< Matthew 19 >

1 Lẹ́yìn tí Jesu ti parí ọ̀rọ̀ yìí, ó kúrò ní Galili. Ó sì yípo padà sí Judea, ó gba ìhà kejì odò Jordani.
Na rĩrĩ, Jesũ aarĩkia kũmeera maũndũ macio-rĩ, akiuma Galili, agĩthiĩ rũgongo rwa Judea mũrĩmo ũũrĩa ũngĩ wa Rũũĩ rwa Jorodani.
2 Ọ̀pọ̀ ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó sì mú wọn láradá níbẹ̀.
Nao andũ aingĩ makĩmũrũmĩrĩra, nake akĩmahoneria kuo.
3 Àwọn Farisi wá sọ́dọ̀ rẹ̀ láti dán an wò. Wọ́n bi í pé, “Ǹjẹ́ ó tọ̀nà fún ọkùnrin láti kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ nítorí ohunkóhun?”
Na Afarisai amwe magĩthiĩ kũrĩ we nĩguo mamũgerie. Makĩmũũria atĩrĩ, “Watho nĩwĩtĩkĩrĩtie mũndũ atigane na mũtumia wake nĩ ũndũ wa gĩtũmi o na kĩrĩkũ?”
4 Ó dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ẹyin kò ti kà á pé ‘ẹni tí ó dá wọn ní ìgbà àtètèkọ́ṣe, Ọlọ́run dá wọn ni ti akọ ti abo.’
Nake akĩmacookeria atĩrĩ, “Kaĩ mũtathomete, atĩ o kĩambĩrĩria Mũũmbi ‘ombire mũndũ-mũrũme na mũndũ-wa-nja’,
5 Ó sì wí fún un pé, ‘Nítorí ìdí èyí ọkùnrin yóò fi baba àti ìyá rẹ̀ sílẹ̀, òun yóò sì dàpọ̀ mọ́ aya rẹ̀, àwọn méjèèjì yóò sì di ara kan.’
na akiuga atĩrĩ, ‘Nĩ ũndũ wa gĩtũmi kĩu mũndũ mũrũme nĩagatigana na ithe na nyina, na anyiitane na mũtumia wake, nao eerĩ matuĩke mwĩrĩ ũmwe’?
6 Wọn kì í túnṣe méjì mọ́, ṣùgbọ́n ara kan. Nítorí náà, ohun tí Ọlọ́run bá ti so ṣọ̀kan, kí ẹnikẹ́ni má ṣe yà wọ́n.”
Na nĩ ũndũ ũcio, acio ti andũ eerĩ rĩngĩ, no nĩ mũndũ ũmwe. Nĩ ũndũ ũcio, arĩa Ngai anyiitithanĩtie, mũndũ ndakanamatigithanie.”
7 Wọ́n bi í pé: “Kí ni ìdí tí Mose fi pàṣẹ pé, ọkùnrin kan lè kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ nípa fífún un ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀?”
Nao makĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩatũmire Musa aathane atĩ mũndũ no ahe mũtumia wake marũa ma gũtigana nake, amũte?”
8 Jesu dáhùn pé, “Nítorí líle àyà yín ni Mose ṣe gbà fún yín láti máa kọ aya yín sílẹ̀. Ṣùgbọ́n láti ìgbà àtètèkọ́ṣe wá, kò rí bẹ́ẹ̀.
Nake Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Musa aamwĩtĩkĩririe mũtiganage na atumia anyu tondũ wa ũmũ wa ngoro cianyu. No gũtiarĩ ũguo kuuma kĩambĩrĩria.
9 Mo sọ èyí fún yín pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀, láìṣe pé nítorí àgbèrè, tí ó bá sì fẹ́ ẹlòmíràn, ó ṣe panṣágà.”
Ngũmwĩra atĩrĩ, mũndũ o wothe angĩtigana na mũtumia wake, tiga amũteire nĩ ũndũ wa ũtharia, nake ahikie mũtumia ũngĩ-rĩ, mũndũ ũcio nĩatharĩtie.”
10 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Bí ọ̀rọ̀ bá rí báyìí láàrín ọkọ àti aya, kó ṣàǹfààní fún wa láti gbé ìyàwó.”
Nao arutwo makĩmwĩra atĩrĩ, “Angĩkorwo ũguo nĩguo kũrĩ gatagatĩ ka mũthuuri na mũtumia-rĩ, nĩ kaba kwaga kũhikania.”
11 Jesu dáhùn pé, “Gbogbo ènìyàn kọ́ ló lé gba ọ̀rọ̀ yìí, bí kò ṣe iye àwọn tí a ti fún.
Nake Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Ti mũndũ o wothe ũngĩhota gwĩtĩkĩra ũhoro ũyũ, tiga no arĩa maheetwo ũhoti ũcio.
