< Matthew 22 >
1 Jesu tún fi òwe sọ̀rọ̀ fún wọn wí pé:
Og Jesus tog til Orde og talte atter i Lignelser til dem og sagde:
2 “Ìjọba ọ̀run dàbí ọba kan ti ó múra àsè ìgbéyàwó ńlá fún ọmọ rẹ̀ ọkùnrin.
„Himmeriges Rige lignes ved en Konge, som gjorde Bryllup for sin Søn.
3 Ó rán àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ lọ pe àwọn tí a ti pè tẹ́lẹ̀ sí ibi àsè ìgbéyàwó. Ṣùgbọ́n wọn kò fẹ́ wá.
Og han udsendte sine Tjenere for at kalde de budne til Brylluppet; og de vilde ikke komme.
4 “Lẹ́yìn náà ó tún rán àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mìíràn pé, ‘Ẹ sọ fún àwọn tí mo ti pè wí pé, mo ti ṣe àsè náà tán. A pa màlúù àti ẹran àbọ́pa mi, a ti ṣe ohun gbogbo tán, ẹ wa sí ibi àsè ìgbéyàwó.’
Han udsendte atter andre Tjenere og sagde: Siger til de budne: Se, jeg har beredt mit Maaltid, mine Okser og Fedekvæget er slagtet, og alting er rede; kommer til Brylluppet!
5 “Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀n-ọn-nì tí ó ránṣẹ́ lọ pè kò kà á si. Wọ́n ń bá iṣẹ́ wọn lọ, ọ̀kan sí ọ̀nà oko rẹ̀, òmíràn sí ibi òwò rẹ̀.”
Men de brøde sig ikke derom og gik hen, den ene paa sin Mark, den anden til sit Købmandsskab;
6 Àwọn ìyókù sì mú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọ́n ṣe àbùkù sí wọn, wọ́n lù wọ́n pa.
og de øvrige grebe hans Tjenere, forhaanede og ihjelsloge dem.
7 Ọba yìí bínú gidigidi, ó sì rán àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, ó sì pa àwọn apànìyàn náà run, ó sì jó ìlú wọn.
Men Kongen blev vred og sendte sine Hære ud og slog disse Manddrabere ihjel og satte Ild paa deres Stad.
8 “Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, ‘Àsè ìgbéyàwó ti ṣe tàn, ṣùgbọ́n àwọn tí a pè kò yẹ fún ọlá náà.
Da siger han til sine Tjenere: Brylluppet er beredt, men de budne vare det ikke værd.
9 Ẹ lọ sí ìgboro àti òpópónà kí ẹ sì pe ẹnikẹ́ni tí ẹ bá lè rí wá àsè ìgbéyàwó náà.’
Gaar derfor ud paa Skillevejene og byder til Brylluppet saa mange, som I finde!
10 Nítorí náà, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ náà sì jáde lọ sí òpópónà. Wọ́n sì mú oríṣìíríṣìí ènìyàn tí wọ́n lè rí wá, àwọn tí ò dára àti àwọn tí kò dára, ilé àsè ìyàwó sì kún fún àlejò.
Og de Tjenere gik ud paa Vejene og samlede alle dem, de fandt, baade onde og gode; og Bryllupshuset blev fuldt af Gæster.
11 “Ṣùgbọ́n nígbà tí ọba sì wọlé wá láti wo àwọn àlejò tí a pè, ó sì rí ọkùnrin kan nínú wọn tí kò wọ aṣọ ìgbéyàwó.
Da nu Kongen gik ind for at se Gæsterne, saa han der et Menneske, som ikke var iført Bryllupsklædning.
12 Ọba sì bi í pé, ‘Ọ̀rẹ́, báwo ni ìwọ ṣe wà níhìn-ín yìí láìní aṣọ ìgbéyàwó?’ Ṣùgbọ́n ọkùnrin náà kò ní ìdáhùn kankan.
Og han siger til ham: Ven! hvorledes er du kommen herind og har ingen Bryllupsklædning paa? Men han tav.
13 “Nígbà náà ni ọba wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ dì í tọwọ́ tẹsẹ̀, kí ẹ sì sọ ọ́ sínú òkùnkùn lóde níbi tí ẹkún àti ìpayínkeke wà.’
Da sagde Kongen til Tjenerne: Binder Fødder og Hænder paa ham, og kaster ham ud i Mørket udenfor; der skal der være Graad og Tænders Gnidsel.
14 “Nítorí ọ̀pọ̀ ni a pè ṣùgbọ́n díẹ̀ ni a yàn.”
Thi mange ere kaldede, men faa ere udvalgte.”
