajuta.
5 “Ohun gbogbo tí wọ́n ń ṣe, wọ́n ń ṣe é kí àwọn ènìyàn ba à lè rí wọn ni. Wọ́n ń sọ filakteri wọn di gbígbòòrò. Wọ́n tilẹ̀ ń bùkún ìṣẹ́tí aṣọ oyè wọn nígbà gbogbo kí ó ba à lè máa tóbi sí i.
Ci își fac toate faptele lor ca să fie văzute de oameni. Își lărgesc filacteriile și își lărgesc franjurile hainelor lor,
6 Wọ́n fẹ́ ipò ọlá ní ibi àsè, àti níbi ìjókòó ìyàsọ́tọ̀ ni Sinagọgu.
și le place locul de cinste la sărbători, locurile cele mai bune din sinagogi,
7 Wọ́n fẹ́ kí ènìyàn máa kí wọn ní ọjà, kí àwọn ènìyàn máa pè wọ́n ní ‘Rabbi.’
salutul în piețe și să fie numiți de oameni “Rabi, Rabi, Rabi”.
8 “Ṣùgbọ́n kí a má ṣe pè yín ni Rabbi, nítorí pé ẹnìkan ni Olùkọ́ yín, àní Kristi, ará sì ni gbogbo yín.
Dar voi nu trebuie să fiți numiți “Rabi”, căci unul singur este învățătorul vostru, Hristosul, și voi toți sunteți frați.
9 Ẹ má ṣe pe ẹnikẹ́ni ní baba yín ni ayé yìí, nítorí baba kan náà ni ẹ ní tí ó ń bẹ ní ọ̀run.
Nu numiți pe nimeni de pe pământ Tatăl vostru, căci unul singur este Tatăl vostru, Cel din ceruri.
10 Kí a má sì ṣe pè yín ní Olùkọ́ nítorí Olùkọ́ kan ṣoṣo ni ẹ̀yin ní, òun náà ni Kristi.
Și nu vă numiți nici stăpâni, căci unul singur este stăpânul vostru, Hristosul.
11 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá pọ̀jù nínú yín, ni yóò jẹ́ ìránṣẹ́ yín.
Ci cel care este cel mai mare dintre voi va fi robul vostru.
12 Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá gbé ara rẹ̀ ga ni a ó sì rẹ̀ sílẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó bá sì rẹ ara wọn sílẹ̀ ni a ó gbéga.
Cine se înalță va fi smerit, iar cine se smerește va fi înălțat.
13 “Ègbé ni fún yín, ẹ̀yin olùkọ́ òfin àti Farisi, ẹ̀yin àgàbàgebè! Ẹ̀yin sé ìjọba ọ̀run mọ́ àwọn ènìyàn nítorí ẹ̀yin tìkára yín kò wọlé, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ wọlé ó wọlé.
“Vai vouă, cărturari și farisei, fățarnici! Căci voi devorați casele văduvelor și, ca un pretext, faceți rugăciuni lungi. De aceea veți primi o condamnare și mai mare.
“Dar vai de voi, cărturari și farisei, fățarnici! Pentru că voi închideți Împărăția Cerurilor împotriva oamenilor; pentru că voi înșivă nu intrați înăuntru, și nici pe cei care intră nu-i lăsați să intre.
15 “Ègbé ni fún yín, ẹ̀yin olùkọ́ òfin àti Farisi, ẹ̀yin àgàbàgebè! Nítorí ẹ̀yin rin yí ilẹ̀ àti òkun ká láti yí ẹnìkan lọ́kàn padà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ń sọ ọ́ di ọmọ ọ̀run àpáàdì ní ìlọ́po méjì ju ẹ̀yin pàápàá. (Geenna )
Vai vouă, cărturari și farisei, ipocriților! Pentru că voi călătoriți pe mare și pe uscat ca să faceți un singur proselit; și când acesta devine unul, îl faceți de două ori mai fiu al Gheenei decât voi înșivă. (Geenna )
16 “Ègbé ni fún yín, ẹ̀yin afọ́jú ti ń fi ọ̀nà han afọ́jú! Tí ó wí pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó ba fi tẹmpili búra kò sí nǹkan kan, ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni bá fi wúrà inú tẹmpili búra, ó di ajigbèsè.’
“Vai de voi, călăuze oarbe, care ziceți: “Oricine se jură pe templu, nu este nimic; dar oricine se jură pe aurul templului, este obligat.
17 Ẹ̀yin aláìmòye afọ́jú: èwo ni ó ga jù, wúrà tàbí tẹmpili tí ó ń sọ wúrà di mímọ́?