12 Àwọn mìíràn jẹ́ akúra nítorí bẹ́ẹ̀ ní a bí wọn, àwọn mìíràn ń bẹ tí ènìyàn sọ wọn di bẹ́ẹ̀; àwọn mìíràn kọ̀ láti gbé ìyàwó nítorí ìjọba ọ̀run. Ẹni tí ó bá lè gbà á kí ó gbà á.”
Nĩgũkorwo andũ amwe maaciarirwo mahaana ta marĩ ahakũre; angĩ maahakũrirwo nĩ andũ; na angĩ makarega kũhikania nĩ ũndũ wa ũthamaki wa igũrũ. Mũndũ ũrĩa ũngĩhota gwĩtĩkĩra ũndũ ũyũ, nĩawĩtĩkĩre.”
13 Lẹ́yìn náà a sì gbé àwọn ọmọ ọwọ́ wá sọ́dọ̀ Jesu, kí ó lè gbé ọwọ́ lé wọn, kí ó sì gbàdúrà fún wọn. Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ bá àwọn tí ó gbé wọn wá wí.
Hĩndĩ ĩyo Jesũ akĩreherwo twana nĩguo atũigĩrĩre moko na atũhooere. No arutwo magĩkũũma arĩa maatũrehete.
14 Ṣùgbọ́n Jesu dáhùn pé, “Ẹ jẹ́ kí àwọn ọmọdé wá sọ́dọ̀ mi, ẹ má ṣe dá wọn lẹ́kun, nítorí irú wọn ni ìjọba ọ̀run.”
Nowe Jesũ akiuga atĩrĩ, “Rekei twana tũũke kũrĩ niĩ, tigai gũtũgiria, nĩgũkorwo ũthamaki wa Igũrũ nĩ wa arĩa mahaana ta tuo.”
15 Lẹ́yìn náà, ó gbé ọwọ́ lé wọn, ó sì kúrò níbẹ̀.
Aarĩkia gũtũigĩrĩra moko, akiuma kũu.
16 Ẹnìkan sì wá ó bí Jesu pé, “Olùkọ́, ohun rere kí ni èmi yóò ṣe, kí èmi kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
Na rĩrĩ, mũndũ ũmwe nĩokire kũrĩ Jesũ, akĩmũũria atĩrĩ, “Mũrutani, nĩ ũndũ ũrĩkũ mwega ingĩĩka nĩgeetha ngĩe na muoyo wa tene na tene?” (aiōnios g166)
17 Jesu dá a lóhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń béèrè nípa ohun rere lọ́wọ́ mi. Ẹni kan ṣoṣo ni ó wà tí í ṣe ẹni rere. Bí ìwọ bá fẹ́ dé ibi ìyè, pa àwọn òfin mọ́.”
Nake Jesũ akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ũkũnjũũria ũhoro wa ũndũ ũrĩa mwega nĩkĩ? Kũrĩ o Ũmwe mwega. Ũngĩenda gũtoonya muoyo-inĩ-rĩ, athĩkagĩra maathani.”
18 Ọkùnrin náà béèrè pé, “Àwọn wo ni òfin wọ̀nyí?” Jesu dáhùn pé, “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn; ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà; ìwọ kò gbọdọ̀ jalè; ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké’,
Mũndũ ũcio akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ maathani marĩkũ?” Jesũ akĩmũcookeria atĩrĩ, “‘Ndũkanoragane, na ndũkanatharanie, na ndũkanaiye, na ndũkanaigĩrĩre mũndũ ũrĩa ũngĩ kĩgeenyo,
19 bọ̀wọ̀ fún baba àti ìyá rẹ. ‘Kí o sì fẹ́ aládùúgbò rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ.’”
na tĩĩa thoguo na nyũkwa,’ o na ‘endaga mũndũ ũrĩa ũngĩ o ta ũrĩa wĩyendete wee mwene.’”
20 Ọmọdékùnrin náà tún wí pé, “Gbogbo òfin wọ̀nyí ni èmi ti ń pamọ́, kí ni nǹkan mìíràn tí èmi ní láti ṣe?”
Mwanake ũcio akiuga atĩrĩ, “Maũndũ macio mothe ndũire ndĩmarũmĩtie, nĩ kĩĩ kĩngĩ ndigairie?”
21 Jesu wí fún un pé, “Bí ìwọ bá fẹ́ di ẹni pípé, lọ ta ohun gbogbo tí ìwọ ní, kí o sì fi owó rẹ̀ tọrẹ fún àwọn aláìní. Ìwọ yóò ní ọrọ̀ ńlá ní ọ̀run. Lẹ́yìn náà, wá láti máa tọ̀ mi lẹ́yìn.”
Nake Jesũ akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ũngĩenda kwagĩrĩra kũna, thiĩ wendie indo ciaku ũhe athĩĩni mbeeca icio, na nĩũkagĩa na mũthiithũ igũrũ. Ũcooke ũũke ũnũmĩrĩre.”
22 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọ̀dọ́mọkùnrin náà gbọ́ èyí, ó kúrò níbẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́, nítorí ó ní ọrọ̀ púpọ̀.
Rĩrĩa mwanake ũcio aiguire ũguo-rĩ, agĩthiĩ arĩ na kĩeha, tondũ aarĩ na ũtonga mũingĩ.
23 Nígbà náà, ní Jesu wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín pé, ó ṣòro fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọ̀run.”
Nake Jesũ akĩĩra arutwo ake atĩrĩ, “Ngũmwĩra atĩrĩ na ma, nĩ ũndũ ũrĩ hinya gĩtonga gũtoonya ũthamaki-inĩ wa igũrũ.
24 Mo tún wí fún yín pé, “Ó rọrùn fún ìbákasẹ láti wọ ojú abẹ́rẹ́ jù fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run.”
O rĩngĩ ngũmwĩra atĩrĩ, nĩ ũhũthũ ngamĩĩra ĩhungurĩre irima rĩa cindano, gũkĩra gĩtonga gũtoonya ũthamaki wa Ngai.”
25 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn gbọ́ èyí, ẹnu sì yà wọn gidigidi, wọ́n béèrè pé, “Ǹjẹ́ ta ni ó ha le là?”
Rĩrĩa arutwo maiguire ũguo-rĩ, makĩmaka mũno, makĩũrania atĩrĩ, “Rĩu-rĩ, nũũ ũngĩkĩhonoka?”
26 Ṣùgbọ́n Jesu wò wọ́n, ó sì wí fún wọn pé, “Ènìyàn ni èyí ṣòro fún; ṣùgbọ́n fún Ọlọ́run ohun gbogbo ni ṣíṣe.”
Nake Jesũ akĩmarora akĩmeera atĩrĩ, “Ũndũ ũcio ndũngĩhoteka nĩ andũ, no maũndũ mothe nĩmahotekaga nĩ Ngai.”
27 Peteru sì wí fún un pé, “Àwa ti fi ohun gbogbo sílẹ̀, a sì tẹ̀lé ọ, kí ni yóò jẹ́ èrè wa?”
Petero akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ithuĩ nĩtũtigĩte maũndũ mothe, tũgakũrũmĩrĩra! Ithuĩ-rĩ, nĩ kĩĩ tũkaaheo?”
28 Jesu dáhùn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín pé, ‘Nígbà ìsọdọ̀tun ohun gbogbo, nígbà tí Ọmọ Ènìyàn yóò jókòó lórí ìtẹ́ tí ó lógo, dájúdájú, ẹ̀yin ọmọ-ẹ̀yìn mi yóò sì jókòó lórí ìtẹ́ méjìlá láti ṣe ìdájọ́ ẹ̀yà Israẹli méjìlá.
Nake Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Ngũmwĩra atĩrĩ na ma, hĩndĩ ĩrĩa Mũrũ wa Mũndũ agaikarĩra gĩtĩ gĩake kĩa ũnene kĩrĩ riiri, thĩinĩ wa thĩ njerũ, inyuĩ arĩa mũnũmagĩrĩra nĩ inyuĩ mũgaikarĩra itĩ ikũmi na igĩrĩ cia ũnene, na nĩmũgatuĩra mĩhĩrĩga ĩrĩa ikũmi na ĩĩrĩ ya Isiraeli ciira.
29 Àti pé ẹnikẹ́ni tí ó bá fi ilé tàbí arákùnrin tàbí arábìnrin tàbí baba tàbí ìyá tàbí àwọn ọmọ, tàbí ohun ìní rẹ̀ sílẹ̀ nítorí orúkọ mí, yóò gba ọgọọgọ́rùn-ún èrè rẹ̀ láyé, wọn ó sì tún jogún ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
Na ũrĩa wothe ũtigĩte nyũmba, kana ariũ a nyina, kana aarĩ a nyina, kana ithe, kana nyina, kana ciana, kana mĩgũnda nĩ ũndũ wakwa nĩakamũkĩra maita igana ma iria atigĩte, na agae muoyo wa tene na tene. (aiōnios g166)
30 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ àwọn tí ó síwájú nísinsin yìí ni yóò kẹ́yìn, àwọn tí ó kẹ́yìn ni yóò sì síwájú.’
No rĩrĩ, andũ aingĩ arĩa marĩ mbere nĩo makaarigia thuutha, na aingĩ arĩa marĩ thuutha nĩo magaatongoria.

< Matthew 19 >