< Matthew 19 >

1 Lẹ́yìn tí Jesu ti parí ọ̀rọ̀ yìí, ó kúrò ní Galili. Ó sì yípo padà sí Judea, ó gba ìhà kejì odò Jordani.
ܘܗܘܐ ܕܟܕ ܫܠܡ ܝܫܘܥ ܡܠܐ ܗܠܝܢ ܫܩܠ ܡܢ ܓܠܝܠܐ ܘܐܬܐ ܠܬܚܘܡܐ ܕܝܗܘܕ ܠܥܒܪܐ ܕܝܘܪܕܢܢ
2 Ọ̀pọ̀ ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó sì mú wọn láradá níbẹ̀.
ܘܐܬܘ ܒܬܪܗ ܟܢܫܐ ܤܓܝܐܐ ܘܐܤܝ ܐܢܘܢ ܬܡܢ
3 Àwọn Farisi wá sọ́dọ̀ rẹ̀ láti dán an wò. Wọ́n bi í pé, “Ǹjẹ́ ó tọ̀nà fún ọkùnrin láti kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ nítorí ohunkóhun?”
ܘܩܪܒܘ ܠܘܬܗ ܦܪܝܫܐ ܘܡܢܤܝܢ ܗܘܘ ܠܗ ܘܐܡܪܝܢ ܐܢ ܫܠܝܛ ܠܐܢܫ ܕܢܫܪܐ ܐܢܬܬܗ ܒܟܠ ܥܠܐ
4 Ó dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ẹyin kò ti kà á pé ‘ẹni tí ó dá wọn ní ìgbà àtètèkọ́ṣe, Ọlọ́run dá wọn ni ti akọ ti abo.’
ܗܘ ܕܝܢ ܥܢܐ ܘܐܡܪ ܠܗܘܢ ܠܐ ܩܪܝܬܘܢ ܕܗܘ ܕܥܒܕ ܡܢ ܒܪܫܝܬ ܕܟܪܐ ܘܢܩܒܬܐ ܥܒܕ ܐܢܘܢ
5 Ó sì wí fún un pé, ‘Nítorí ìdí èyí ọkùnrin yóò fi baba àti ìyá rẹ̀ sílẹ̀, òun yóò sì dàpọ̀ mọ́ aya rẹ̀, àwọn méjèèjì yóò sì di ara kan.’
ܘܐܡܪ ܡܛܠ ܗܢܐ ܢܫܒܘܩ ܓܒܪܐ ܠܐܒܘܗܝ ܘܠܐܡܗ ܘܢܩܦ ܠܐܢܬܬܗ ܘܢܗܘܘܢ ܬܪܝܗܘܢ ܚܕ ܒܤܪ
6 Wọn kì í túnṣe méjì mọ́, ṣùgbọ́n ara kan. Nítorí náà, ohun tí Ọlọ́run bá ti so ṣọ̀kan, kí ẹnikẹ́ni má ṣe yà wọ́n.”
ܡܕܝܢ ܠܐ ܗܘܘ ܬܪܝܢ ܐܠܐ ܚܕ ܦܓܪ ܡܕܡ ܗܟܝܠ ܕܐܠܗܐ ܙܘܓ ܒܪܢܫܐ ܠܐ ܢܦܪܫ
7 Wọ́n bi í pé: “Kí ni ìdí tí Mose fi pàṣẹ pé, ọkùnrin kan lè kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ nípa fífún un ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀?”
ܐܡܪܝܢ ܠܗ ܠܡܢܐ ܗܟܝܠ ܡܘܫܐ ܦܩܕ ܕܢܬܠ ܟܬܒܐ ܕܫܘܒܩܢܐ ܘܢܫܪܝܗ
8 Jesu dáhùn pé, “Nítorí líle àyà yín ni Mose ṣe gbà fún yín láti máa kọ aya yín sílẹ̀. Ṣùgbọ́n láti ìgbà àtètèkọ́ṣe wá, kò rí bẹ́ẹ̀.
ܐܡܪ ܠܗܘܢ ܡܘܫܐ ܠܘܩܒܠ ܩܫܝܘܬ ܠܒܟܘܢ ܐܦܤ ܠܟܘܢ ܕܬܫܪܘܢ ܢܫܝܟܘܢ ܡܢ ܒܪܫܝܬ ܕܝܢ ܠܐ ܗܘܐ ܗܟܢܐ
9 Mo sọ èyí fún yín pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀, láìṣe pé nítorí àgbèrè, tí ó bá sì fẹ́ ẹlòmíràn, ó ṣe panṣágà.”
