< Matthew 20 >

1 “Nítorí ìjọba ọ̀run dàbí ọkùnrin tí ó jẹ́ baálé kan, tí ó jíjáde lọ ní kùtùkùtù òwúrọ̀, tí ó gba àwọn alágbàṣe sínú ọgbà àjàrà rẹ̀.
„Hasonló a mennyek országa a gazdához, aki korán reggel kiment, hogy munkásokat fogadjon szőlőjébe.
2 Òun pinnu láti san dínárì kan fún iṣẹ́ òòjọ́ kan. Lẹ́yìn èyí ó sì rán wọn lọ sínú ọgbà àjàrà rẹ̀.
Megegyezett a munkásokkal napi tíz pénzben, és elküldte őket szőlőjébe.
3 “Ní wákàtí kẹta ọjọ́ bí ó ti ń kọjá níwájú ilé ìgbanisíṣẹ́, ó rí díẹ̀ nínú àwọn aláìríṣẹ́ tí wọ́n dúró ní ọjà.
Amikor kiment három óra tájban, látott másokat is, akik tétlenül a piacon álltak.
4 Ó wí fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin pàápàá, ẹ lọ ṣiṣẹ́ nínú ọgbà àjàrà mi, bí ó bá sì di òpin ọjọ́, èmi yóò san iye ti ó bá yẹ fún yín.’
Ezt mondta nekik: Menjetek el ti is a szőlőbe, és ami igazságos, megadom nektek.
5 Wọ́n sì lọ. “Ó tún jáde lọ́sàn án ní nǹkan bí wákàtí kẹfà àti wákàtí kẹsànán, ó túnṣe bákan náà.
Azok pedig elmentek. Hat és kilenc óra tájban ismét kiment, és ugyanúgy cselekedett.
6 Lọ́jọ́ kan náà ní wákàtí kọkànlá ọjọ́, ó tún jáde sí àárín ìlú, ó sì rí àwọn aláìríṣẹ́ mìíràn tí wọ́n dúró. Ó bi wọ́n pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin kì í ṣiṣẹ́ ní gbogbo ọjọ́?’
Tizenegy óra tájban is kiment, és talált másokat, akik tétlenül álltak ott, és megkérdezte tőlük: Miért álltok itt egész napon át tétlenül?
7 “Wọ́n sì dáhùn pé, ‘Nítorí pé kò sí ẹni tí yóò fún wa ní iṣẹ́ ṣe.’ “Ó tún sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin náà ẹ jáde lọ ṣiṣẹ́ pẹ̀lú nínú ọgbà àjàrà mi.’
Azok így feleltek: Mert senki sem fogadott fel minket. Erre ezt mondta nekik: Menjetek el ti is a szőlőbe, és ami igazságos megkapjátok.
8 “Nígbà tí ó di àṣálẹ́, ẹni tó ni ọgbà àjàrà sọ fún aṣojú rẹ̀ pé, ‘Pe àwọn òṣìṣẹ́ náà, kí ó san owó iṣẹ́ wọn fún wọn, bẹ̀rẹ̀ láti ẹni ìkẹyìn lọ sí ti ìṣáájú.’
Mikor beesteledett, a szőlőnek ura ezt mondta vincellérjének: Hívd elő a munkásokat, és add ki nekik a bért, az utolsóktól kezdve mind az elsőkig.
9 “Nígbà tí àwọn ti a pè ní wákàtí kọkànlá ọjọ́ dé, ẹnìkọ̀ọ̀kan gba owó dínárì kan.
És jöttek a tizenegy órások, fejenként tíz-tíz pénzt kaptak.
10 Nígbà tí àwọn tí a gbà ṣiṣẹ́ lákọ̀ọ́kọ́ fẹ́ gba owó tiwọn, èrò wọn ni pé àwọn yóò gba jù bẹ́ẹ̀ lọ, ṣùgbọ́n ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn gba owó dínárì kan.
Jöttek azután az elsők, és azt gondolták, hogy ők többet kapnak, de ők is tíz-tíz pénz kaptak fejenként.
11 Bí wọ́n ti ń gbà á, wọ́n ń kùn sí onílẹ̀ náà,
Amint pedig fölvették, zúgolódni kezdtek a házigazda ellen,
12 pé, ‘Wákàtí kan péré ni àwọn tí a gbà kẹ́yìn fi ṣiṣẹ́, ìwọ sì san iye kan náà fún wọn àti àwa náà ti a fi gbogbo ọjọ́ ṣiṣẹ́ nínú oòrùn gangan.’
