< Matthew 16 >

1 Àwọn Farisi àti àwọn Sadusi wá láti dán Jesu wò. Wọ́n ní kí ó fi àmì ńlá kan hàn àwọn ní ojú ọ̀run.
PHARISEES ki Saducees ipok'itotoiau ki as'saksksĭnnuyiauaie, ai'puĭnŭmiau mŏkanĭs'tsĭnnomoŏsax spots'im ĭstap'stosĭnni.
2 Ó dá wọn lóhùn pé, “Nígbà tí ó bá di àṣálẹ́, ẹ ó sọ pé, ‘Ìbá dára kí ojú ọ̀run pọ́n.’
Nokŭt'anĭstsiuax, autŭkkus' si, kitan'ipuan ak'etameksĭstsi ku; ămawk'ĭssoksĭstsikuists.
3 Ní òwúrọ̀, ‘Ẹ̀yin yóò wí pé ọjọ́ kì yóò dára lónìí, nítorí ti ojú ọ̀run pọ́n, ó sì ṣú dẹ̀dẹ̀,’ ẹ̀yin àgàbàgebè, ẹ̀yin le sọ àmì ojú ọ̀run, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò le mọ àmì àwọn àkókò wọ̀nyí.
Ki ksĭskŭnna'tŭnnĭssi, ak'akapiksĭstsiku annok' ksĭstsikui, amawkĭssoksĭstsikuists ki ĭkikĭn'inatsiu. Kitsiksĭs'tapokămotsitappiansuai! Kitokot'ainipuau assoksĭs'tsikuĭsts ostokso'auĕsts; ki kimatokot'ainipuau annists'isk ksĭstsiku'ĭstsk ĭstsap'stosĭsts.
4 Ìran búburú aláìgbàgbọ́ yìí ń béèrè àmì àjèjì mélòó kàn ni ojú sánmọ̀, ṣùgbọ́n a kí yóò fún ẹnìkankan ní àmì bí kò ṣe àmì Jona.” Nígbà náà ni Jesu fi wọ́n sílẹ̀, ó sì bá tirẹ̀ lọ.
Otsauum'itsitappiisĭn'na ki otau'ŏkotaitappiisĭn'na ap'satsĭmiau apsto'sĭnni; ki matakokotau'axau apsto'sĭnni; prophet Jonas otap'stosĭnni akokotauaie'. Ki skĭtsiu'ax ki itsĭs'tapu.
5 Nígbà tí wọ́n dé apá kejì adágún, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ṣàkíyèsí pé wọ́n ti gbàgbé láti mú àkàrà kankan lọ́wọ́.
Ki otŭs'ksĭnĭmatsax otau'pŭmmosau pakhts'esaiĭsksĭnĭmiau mŏk'atŭksau ke'tani.
6 Jesu sì kìlọ̀ fún wọn pé, “Ẹ kíyèsára, ẹ sì ṣọ́ra, ní ti ìwúkàrà àwọn Farisi àti àwọn Sadusi.”
Jesus itŭm'anĭstsiuax Mokŏk'ik ki iskskats'ĭk Pharisees ki Saducees ĭstsi'kopŭtsketatsĭsau.
7 Wọ́n ń sọ eléyìí ni àárín ara wọn wí pé, “Nítorí tí àwa kò mú àkàrà lọ́wọ́ ni.”
Ki ai'sĭtsĭpsattseiau, ki an'iau, nimatotsipĭnan'a ke'tani,
8 Nígbà tí ó gbọ́ ohun ti wọ́n ń sọ, Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ẹ̀yin onígbàgbọ́ kékeré, èéṣe tí ẹ̀yin ń dààmú ara yín pé ẹ̀yin kò mú oúnjẹ lọ́wọ́?
Jesus otsĭnno'ŏsax, an'istsiuax, Inŭk'aumaitŭkkix, kumauk'sĭtsĭpsăttseipuauaisks, kitsauo'tŭksuai ke'tani?
9 Tàbí ọ̀rọ̀ kò yé yín di ìsinsin yìí? Ẹ̀yin kò rántí pé mo bọ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ènìyàn pẹ̀lú ìṣù àkàrà márùn-ún àti iye agbọ̀n tí ẹ kójọ bí àjẹkù?
Kikŭt'taisakiaisauokhtsĭmipuaua, kikŭttaisauŭsksĭnipuaua nĭsito'mŭksikepippix matap'pix ĭstsĭsĭttu'ĭsts ke'tanĭsts, ki tsanetso'ă kitots'ipuauĕsts ĭsksĭmmatŭk'isokaiĭsts?
10 Ẹ kò sì tún rántí ìṣù méje tí mo fi bọ́ ẹgbàajì ènìyàn àti iye agbọ̀n tí ẹ̀yín kójọ?
