< Matthew 22 >
1 Jesu tún fi òwe sọ̀rọ̀ fún wọn wí pé:
ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϦⲈⲚϨⲀⲚⲠⲀⲢⲀⲂⲞⲖⲎ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ.
2 “Ìjọba ọ̀run dàbí ọba kan ti ó múra àsè ìgbéyàwó ńlá fún ọmọ rẹ̀ ọkùnrin.
ⲃ̅ⲤⲞⲚⲒ ⲚϪⲈϮⲘⲈⲦⲞⲨⲢⲞ ⲚⲦⲈⲚⲒⲪⲎⲞⲨⲒ ⲚⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲚⲞⲨⲢⲞ ⲈⲀϤⲒⲢⲒ ⲚⲞⲨϨⲞⲠ ⲈⲠⲈϤϢⲎⲢⲒ.
3 Ó rán àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ lọ pe àwọn tí a ti pè tẹ́lẹ̀ sí ibi àsè ìgbéyàwó. Ṣùgbọ́n wọn kò fẹ́ wá.
ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲞⲨⲰⲢⲠ ⲚⲚⲈϤⲈⲂⲒⲀⲒⲔ ⲈⲘⲞⲨϮ ⲞⲨⲂⲈ ⲚⲎ ⲈⲦⲐⲀϨⲈⲘ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲒϨⲞⲠ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲞⲨⲞⲨⲰϢ ⲈⲒ.
4 “Lẹ́yìn náà ó tún rán àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mìíràn pé, ‘Ẹ sọ fún àwọn tí mo ti pè wí pé, mo ti ṣe àsè náà tán. A pa màlúù àti ẹran àbọ́pa mi, a ti ṣe ohun gbogbo tán, ẹ wa sí ibi àsè ìgbéyàwó.’
ⲇ̅ⲠⲀⲖⲒⲚ ⲞⲚ ⲀϤⲞⲨⲰⲢⲠ ⲚϨⲀⲚⲈⲂⲒⲀⲒⲔ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲀϪⲞⲤ ⲚⲚⲎ ⲈⲦⲐⲀϨⲈⲘ ϪⲈ ⲒⲤ ⲠⲀⲀⲢⲒⲤⲦⲞⲚ ⲀⲒⲤⲈⲂⲦⲰⲦϤ ⲚⲀⲘⲀⲤⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲦϢⲀⲚⲈⲨϢ ⲤⲈϢⲀⲦ ⲤⲈⲤⲈⲂⲦⲰⲦ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲀⲘⲰⲒⲚⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲒϨⲞⲠ.
5 “Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀n-ọn-nì tí ó ránṣẹ́ lọ pè kò kà á si. Wọ́n ń bá iṣẹ́ wọn lọ, ọ̀kan sí ọ̀nà oko rẹ̀, òmíràn sí ibi òwò rẹ̀.”
ⲉ̅ⲚⲐⲰⲞⲨ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲨⲈⲢⲀⲘⲈⲖⲈⲤ ⲀⲨϢⲈ ⲚⲰⲞⲨ ⲞⲨⲀⲒ ⲘⲈⲚ ⲈⲠⲈϤⲒⲞϨⲒ ⲔⲈⲞⲨⲀⲒ ⲆⲈ ⲈⲦⲈϤⲒⲈⲂϢⲰⲦ.
6 Àwọn ìyókù sì mú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọ́n ṣe àbùkù sí wọn, wọ́n lù wọ́n pa.
ⲋ̅ⲠⲤⲈⲠⲒ ⲆⲈ ⲀⲨⲀⲘⲞⲚⲒ ⲚⲚⲈϤⲈⲂⲒⲀⲒⲔ ⲀⲨϢⲞϢⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϦⲞⲐⲂⲞⲨ.
7 Ọba yìí bínú gidigidi, ó sì rán àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, ó sì pa àwọn apànìyàn náà run, ó sì jó ìlú wọn.
