< Matthew 15 >

1 Nígbà náà ní àwọn Farisi àti àwọn olùkọ́ òfin tọ Jesu wá láti Jerusalẹmu,
Alors des Scribes et des Pharisiens vinrent de Jérusalem à Jésus, et lui dirent:
2 wọn béèrè pé, “Èéṣe tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ fi ń rú òfin àtayébáyé àwọn alàgbà? Nítorí tí wọn kò wẹ ọwọ́ wọn kí wọ́n tó jẹun!”
Pourquoi tes Disciples transgressent-ils la tradition des Anciens? car ils ne lavent point leurs mains quand ils prennent leur repas.
3 Jesu sì dá wọn lóhùn pé, “Èéha ṣe tí ẹ̀yin fi rú òfin Ọlọ́run, nítorí àṣà yín?
Mais il répondit, et leur dit: et vous, pourquoi transgressez-vous le commandement de Dieu par votre tradition?
4 Nítorí Ọlọ́run wí pé, ‘Bọ̀wọ̀ fún Baba òun ìyá rẹ,’ àti pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ ọ̀rọ̀-òdì sí baba tàbí ìyá rẹ̀, ní láti kú.’
Car Dieu a commandé, disant: honore ton père et ta mère. Et [il a dit aussi]: que celui qui maudira son père ou sa mère, meure de mort.
5 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá wí fún baba tàbí ìyá rẹ̀ pé, ‘Ẹ̀bùn fún Ọlọ́run ni ohunkóhun tí ìwọ ìbá fi jèrè lára mi,’
Mais vous dites: quiconque aura dit à son père ou à sa mère: [Tout] don qui [sera offert] de par moi, sera à ton profit;
6 tí Òun kò sì bọ̀wọ̀ fún baba tàbí ìyá rẹ̀, ó bọ́; bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin sọ òfin Ọlọ́run di asán nípa àṣà yín.
Encore qu'il n'honore pas son père, ou sa mère, [il ne sera point coupable]; et ainsi vous avez anéanti le commandement de Dieu par votre tradition.
7 Ẹ̀yin àgàbàgebè, ní òtítọ́ ni Wòlíì Isaiah sọtẹ́lẹ̀ nípa yín wí pé:
Hypocrites, Esaïe a bien prophétisé de vous, en disant:
8 “‘Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń fi ẹnu lásán bu ọlá fún mi, ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnnà réré sí mi.
Ce peuple s'approche de moi de sa bouche, et m'honore de ses lèvres; mais leur cœur est fort éloigné de moi.
9 Lásán ni ìsìn wọn; nítorí pé wọ́n ń fi òfin ènìyàn kọ́ ni ní ẹ̀kọ́.’”
Mais ils m'honorent en vain, enseignant des doctrines [qui ne sont que] des commandements d'hommes.
10 Jesu pe ọ̀pọ̀ ènìyàn wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, ó wí pé, “Ẹ tẹ́tí, ẹ sì jẹ́ kí nǹkan tí mo sọ yé yín.
Puis ayant appelé les troupes, il leur dit: écoutez, et comprenez [ceci].
11 Ènìyàn kò di aláìmọ́ nípa ohun tí ó wọ ẹnu ènìyàn, ṣùgbọ́n èyí tí ó ti ẹnu jáde wá ni ó sọ ní di aláìmọ́.”
Ce n'est pas ce qui entre dans la bouche qui souille l'homme; mais ce qui sort de la bouche c'est ce qui souille l'homme.
12 Nígbà náà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n wí fún un pé, “Ǹjẹ́ ìwọ mọ̀ pé inú bí àwọn Farisi lẹ́yìn tí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ tí ó sọ yìí?”
Sur cela les Disciples s'approchant, lui dirent: n'as-tu pas connu que les Pharisiens ont été scandalisés quand ils ont ouï ce discours?
13 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Gbogbo igi tí Baba mi ti ń bẹ ni ọ̀run kò bá gbìn ni á ó fàtu tigbòǹgbò tigbòǹgbò,
Et il répondit, et dit: toute plante que mon Père céleste n'a pas plantée, sera déracinée.
14 ẹ fi wọ́n sílẹ̀; afọ́jú tí ń fi ọ̀nà han afọ́jú ni wọ́n. Bí afọ́jú bá sì ń fi ọ̀nà han afọ́jú, àwọn méjèèjì ni yóò jìn sí kòtò.”
Laissez-les, ce sont des aveugles, conducteurs d'aveugles; si un aveugle conduit un [autre] aveugle, ils tomberont tous deux dans la fosse.
15 Peteru wí, “Ṣe àlàyé òwe yìí fún wa.”
Alors Pierre prenant la parole, lui dit: explique-nous cette similitude.