Nĭstoyĭm'i omŭk'sikepĭppix matap'pix ĭstokĭtsikaists ke'tanĭsts ki tsanetso'ă kitots'ipuauĕsts ĭsksĭmmatŭk'isokaiĭsts?
11 Èéha ṣe tí kò fi yé yín pé èmi kò sọ̀rọ̀ nípa ti àkàrà? Lẹ́ẹ̀kan sí i, mo wí fún yín, ẹ ṣọ́ra fún ìwúkàrà àwọn Farisi àti ti Sadusi.”
Kumauk'staiokhtsĭmipuauaisks kimat'sĭtsĭpsattopuau'ats ke'tani, kŏkĭskskatsissuai Pharisees ki Saducees ĭstsi'koputsketatsĭsau?
12 Nígbà náà ni ó ṣẹ̀ṣẹ̀ wáyé wọn pé, kì í ṣe nípa ti ìwúkàrà ní ó sọ wí pé kí wọ́n kíyèsára, bí kò ṣe tí ẹ̀kọ́ àwọn Farisi àti Sadusi.
Itŭm'ĭsksĭnĭmiau matsemiu'atsax mŏksĭskatsĭsaie ke'tani istsi'koputsketatsĭs, ki ai'semiuaxmŏks'ĭskatsĭsaie Pharisees ki Saducees ots'ksĭnĭmats'tŭksuaiax.
13 Nígbà tí Jesu sì dé Kesarea-Filipi, ó bi àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ta ni àwọn ènìyàn ń fi Ọmọ Ènìyàn pè?”
Jesus otsito'tosi Cesarea Philippi, ai'sŭppoŏtsesattsiuax otŭsksĭnĭmats'ax, Tsa aniu'axau matap'pi nesto'a nĭn'au okku'i nŏk'ŭmsi?
14 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Àwọn kan ni Johanu onítẹ̀bọmi ni, àwọn mìíràn wí pé, Elijah ni, àwọn mìíràn wí pé, Jeremiah ni, tàbí ọ̀kan nínú àwọn wòlíì.”
Ki an'iau, stsik'ix John Baptist: stsĭk'ix, Elias: ki stsĭk'ix, Jeremias, ki stsĭk'ă prophet.
15 “Ṣùgbọ́n ẹyin ń kọ?” Ó bi í léèrè pé, “Ta ni ẹ̀yin ń fi mi pè?”
An'ĭstsiuax Tsa kitak'anipuau nŏk'ŭm-si?
16 Simoni Peteru dáhùn pé, “Ìwọ ni Kristi náà, Ọmọ Ọlọ́run alààyè.”
Ki Simon Peter nokŭt'anĭstsiuaie ksĕsto'ăkauk Christ, Ap'istotokiuă ipai'tappiiuŭk okku'i.
17 Jesu sì wí fún un pé, “Alábùkún fún ni ìwọ Simoni ọmọ Jona, nítorí ẹran-ara àti ẹ̀jẹ̀ kọ́ ló fi èyí hàn bí kò ṣe Baba mi tí ó ń bẹ ní ọ̀run.
Jesus nokŭt'anĭstsiuaie kitatsĭm'si, Simon Bar Jonas. Ik'sisakuyi ki aa'pŭni kimat'ŭsksĭnĭmatsok'astsau: nin'a spots'im kitusksĭnĭmats'ok.
18 Èmi wí fún ọ, ìwọ ni Peteru àti pé orí àpáta yìí ni èmi yóò kọ́ ìjọ mi lé, àti ẹnu-ọ̀nà ipò òkú kì yóò lè borí rẹ̀. (Hadēs g86)
Ki kita'atanĭsto, ksĕsto'akauk Peter, ki am'om ok'otokŭm nitak'ittokhitokoĭska church; ki Hades istokh'sepĭstanĭsts matakatsiu'atsaie. (Hadēs g86)
19 Èmi yóò fún ní àwọn kọ́kọ́rọ́ ìjọba Ọ̀run; ohun tí ìwọ bá dè ní ayé, òun ni a ó dè ní ọ̀run. Ohunkóhun tí ìwọ bá sì tú ní ayé yìí, a ó sì tú ní ọ̀run.”
Ki kitai'akokoto spots' im istsĭn'naiisĭnni itotai'kauaipixĭxtŭkiopi; ksŏk'kum kitai'akomianĭstomopipi, spots'im ak'itomopipo; ksŏk' kum kitai'akomianĭstapotsippi spots'im ak'itapotsip.
20 Nígbà náà ó kìlọ̀ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé wọn kò gbọdọ̀ sọ fún ẹnikẹ́ni pé Òun ni Kristi náà.