ⲍ̅ⲠⲒⲞⲨⲢⲞ ⲆⲈ ⲀϤϪⲰⲚⲦ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲦⲀⲞⲨⲞ ⲘⲠⲈϤⲤⲦⲢⲀⲦⲈⲨⲘⲀ ⲀϤⲦⲀⲔⲞ ⲚⲚⲒⲢⲈϤϦⲰⲦⲈⲂ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲦⲞⲨⲂⲀⲔⲒ ⲀϤⲢⲞⲔϨⲤ ϦⲈⲚⲠⲒⲬⲢⲰⲘ.
8 “Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, ‘Àsè ìgbéyàwó ti ṣe tàn, ṣùgbọ́n àwọn tí a pè kò yẹ fún ọlá náà.
ⲏ̅ⲦⲞⲦⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲚⲈϤⲈⲂⲒⲀⲔ ϪⲈ ⲠⲒϨⲞⲠ ⲘⲈⲚ ϤⲤⲈⲂⲦⲰⲦ ⲚⲎ ⲈⲦⲐⲀϨⲈⲘ ⲆⲈ ⲚⲀⲨⲘⲠϢⲀ ⲀⲚ ⲠⲈ.
9 Ẹ lọ sí ìgboro àti òpópónà kí ẹ sì pe ẹnikẹ́ni tí ẹ bá lè rí wá àsè ìgbéyàwó náà.’
ⲑ̅ⲘⲀϢⲈ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲆⲈ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲚⲒⲘⲀⲚⲘⲞϢⲒ ⲚⲦⲈⲚⲒⲘⲰⲒⲦ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲎ ⲈⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀϪⲈⲘⲞⲨ ⲐⲀϨⲘⲞⲨ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲒϨⲞⲠ.
10 Nítorí náà, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ náà sì jáde lọ sí òpópónà. Wọ́n sì mú oríṣìíríṣìí ènìyàn tí wọ́n lè rí wá, àwọn tí ò dára àti àwọn tí kò dára, ilé àsè ìyàwó sì kún fún àlejò.
ⲓ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϪⲈⲚⲒⲈⲂⲒⲀⲒⲔ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ϨⲒ ⲚⲒⲘⲰⲒⲦ ⲀⲨⲐⲰⲞⲨϮ ⲚⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦⲀⲨϪⲈⲘⲞⲨ ⲚⲎ ⲈⲦϨⲰⲞⲨ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲐⲚⲀⲚⲈⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲘⲞϨ ⲚϪⲈⲠⲒϨⲞⲠ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲎ ⲈⲐⲢⲰⲦⲈⲂ.
11 “Ṣùgbọ́n nígbà tí ọba sì wọlé wá láti wo àwọn àlejò tí a pè, ó sì rí ọkùnrin kan nínú wọn tí kò wọ aṣọ ìgbéyàwó.
ⲓ̅ⲁ̅ⲈⲦⲀϤⲒ ⲆⲈ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲚϪⲈⲠⲒⲞⲨⲢⲞ ⲈⲚⲀⲨ ⲈⲚⲎ ⲈⲐⲢⲰⲦⲈⲂ ⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲘⲘⲀⲨ ⲚⲦϨⲈⲂⲤⲰ ⲘⲠⲒϨⲞⲠ ⲦⲞⲒ ϨⲒⲰⲦϤ ⲀⲚ.
12 Ọba sì bi í pé, ‘Ọ̀rẹ́, báwo ni ìwọ ṣe wà níhìn-ín yìí láìní aṣọ ìgbéyàwó?’ Ṣùgbọ́n ọkùnrin náà kò ní ìdáhùn kankan.
ⲓ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲠⲀϢⲪⲎⲢ ⲠⲰⲤ ⲀⲔⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲘⲚⲀⲒ ⲚⲦϨⲈⲂⲤⲰ ⲘⲠⲒϨⲞⲠ ⲦⲞⲒ ϨⲒⲰⲦⲔ ⲀⲚ ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲀⲢⲰϤ ⲐⲰⲘ.
