< Matthew 20 >

1 “Nítorí ìjọba ọ̀run dàbí ọkùnrin tí ó jẹ́ baálé kan, tí ó jíjáde lọ ní kùtùkùtù òwúrọ̀, tí ó gba àwọn alágbàṣe sínú ọgbà àjàrà rẹ̀.
Fiindcă împărăția cerului se aseamănă cu un om gospodar, care a ieșit devreme dimineața să angajeze lucrători în via lui.
2 Òun pinnu láti san dínárì kan fún iṣẹ́ òòjọ́ kan. Lẹ́yìn èyí ó sì rán wọn lọ sínú ọgbà àjàrà rẹ̀.
Și după ce s-a învoit cu lucrătorii cu câte un dinar pe zi, i-a trimis în via lui.
3 “Ní wákàtí kẹta ọjọ́ bí ó ti ń kọjá níwájú ilé ìgbanisíṣẹ́, ó rí díẹ̀ nínú àwọn aláìríṣẹ́ tí wọ́n dúró ní ọjà.
Și a ieșit pe la ora a treia și a văzut pe alții stând în picioare fără lucru în piață.
4 Ó wí fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin pàápàá, ẹ lọ ṣiṣẹ́ nínú ọgbà àjàrà mi, bí ó bá sì di òpin ọjọ́, èmi yóò san iye ti ó bá yẹ fún yín.’
Și le-a spus: Duceți-vă și voi în vie și vă voi da ce este drept. Și s-au dus.
5 Wọ́n sì lọ. “Ó tún jáde lọ́sàn án ní nǹkan bí wákàtí kẹfà àti wákàtí kẹsànán, ó túnṣe bákan náà.
A ieșit din nou pe la ora a șasea și pe la ora a nouă și a făcut la fel.
6 Lọ́jọ́ kan náà ní wákàtí kọkànlá ọjọ́, ó tún jáde sí àárín ìlú, ó sì rí àwọn aláìríṣẹ́ mìíràn tí wọ́n dúró. Ó bi wọ́n pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin kì í ṣiṣẹ́ ní gbogbo ọjọ́?’
Și pe la ora a unsprezecea a ieșit și a găsit pe alții stând în picioare fără lucru și le-a spus: De ce stați aici în picioare toată ziua fără lucru?
7 “Wọ́n sì dáhùn pé, ‘Nítorí pé kò sí ẹni tí yóò fún wa ní iṣẹ́ ṣe.’ “Ó tún sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin náà ẹ jáde lọ ṣiṣẹ́ pẹ̀lú nínú ọgbà àjàrà mi.’
Iar ei i-au răspuns: Pentru că nimeni nu ne-a angajat. Iar el le-a spus: Duceți-vă și voi în vie; și veți primi ce este drept.
8 “Nígbà tí ó di àṣálẹ́, ẹni tó ni ọgbà àjàrà sọ fún aṣojú rẹ̀ pé, ‘Pe àwọn òṣìṣẹ́ náà, kí ó san owó iṣẹ́ wọn fún wọn, bẹ̀rẹ̀ láti ẹni ìkẹyìn lọ sí ti ìṣáájú.’
Și când s-a făcut seară, domnul viei i-a spus administratorului său: Cheamă lucrătorii și dă-le plata, începând de la cei de pe urmă până la cei dintâi.
9 “Nígbà tí àwọn ti a pè ní wákàtí kọkànlá ọjọ́ dé, ẹnìkọ̀ọ̀kan gba owó dínárì kan.
Și când au venit angajații de pe la ora a unsprezecea, au primit fiecare câte un dinar.
10 Nígbà tí àwọn tí a gbà ṣiṣẹ́ lákọ̀ọ́kọ́ fẹ́ gba owó tiwọn, èrò wọn ni pé àwọn yóò gba jù bẹ́ẹ̀ lọ, ṣùgbọ́n ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn gba owó dínárì kan.
Dar când au venit primii, presupuneau că vor primi mai mult; dar au primit de asemenea fiecare câte un dinar.
11 Bí wọ́n ti ń gbà á, wọ́n ń kùn sí onílẹ̀ náà,
Și când au primit, cârteau împotriva stăpânului casei,
12 pé, ‘Wákàtí kan péré ni àwọn tí a gbà kẹ́yìn fi ṣiṣẹ́, ìwọ sì san iye kan náà fún wọn àti àwa náà ti a fi gbogbo ọjọ́ ṣiṣẹ́ nínú oòrùn gangan.’