Voi, nebuni orbi! Căci ce este mai mare, aurul sau templul care sfințește aurul?
18 Àti pé, ẹnikẹ́ni tó bá fi pẹpẹ búra, kò jámọ́ nǹkan, ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni tí ó ba fi ẹ̀bùn tí ó wà lórí rẹ̀ búra, ó di ajigbèsè.
Și: “Oricine se jură pe altar, nu este nimic; dar oricine se jură pe darul care este pe el, este obligat?”
19 Ẹ̀yin aláìmòye afọ́jú wọ̀nyí! Èwo ni ó pọ̀jù: ẹ̀bùn tí ó wà lórí pẹpẹ ni tàbí pẹpẹ fúnra rẹ̀ tí ó sọ ẹ̀bùn náà di mímọ́?
Nebuni orbi! Căci ce este mai mare, darul sau altarul care sfințește darul?
20 Nítorí náà ẹnikẹ́ni tí ó bá ń fi pẹpẹ búra, ó fi í búra àti gbogbo ohun tí ó wà lórí rẹ̀.
Așadar, cine jură pe altar, jură pe el și pe tot ce este pe el.
21 Àti pé, ẹni tí ó bá fi tẹmpili búra, ó fi í búra àti ẹni tí ń gbé inú rẹ̀.
Cine se jură pe templu, se jură pe el și pe cel care a locuit în el.
22 Àti pé, ẹni tí ó bá sì fi ọ̀run búra, ó fi ìtẹ́ Ọlọ́run àti ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀ búra.
Cine se jură pe cer, se jură pe tronul lui Dumnezeu și pe cel care stă pe el.
23 “Ègbé ni fún yín ẹ̀yin olùkọ́ òfin àti Farisi, ẹ̀yin àgàbàgebè! Nítorí ẹ̀yin ń gba ìdámẹ́wàá minti, dili àti kumini, ẹ̀yin sì ti fi ohun tí ó ṣe pàtàkì jùlọ nínú òfin sílẹ̀ láìṣe, ìdájọ́, àánú àti ìgbàgbọ́. Wọ̀nyí ni ó tọ́ tí ẹ̀yin ìbá ṣe, ẹ̀yin kò bá fi wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀ láìṣe.
“Vai de voi, cărturari și farisei, fățarnici! Pentru că voi dați zeciuială la mentă, mărar și chimen și ați lăsat deoparte cele mai grele lucruri ale Legii: dreptatea, mila și credința. Dar trebuia să le faceți pe acestea și să nu le lăsați pe celelalte nefăcute.
24 Ẹ̀yin afọ́jú tó ń fi afọ́jú mọ̀nà! Ẹ tu kòkòrò-kantíkantí tó bọ́ sì yín lẹ́nu nù, ẹ gbé ìbákasẹ mì.
Voi, călăuze oarbe, care strecurați un țânțar și înghițiți o cămilă!
25 “Ègbé ni fún yín ẹ̀yin Farisi àti ẹ̀yin olùkọ́ òfin, ẹ̀yin àgàbàgebè. Ẹ̀yin ń fọ òde ago àti àwo ṣùgbọ́n inú rẹ̀ kún fún ìrẹ́jẹ àti ẹ̀gbin gbogbo.
“Vai vouă, cărturari și farisei, fățarnici! Pentru că voi curățați partea exterioară a paharului și a farfuriei, dar înăuntru sunt pline de jaf și de nedreptate.
26 Ìwọ afọ́jú Farisi, tètè kọ́ fọ inú ago àti àwo, gbogbo ago náà yóò sì di mímọ́.
Fariseu orb, curăță mai întâi interiorul paharului și al platoului, pentru ca și exteriorul lui să devină curat.
27 “Ègbé ni fún yín ẹ̀yin Farisi àti ẹ̀yin olùkọ́ òfin, ẹ̀yin àgàbàgebè. Ẹ dàbí ibojì funfun tí ó dára ní wíwò, ṣùgbọ́n tí ó kún fún egungun ènìyàn àti fún ẹ̀gbin àti ìbàjẹ́.
“Vai de voi, cărturari și farisei, fățarnici! Pentru că sunteți ca niște morminte albite, care în afară par frumoase, dar înăuntru sunt pline de oase de morți și de toată necurăția.
28 Ẹ̀yin gbìyànjú láti farahàn bí ènìyàn mímọ́, olódodo, lábẹ́ aṣọ mímọ́ yín ni ọkàn tí ó kún fún ìbàjẹ́ pẹ̀lú oríṣìíríṣìí àgàbàgebè àti ẹ̀ṣẹ̀ wà.
