< Matthew 18 >
1 Ní àkókò náà ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Jesu tọ̀ ọ́ wá, wọ́n bi í léèrè pé, “Ta ni ẹni ti ó pọ̀jù ní ìjọba ọ̀run?”
tadAnIM shiShyA yIshoH samIpamAgatya pR^iShTavantaH svargarAjye kaH shreShThaH?
2 Jesu sì pe ọmọ kékeré kan sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀. Ó sì mú un dúró láàrín wọn.
tato yIshuH kShudramekaM bAlakaM svasamIpamAnIya teShAM madhye nidhAya jagAda,
3 Ó wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, àfi bí ẹ̀yin bá yí padà kí ẹ sì dàbí àwọn ọmọdé, ẹ̀yin kì yóò lè wọ ìjọba ọ̀run.
yuShmAnahaM satyaM bravImi, yUyaM manovinimayena kShudrabAlavat na santaH svargarAjyaM praveShTuM na shaknutha|
4 Nítorí náà, ẹni tí ó bá rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọmọdé yìí, ni yóò pọ̀ jùlọ ní ìjọba ọ̀run.
yaH kashchid etasya kShudrabAlakasya samamAtmAnaM namrIkaroti, saeva svargarAjaye shreShThaH|
5 Àti pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá gba ọmọ kékeré bí èyí nítorí orúkọ mi, gbà mí.
yaH kashchid etAdR^ishaM kShudrabAlakamekaM mama nAmni gR^ihlAti, sa mAmeva gR^ihlAti|
6 “Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni nínú yín tí ó bá mú ọ̀kan nínú àwọn ọmọ kékeré wọ̀nyí tí ó gbà mí gbọ́ ṣìnà, yóò sàn fún un kí a so òkúta ńlá mọ́ ọn ní ọrùn, kí a sì rì í sí ìsàlẹ̀ ibú omi Òkun.
kintu yo jano mayi kR^itavishvAsAnAmeteShAM kShudraprANinAm ekasyApi vidhniM janayati, kaNThabaddhapeShaNIkasya tasya sAgarAgAdhajale majjanaM shreyaH|
7 Ègbé ni fún ayé nítorí gbogbo ohun ìkọ̀sẹ̀ rẹ̀! Ohun ìkọ̀sẹ̀ kò le ṣe kó má wà, ṣùgbọ́n ègbé ni fún ọkùnrin náà nípasẹ̀ ẹni tí ìkọ̀sẹ̀ náà ti wá!
vighnAt jagataH santApo bhaviShyati, vighno. avashyaM janayiShyate, kintu yena manujena vighno janiShyate tasyaiva santApo bhaviShyati|
8 Nítorí náà, bí ọwọ́ tàbí ẹsẹ̀ rẹ yóò bá mú ọ dẹ́ṣẹ̀, gé e kúrò, kí o sì jù ú nù. Ó kúkú sàn fún ọ láti wọ ìjọba ọ̀run ní akéwọ́ tàbí akésẹ̀ ju pé kí o ni ọwọ́ méjì àti ẹsẹ̀ méjì ki a sì sọ ọ́ sínú iná ayérayé. (aiōnios )
tasmAt tava karashcharaNo vA yadi tvAM bAdhate, tarhi taM ChittvA nikShipa, dvikarasya dvipadasya vA tavAnaptavahnau nikShepAt, kha njasya vA Chinnahastasya tava jIvane pravesho varaM| (aiōnios )
9 Bí ojú rẹ yóò bá sì mú kí o dẹ́ṣẹ̀, yọ ọ́ kúrò kí ó sì sọ ọ́ nù. Ó kúkú sàn fún ọ láti lọ sínú ìyè pẹ̀lú ojú kan, ju pé kí o ní ojú méjì, kí a sì jù ọ́ sí iná ọ̀run àpáàdì. (Geenna )
aparaM tava netraM yadi tvAM bAdhate, tarhi tadapyutpAvya nikShipa, dvinetrasya narakAgnau nikShepAt kANasya tava jIvane pravesho varaM| (Geenna )
10 “Ẹ rí i pé ẹ kò fi ojú tẹ́ńbẹ́lú ọ̀kan nínú àwọn kéékèèké wọ̀nyí. Lóòótọ́ ni mo wí fún yin pé, nígbà gbogbo ni ọ̀run ni àwọn angẹli ń wo ojú Baba mi tí ń bẹ ní ọ̀run.