Spunând: Aceștia, ultimii, nu au lucrat decât o oră și i-ai făcut egali cu noi, care am dus greul și arșița zilei.
13 “Ṣùgbọ́n ó dá ọ̀kan nínú wọn lóhùn pé, ‘Ọ̀rẹ́, kò sí aburú nínú nǹkan tí èmi ṣe sí yín. Kì í ha ṣe pé ẹ̀yin gbà láti ṣiṣẹ́ fún owó dínárì kan.
Dar el a răspuns unuia dintre ei și a zis: Prietene, nu îți fac nicio nedreptate; nu te-ai învoit cu mine cu un dinar?
14 Ó ní, gba èyí tí í ṣé tìrẹ, ki ó sì máa lọ. Èmi fẹ́ láti fún ẹni ìkẹyìn gẹ́gẹ́ bí mo ti fi fún ọ.
Ia ce este al tău și pleacă; voiesc să plătesc acestuia ultim, ca și ție.
15 Àbí ó lòdì sí òfin pé kí èmi fún ẹnikẹ́ni ní owó mi bí mo bá yàn láti ṣe bẹ́ẹ̀? Kí ni ìdí tí ìwọ ní láti bínú nítorí èmi ṣe ohun rere?’
Nu îmi este legiuit să fac ce voiesc cu ce este al meu? Este ochiul tău rău pentru că eu sunt bun?
16 “Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ẹni ìkẹyìn yóò di ẹni ìṣáájú, ẹni ìṣáájú yóò sì di ẹni ìkẹyìn.”
Astfel că aceia din urmă vor fi cei dintâi și cei dintâi vor fi cei din urmă; fiindcă mulți sunt chemați, dar puțini sunt aleși.
17 Bí Jesu ti ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu, ó pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ méjìlá sí apá kan ó sì wí pé,
Și Isus, urcând la Ierusalim, a luat pe cei doisprezece discipoli deoparte, pe cale și le-a spus:
18 “Wò ó, àwa ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu. Ó sọ fún wọn pé, a ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin lọ́wọ́, wọn yóò sì dá mi lẹ́bi ikú.
Iată, urcăm la Ierusalim; și Fiul omului va fi trădat [și predat] marilor preoți și scribilor și îl vor condamna la moarte,
19 Wọn yóò sì fà á lé àwọn kèfèrí lọ́wọ́ láti fi ṣe ẹlẹ́yà àti láti náà án, àti láti kàn mi mọ́ àgbélébùú, ní ọjọ́ kẹta, yóò jí dìde.”
Și îl vor preda neamurilor să îl batjocorească și să îl biciuiască și să îl crucifice; și a treia zi va învia.
20 Nígbà náà ni ìyá àwọn ọmọ Sebede bá àwọn ọmọ rẹ̀ wá sọ́dọ̀ Jesu, ó wólẹ̀ lórí eékún rẹ̀, o béèrè fún ojúrere rẹ̀.
Atunci a venit la el mama copiilor lui Zebedei, cu fiii ei, închinându-se și dorind ceva anume de la el.
21 Jesu béèrè pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?” Ó sì dáhùn pé, “Jẹ́ kí àwọn ọmọ mi méjèèjì jókòó ní apá ọ̀tún àti apá òsì lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ?”
Și el i-a spus: Ce voiești? Iar ea i-a spus: Permite ca acești doi fii ai mei să șadă unul la dreapta ta și altul la stânga, în împărăția ta.
22 Ṣùgbọ́n Jesu dáhùn ó sì wí pé, “Ẹ̀yin kò mọ ohun tí ẹ̀yin ń béèrè, ẹ̀yin ha le mu nínú ago tí èmi ó mu?” Wọ́n dáhùn pé, “Àwa lè mu ún.”
Dar Isus răspunzând a zis: Nu știți ce cereți. Puteți bea paharul pe care îl voi bea eu? Și să fiți botezați cu botezul cu care sunt botezat eu? Ei i-au spus: Putem.