és ezt mondták: Azok az utolsók egyetlen óráig dolgoztak, és egyenlővé tetted őket velünk, akik a napnak terhét és hőségét szenvedtük.
13 “Ṣùgbọ́n ó dá ọ̀kan nínú wọn lóhùn pé, ‘Ọ̀rẹ́, kò sí aburú nínú nǹkan tí èmi ṣe sí yín. Kì í ha ṣe pé ẹ̀yin gbà láti ṣiṣẹ́ fún owó dínárì kan.
Ő pedig így felelt közülük egynek: Barátom, nem cselekszem igazságtalanul veled: Vagy nem tíz pénzben szerződtél velem?
14 Ó ní, gba èyí tí í ṣé tìrẹ, ki ó sì máa lọ. Èmi fẹ́ láti fún ẹni ìkẹyìn gẹ́gẹ́ bí mo ti fi fún ọ.
Vedd, ami a tiéd, és menj el. Én pedig ennek az utolsónak is annyit akarok adni, mint neked.
15 Àbí ó lòdì sí òfin pé kí èmi fún ẹnikẹ́ni ní owó mi bí mo bá yàn láti ṣe bẹ́ẹ̀? Kí ni ìdí tí ìwọ ní láti bínú nítorí èmi ṣe ohun rere?’
Talán nem szabad nekem a magaméval azt tennem, amit akarok? Vagy a te szemed azért gonosz, mert én jó vagyok?
16 “Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ẹni ìkẹyìn yóò di ẹni ìṣáájú, ẹni ìṣáájú yóò sì di ẹni ìkẹyìn.”
Ekképpen lesznek az utolsók elsők és az elsők utolsók; mert sokan vannak a hivatalosak, de kevesen a választottak.“
17 Bí Jesu ti ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu, ó pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ méjìlá sí apá kan ó sì wí pé,
Amikor felment Jézus Jeruzsálembe, útközben csupán a tizenkét tanítványt vette magához, és ezt mondta nekik:
18 “Wò ó, àwa ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu. Ó sọ fún wọn pé, a ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin lọ́wọ́, wọn yóò sì dá mi lẹ́bi ikú.
„Íme, felmegyünk Jeruzsálembe, és az Emberfia átadatik a főpapoknak és írástudóknak, és halálra ítélik őt.
19 Wọn yóò sì fà á lé àwọn kèfèrí lọ́wọ́ láti fi ṣe ẹlẹ́yà àti láti náà án, àti láti kàn mi mọ́ àgbélébùú, ní ọjọ́ kẹta, yóò jí dìde.”
A pogányok kezébe adják, hogy megcsúfolják, megostorozzák, és keresztre feszítsék, de harmadnapon feltámad.“
20 Nígbà náà ni ìyá àwọn ọmọ Sebede bá àwọn ọmọ rẹ̀ wá sọ́dọ̀ Jesu, ó wólẹ̀ lórí eékún rẹ̀, o béèrè fún ojúrere rẹ̀.
Ekkor hozzáment a Zebedeus fiainak anyja fiaival együtt, leborult előtte, hogy kérjen tőle valamit.
21 Jesu béèrè pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?” Ó sì dáhùn pé, “Jẹ́ kí àwọn ọmọ mi méjèèjì jókòó ní apá ọ̀tún àti apá òsì lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ?”
Ő pedig megkérdezte tőle: „Mit akarsz?“Ő ezt mondta neki: „Mondd, hogy az én két fiam üljön a te országodban: egyik jobb kezed felől, a másik bal kezed felől.“
22 Ṣùgbọ́n Jesu dáhùn ó sì wí pé, “Ẹ̀yin kò mọ ohun tí ẹ̀yin ń béèrè, ẹ̀yin ha le mu nínú ago tí èmi ó mu?” Wọ́n dáhùn pé, “Àwa lè mu ún.”
Jézus pedig ezt felelte neki: „Nem tudjátok, mit kértek. Megisszátok-e a poharat, melyet én iszom? És megkeresztelkedtek-e azzal a keresztséggel, amellyel én megkeresztelkedem?“Azt mondták neki: „Meg.“
23 Jesu sì wí fún wọn pé, “Dájúdájú, ẹ̀yin yóò mu nínú ago mi, ṣùgbọ́n èmi kò ní àṣẹ láti sọ irú ènìyàn tí yóò jókòó ní apá ọ̀tún tàbí apá òsì. Baba mi ti pèsè ààyè wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀ fún kìkì àwọn tí ó yàn.”
