< Matthew 19 >

1 Lẹ́yìn tí Jesu ti parí ọ̀rọ̀ yìí, ó kúrò ní Galili. Ó sì yípo padà sí Judea, ó gba ìhà kejì odò Jordani.
A gdy Jezus dokończył tych mów, odszedł z Galilei i przybył na pogranicze Judei za Jordan.
2 Ọ̀pọ̀ ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó sì mú wọn láradá níbẹ̀.
I poszły za nim wielkie tłumy, a on ich tam uzdrowił.
3 Àwọn Farisi wá sọ́dọ̀ rẹ̀ láti dán an wò. Wọ́n bi í pé, “Ǹjẹ́ ó tọ̀nà fún ọkùnrin láti kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ nítorí ohunkóhun?”
Wtedy przyszli do niego faryzeusze, wystawiając go na próbę i pytając: Czy wolno człowiekowi oddalić swoją żonę z jakiegokolwiek powodu?
4 Ó dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ẹyin kò ti kà á pé ‘ẹni tí ó dá wọn ní ìgbà àtètèkọ́ṣe, Ọlọ́run dá wọn ni ti akọ ti abo.’
A on im odpowiedział: Nie czytaliście, że ten, który stworzył [ich] na początku, uczynił ich mężczyzną i kobietą?
5 Ó sì wí fún un pé, ‘Nítorí ìdí èyí ọkùnrin yóò fi baba àti ìyá rẹ̀ sílẹ̀, òun yóò sì dàpọ̀ mọ́ aya rẹ̀, àwọn méjèèjì yóò sì di ara kan.’
I powiedział: Dlatego opuści mężczyzna ojca i matkę i połączy się ze swoją żoną, i będą dwoje jednym ciałem.
6 Wọn kì í túnṣe méjì mọ́, ṣùgbọ́n ara kan. Nítorí náà, ohun tí Ọlọ́run bá ti so ṣọ̀kan, kí ẹnikẹ́ni má ṣe yà wọ́n.”
A tak już nie są dwoje, ale jedno ciało. Co więc Bóg złączył, człowiek niech nie rozłącza.
7 Wọ́n bi í pé: “Kí ni ìdí tí Mose fi pàṣẹ pé, ọkùnrin kan lè kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ nípa fífún un ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀?”
Zapytali go: Dlaczego więc Mojżesz nakazał dać list rozwodowy i oddalić ją?
8 Jesu dáhùn pé, “Nítorí líle àyà yín ni Mose ṣe gbà fún yín láti máa kọ aya yín sílẹ̀. Ṣùgbọ́n láti ìgbà àtètèkọ́ṣe wá, kò rí bẹ́ẹ̀.
Odpowiedział im: Z powodu zatwardziałości waszego serca Mojżesz pozwolił wam oddalić wasze żony, ale od początku tak nie było.
9 Mo sọ èyí fún yín pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀, láìṣe pé nítorí àgbèrè, tí ó bá sì fẹ́ ẹlòmíràn, ó ṣe panṣágà.”
Lecz ja wam mówię: Kto oddala swoją żonę – z wyjątkiem przypadku nierządu – i żeni się z inną, cudzołoży, a kto żeni się z oddaloną, cudzołoży.
10 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Bí ọ̀rọ̀ bá rí báyìí láàrín ọkọ àti aya, kó ṣàǹfààní fún wa láti gbé ìyàwó.”
Powiedzieli mu jego uczniowie: Jeśli tak ma się sprawa mężczyzny z [jego] żoną, to lepiej się nie żenić.
11 Jesu dáhùn pé, “Gbogbo ènìyàn kọ́ ló lé gba ọ̀rọ̀ yìí, bí kò ṣe iye àwọn tí a ti fún.
A on im powiedział: Nie wszyscy to pojmują, ale [tylko ci], którym to jest dane.
12 Àwọn mìíràn jẹ́ akúra nítorí bẹ́ẹ̀ ní a bí wọn, àwọn mìíràn ń bẹ tí ènìyàn sọ wọn di bẹ́ẹ̀; àwọn mìíràn kọ̀ láti gbé ìyàwó nítorí ìjọba ọ̀run. Ẹni tí ó bá lè gbà á kí ó gbà á.”
Są bowiem eunuchowie, którzy tacy wyszli z łona matki; są też eunuchowie, których ludzie takimi uczynili; są również eunuchowie, którzy się sami takimi uczynili dla królestwa niebieskiego. Kto może pojąć, niech pojmuje.
13 Lẹ́yìn náà a sì gbé àwọn ọmọ ọwọ́ wá sọ́dọ̀ Jesu, kí ó lè gbé ọwọ́ lé wọn, kí ó sì gbàdúrà fún wọn. Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ bá àwọn tí ó gbé wọn wá wí.
Wtedy przyniesiono mu dzieci, aby położył na nie ręce i pomodlił się, ale uczniowie ich gromili.
14 Ṣùgbọ́n Jesu dáhùn pé, “Ẹ jẹ́ kí àwọn ọmọdé wá sọ́dọ̀ mi, ẹ má ṣe dá wọn lẹ́kun, nítorí irú wọn ni ìjọba ọ̀run.”
Lecz Jezus powiedział: Zostawcie dzieci i nie zabraniajcie im przychodzić do mnie, bo do takich należy królestwo niebieskie.
15 Lẹ́yìn náà, ó gbé ọwọ́ lé wọn, ó sì kúrò níbẹ̀.
Położył na nie ręce i odszedł stamtąd.