tasmAdavadhaddhaM, eteShAM kShudraprANinAm ekamapi mA tuchChIkuruta,
yato yuShmAnahaM tathyaM bravImi, svarge teShAM dUtA mama svargasthasya piturAsyaM nityaM pashyanti| evaM ye ye hAritAstAn rakShituM manujaputra AgachChat|
12 “Kí ni ẹ̀yin rò? Bí ọkùnrin kan bá ni ọgọ́rùn-ún àgùntàn, tí ẹyọ kan nínú wọn sì sọnù, ṣé òun kì yóò fi mọ́kàndínlọ́gọ́rùn-ún ìyókù sílẹ̀ sórí òkè láti lọ wá ẹyọ kan tó nù náà bí?
yUyamatra kiM viviMgghve? kasyachid yadi shataM meShAH santi, teShAmeko hAryyate cha, tarhi sa ekonashataM meShAn vihAya parvvataM gatvA taM hAritamekaM kiM na mR^igayate?
13 Ǹjẹ́ bí òun bá sì wá á rí i, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ǹjẹ́ ẹ̀yin kò mọ̀ pé inú rẹ̀ yóò dùn nítorí rẹ̀ ju àwọn mọ́kàndínlọ́gọ́rùn-ún tí kò nù lọ?
yadi cha kadAchit tanmeShoddeshaM lamate, tarhi yuShmAnahaM satyaM kathayAmi, so. avipathagAmibhya ekonashatameShebhyopi tadekahetoradhikam AhlAdate|
14 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ni kì í ṣe ìfẹ́ Baba yín tí ń bẹ ní ọ̀run, pé ọ̀kan nínú àwọn kékeré wọ̀nyí kí ó ṣègbé.
tadvad eteShAM kShudraprAenAm ekopi nashyatIti yuShmAkaM svargasthapitu rnAbhimatam|
15 “Bí arákùnrin rẹ bá ṣẹ̀ ọ́, lọ ní ìkọ̀kọ̀ kí o sì sọ ẹ̀bi rẹ̀ fún un. Bí ó bá gbọ́ tìrẹ, ìwọ ti mú arákùnrin kan bọ̀ sí ipò.
yadyapi tava bhrAtA tvayi kimapyaparAdhyati, tarhi gatvA yuvayordvayoH sthitayostasyAparAdhaM taM j nApaya| tatra sa yadi tava vAkyaM shR^iNoti, tarhi tvaM svabhrAtaraM prAptavAn,
16 Ṣùgbọ́n bí òun kò bá tẹ́tí sí ọ, nígbà náà mú ẹnìkan tàbí ẹni méjì pẹ̀lú rẹ, kí ẹ sì tún padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i, kí ọ̀rọ̀ náà bá le fi ìdí múlẹ̀ pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́rìí méjì tàbí mẹ́ta náà.
kintu yadi na shR^iNoti, tarhi dvAbhyAM tribhi rvA sAkShIbhiH sarvvaM vAkyaM yathA nishchitaM jAyate, tadartham ekaM dvau vA sAkShiNau gR^ihItvA yAhi|
17 Bí òun bá sì tún kọ̀ láti tẹ́tí sí wọn, nígbà náà sọ fún ìjọ ènìyàn Ọlọ́run. Bí o bá kọ̀ láti gbọ́ ti ìjọ ènìyàn Ọlọ́run, jẹ́ kí ó dàbí kèfèrí sí ọ tàbí agbowó òde.