13 “Nígbà náà ni ọba wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ dì í tọwọ́ tẹsẹ̀, kí ẹ sì sọ ọ́ sínú òkùnkùn lóde níbi tí ẹkún àti ìpayínkeke wà.’
ⲓ̅ⲅ̅ⲦⲞⲦⲈ ⲠⲈϪⲈ ⲠⲒⲞⲨⲢⲞ ⲚⲚⲒⲆⲒⲀⲔⲰⲚ ϪⲈ ⲤⲰⲚϨ ⲘⲪⲀⲒ ⲚⲦⲞⲦϤ ⲚⲈⲘ ⲢⲀⲦϤ ϨⲒⲦϤ ⲈⲠⲒⲬⲀⲔⲒ ⲈⲦⲤⲀⲂⲞⲖ ⲠⲒⲘⲀ ⲈⲦⲀ ⲪⲢⲒⲘⲒ ⲚⲀϢⲰⲠⲒ ⲘⲘⲞϤ ⲚⲈⲘ ⲠⲤⲐⲈⲢⲦⲈⲢ ⲚⲦⲈⲚⲒⲚⲀϪϨⲒ.
14 “Nítorí ọ̀pọ̀ ni a pè ṣùgbọ́n díẹ̀ ni a yàn.”
ⲓ̅ⲇ̅ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲘⲎϢ ⲄⲀⲢ ⲈⲨⲐⲀϨⲈⲘ ϨⲀⲚⲔⲞⲨϪⲒ ⲚⲈⲚⲒⲤⲰⲦⲠ.
15 Nígbà náà ni àwọn Farisi péjọpọ̀ láti ronú ọ̀nà tì wọn yóò gbà fi ọ̀rọ̀ ẹnu mú un.
ⲓ̅ⲉ̅ⲦⲞⲦⲈ ⲀⲨϢⲈ ⲚϪⲈⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲀⲨⲈⲢ ⲞⲨⲤⲞϬⲚⲒ ϦⲀⲢⲞϤ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲤⲈϪⲞⲢϪϤ ⲚⲞⲨⲤⲀϪⲒ.
16 Wọ́n sì rán àwọn ọmọ-ẹ̀yìn wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Herodu lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Olùkọ́, àwa mọ̀ pé olóòtítọ́ ni ìwọ, ìwọ sì ń kọ́ni ní ọ̀nà Ọlọ́run ní òtítọ́. Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì í wo ojú ẹnikẹ́ni; nítorí tí ìwọ kì í ṣe ojúsàájú ènìyàn.
ⲓ̅ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲞⲨⲰⲢⲠ ⲚⲚⲞⲨⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ ϨⲀⲢⲞϤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲎⲢⲰⲆⲒⲀⲚⲞⲤ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲪⲢⲈϤϮⲤⲂⲰ ⲦⲈⲚⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲞⲨⲐⲘⲎⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲒⲘⲰⲒⲦ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲔϮⲤⲂⲰ ⲘⲘⲞϤ ϦⲈⲚⲞⲨⲘⲈⲐⲘⲎ ⲒⲞⲨⲞϨ ⲤⲈⲢⲘⲈⲖⲒⲚ ⲚⲀⲔ ⲀⲚ ϦⲀⲦϨⲎ ⲚϨⲖⲒ ⲔϪⲞⲨϢⲦ ⲄⲀⲢ ⲀⲚ ⲈϨⲞ ⲚⲢⲰⲘⲒ.
17 Nísinsin yìí sọ fún wa, kí ni èrò rẹ? Ǹjẹ́ ó tọ́ láti san owó orí fún Kesari tàbí kò tọ́?”
ⲓ̅ⲍ̅ⲀϪⲞⲤ ⲞⲨⲚ ⲚⲀⲚ ϪⲈ ⲞⲨ ⲠⲈⲦⲈⲔⲘⲈⲨⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲤϢⲈ ⲈϮϨⲰϮ ⲘⲠⲞⲨⲢⲞ ϢⲀⲚ ⲘⲘⲞⲚ.