16 Ẹnìkan sì wá ó bí Jesu pé, “Olùkọ́, ohun rere kí ni èmi yóò ṣe, kí èmi kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
A oto pewien człowiek podszedł i zapytał go: Nauczycielu dobry, co dobrego mam czynić, aby mieć życie wieczne? (aiōnios g166)
17 Jesu dá a lóhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń béèrè nípa ohun rere lọ́wọ́ mi. Ẹni kan ṣoṣo ni ó wà tí í ṣe ẹni rere. Bí ìwọ bá fẹ́ dé ibi ìyè, pa àwọn òfin mọ́.”
Lecz on mu odpowiedział: Dlaczego nazywasz mnie dobrym? Nikt nie jest dobry, tylko jeden – Bóg. A jeśli chcesz wejść do życia, przestrzegaj przykazań.
18 Ọkùnrin náà béèrè pé, “Àwọn wo ni òfin wọ̀nyí?” Jesu dáhùn pé, “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn; ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà; ìwọ kò gbọdọ̀ jalè; ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké’,
I zapytał go: Których? Jezus odpowiedział: Nie będziesz zabijał, nie będziesz cudzołożył, nie będziesz kradł, nie będziesz mówił fałszywego świadectwa;
19 bọ̀wọ̀ fún baba àti ìyá rẹ. ‘Kí o sì fẹ́ aládùúgbò rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ.’”
Czcij swego ojca i matkę oraz będziesz miłował swego bliźniego jak samego siebie.
20 Ọmọdékùnrin náà tún wí pé, “Gbogbo òfin wọ̀nyí ni èmi ti ń pamọ́, kí ni nǹkan mìíràn tí èmi ní láti ṣe?”
Powiedział mu młodzieniec: Tego wszystkiego przestrzegałem od mojej młodości. Czego mi jeszcze brakuje?
21 Jesu wí fún un pé, “Bí ìwọ bá fẹ́ di ẹni pípé, lọ ta ohun gbogbo tí ìwọ ní, kí o sì fi owó rẹ̀ tọrẹ fún àwọn aláìní. Ìwọ yóò ní ọrọ̀ ńlá ní ọ̀run. Lẹ́yìn náà, wá láti máa tọ̀ mi lẹ́yìn.”
Jezus mu odpowiedział: Jeśli chcesz być doskonały, idź, sprzedaj, co posiadasz, i rozdaj ubogim, a będziesz miał skarb w niebie. Potem przyjdź i chodź za mną.
22 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọ̀dọ́mọkùnrin náà gbọ́ èyí, ó kúrò níbẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́, nítorí ó ní ọrọ̀ púpọ̀.
Kiedy młodzieniec usłyszał te słowa, odszedł smutny, miał bowiem wiele dóbr.
23 Nígbà náà, ní Jesu wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín pé, ó ṣòro fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọ̀run.”
Wtedy Jezus powiedział swoim uczniom: Zaprawdę powiadam wam, że bogaty z trudnością wejdzie do królestwa niebieskiego.
24 Mo tún wí fún yín pé, “Ó rọrùn fún ìbákasẹ láti wọ ojú abẹ́rẹ́ jù fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run.”
Mówię wam też: Łatwiej jest wielbłądowi przejść przez ucho igielne, niż bogatemu wejść do królestwa Bożego.
25 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn gbọ́ èyí, ẹnu sì yà wọn gidigidi, wọ́n béèrè pé, “Ǹjẹ́ ta ni ó ha le là?”
Gdy jego uczniowie [to] usłyszeli, zdumieli się bardzo i pytali: Któż więc może być zbawiony?
26 Ṣùgbọ́n Jesu wò wọ́n, ó sì wí fún wọn pé, “Ènìyàn ni èyí ṣòro fún; ṣùgbọ́n fún Ọlọ́run ohun gbogbo ni ṣíṣe.”
A Jezus, spojrzawszy na nich, powiedział im: U ludzi to niemożliwe, lecz u Boga wszystko jest możliwe.
27 Peteru sì wí fún un pé, “Àwa ti fi ohun gbogbo sílẹ̀, a sì tẹ̀lé ọ, kí ni yóò jẹ́ èrè wa?”
Wtedy Piotr odezwał się do niego: Oto my opuściliśmy wszystko i poszliśmy za tobą. Cóż [za] to będziemy mieli?
28 Jesu dáhùn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín pé, ‘Nígbà ìsọdọ̀tun ohun gbogbo, nígbà tí Ọmọ Ènìyàn yóò jókòó lórí ìtẹ́ tí ó lógo, dájúdájú, ẹ̀yin ọmọ-ẹ̀yìn mi yóò sì jókòó lórí ìtẹ́ méjìlá láti ṣe ìdájọ́ ẹ̀yà Israẹli méjìlá.
A Jezus im powiedział: Zaprawdę powiadam wam, że przy odrodzeniu, gdy Syn Człowieczy zasiądzie na tronie swojej chwały, i wy, którzy poszliście za mną, zasiądziecie na dwunastu tronach, sądząc dwanaście pokoleń Izraela.
29 Àti pé ẹnikẹ́ni tí ó bá fi ilé tàbí arákùnrin tàbí arábìnrin tàbí baba tàbí ìyá tàbí àwọn ọmọ, tàbí ohun ìní rẹ̀ sílẹ̀ nítorí orúkọ mí, yóò gba ọgọọgọ́rùn-ún èrè rẹ̀ láyé, wọn ó sì tún jogún ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
I każdy, kto opuści domy, braci lub siostry, ojca lub matkę, żonę, dzieci lub pole dla mego imienia, stokroć więcej otrzyma i odziedziczy życie wieczne. (aiōnios g166)
30 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ àwọn tí ó síwájú nísinsin yìí ni yóò kẹ́yìn, àwọn tí ó kẹ́yìn ni yóò sì síwájú.’
A wielu pierwszych będzie ostatnimi, a ostatnich pierwszymi.

< Matthew 19 >