tena sa yadi tayo rvAkyaM na mAnyate, tarhi samAjaM tajj nApaya, kintu yadi samAjasyApi vAkyaM na mAnyate, tarhi sa tava samIpe devapUjakaiva chaNDAlaiva cha bhaviShyati|
18 “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ohunkóhun tí ẹ̀yin bá dè ní ayé, ni a dè ní ọ̀run. Ohunkóhun ti ẹ̀yin bá sì ti tú ni ayé, á ò tú u ní ọ̀run.
ahaM yuShmAn satyaM vadAmi, yuShmAbhiH pR^ithivyAM yad badhyate tat svarge bhaMtsyate; medinyAM yat bhochyate, svarge. api tat mokShyate|
19 “Mo tún sọ èyí fún yín, bí ẹ̀yin méjì bá fi ohùn ṣọ̀kan ní ayé yìí, nípa ohunkóhun tí ẹ béèrè, Baba mi ti ń bẹ ní ọ̀run yóò sì ṣe é fún yín.
punarahaM yuShmAn vadAmi, medinyAM yuShmAkaM yadi dvAvekavAkyIbhUya ki nchit prArthayete, tarhi mama svargasthapitrA tat tayoH kR^ite sampannaM bhaviShyati|
20 Nítorí níbi ti ènìyàn méjì tàbí mẹ́ta bá kó ara jọ ni orúkọ mi, èmi yóò wà láàrín wọn níbẹ̀.”
yato yatra dvau trayo vA mama nAnni milanti, tatraivAhaM teShAM madhye. asmi|
21 Nígbà náà ni Peteru wá sọ́dọ̀ Jesu, ó béèrè pé, “Olúwa, nígbà mélòó ni arákùnrin mi yóò ṣẹ̀ mi, tí èmi yóò sì dáríjì í? Tàbí ní ìgbà méje ni?”
tadAnIM pitarastatsamIpamAgatya kathitavAn he prabho, mama bhrAtA mama yadyaparAdhyati, tarhi taM katikR^itvaH kShamiShye?
22 Jesu dáhùn pé, “Mo wí fún ọ, kì í ṣe ìgbà méje, ṣùgbọ́n ní ìgbà àádọ́rin méje.
kiM saptakR^itvaH? yIshustaM jagAda, tvAM kevalaM saptakR^itvo yAvat na vadAmi, kintu saptatyA guNitaM saptakR^itvo yAvat|
23 “Nítorí náà, ìjọba ọ̀run dàbí ọba kan tí ó fẹ́ ṣe ìṣirò pẹ̀lú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀.
aparaM nijadAsaiH saha jigaNayiShuH kashchid rAjeva svargarAjayaM|
24 Bí ó ti ń ṣe èyí, a mú ajigbèsè kan wá sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó jẹ ẹ́ ní ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá tálẹ́ǹtì.
Arabdhe tasmin gaNane sArddhasahasramudrApUritAnAM dashasahasrapuTakAnAm eko. aghamarNastatsamakShamAnAyi|
25 Nígbà tí kò tì í ní agbára láti san án, nígbà náà ni olúwa rẹ̀ pàṣẹ pé kí a ta òun àti ìyàwó àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó ní láti fi san gbèsè náà.
tasya parishodhanAya dravyAbhAvAt parishodhanArthaM sa tadIyabhAryyAputrAdisarvvasva ncha vikrIyatAmiti tatprabhurAdidesha|
26 “Nígbà náà ni ọmọ ọ̀dọ̀ náà wólẹ̀ lórí eékún níwájú rẹ. ‘Ó bẹ̀bẹ̀ pé, mú sùúrù fún mi, èmi yóò sì san gbogbo rẹ̀ fún ọ.’