15 Nígbà náà ni àwọn Farisi péjọpọ̀ láti ronú ọ̀nà tì wọn yóò gbà fi ọ̀rọ̀ ẹnu mú un.
Da gik Farisæerne hen og holdt Raad om, hvorledes de kunde fange ham i Ord.
16 Wọ́n sì rán àwọn ọmọ-ẹ̀yìn wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Herodu lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Olùkọ́, àwa mọ̀ pé olóòtítọ́ ni ìwọ, ìwọ sì ń kọ́ni ní ọ̀nà Ọlọ́run ní òtítọ́. Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì í wo ojú ẹnikẹ́ni; nítorí tí ìwọ kì í ṣe ojúsàájú ènìyàn.
Og de sende deres Disciple til ham tillige med Herodianerne og sige: „Mester! vi vide, at du er sanddru og lærer Guds Vej i Sandhed og ikke bryder dig om nogen; thi du ser ikke paa Menneskers Person.
17 Nísinsin yìí sọ fún wa, kí ni èrò rẹ? Ǹjẹ́ ó tọ́ láti san owó orí fún Kesari tàbí kò tọ́?”
Sig os derfor: Hvad tykkes dig? Er det tilladt at give Kejseren Skat, eller ej?”
18 Ṣùgbọ́n Jesu ti mọ èrò búburú inú wọn, ó wí pé, “Ẹ̀yin àgàbàgebè, èéṣe ti ẹ̀yin fi ń dán mi wò?
Men da Jesus mærkede deres Ondskab, sagde han: „I Hyklere, hvorfor friste I mig?
19 Ẹ fi owó ẹyọ tí a fi ń san owó orí kan hàn mi.” Wọn mú dínárì kan wá fún un,
Viser mig Skattens Mønt!” Og de bragte ham en Denar.
20 ó sì bi wọ́n pé, “Àwòrán ta ni èyí? Àkọlé tà sì ní?”
Og han siger til dem: „Hvis Billede og Overskrift er dette?”
21 Wọ́n sì dáhùn pé, “Ti Kesari ni.” “Nígbà náà ni ó wí fún wọn pé,” “Ẹ fi èyí tí í ṣe ti Kesari fún Kesari, ẹ sì fi èyí ti ṣe ti Ọlọ́run fún Ọlọ́run.”
De sige til ham: „Kejserens.” Da siger han til dem: „Saa giver Kejseren, hvad Kejserens er, og Gud, hvad Guds er!”
22 Nígbà tí wọ́n gbọ́ èyí, ẹnu yà wọ́n. Wọ́n fi í sílẹ̀, wọ́n sì bá tiwọn lọ.
Og da de hørte det, undrede de sig, og de forlode ham og gik bort.
23 Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kan náà, àwọn Sadusi tí wọ́n sọ pé kò si àjíǹde lẹ́yìn ikú tọ Jesu wá láti bi í ní ìbéèrè,
Samme Dag kom der Saddukæere til ham, hvilke sige, at der ingen Opstandelse er, og de spurgte ham og sagde:
24 wọ́n wí pé, “Olùkọ́, Mose wí fún wa pé, bí ọkùnrin kan bá kú ní àìlọ́mọ, kí arákùnrin rẹ̀ ṣú aya rẹ̀ lópó, kí ó sì bí ọmọ fún un.
„Mester! Moses har sagt: Naar nogen dør og ikke har Børn, skal hans Broder for Svogerskabets Skyld tage hans Hustru til Ægte og oprejse sin Broder Afkom.
25 Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, láàrín wa níhìn-ín yìí, ìdílé kan wà tí ó ní arákùnrin méje. Èyí èkínní nínú wọn gbéyàwó, lẹ́yìn náà ó kú ní àìlọ́mọ. Nítorí náà ìyàwó rẹ̀ di ìyàwó arákùnrin kejì.
Men nu var der hos os syv Brødre; og den første giftede sig og døde; og efterdi han ikke havde Afkom, efterlod han sin Hustru til sin Broder.
26 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ arákùnrin èkejì náà sì tún kú láìlọ́mọ. A sì fi ìyàwó rẹ̀ fún arákùnrin tí ó tún tẹ̀lé e. Bẹ́ẹ̀ sì ni títí tí òun fi di ìyàwó ẹni keje.
Ligesaa ogsaa den anden og den tredje, indtil den syvende;
27 Níkẹyìn obìnrin náà pàápàá sì kú.
men sidst af alle døde Hustruen.
28 Nítorí tí ó ti ṣe ìyàwó àwọn arákùnrin méjèèje, ìyàwó ta ni yóò jẹ́ ní àjíǹde òkú?”
Hvem af disse syv skal nu have hende til Hustru i Opstandelsen? thi de have alle haft hende.”