Itŭm'anĭstsiuax otŭsksĭnĭmats'ax mŏkstaitsĭnnikoŏsax'aie osto'i otŭm'si Jesus Christ.
21 Láti ìgbà yìí lọ, Jesu bẹ̀rẹ̀ sí ṣàlàyé fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kedere nípa lílọ sí Jerusalẹmu láti jẹ ọ̀pọ̀ ìyà lọ́wọ́ àwọn àgbàgbà, àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé, kí a sì pa òun, àti ní ọjọ́ kẹta, kí ó sì jíǹde.
Annik' Jesus itaumŭtŭp'anĭstsĭnomoyiuax otŭsksĭnĭmats'ax manĭstakittappopi Jerusalem, manĭstaks'ipuinaistoto'awpianaie omŭx'ĭmĭx ki omŭk'atoiapiekuax ki ai'sĭnakix, ki manistaks'enitawpiauaie, manistaks'ipuauĭstotoawpiuaie nioks'kai ksĭstsikui.
22 Peteru mú Jesu sí ẹ̀gbẹ́ kan, ó bẹ̀rẹ̀ sí í bá a wí pé, “Kí a má rí i Olúwa! Èyí kì yóò ṣẹlẹ̀ sí Ọ!”
Peter itŭmo'toyiuaie, ki aumŭtŭp'sitsĭpsattsiuaie, ki an'iu, Nin'a kŏkŭnĭstsĭp'piokosi; matakittotstsiu'ats ksĕsto'a.
23 Jesu pa ojú dà, ó sì wí fún Peteru pé, “Kúrò lẹ́yìn mi, Satani! Ohun ìkọ̀sẹ̀ ni ìwọ jẹ́ fún mi; ìwọ kò ro ohun tí i ṣe ti Ọlọ́run, bí kò ṣe èyí ti ṣe ti ènìyàn.”
Ki itapotŭkau'aie, ki an'ĭstsiuaie Peter apŭt'tokokit, Satan; kŏk'kĭtstsskĭmskŭki; kimatsskŭmau'ats Ap'ĭstotokiŭă kitsksska'tŭksists annom' ksŏkkum.
24 Nígbà náà ni Jesu wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ tọ̀ mí lẹ́yìn, kí ó sẹ́ ara rẹ̀, kí ó sì gbé àgbélébùú rẹ̀, kí ó sì máa tọ̀ mí lẹ́yìn.
Itŭmanĭstsiuax otŭsksĭnĭmats'ax Iststsi'ki matap'pi makopokiuo'ŏssi nĕsto'a, ŭnnianĭst'auŭtsikĭmatsĭstotos, ki ŭnnianĭstto'tsĭs otauai'staksĭnni, ki ŭnnianĭstopokiuos nĕsto'a.
25 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ gba ẹ̀mí rẹ̀ là, yóò sọ ẹ̀mí rẹ̀ nù ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ ẹ̀mí rẹ̀ nù nítorí mi, yóò rí i.
Annŏk'aiakitsikŏmotsepiosiuok opai'tappiisĭnni, akatstomaie': ki annŏk' itai'akatstomŏk opai'tappiisĭnni, nĕstoi umutak'atstomaie, ai'akokonimaie.
26 Èrè kí ni ó jẹ́ fún ènìyàn bí ó bá jèrè gbogbo ayé yìí, tí ó sì sọ ẹ̀mí rẹ̀ nù? Tàbí kí ni ènìyàn yóò fi dípò ẹ̀mí rẹ̀?
Tsanetso'ă matap'pi ak'okuiĭstŭpasokuiĭm'ats minan'attŭssi kŏnŭs'ksŏkkum, ki atsto'si otsipai'tappiisĭnni? Awx'a otai'akokotawpiaie opai'tappiisĭnni?
27 Nítorí Ọmọ Ènìyàn yóò wá nínú ògo baba rẹ pẹ̀lú àwọn angẹli rẹ̀, nígbà náà ni yóò sì san án fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.
Nin'au okku'i akototo'yĭnaie Un'ni ots'tsapĭnasĭnni ki oto'tokatatsix akopokiuo'iax, ki kŏnai'tappix manĭstsi'piĕsts otap'otŭksuauĕsts ak'ŭnĭstokotsiuax.
28 “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín. Ẹlòmíràn wà nínú àwọn tí ó wà níhìn-ín yìí, tí kì yóò ri ikú títí wọn ó fi rí Ọmọ Ènìyàn tí yóò máa bọ̀ ní ìjọba rẹ̀.”
Kit au'mŭnĭstopuau stsik'ix annom' itai'puyiau, mataksattotsĭm'axau eĭno'sĭnni otsauomai'noŏsau nĭn'au okku'i otsĭn'aipuksipusi mŏks'ĭnaiisi.

< Matthew 16 >