Erre ő azt mondta nekik: „Az én poharamat megisszátok ugyan, és a keresztséggel, amellyel én megkeresztelkedem, megkeresztelkedtek, de az én jobb és bal kezem felől való ülést nem az én dolgom megadni, hanem azoké lesz az, akiknek az én Atyám elkészítette.“
24 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mẹ́wàá ìyókù sì gbọ́ èyí, wọ́n bínú sí àwọn arákùnrin méjì yìí.
Amikor ezt meghallotta a többi tíz, bosszankodtak a két testvérre.
25 Ṣùgbọ́n Jesu pé wọ́n papọ̀, ó wí pé, “Dájúdájú, ẹ̀yin mọ̀ pé àwọn ọba aláìkọlà a máa lo agbára lórí wọn, àwọn ẹni ńlá láàrín wọn a sì máa fi ọlá tẹrí àwọn tí ó wà lábẹ́ wọn ba.
Jézus pedig előszólította őket, és ezt mondta: „Tudjátok, hogy a pogányok fejedelmei uralkodnak szolgáikon, és a nagyok hatalmaskodnak rajtuk.
26 Ṣùgbọ́n èyí yàtọ̀ láàrín yín. Dípò bẹ́ẹ̀, ẹni tí ó bá ń fẹ́ ṣe olórí láàrín yín, ní láti ṣe bí ìránṣẹ́ fún yín ni,
De ne így legyen közöttetek, hanem aki közöttetek nagy akar lenni, legyen a ti szolgátok,
27 àti ẹni tí ó bá fẹ́ ṣe olórí nínú yín, ẹ jẹ́ kí ó máa ṣe ọmọ ọ̀dọ̀ yin.
és aki közöttetek első akar lenni, legyen a ti szolgátok.
28 Gẹ́gẹ́ bí Ọmọ Ènìyàn kò ṣe wá sí ayé, kí ẹ lè ṣe ìránṣẹ́ fún un, ṣùgbọ́n láti ṣe ìránṣẹ́ fún yín, àti láti fi ẹ̀mí rẹ ṣe ìràpadà ọ̀pọ̀ ènìyàn.”
Amint az Emberfia sem azért jött, hogy neki szolgáljanak, hanem, hogy ő szolgáljon, és adja az ő életét váltságul sokakért.“
29 Bí Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ti ń fi ìlú Jeriko sílẹ̀, ọ̀pọ̀ ènìyàn sì wọ́ tẹ̀lé e lẹ́yìn.
Amikor Jerikóból távoztak, nagy sokaság követte őt.
30 Àwọn ọkùnrin afọ́jú méjì sì jókòó lẹ́bàá ọ̀nà, nígbà tí wọ́n sí gbọ́ pé Jesu ń kọjá lọ, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í kígbe pé, “Olúwa, Ọmọ Dafidi, ṣàánú fún wa!”
És íme, két vak, aki az út mellett ült, meghallva, hogy Jézus arra megy el, elkezdett kiáltozni: „Uram, Dávidnak Fia, könyörülj rajtunk!“
31 Àwọn ènìyàn sí bá wọn wí pé kí wọn dákẹ́, ṣùgbọ́n wọ́n kígbe sókè sí i. “Olúwa, ọmọ Dafidi, ṣàánú fún wa!”
A sokaság pedig megdorgálta őket, hogy hallgassanak, de azok annál jobban kiáltoztak: „Uram, Dávidnak Fia, könyörülj rajtunk!“
32 Jesu dúró lójú ọ̀nà, ó sì pè wọ́n, Ó béèrè pé, “Kí ni ẹ̀yin fẹ́ kí èmi ṣe fún yín?”
Jézus pedig megállt, és megszólította őket, és ezt kérdezte: „Mit akartok, hogy cselekedjem veletek?“
33 Wọ́n dáhùn pé, “Olúwa, àwa fẹ́ kí a ríran.”
Ők így feleltek neki: „Azt, Uram, hogy megnyíljanak szemeink.“
34 Àánú wọn sì ṣe Jesu, ó fi ọwọ́ kan ojú wọn. Lójúkan náà, wọ́n sì ríran, wọ́n sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
Jézus pedig megszánta őket, megérintette szemeiket, és szemeik azonnal megnyíltak, és követték őt.

< Matthew 20 >