18 Ṣùgbọ́n Jesu ti mọ èrò búburú inú wọn, ó wí pé, “Ẹ̀yin àgàbàgebè, èéṣe ti ẹ̀yin fi ń dán mi wò?
ⲓ̅ⲏ̅ⲈⲦⲀϤⲈⲘⲒ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈⲦⲞⲨⲘⲈⲦⲤⲀⲘⲠⲈⲦϨⲰⲞⲨ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲦⲈⲦⲈⲚϬⲰⲚⲦ ⲘⲘⲞⲒ ⲚⲒϢⲞⲂⲒ.
19 Ẹ fi owó ẹyọ tí a fi ń san owó orí kan hàn mi.” Wọn mú dínárì kan wá fún un,
ⲓ̅ⲑ̅ⲘⲀⲦⲀⲘⲞⲒ ⲪⲚⲞⲘⲒⲤⲘⲀ ⲚⲦⲈⲚⲒⲔⲎⲚⲤⲞⲤ ⲚⲐⲰⲞⲨ ⲆⲈ ⲀⲨⲒⲚⲒ ⲚⲀϤ ⲚⲞⲨⲤⲀⲐⲈⲢⲒ.
20 ó sì bi wọ́n pé, “Àwòrán ta ni èyí? Àkọlé tà sì ní?”
ⲕ̅ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϪⲈ ⲦⲀⲒϨⲒⲔⲰⲚ ⲐⲀ ⲚⲒⲘ ⲦⲈ ⲚⲈⲘ ⲚⲀⲒⲤϦⲀⲒ.
21 Wọ́n sì dáhùn pé, “Ti Kesari ni.” “Nígbà náà ni ó wí fún wọn pé,” “Ẹ fi èyí tí í ṣe ti Kesari fún Kesari, ẹ sì fi èyí ti ṣe ti Ọlọ́run fún Ọlọ́run.”
ⲕ̅ⲁ̅ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲚⲀ ⲠⲞⲨⲢⲞ ⲚⲈⲦⲞⲦⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲘⲀ ⲚⲀ ⲠⲞⲨⲢⲞ ⲘⲠⲞⲨⲢⲞ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲀ ⲚⲀ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ.
22 Nígbà tí wọ́n gbọ́ èyí, ẹnu yà wọ́n. Wọ́n fi í sílẹ̀, wọ́n sì bá tiwọn lọ.
ⲕ̅ⲃ̅ⲈⲦⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲆⲈ ⲀⲨⲈⲢϢⲪⲎⲢⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲬⲀϤ ⲀⲨϢⲈ ⲚⲰⲞⲨ.
23 Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kan náà, àwọn Sadusi tí wọ́n sọ pé kò si àjíǹde lẹ́yìn ikú tọ Jesu wá láti bi í ní ìbéèrè,
ⲕ̅ⲅ̅ϦⲈⲚ ⲠⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲆⲈ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲀⲨⲒ ϨⲀⲢⲞϤ ⲚϪⲈϨⲀⲚⲤⲀⲆⲆⲞⲨⲔⲈⲞⲤ ⲚⲎ ⲈⲦϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲘⲘⲞⲚ ⲀⲚⲀⲤⲦⲀⲤⲒⲤ ⲚⲀϢⲰⲠⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϢⲈⲚϤ
24 wọ́n wí pé, “Olùkọ́, Mose wí fún wa pé, bí ọkùnrin kan bá kú ní àìlọ́mọ, kí arákùnrin rẹ̀ ṣú aya rẹ̀ lópó, kí ó sì bí ọmọ fún un.
ⲕ̅ⲇ̅ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲪⲢⲈϤϮⲤⲂⲰ Ⲁ- ⲘⲰⲨⲤⲎⲤ ϪⲞⲤ ⲚⲀⲚ ϪⲈ ⲈϢⲰⲠ ⲀⲢⲈϢⲀⲚ ⲞⲨⲀⲒ ⲘⲞⲨ ⲘⲘⲞⲚⲦⲈϤ ϢⲎⲢⲒ ⲘⲘⲀⲨ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈⲠⲈϤⲤⲞⲚ ϬⲒ ⲚⲦⲈϤⲤϨⲒⲘⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲈϤⲦⲞⲨⲚⲞⲤ ⲞⲨϪⲢⲞϪ ⲘⲠⲈϤⲤⲞⲚ.