Tot așa și voi, în aparență, păreți drepți în fața oamenilor, dar pe dinăuntru sunteți plini de fățărnicie și de nelegiuire.
29 “Ègbé ni fún yín ẹ̀yin olùkọ́ òfin àti Farisi, ẹ̀yin àgàbàgebè, nítorí ẹ̀yin kọ́ ibojì àwọn wòlíì tí í ṣe ibojì àwọn olódodo ní ọ̀ṣọ́.
“Vai vouă, cărturari și farisei, fățarnici! Căci voi zidiți mormintele profeților și împodobiți mormintele drepților
30 Ẹ̀yin sì wí pé, ‘Àwa ìbá wà ní àsìkò àwọn baba wa, àwa kì bá ní ọwọ́ nínú ẹ̀jẹ̀ àwọn wòlíì’.
și spuneți: “Dacă am fi trăit în zilele părinților noștri, nu am fi fost părtași cu ei la sângele profeților”.
31 Ǹjẹ́ ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí fún ara yín pé, ẹ̀yin ni ọmọ àwọn tí ó pa àwọn wòlíì.
De aceea vă mărturisiți vouă înșivă că sunteți copiii celor care au ucis pe profeți.
32 Àti pé, ẹ̀yin ń tẹ̀lé ìṣísẹ̀ àwọn baba yín. Ẹ̀yin ń kún òsùwọ̀n ìwà búburú wọn dé òkè.
Umpleți, așadar, măsura părinților voștri.
33 “Ẹ̀yin ejò! Ẹ̀yin paramọ́lẹ̀! Ẹ̀yin yóò ti ṣe yọ nínú ẹ̀bi ọ̀run àpáàdì? (Geenna )
Voi, șerpi, urmași ai viperelor, cum veți scăpa de judecata Gheenei? (Geenna )
34 Nítorí náà èmi yóò rán àwọn wòlíì àti àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin tí ó kún fún ẹ̀mí mímọ́, àti àwọn akọ̀wé sí yín. Ẹ̀yin yóò pa àwọn kan nínú wọn nípa kíkàn wọ́n mọ́ àgbélébùú. Ẹ̀yin yóò fi pàṣán na àwọn ẹlòmíràn nínú Sinagọgu yín, tí ẹ̀yin yóò sì ṣe inúnibíni sí wọn láti ìlú dé ìlú.
De aceea, iată, trimit la voi profeți, înțelepți și cărturari. Pe unii dintre ei îi veți ucide și îi veți răstigni, iar pe alții îi veți biciui în sinagogile voastre și îi veți persecuta din cetate în cetate,
35 Kí ẹ̀yin lè jẹ̀bi gbogbo ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodo tí ẹ ta sílẹ̀ ní ayé, láti ẹ̀jẹ̀ Abeli títí dé ẹ̀jẹ̀ Sekariah ọmọ Berekiah ẹni tí ẹ pa nínú tẹmpili láàrín ibi pẹpẹ àti ibi ti ẹ yà sí mímọ́ fún Ọlọ́run.
pentru ca asupra voastră să cadă tot sângele neprihănit vărsat pe pământ, de la sângele neprihănitului Abel până la sângele lui Zaharia, fiul lui Barachia, pe care l-ați ucis între sanctuar și altar.
36 Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò wà sórí ìran yìí.
Cu siguranță vă spun că toate aceste lucruri vor veni peste această generație.
37 “Jerusalẹmu, Jerusalẹmu, ìlú tí ó pa àwọn wòlíì, tí ó sì sọ òkúta lu àwọn tí a rán sí i. Ọ̀pọ̀ ìgbà ni èmi tí ń fẹ́ kó àwọn ọmọ rẹ jọ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àgbébọ̀ adìyẹ ti í dáàbò bo àwọn ọmọ rẹ̀ lábẹ́ ìyẹ́ rẹ, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kọ̀.
“Ierusalime, Ierusalime, care ucizi pe prooroci și ucizi cu pietre pe cei trimiși la ea! De câte ori aș fi vrut să-ți adun copiii, cum își adună găina puii sub aripi, și tu n-ai vrut!
38 Wò ó, a fi ilé yín sílẹ̀ fún yín ní ahoro.
Iată, casa ta este lăsată pustie pentru tine.
39 Nítorí èmi sọ èyí fún yín, ẹ̀yin kì yóò rí mi mọ́, títí ẹ̀yin yóò fi sọ pé, ‘Olùbùkún ni ẹni tó ń bọ̀ ní orúkọ Olúwa.’”
Căcivă spun că nu mă veți mai vedea de acum înainte, până când nu veți zice: “Binecuvântat este cel ce vine în numele Domnului!”.”