ܐܡܪ ܐܢܐ ܠܟܘܢ ܕܝܢ ܕܡܢ ܕܫܒܩ ܐܢܬܬܗ ܕܠܐ ܓܘܪܐ ܘܢܤܒ ܐܚܪܬܐ ܓܐܪ ܘܡܢ ܕܢܤܒ ܫܒܝܩܬܐ ܓܐܪ
10 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Bí ọ̀rọ̀ bá rí báyìí láàrín ọkọ àti aya, kó ṣàǹfààní fún wa láti gbé ìyàwó.”
ܐܡܪܝܢ ܠܗ ܬܠܡܝܕܘܗܝ ܐܢ ܗܟܢܐ ܐܝܬ ܥܕܠܝܐ ܒܝܢܝ ܓܒܪܐ ܠܐܢܬܬܐ ܠܐ ܦܩܚ ܠܡܤܒ ܐܢܬܬܐ
11 Jesu dáhùn pé, “Gbogbo ènìyàn kọ́ ló lé gba ọ̀rọ̀ yìí, bí kò ṣe iye àwọn tí a ti fún.
ܗܘ ܕܝܢ ܐܡܪ ܠܗܘܢ ܠܐ ܟܠܢܫ ܤܦܩ ܠܗ ܠܡܠܬܐ ܗܕܐ ܐܠܐ ܡܢ ܕܝܗܝܒ ܠܗ
12 Àwọn mìíràn jẹ́ akúra nítorí bẹ́ẹ̀ ní a bí wọn, àwọn mìíràn ń bẹ tí ènìyàn sọ wọn di bẹ́ẹ̀; àwọn mìíràn kọ̀ láti gbé ìyàwó nítorí ìjọba ọ̀run. Ẹni tí ó bá lè gbà á kí ó gbà á.”
ܐܝܬ ܓܝܪ ܡܗܝܡܢܐ ܕܡܢ ܟܪܤܐ ܕܐܡܗܘܢ ܐܬܝܠܕܘ ܗܟܢܐ ܘܐܝܬ ܡܗܝܡܢܐ ܕܡܢ ܒܢܝܢܫܐ ܗܘܘ ܡܗܝܡܢܐ ܘܐܝܬ ܡܗܝܡܢܐ ܕܗܢܘܢ ܥܒܕܘ ܢܦܫܗܘܢ ܡܗܝܡܢܐ ܡܛܠ ܡܠܟܘܬܐ ܕܫܡܝܐ ܡܢ ܕܡܫܟܚ ܕܢܤܦܩ ܢܤܦܩ
13 Lẹ́yìn náà a sì gbé àwọn ọmọ ọwọ́ wá sọ́dọ̀ Jesu, kí ó lè gbé ọwọ́ lé wọn, kí ó sì gbàdúrà fún wọn. Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ bá àwọn tí ó gbé wọn wá wí.
ܗܝܕܝܢ ܩܪܒܘ ܠܗ ܛܠܝܐ ܕܢܤܝܡ ܐܝܕܗ ܥܠܝܗܘܢ ܘܢܨܠܐ ܘܟܐܘ ܒܗܘܢ ܬܠܡܝܕܘܗܝ
14 Ṣùgbọ́n Jesu dáhùn pé, “Ẹ jẹ́ kí àwọn ọmọdé wá sọ́dọ̀ mi, ẹ má ṣe dá wọn lẹ́kun, nítorí irú wọn ni ìjọba ọ̀run.”
ܗܘ ܕܝܢ ܝܫܘܥ ܐܡܪ ܠܗܘܢ ܫܒܘܩܘ ܛܠܝܐ ܐܬܝܢ ܠܘܬܝ ܘܠܐ ܬܟܠܘܢ ܐܢܘܢ ܕܕܐܝܠܝܢ ܓܝܪ ܕܐܝܟ ܗܠܝܢ ܐܢܘܢ ܐܝܬܝܗ ܡܠܟܘܬܐ ܕܫܡܝܐ
15 Lẹ́yìn náà, ó gbé ọwọ́ lé wọn, ó sì kúrò níbẹ̀.
ܘܤܡ ܐܝܕܗ ܥܠܝܗܘܢ ܘܐܙܠ ܡܢ ܬܡܢ
16 Ẹnìkan sì wá ó bí Jesu pé, “Olùkọ́, ohun rere kí ni èmi yóò ṣe, kí èmi kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
ܘܐܬܐ ܚܕ ܩܪܒ ܘܐܡܪ ܠܗ ܡܠܦܢܐ ܛܒܐ ܡܢܐ ܕܛܒ ܐܥܒܕ ܕܢܗܘܘܢ ܠܝ ܚܝܐ ܕܠܥܠܡ (aiōnios g166)
17 Jesu dá a lóhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń béèrè nípa ohun rere lọ́wọ́ mi. Ẹni kan ṣoṣo ni ó wà tí í ṣe ẹni rere. Bí ìwọ bá fẹ́ dé ibi ìyè, pa àwọn òfin mọ́.”