25 Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, láàrín wa níhìn-ín yìí, ìdílé kan wà tí ó ní arákùnrin méje. Èyí èkínní nínú wọn gbéyàwó, lẹ́yìn náà ó kú ní àìlọ́mọ. Nítorí náà ìyàwó rẹ̀ di ìyàwó arákùnrin kejì.
ⲕ̅ⲉ̅ⲚⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲌⲞⲨⲚ ⲚⲤⲞⲚ ϦⲀⲦⲞⲦⲈⲚ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲒϨⲞⲨⲒⲦ ⲈⲦⲀϤϬⲒ ⲀϤⲘⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲈⲘⲘⲞⲚⲦⲈϤ ϪⲢⲞϪ ⲘⲘⲀⲨ ⲀϤⲬⲀ ⲦⲈϤⲤϨⲒⲘⲒ ⲘⲠⲈϤⲤⲞⲚ.
26 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ arákùnrin èkejì náà sì tún kú láìlọ́mọ. A sì fi ìyàwó rẹ̀ fún arákùnrin tí ó tún tẹ̀lé e. Bẹ́ẹ̀ sì ni títí tí òun fi di ìyàwó ẹni keje.
ⲕ̅ⲋ̅ⲠⲀⲒⲢⲎϮ ⲞⲚ ⲠⲒⲘⲀϨⲂ ⲚⲈⲘ ⲠⲒⲘⲀϨⲄ ϢⲀ ⲠⲒⲘⲀϨⲌ.
27 Níkẹyìn obìnrin náà pàápàá sì kú.
ⲕ̅ⲍ̅ⲈⲠϦⲀⲈ ⲆⲈ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲀⲤⲘⲞⲨ ⲚϪⲈϮⲔⲈⲤϨⲒⲘⲒ.
28 Nítorí tí ó ti ṣe ìyàwó àwọn arákùnrin méjèèje, ìyàwó ta ni yóò jẹ́ ní àjíǹde òkú?”
ⲕ̅ⲏ̅ϦⲈⲚ ϮⲀⲚⲀⲤⲦⲀⲤⲒⲤ ⲞⲨⲚ ⲀⲤⲚⲀⲈⲢⲤϨⲒⲘⲒ ⲚⲚⲒⲘ ϦⲈⲚⲠⲒⲌ ⲀⲨϬⲒⲤ ⲄⲀⲢ ⲦⲎⲢⲞⲨ.
29 Ṣùgbọ́n Jesu dá wọn lóhùn pé, “Àìmọ̀kan yín ni ó fa irú ìbéèrè báyìí. Nítorí ẹ̀yin kò mọ Ìwé Mímọ́ àti agbára Ọlọ́run.
ⲕ̅ⲑ̅ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲦⲈⲦⲈⲚⲤⲞⲢⲈⲘ ⲦⲈⲦⲈⲚⲤⲰⲞⲨⲚ ⲀⲚ ⲚⲚⲒⲄⲢⲀⲪⲎ ⲞⲨⲆⲈ ϮϪⲞⲘ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
30 Nítorí ní àjíǹde kò ní sí ìgbéyàwó, a kò sì ní fi í fún ni ní ìyàwó. Gbogbo ènìyàn yóò sì dàbí àwọn angẹli ní ọ̀run.
ⲗ̅ϦⲈⲚ ϮⲀⲚⲀⲤⲦⲀⲤⲒⲤ ⲄⲀⲢ ⲘⲠⲀⲨϬⲒ ⲞⲨⲆⲈ ⲘⲠⲀⲨϬⲒⲦⲞⲨ ⲀⲖⲖⲀ ⲀⲨⲚⲀⲈⲢ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲚⲚⲒⲀⲄⲄⲈⲖⲞⲤ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ϦⲈⲚⲦⲪⲈ.