23 Jesu sì wí fún wọn pé, “Dájúdájú, ẹ̀yin yóò mu nínú ago mi, ṣùgbọ́n èmi kò ní àṣẹ láti sọ irú ènìyàn tí yóò jókòó ní apá ọ̀tún tàbí apá òsì. Baba mi ti pèsè ààyè wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀ fún kìkì àwọn tí ó yàn.”
Iar el le-a spus: Într-adevăr, veți bea paharul meu, și cu botezul cu care sunt botezat eu, veți fi botezați; dar a ședea la dreapta și la stânga mea nu este al meu să dau, ci va fi dat celor pentru care a fost pregătit de Tatăl meu.
24 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mẹ́wàá ìyókù sì gbọ́ èyí, wọ́n bínú sí àwọn arákùnrin méjì yìí.
Și după ce au auzit cei zece, au fost foarte supărați pe cei doi frați.
25 Ṣùgbọ́n Jesu pé wọ́n papọ̀, ó wí pé, “Dájúdájú, ẹ̀yin mọ̀ pé àwọn ọba aláìkọlà a máa lo agbára lórí wọn, àwọn ẹni ńlá láàrín wọn a sì máa fi ọlá tẹrí àwọn tí ó wà lábẹ́ wọn ba.
Dar Isus i-a chemat și a spus: Știți că domnitorii neamurilor exercită domnie asupra lor și cei mari exercită autoritate asupra lor.
26 Ṣùgbọ́n èyí yàtọ̀ láàrín yín. Dípò bẹ́ẹ̀, ẹni tí ó bá ń fẹ́ ṣe olórí láàrín yín, ní láti ṣe bí ìránṣẹ́ fún yín ni,
Dar între voi nu va fi așa; ci oricine voiește să devină mare între voi, să vă fie servitor;
27 àti ẹni tí ó bá fẹ́ ṣe olórí nínú yín, ẹ jẹ́ kí ó máa ṣe ọmọ ọ̀dọ̀ yin.
Și oricine voiește să devină primul între voi, să vă fie rob;
28 Gẹ́gẹ́ bí Ọmọ Ènìyàn kò ṣe wá sí ayé, kí ẹ lè ṣe ìránṣẹ́ fún un, ṣùgbọ́n láti ṣe ìránṣẹ́ fún yín, àti láti fi ẹ̀mí rẹ ṣe ìràpadà ọ̀pọ̀ ènìyàn.”
Chiar așa cum Fiul omului nu a venit ca să fie servit ci ca să servească, și ca să își dea viața răscumpărare pentru mulți.
29 Bí Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ti ń fi ìlú Jeriko sílẹ̀, ọ̀pọ̀ ènìyàn sì wọ́ tẹ̀lé e lẹ́yìn.
Și pe când ieșeau din Ierihon, o mare mulțime l-a urmat.
30 Àwọn ọkùnrin afọ́jú méjì sì jókòó lẹ́bàá ọ̀nà, nígbà tí wọ́n sí gbọ́ pé Jesu ń kọjá lọ, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í kígbe pé, “Olúwa, Ọmọ Dafidi, ṣàánú fún wa!”
Și, iată, doi orbi șezând lângă drumul mare, când au auzit că trece Isus, au strigat, spunând: Ai milă de noi, Doamne, Fiul lui David!
31 Àwọn ènìyàn sí bá wọn wí pé kí wọn dákẹ́, ṣùgbọ́n wọ́n kígbe sókè sí i. “Olúwa, ọmọ Dafidi, ṣàánú fún wa!”
Și mulțimea îi mustra pentru că trebuiau să tacă; dar strigau mai tare, spunând: Ai milă de noi, Doamne, Fiul lui David!
32 Jesu dúró lójú ọ̀nà, ó sì pè wọ́n, Ó béèrè pé, “Kí ni ẹ̀yin fẹ́ kí èmi ṣe fún yín?”
Și Isus s-a oprit și i-a chemat și a spus: Ce voiți să vă fac?
33 Wọ́n dáhùn pé, “Olúwa, àwa fẹ́ kí a ríran.”
Iar ei i-au spus: Doamne, să ne fie deschiși ochii.
34 Àánú wọn sì ṣe Jesu, ó fi ọwọ́ kan ojú wọn. Lójúkan náà, wọ́n sì ríran, wọ́n sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
Și Isus, făcându-i-se milă, le-a atins ochii; și îndată ochii lor [și]-au primit vederea; și ei l-au urmat.

< Matthew 20 >