ܗܘ ܕܝܢ ܐܡܪ ܠܗ ܡܢܐ ܩܪܐ ܐܢܬ ܠܝ ܛܒܐ ܠܝܬ ܛܒܐ ܐܠܐ ܐܢ ܚܕ ܐܠܗܐ ܐܢ ܕܝܢ ܨܒܐ ܐܢܬ ܕܬܥܘܠ ܠܚܝܐ ܛܪ ܦܘܩܕܢܐ
18 Ọkùnrin náà béèrè pé, “Àwọn wo ni òfin wọ̀nyí?” Jesu dáhùn pé, “‘Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn; ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà; ìwọ kò gbọdọ̀ jalè; ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké’,
ܐܡܪ ܠܗ ܐܝܠܝܢ ܗܘ ܕܝܢ ܝܫܘܥ ܐܡܪ ܠܗ ܕܠܐ ܬܩܛܘܠ ܘܠܐ ܬܓܘܪ ܘܠܐ ܬܓܢܘܒ ܘܠܐ ܬܤܗܕ ܤܗܕܘܬ ܫܘܩܪܐ
19 bọ̀wọ̀ fún baba àti ìyá rẹ. ‘Kí o sì fẹ́ aládùúgbò rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ.’”
ܘܝܩܪ ܠܐܒܘܟ ܘܠܐܡܟ ܘܬܚܒ ܠܩܪܝܒܟ ܐܝܟ ܢܦܫܟ
20 Ọmọdékùnrin náà tún wí pé, “Gbogbo òfin wọ̀nyí ni èmi ti ń pamọ́, kí ni nǹkan mìíràn tí èmi ní láti ṣe?”
ܐܡܪ ܠܗ ܗܘ ܥܠܝܡܐ ܗܠܝܢ ܟܠܗܝܢ ܢܛܪܬ ܐܢܝܢ ܡܢ ܛܠܝܘܬܝ ܡܢܐ ܚܤܝܪ ܐܢܐ
21 Jesu wí fún un pé, “Bí ìwọ bá fẹ́ di ẹni pípé, lọ ta ohun gbogbo tí ìwọ ní, kí o sì fi owó rẹ̀ tọrẹ fún àwọn aláìní. Ìwọ yóò ní ọrọ̀ ńlá ní ọ̀run. Lẹ́yìn náà, wá láti máa tọ̀ mi lẹ́yìn.”
ܐܡܪ ܠܗ ܝܫܘܥ ܐܢ ܨܒܐ ܐܢܬ ܓܡܝܪܐ ܠܡܗܘܐ ܙܠ ܙܒܢ ܩܢܝܢܟ ܘܗܒ ܠܡܤܟܢܐ ܘܬܗܘܐ ܠܟ ܤܝܡܬܐ ܒܫܡܝܐ ܘܬܐ ܒܬܪܝ
22 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọ̀dọ́mọkùnrin náà gbọ́ èyí, ó kúrò níbẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́, nítorí ó ní ọrọ̀ púpọ̀.
ܫܡܥ ܕܝܢ ܗܘ ܥܠܝܡܐ ܡܠܬܐ ܗܕܐ ܘܐܙܠ ܟܕ ܟܪܝܐ ܠܗ ܐܝܬ ܗܘܐ ܠܗ ܓܝܪ ܩܢܝܢܐ ܤܓܝܐܐ
23 Nígbà náà, ní Jesu wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín pé, ó ṣòro fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọ̀run.”
ܝܫܘܥ ܕܝܢ ܐܡܪ ܠܬܠܡܝܕܘܗܝ ܐܡܝܢ ܐܡܪ ܐܢܐ ܠܟܘܢ ܕܥܛܠܐ ܗܝ ܠܥܬܝܪܐ ܕܢܥܘܠ ܠܡܠܟܘܬ ܫܡܝܐ
24 Mo tún wí fún yín pé, “Ó rọrùn fún ìbákasẹ láti wọ ojú abẹ́rẹ́ jù fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run.”