31 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nípa ti àjíǹde òkú, tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ pé Ọlọ́run ń bá yín sọ̀rọ̀ nígbà ti ó wí pé:
ⲗ̅ⲁ̅ⲈⲐⲂⲈ ϮⲀⲚⲀⲤⲦⲀⲤⲒⲤ ⲆⲈ ⲚⲦⲈⲚⲒⲢⲈϤⲘⲰⲞⲨⲦ ⲘⲠⲈⲦⲈⲚⲰϢ ⲘⲪⲎ ⲈⲦⲀⲨϪⲞϤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ.
32 ‘Èmi ni Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu.’ Ọlọ́run kì í ṣe Ọlọ́run òkú, ṣùgbọ́n tí àwọn alààyè.”
ⲗ̅ⲃ̅ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲠⲈ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲀⲂⲢⲀⲀⲘ ⲚⲈⲘ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲒⲤⲀⲀⲔ ⲚⲈⲘ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲒⲀⲔⲰⲂ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲪⲀ ⲚⲎ ⲈⲐⲘⲰⲞⲨⲦ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲀⲖⲖⲀ ⲪⲀ ⲚⲎ ⲈⲦⲞⲚϦ ⲠⲈ.
33 Nígbà ti àwọn ènìyàn gbọ́ èyí ẹnu yà wọ́n sí ẹ̀kọ́ rẹ.
ⲗ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲚⲒⲘⲎϢ ⲀⲨⲈⲢϢⲪⲎⲢⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲦⲈϤⲤⲂⲰ.
34 Nígbà ti wọ́n sì gbọ́ pé ó ti pa àwọn Sadusi lẹ́nu mọ́, àwọn Farisi pé ara wọn jọ.
ⲗ̅ⲇ̅ⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ϪⲈ ⲀϤⲐⲰⲘ ⲚⲢⲰⲞⲨ ⲚⲚⲒⲤⲀⲆⲆⲞⲨⲔⲈⲞⲤ ⲀⲨⲐⲰⲞⲨϮ ⲈⲨⲘⲀ.
35 Ọ̀kan nínú wọn tí ṣe amòfin dán an wò pẹ̀lú ìbéèrè yìí.
ⲗ̅ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϢⲈⲚϤ ⲚϪⲈⲞⲨⲀⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϦⲎⲦⲞⲨ ⲈⲞⲨⲚⲞⲘⲒⲔⲞⲤ ⲠⲈ ⲈϤϬⲰⲚⲦ ⲘⲘⲞϤ.
36 Ó wí pé, “Olùkọ́ èwo ni ó ga jùlọ nínú àwọn òfin?”
ⲗ̅ⲋ̅ϪⲈ ⲪⲢⲈϤϮⲤⲂⲰ ⲀϢ ⲦⲈ ϮⲚⲒϢϮ ⲚⲈⲚⲦⲞⲖⲎ ⲈⲦϦⲈⲚ ⲠⲒⲚⲞⲘⲞⲤ.
37 Jesu dáhùn pé, “‘Fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, gbogbo ẹ̀mí rẹ àti gbogbo inú rẹ.’
ⲗ̅ⲍ̅ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲈⲔⲈⲘⲈⲚⲢⲈ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲠⲈⲔⲚⲞⲨϮ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲈⲔϨⲎⲦ ⲦⲎⲢϤ ⲚⲈⲘ ⲦⲈⲔⲮⲨⲬⲎ ⲦⲎⲢⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲈⲔⲘⲈⲨⲒ ⲦⲎⲢⲞⲨ.
38 Èyí ni òfin àkọ́kọ́ àti èyí tí ó tóbi jùlọ.
ⲗ̅ⲏ̅ⲐⲀⲒ ⲦⲈ ϮⲚⲒϢϮ ⲞⲨⲞϨ ⲚϨⲞⲨⲒϮ ⲚⲈⲚⲦⲞⲖⲎ.
39 Èkejì tí ó tún dàbí rẹ̀ ní pé, ‘Fẹ́ràn ọmọnìkejì rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ.’