29 Ṣùgbọ́n Jesu dá wọn lóhùn pé, “Àìmọ̀kan yín ni ó fa irú ìbéèrè báyìí. Nítorí ẹ̀yin kò mọ Ìwé Mímọ́ àti agbára Ọlọ́run.
Men Jesus svarede og sagde til dem: „I fare vild, idet I ikke kende Skrifterne, ej heller Guds Kraft.
30 Nítorí ní àjíǹde kò ní sí ìgbéyàwó, a kò sì ní fi í fún ni ní ìyàwó. Gbogbo ènìyàn yóò sì dàbí àwọn angẹli ní ọ̀run.
Thi i Opstandelsen tage de hverken til Ægte eller bortgiftes, men de ere ligesom Guds Engle i Himmelen.
31 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nípa ti àjíǹde òkú, tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ pé Ọlọ́run ń bá yín sọ̀rọ̀ nígbà ti ó wí pé:
Men hvad de dødes Opstandelse angaar, have I da ikke læst, hvad der er talt til eder af Gud, naar han siger:
32 ‘Èmi ni Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu.’ Ọlọ́run kì í ṣe Ọlọ́run òkú, ṣùgbọ́n tí àwọn alààyè.”
„Jeg er Abrahams Gud og Isaks Gud og Jakobs Gud.” Han er ikke dødes, men levendes Gud.”
33 Nígbà ti àwọn ènìyàn gbọ́ èyí ẹnu yà wọ́n sí ẹ̀kọ́ rẹ.
Og da Skarerne hørte dette, bleve de slagne af Forundring over hans Lære.
34 Nígbà ti wọ́n sì gbọ́ pé ó ti pa àwọn Sadusi lẹ́nu mọ́, àwọn Farisi pé ara wọn jọ.
Men da Farisæerne hørte, at han havde stoppet Munden paa Saddukæerne, forsamlede de sig.
35 Ọ̀kan nínú wọn tí ṣe amòfin dán an wò pẹ̀lú ìbéèrè yìí.
Og en af dem, en lovkyndig, spurgte og fristede ham og sagde:
36 Ó wí pé, “Olùkọ́ èwo ni ó ga jùlọ nínú àwọn òfin?”
„Mester, hvilket er det store Bud i Loven?”
37 Jesu dáhùn pé, “‘Fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, gbogbo ẹ̀mí rẹ àti gbogbo inú rẹ.’
Men han sagde til ham: „Du skal elske Herren din Gud med hele dit Hjerte og med hele din Sjæl og med hele dit Sind.
38 Èyí ni òfin àkọ́kọ́ àti èyí tí ó tóbi jùlọ.
Dette er det store og første Bud.
39 Èkejì tí ó tún dàbí rẹ̀ ní pé, ‘Fẹ́ràn ọmọnìkejì rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ.’
Men et andet er dette ligt: Du skal elske din Næste som dig selv.
40 Lórí àwọn òfin méjèèjì yìí ni gbogbo òfin àti àwọn wòlíì rọ̀ mọ́.”
Af disse to Bud afhænger hele Loven og Profeterne.”
41 Bí àwọn Farisi ti kó ara wọn jọ, Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé,
Men da Farisæerne vare forsamlede, spurgte Jesus dem og sagde:
42 “Kí ni ẹ rò nípa Kristi? Ọmọ ta ni òun ń ṣe?” Wọ́n dáhùn pé, “Ọmọ Dafidi.”
„Hvad tykkes eder om Kristus? Hvis Søn er han?” De sige til ham: „Davids.”
43 Ó sì wí fún wọn pé, “Kí lo dé tí Dafidi, tí ẹ̀mí ń darí, pè é ní ‘Olúwa’? Nítorí ó wí pé,
Han siger til dem: „Hvorledes kan da David i Aanden kalde ham Herre, idet han siger:
44 “‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé, “Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi títí tí èmi yóò fi fi àwọn ọ̀tá rẹ sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ.”’
Herren sagde til min Herre: Sæt dig ved min højre Haand, indtil jeg faar lagt dine Fjender under dine Fødder.
45 Ǹjẹ́ bí Dafidi bá pè é ni ‘Olúwa,’ báwo ni òun ṣe lè jẹ́ ọmọ rẹ̀?”
Naar nu David kalder ham Herre, hvorledes er han da hans Søn?”
46 Kò sí ẹnìkan tí ó lè sọ ọ̀rọ̀ kan ni ìdáhùn, kò tún sí ẹni tí ó tún bí i léèrè ohun kan mọ́ láti ọjọ́ náà mọ́.
Og ingen kunde svare ham et Ord, og ingen vovede mere at rette Spørgsmaal til ham efter den Dag.