ܬܘܒ ܕܝܢ ܐܡܪܢܐ ܠܟܘܢ ܕܕܠܝܠ ܗܘ ܠܓܡܠܐ ܠܡܥܠ ܒܚܪܘܪܐ ܕܡܚܛܐ ܐܘ ܥܬܝܪܐ ܕܢܥܘܠ ܠܡܠܟܘܬܐ ܕܐܠܗܐ
25 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn gbọ́ èyí, ẹnu sì yà wọn gidigidi, wọ́n béèrè pé, “Ǹjẹ́ ta ni ó ha le là?”
ܬܠܡܝܕܐ ܕܝܢ ܟܕ ܫܡܥܘ ܬܗܝܪܝܢ ܗܘܘ ܛܒ ܘܐܡܪܝܢ ܡܢܘ ܟܝ ܡܫܟܚ ܕܢܚܐ
26 Ṣùgbọ́n Jesu wò wọ́n, ó sì wí fún wọn pé, “Ènìyàn ni èyí ṣòro fún; ṣùgbọ́n fún Ọlọ́run ohun gbogbo ni ṣíṣe.”
ܚܪ ܒܗܘܢ ܝܫܘܥ ܘܐܡܪ ܠܗܘܢ ܠܘܬ ܒܢܝܢܫܐ ܗܕܐ ܠܐ ܡܫܟܚܐ ܠܘܬ ܐܠܗܐ ܕܝܢ ܟܠܡܕܡ ܡܫܟܚܐ
27 Peteru sì wí fún un pé, “Àwa ti fi ohun gbogbo sílẹ̀, a sì tẹ̀lé ọ, kí ni yóò jẹ́ èrè wa?”
ܗܝܕܝܢ ܥܢܐ ܟܐܦܐ ܘܐܡܪ ܠܗ ܗܐ ܐܢܚܢܢ ܫܒܩܢ ܟܠܡܕܡ ܘܐܬܝܢ ܒܬܪܟ ܡܢܐ ܟܝ ܢܗܘܐ ܠܢ
28 Jesu dáhùn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín pé, ‘Nígbà ìsọdọ̀tun ohun gbogbo, nígbà tí Ọmọ Ènìyàn yóò jókòó lórí ìtẹ́ tí ó lógo, dájúdájú, ẹ̀yin ọmọ-ẹ̀yìn mi yóò sì jókòó lórí ìtẹ́ méjìlá láti ṣe ìdájọ́ ẹ̀yà Israẹli méjìlá.
ܐܡܪ ܠܗܘܢ ܝܫܘܥ ܐܡܝܢ ܐܡܪ ܐܢܐ ܠܟܘܢ ܕܐܢܬܘܢ ܕܐܬܝܬܘܢ ܒܬܪܝ ܒܥܠܡܐ ܚܕܬܐ ܡܐ ܕܝܬܒ ܒܪܗ ܕܐܢܫܐ ܥܠ ܬܪܢܘܤ ܕܫܘܒܚܗ ܬܬܒܘܢ ܐܦ ܐܢܬܘܢ ܥܠ ܬܪܥܤܪ ܟܘܪܤܘܢ ܘܬܕܘܢܘܢ ܬܪܥܤܪ ܫܒܛܐ ܕܐܝܤܪܐܝܠ
29 Àti pé ẹnikẹ́ni tí ó bá fi ilé tàbí arákùnrin tàbí arábìnrin tàbí baba tàbí ìyá tàbí àwọn ọmọ, tàbí ohun ìní rẹ̀ sílẹ̀ nítorí orúkọ mí, yóò gba ọgọọgọ́rùn-ún èrè rẹ̀ láyé, wọn ó sì tún jogún ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
ܘܟܠܢܫ ܕܫܒܩ ܒܬܐ ܐܘ ܐܚܐ ܐܘ ܐܚܘܬܐ ܐܘ ܐܒܐ ܐܘ ܐܡܐ ܐܘ ܐܢܬܬܐ ܐܘ ܒܢܝܐ ܐܘ ܩܘܪܝܐ ܡܛܠ ܫܡܝ ܚܕ ܒܡܐܐ ܢܩܒܠ ܘܚܝܐ ܕܠܥܠܡ ܢܐܪܬ (aiōnios g166)
30 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ àwọn tí ó síwájú nísinsin yìí ni yóò kẹ́yìn, àwọn tí ó kẹ́yìn ni yóò sì síwájú.’
ܤܓܝܐܐ ܕܝܢ ܩܕܡܝܐ ܕܢܗܘܘܢ ܐܚܪܝܐ ܘܐܚܪܝܐ ܩܕܡܝܐ

< Matthew 19 >