ⲗ̅ⲑ̅ϮⲘⲀϨⲤⲚⲞⲨϮ ⲦⲈ ⲈⲦⲞⲚⲒ ⲚⲐⲀⲒ ⲈⲔⲈⲘⲈⲚⲢⲈ ⲠⲈⲔϢⲪⲎⲢ ⲘⲠⲈⲔⲢⲎϮ.
40 Lórí àwọn òfin méjèèjì yìí ni gbogbo òfin àti àwọn wòlíì rọ̀ mọ́.”
ⲙ̅ϦⲈⲚ ⲦⲀⲒⲈⲚⲦⲞⲖⲎ ⲤⲚⲞⲨϮ ⲠⲒⲚⲞⲘⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲀⲨⲀϢⲀⲒ ⲈⲢⲰⲞⲨ.
41 Bí àwọn Farisi ti kó ara wọn jọ, Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé,
ⲙ̅ⲁ̅ⲈⲦⲀⲨⲐⲰⲞⲨϮ ⲆⲈ ⲈⲨⲘⲀ ⲚϪⲈⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲀϤϢⲈⲚⲞⲨ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ.
42 “Kí ni ẹ rò nípa Kristi? Ọmọ ta ni òun ń ṣe?” Wọ́n dáhùn pé, “Ọmọ Dafidi.”
ⲙ̅ⲃ̅ϪⲈ ⲞⲨ ⲠⲈⲦⲈⲚⲘⲈⲨⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲈⲐⲂⲈ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲚⲚⲒⲘ ⲠⲈ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲚⲆⲀⲨⲒⲆ.
43 Ó sì wí fún wọn pé, “Kí lo dé tí Dafidi, tí ẹ̀mí ń darí, pè é ní ‘Olúwa’? Nítorí ó wí pé,
ⲙ̅ⲅ̅ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϪⲈ ⲠⲰⲤ ⲞⲨⲚ ⲆⲀⲨⲒⲆ ϦⲈⲚⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀϤⲘⲞⲨϮ ⲈⲢⲞϤ ϪⲈ ⲠⲀϬⲞⲒⲤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ.
44 “‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé, “Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi títí tí èmi yóò fi fi àwọn ọ̀tá rẹ sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ.”’
ⲙ̅ⲇ̅ϪⲈ ⲠⲈϪⲈ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲘⲠⲀϬⲞⲒⲤ ϪⲈ ϨⲈⲘⲤⲒ ⲤⲀⲦⲞⲨⲒⲚⲀⲘ ϢⲀϮⲬⲰ ⲚⲚⲈⲔϪⲀϪⲒ ⲤⲀⲠⲈⲤⲎⲦ ⲚⲚⲈⲔϬⲀⲖⲀⲨϪ.
45 Ǹjẹ́ bí Dafidi bá pè é ni ‘Olúwa,’ báwo ni òun ṣe lè jẹ́ ọmọ rẹ̀?”
ⲙ̅ⲉ̅ⲒⲤϪⲈ ⲞⲨⲚ ⲆⲀⲨⲒⲆ ϤⲘⲞⲨϮ ⲈⲢⲞϤ ϪⲈ ⲠⲀϬⲞⲒⲤ ⲠⲰⲤ ⲠⲈϤϢⲎⲢⲒ ⲠⲈ.
46 Kò sí ẹnìkan tí ó lè sọ ọ̀rọ̀ kan ni ìdáhùn, kò tún sí ẹni tí ó tún bí i léèrè ohun kan mọ́ láti ọjọ́ náà mọ́.
ⲙ̅ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈ ϨⲖⲒ ϢϪⲈⲘϪⲞⲘ ⲚⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚⲀϤ ⲚⲞⲨⲤⲀϪⲒ ⲞⲨⲆⲈ ⲘⲠⲈ ϨⲖⲒ ϢⲈⲢⲦⲞⲖⲘⲀⲚ ⲈϢⲈⲚϤ ⲒⲤϪⲈⲚ ⲠⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ.