< Matthew 19 >

1 Lẹ́yìn tí Jesu ti parí ọ̀rọ̀ yìí, ó kúrò ní Galili. Ó sì yípo padà sí Judea, ó gba ìhà kejì odò Jordani.
ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⲉⲧⲁ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ϫⲉⲕ ⲛⲁⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁϥⲟⲩ⳿ⲱⲧⲉⲃ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ϯⲄⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ ϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲛⲓϭⲓ⳿ⲏ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲒⲟⲩⲇⲉ⳿ⲁ ϩⲓⲙⲏⲣ ⳿ⲙⲡⲓⲒⲟⲣⲇⲁⲛⲏⲥ.
2 Ọ̀pọ̀ ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó sì mú wọn láradá níbẹ̀.
ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲟⲩ⳿ⲁϩⲟⲩ ⳿ⲛⲥⲱϥ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛⲛⲓϣϯ ⳿ⲙⲙⲏϣ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲉⲣⲫⲁϧⲣⲓ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲁⲩ.
3 Àwọn Farisi wá sọ́dọ̀ rẹ̀ láti dán an wò. Wọ́n bi í pé, “Ǹjẹ́ ó tọ̀nà fún ọkùnrin láti kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ nítorí ohunkóhun?”
ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩ⳿ⲓ ϩⲁⲣⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛⲪⲁⲣⲓⲥⲉⲟⲥ ⲉⲩⲉⲣⲡⲓⲣⲁⲍⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲁⲛ ⳿ⲥϣⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ϩⲓ ⲧⲉϥ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲟⲃⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
4 Ó dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ẹyin kò ti kà á pé ‘ẹni tí ó dá wọn ní ìgbà àtètèkọ́ṣe, Ọlọ́run dá wọn ni ti akọ ti abo.’
ⲇ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲁϥ⳿ⲉⲣⲟⲩ⳿ⲱ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉⲛⲱϣ ⲓⲥϫⲉⲛ ϩⲏ ⲟⲩϩⲱⲟⲩⲧ ⲛⲉⲙ ⲟⲩ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲡⲉⲧⲁϥⲥⲟⲛⲧⲟⲩ.
5 Ó sì wí fún un pé, ‘Nítorí ìdí èyí ọkùnrin yóò fi baba àti ìyá rẹ̀ sílẹ̀, òun yóò sì dàpọ̀ mọ́ aya rẹ̀, àwọn méjèèjì yóò sì di ara kan.’
ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⲉⲑⲃⲉ ⲫⲁⲓ ⳿ⲉⲣⲉ ⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⲭⲁ ⲡⲉϥⲓⲱⲧ ⲛⲉⲙ ⲧⲉϥⲙⲁⲩ ⳿ⲛⲥⲱϥ ⲟⲩⲟϩ ⲉϥ⳿ⲉⲧⲟⲙϥ ⳿ⲉⲧⲉϥ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲩ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙ⳿ⲡⲃ̅ ⲉⲩⲥⲁⲣⲝ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ.
6 Wọn kì í túnṣe méjì mọ́, ṣùgbọ́n ara kan. Nítorí náà, ohun tí Ọlọ́run bá ti so ṣọ̀kan, kí ẹnikẹ́ni má ṣe yà wọ́n.”
ⲋ̅ϩⲱⲥⲧⲉ ⲃ̅ ⲁⲛ ϫⲉ ⲛⲉ ⲁⲗⲗⲁ ⲟⲩⲥⲁⲣⲝ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ ⲧⲉ ⲫⲏ ⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲧⲁ Ⲫϯ ⲧⲟⲙϥ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉ ⳿ⲫⲣⲱⲙⲓ ⲫⲟⲣϫϥ.
7 Wọ́n bi í pé: “Kí ni ìdí tí Mose fi pàṣẹ pé, ọkùnrin kan lè kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ nípa fífún un ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀?”
ⲍ̅ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩ ⲟⲩⲛ ⳿ⲁ Ⲙⲱ⳿ⲩⲥⲏⲥ ϩⲟⲛϩⲉⲛ ⲉϯ ⳿ⲥϧⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲉⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉϩⲓⲧⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
8 Jesu dáhùn pé, “Nítorí líle àyà yín ni Mose ṣe gbà fún yín láti máa kọ aya yín sílẹ̀. Ṣùgbọ́n láti ìgbà àtètèkọ́ṣe wá, kò rí bẹ́ẹ̀.
ⲏ̅ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲉⲑⲃⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲙⲉⲧⲛⲁϣⲧϩⲏ ⲧ ⳿ⲁ Ⲙⲱ⳿ⲩⲥⲏⲥ ⲟⲩⲁϩⲥⲁϩⲛⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉϩⲓ ⲛⲉⲧⲉⲛϩⲓ⳿ⲟⲙⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲓⲥϫⲉⲛ ϩⲏ ⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ.
9 Mo sọ èyí fún yín pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀, láìṣe pé nítorí àgbèrè, tí ó bá sì fẹ́ ẹlòmíràn, ó ṣe panṣágà.”
ⲑ̅ϯϫⲱ ⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⲫⲏⲉⲑⲛⲁϩⲓ ⲧⲉϥ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ⲉϣⲉⲛⲥⲁϫⲓ ⳿ⲙⲡⲟⲣⲛⲓ⳿ⲁ ⲁϥ⳿ⲑⲣⲟ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⳿ⲉ⳿ϫⲫⲉ ⲛⲱⲓⲕ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏⲉⲑⲛⲁϭⲓ ⳿ⲛⲑⲏⲉⲧϩⲱⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ϥⲟⲓ ⳿ⲛⲛⲱⲓⲕ.
10 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Bí ọ̀rọ̀ bá rí báyìí láàrín ọkọ àti aya, kó ṣàǹfààní fún wa láti gbé ìyàwó.”
ⲓ̅ⲡⲉϫⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲓⲥϫⲉ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲡⲉ ⳿ⲧⲉⲧⲓ⳿ⲁ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⲛⲉⲙ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲥⲉⲣⲛⲟϥⲣⲓ ⲁⲛ ⳿ⲉϭⲓ.
11 Jesu dáhùn pé, “Gbogbo ènìyàn kọ́ ló lé gba ọ̀rọ̀ yìí, bí kò ṣe iye àwọn tí a ti fún.
ⲓ̅ⲁ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϣⲱⲡ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲏⲗ ⳿ⲉⲛⲏ⳿ⲉⲧⲉⲥⲧⲟⲓ ⲛⲱⲟⲩ.
12 Àwọn mìíràn jẹ́ akúra nítorí bẹ́ẹ̀ ní a bí wọn, àwọn mìíràn ń bẹ tí ènìyàn sọ wọn di bẹ́ẹ̀; àwọn mìíràn kọ̀ láti gbé ìyàwó nítorí ìjọba ọ̀run. Ẹni tí ó bá lè gbà á kí ó gbà á.”
ⲓ̅ⲃ̅
13 Lẹ́yìn náà a sì gbé àwọn ọmọ ọwọ́ wá sọ́dọ̀ Jesu, kí ó lè gbé ọwọ́ lé wọn, kí ó sì gbàdúrà fún wọn. Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ bá àwọn tí ó gbé wọn wá wí.
ⲓ̅ⲅ̅ⲧⲟⲧⲉ ⲁⲩ⳿ⲓⲛⲓ ⲛⲁϥ ⳿ⲛϩⲁⲛ⳿ⲁⲗⲱⲟⲩ⳿ⲓ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥⲭⲁ ϫⲓϫ ⳿ⲉϫⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥⲧⲱⲃϩ ⳿ⲉϫⲱⲟⲩ ⲛⲓⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲇⲉ ⲁⲩⲉⲣ⳿ⲉⲡⲓⲧⲓⲙⲁⲛ ⲛⲱⲟⲩ.
14 Ṣùgbọ́n Jesu dáhùn pé, “Ẹ jẹ́ kí àwọn ọmọdé wá sọ́dọ̀ mi, ẹ má ṣe dá wọn lẹ́kun, nítorí irú wọn ni ìjọba ọ̀run.”
ⲓ̅ⲇ̅Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲭⲁ ⲛⲓ⳿ⲁⲗⲱⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲣⲧⲁϩⲛⲟ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ⲓ ϩⲁⲣⲟⲓ ⲛⲓⲟⲩⲟⲛ ⲅⲁⲣ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲑⲱⲟⲩ ⲧⲉ ϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲫⲏⲟⲩ⳿ⲓ.
15 Lẹ́yìn náà, ó gbé ọwọ́ lé wọn, ó sì kúrò níbẹ̀.
ⲓ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲭⲁ ϫⲓϫ ⳿ⲉϫⲱⲟⲩ ⲁϥϣⲉⲛⲁϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲁⲩ.
16 Ẹnìkan sì wá ó bí Jesu pé, “Olùkọ́, ohun rere kí ni èmi yóò ṣe, kí èmi kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
ⲓ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲓⲥ ⲟⲩⲁⲓ ϥ⳿ⲓ ϩⲁⲣⲟϥ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⳿ⲫⲣⲉϥϯ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲛ⳿ⲁⲅⲁⲑⲟⲥ ⲟⲩ ⳿ⲛ⳿ⲁⲅⲁⲑⲟⲛ ⳿ⲉϯⲛⲁⲁⲓϥ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲁⲉⲣ⳿ⲕⲗⲏⲣⲟⲛⲟⲙⲓⲛ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲛϧ ⳿ⲛ⳿⳿ⲉⲛⲉϩ. (aiōnios g166)
17 Jesu dá a lóhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń béèrè nípa ohun rere lọ́wọ́ mi. Ẹni kan ṣoṣo ni ó wà tí í ṣe ẹni rere. Bí ìwọ bá fẹ́ dé ibi ìyè, pa àwọn òfin mọ́.”
ⲓ̅ⲍ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩ ⳿ⲕϣⲓⲛⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲓ ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲓ⳿ⲁⲅⲁⲑⲟⲛ ⲟⲩⲁⲓ ⲅⲁⲣ ⲡⲉ ⲡⲓ⳿ⲁⲅⲁⲑⲟⲥ Ⲫϯ ⲓⲥϫⲉ ⲇⲉ ⳿ⲭⲟⲩⲱϣ ⳿ⲉ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲡⲓⲱⲛϧ ⳿ⲁⲣⲉϩ ⳿ⲉⲛⲓⲉⲛⲧⲟⲗⲏ.
18 Ọkùnrin náà béèrè pé, “Àwọn wo ni òfin wọ̀nyí?” Jesu dáhùn pé, “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn; ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà; ìwọ kò gbọdọ̀ jalè; ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké’,
ⲓ̅ⲏ̅ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲁϣ ⲛⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⳿ⲛⲛⲉⲕϧⲱⲧⲉⲃ ⳿ⲛⲛⲉⲕⲉⲣⲛⲱⲓⲕ ⳿ⲛⲛⲉⲕϭⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲛⲛⲉⲕⲉⲣⲙⲉⲑⲣⲉ ⳿ⲛⲛⲟⲩϫ.
19 bọ̀wọ̀ fún baba àti ìyá rẹ. ‘Kí o sì fẹ́ aládùúgbò rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ.’”
ⲓ̅ⲑ̅ⲙⲁⲧⲁⲓ⳿ⲉ ⲡⲉⲕⲓⲱⲧ ⲛⲉⲙ ⲧⲉⲕⲙⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲕ⳿ⲉⲙⲉⲛⲣⲉ ⲡⲉⲕ⳿ϣⲫⲏⲣ ⳿ⲙⲡⲉⲕⲣⲏϯ.
20 Ọmọdékùnrin náà tún wí pé, “Gbogbo òfin wọ̀nyí ni èmi ti ń pamọ́, kí ni nǹkan mìíràn tí èmi ní láti ṣe?”
ⲕ̅ⲡⲉϫⲉ ⲡⲓϧⲉⲗϣ⳿ⲓⲣⲓ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲛⲁⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲁⲓ⳿ⲁⲣⲉϩ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲓⲥϫⲉⲛ ⲧⲁⲙⲉⲧ⳿ⲁⲗⲟⲩ ⲟⲩ ⲟⲛ ⲡⲉ ϯϣⲁⲧ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
21 Jesu wí fún un pé, “Bí ìwọ bá fẹ́ di ẹni pípé, lọ ta ohun gbogbo tí ìwọ ní, kí o sì fi owó rẹ̀ tọrẹ fún àwọn aláìní. Ìwọ yóò ní ọrọ̀ ńlá ní ọ̀run. Lẹ́yìn náà, wá láti máa tọ̀ mi lẹ́yìn.”
ⲕ̅ⲁ̅ⲁϥ⳿ⲉⲣⲟⲩ⳿ⲱ ⲛⲁϥ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ϫⲉ ⲓⲥϫⲉ ⳿ⲭⲟⲩⲱϣ ⳿ⲉⲉⲣ ⲟⲩⲧⲉⲗⲓⲟⲥ ⲙⲁϣⲉⲛⲁⲕ ⲙⲁ ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲛⲧⲁⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲙⲏⲓⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓϩⲏⲕⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲕ⳿ⲉ⳿ϫⲫⲟ ⲛⲁⲕ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ⲁϩⲟ ⳿ⲛ⳿ϩⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲫⲉ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲁⲙⲟⲩ ⲟⲩⲁϩⲕ ⳿ⲛⲥⲱⲓ.
22 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọ̀dọ́mọkùnrin náà gbọ́ èyí, ó kúrò níbẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́, nítorí ó ní ọrọ̀ púpọ̀.
ⲕ̅ⲃ̅⳿ⲉⲧⲁϥⲥⲱⲧⲉⲙ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓϧⲉⲗϣ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲉⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⲁϥϣⲉⲛⲁϥ ⳿ⲉⲣⲉ ⲡⲉϥϩⲏⲧ ⲙⲟⲕϩ ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛⲧⲉϥ ⲟⲩⲙⲏϣ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛϩⲩⲡⲁⲣⲭⲟⲛⲧⲁ ⳿ⲙⲙⲁⲩ.
23 Nígbà náà, ní Jesu wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín pé, ó ṣòro fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọ̀run.”
ⲕ̅ⲅ̅Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⳿ⲛⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ϫⲉ ⳿ⲁⲙⲏⲛ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⳿ⲥⲙⲟⲕϩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩⲣⲁⲙⲁ⳿ⲟ ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲫⲏⲟⲩ⳿ⲓ.
24 Mo tún wí fún yín pé, “Ó rọrùn fún ìbákasẹ láti wọ ojú abẹ́rẹ́ jù fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run.”
ⲕ̅ⲇ̅ⲡⲁⲗⲓⲛ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⳿ⲥⲙⲟⲧⲉⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩϫⲁⲙⲟⲩⲗ ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ϧⲉⲛ ⳿ⲑⲟⲩⲁⲑⲛⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩⲙⲁ⳿ⲛⲑⲱⲣⲡ ⲓⲉ ⲟⲩⲣⲁⲙⲁ⳿ⲟ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ.
25 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn gbọ́ èyí, ẹnu sì yà wọn gidigidi, wọ́n béèrè pé, “Ǹjẹ́ ta ni ó ha le là?”
ⲕ̅ⲉ̅⳿ⲉⲧⲁⲩⲥⲱⲧⲉⲙ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲁⲩⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ⳿ⲉⲙⲁϣⲱ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲛⲓⲙ ϩⲁⲣⲁ ⳿ⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲛⲟϩⲉⲙ.
26 Ṣùgbọ́n Jesu wò wọ́n, ó sì wí fún wọn pé, “Ènìyàn ni èyí ṣòro fún; ṣùgbọ́n fún Ọlọ́run ohun gbogbo ni ṣíṣe.”
ⲕ̅ⲋ̅⳿ⲉⲧⲁϥϫⲟⲩϣⲧ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲛⲧⲉⲛ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲟⲩⲙⲉⲧⲁⲧϫⲟⲙ ⲡⲉ ⲫⲁⲓ ⳿ⲛⲧⲉⲛ Ⲫϯ ⲇⲉ ⲟⲩⲟⲛ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
27 Peteru sì wí fún un pé, “Àwa ti fi ohun gbogbo sílẹ̀, a sì tẹ̀lé ọ, kí ni yóò jẹ́ èrè wa?”
ⲕ̅ⲍ̅ⲧⲟⲧⲉ ⲁϥ⳿ⲉⲣⲟⲩ⳿ⲱ ⳿ⲛϫⲉ Ⲡⲉⲧⲣⲟⲥ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ϩⲏⲡⲡⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲁⲛⲭⲁ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲛⲥⲱⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲛⲟⲩⲁϩⲧⲉⲛ ⳿ⲛⲥⲱⲕ ⲟⲩ ϩⲁⲣⲁ ⲡⲉⲑⲛⲁϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲛ.
28 Jesu dáhùn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín pé, ‘Nígbà ìsọdọ̀tun ohun gbogbo, nígbà tí Ọmọ Ènìyàn yóò jókòó lórí ìtẹ́ tí ó lógo, dájúdájú, ẹ̀yin ọmọ-ẹ̀yìn mi yóò sì jókòó lórí ìtẹ́ méjìlá láti ṣe ìdájọ́ ẹ̀yà Israẹli méjìlá.
ⲕ̅ⲏ̅Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲁⲙⲏⲛ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ϧⲁ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲁⲩⲙⲟϣⲓ ⳿ⲛⲥⲱⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲟⲩ⳿ⲁϩⲉⲙⲥⲱⲛⲧ ⳿ⲉϣⲱⲡ ⳿ⲁⲣⲉϣⲁⲛ Ⲡ̇ϣⲏⲣⲓ ⳿ⲙⲪ̇ⲣⲱⲙⲓ ϩⲉⲙⲥⲓ ϩⲓ ⲡⲓ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉϥ⳿ⲱⲟⲩ ⲉⲩ⳿ⲉ⳿ⲧϩⲉⲙⲥⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϩⲱⲧⲉⲛ ϩⲓ ⲓ̅ⲃ̅ ⳿ⲛ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⳿ⲉⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉϯϩⲁⲡ ⳿ⲉϯⲓ̅ⲃ̅ ⳿ⲙⲫⲩⲗⲏ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲓ̅ⲥ̅ⲗ̅.
29 Àti pé ẹnikẹ́ni tí ó bá fi ilé tàbí arákùnrin tàbí arábìnrin tàbí baba tàbí ìyá tàbí àwọn ọmọ, tàbí ohun ìní rẹ̀ sílẹ̀ nítorí orúkọ mí, yóò gba ọgọọgọ́rùn-ún èrè rẹ̀ láyé, wọn ó sì tún jogún ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
ⲕ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉⲧⲁϥⲭⲁ ⲥⲟⲛ ⳿ⲛⲥⲱϥ ⲓⲉ ⲥⲱⲛⲓ ⲓⲉ ⲓⲱⲧ ⲓⲉ ⲙⲁⲩ ⲓⲉ ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲓⲉ ϣⲏⲣⲓ ⲓⲉ ⲓⲟϩⲓ ⲓⲉ ⲏⲓ ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲁⲣⲁⲛ ⲉϥ⳿ⲉϭⲓⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲣ̅ ⳿ⲛⲕⲱⲃ ⳿ⲛⲥⲟⲡ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲱⲛϧ ⳿ⲛ⳿⳿ⲉⲛⲉϩ ⲉϥ⳿ⲉⲉⲣ⳿ⲕⲗⲏⲣⲟⲛⲟⲙⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ. (aiōnios g166)
30 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ àwọn tí ó síwájú nísinsin yìí ni yóò kẹ́yìn, àwọn tí ó kẹ́yìn ni yóò sì síwájú.’
ⲗ̅ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛϣⲟⲣⲡ ⲉⲩⲛⲁⲉⲣϧⲁ⳿ⲉ ⲟⲩⲟϩ ϩⲁⲛϧⲁⲉⲩ ⲉⲩⲛⲁⲉⲣϣⲟⲣⲡ

< Matthew 19 >