tena sa dAsastasya pAdayoH patan praNamya kathitavAn, he prabho bhavatA ghairyye kR^ite mayA sarvvaM parishodhiShyate|
27 Nígbà náà, ni olúwa ọmọ ọ̀dọ̀ náà sì ṣàánú fún un. Ó tú u sílẹ̀, ó sì fi gbèsè náà jì í.
tadAnIM dAsasya prabhuH sakaruNaH san sakalarNaM kShamitvA taM tatyAja|
28 “Ṣùgbọ́n bí ọmọ ọ̀dọ̀ náà ti jáde lọ, ó rí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ẹgbẹ́ rẹ̀ tí ó jẹ ẹ́ ní ọgọ́rùn-ún owó idẹ, ó gbé ọwọ́ lé e, ó fún un ní ọrùn, ó wí pé, ‘San gbèsè tí o jẹ mí lójú ẹsẹ̀.’
kintu tasmin dAse bahi ryAte, tasya shataM mudrAchaturthAMshAn yo dhArayati, taM sahadAsaM dR^iShdvA tasya kaNThaM niShpIDya gaditavAn, mama yat prApyaM tat parishodhaya|
29 “Ọmọ ọ̀dọ̀ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ náà sì wólẹ̀ lórí eékún níwájú rẹ̀, ò ń bẹ̀ ẹ́ pé, ‘Mú sùúrù fún mi, èmi yóò sì san án fún ọ.’
tadA tasya sahadAsastatpAdayoH patitvA vinIya babhAShe, tvayA dhairyye kR^ite mayA sarvvaM parishodhiShyate|
30 “Ṣùgbọ́n òun kọ̀ fún un. Ó pàṣẹ kí a mú ọkùnrin náà, kí a sì jù ú sínú túbú títí tí yóò fi san gbèsè náà tán pátápátá.
tathApi sa tat nA NagIkR^itya yAvat sarvvamR^iNaM na parishodhitavAn tAvat taM kArAyAM sthApayAmAsa|
31 Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ rí ohun tí ó ṣẹlẹ̀, inú bí wọn gidigidi, wọ́n lọ láti lọ sọ fún olúwa wọn, gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀.
tadA tasya sahadAsAstasyaitAdR^ig AcharaNaM vilokya prabhoH samIpaM gatvA sarvvaM vR^ittAntaM nivedayAmAsuH|
32 “Nígbà tí olúwa rẹ̀ pè ọmọ ọ̀dọ̀ náà wọlé, ó wí fún un pé, ‘Ìwọ ọmọ ọ̀dọ̀ búburú, níhìn-ín ni mo ti dárí gbogbo gbèsè rẹ jì ọ́ nítorí tí ìwọ bẹ̀ mi.
tadA tasya prabhustamAhUya jagAda, re duShTa dAsa, tvayA matsannidhau prArthite mayA tava sarvvamR^iNaM tyaktaM;
33 Kò ha ṣe ẹ̀tọ́ fún ọ láti ṣàánú fún àwọn ẹlòmíràn, gẹ́gẹ́ bí èmi náà ti ṣàánú fún ọ?’
yathA chAhaM tvayi karuNAM kR^itavAn, tathaiva tvatsahadAse karuNAkaraNaM kiM tava nochitaM?
34 Ní ìbínú, olówó rẹ̀ fi í lé àwọn onítúbú lọ́wọ́ láti fi ìyà jẹ ẹ́, títí tí yóò fi san gbogbo gbèsè èyí ti ó jẹ ẹ́.
iti kathayitvA tasya prabhuH kruddhyan nijaprApyaM yAvat sa na parishodhitavAn, tAvat prahArakAnAM kareShu taM samarpitavAn|
35 “Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ sì ni Baba mi tí ń bẹ ní ọ̀run yóò sí ṣe sì ẹnìkọ̀ọ̀kan, bí ẹ̀yin kò bá fi tọkàntọkàn dárí ji àwọn arákùnrin yín.”
yadi yUyaM svAntaHkaraNaiH svasvasahajAnAm aparAdhAn na kShamadhve, tarhi mama svargasyaH pitApi yuShmAn pratItthaM kariShyati|