16 Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéha ṣe tí ìwọ fi jẹ́ aláìmòye síbẹ̀”?
Et Jésus dit: êtes-vous encore, vous aussi, sans intelligence?
17 “Ẹyin kò mọ̀ pé ohunkóhun tí ó gba ẹnu wọlé, yóò gba ti ọ̀nà oúnjẹ lọ, a yóò sì yà á jáde?
N'entendez-vous pas encore que tout ce qui entre dans la bouche descend dans l'estomac et ensuite est jeté au secret?
18 Ṣùgbọ́n ohun tí a ń sọ jáde láti ẹnu, inú ọkàn ni ó ti ń wá, èyí sì ni ó ń sọ ènìyàn di aláìmọ́.
Mais les choses qui sortent de la bouche partent du cœur, et ces choses-là souillent l'homme.
19 Ṣùgbọ́n láti ọkàn ni èrò búburú ti wá, bí ìpànìyàn, panṣágà, àgbèrè, olè jíjà, irọ́ àti ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́.
Car du cœur sortent les mauvaises pensées, les meurtres, les adultères, les fornications, les larcins, les faux témoignages, les médisances.
20 Àwọn tí a dárúkọ wọ̀nyí ni ó ń sọ ènìyàn di aláìmọ́. Ṣùgbọ́n láti jẹun láì wẹ ọwọ́, kò lè sọ ènìyàn di aláìmọ́.”
Ce sont là les choses qui souillent l'homme; mais de manger sans avoir les mains lavées, cela ne souille point l'homme.
21 Jesu sì ti ibẹ̀ kúrò lọ sí Tire àti Sidoni.
Alors Jésus partant de là se retira vers les quartiers de Tyr et de Sidon.
22 Obìnrin kan láti Kenaani, tí ó ń gbé ibẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Ó ń bẹ̀bẹ̀, ó sì kígbe pé, “Olúwa, ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi; ọmọbìnrin mi ní ẹ̀mí èṣù ti ń dá a lóró gidigidi.”
Et voici, une femme Cananéenne, qui était partie de ces quartiers-là, s'écria, en lui disant: Seigneur! Fils de David, aie pitié de moi! ma fille est misérablement tourmentée d'un démon.
23 Ṣùgbọ́n Jesu kò fún un ní ìdáhùn, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì gbà á níyànjú pé, “Lé obìnrin náà lọ, nítorí ó ń kígbe tọ̀ wá lẹ́yìn.”
Mais il ne lui répondit mot; et ses Disciples s'approchant le prièrent, disant: renvoie-la; car elle crie après nous.
24 Ó dáhùn pé, “Àgùntàn ilẹ̀ Israẹli tí ó nù nìkan ni a rán mi sí.”
Et il répondit, et dit: je ne suis envoyé qu'aux brebis perdues de la maison d'Israël.
25 Obìnrin náà wá, ó wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó bẹ̀bẹ̀ sí i pé, “Olúwa ṣàánú fún mi.”
Mais elle vint, et l'adora, disant: Seigneur, assiste-moi!
26 Ó sì dáhùn wí pé, “Kò tọ́ kí a gbé oúnjẹ àwọn ọmọ fún àwọn ajá.”
Et il lui répondit, et dit: il ne convient pas de prendre le pain des enfants, et de le jeter aux petits chiens.
27 Obìnrin náà sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, síbẹ̀síbẹ̀ àwọn ajá a máa jẹ èrúnrún tí ó ti orí tábìlì olówó wọn bọ́ sílẹ̀.”
Mais elle dit: cela est vrai, Seigneur! cependant les petits chiens mangent des miettes qui tombent de la table de leurs maîtres.
28 Jesu sì sọ fún obìnrin náà pé, “Ìgbàgbọ́ ńlá ni tìrẹ! A sì ti dáhùn ìbéèrè rẹ.” A sì mú ọmọbìnrin rẹ̀ láradá ní wákàtí kan náà.
Alors Jésus répondant, lui dit: Ô femme! ta foi est grande; qu'il te soit fait comme tu le souhaites: et dès ce moment-là sa fille fut guérie.
29 Jesu ti ibẹ̀ lọ sí Òkun Galili. Ó gun orí òkè, o sì jókòó níbẹ̀.
Et Jésus partant de là vint près de la mer de Galilée; puis il monta sur une montagne, et s'assit là.
30 Ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn sì tọ̀ ọ́ wá, àti àwọn arọ, afọ́jú, amúnkùn ún, odi àti ọ̀pọ̀ àwọn aláìsàn mìíràn. Wọ́n gbé wọn kalẹ̀ lẹ́sẹ̀ Jesu. Òun sì mú gbogbo wọn láradá.
Et plusieurs troupes de gens vinrent à lui, ayant avec eux des boiteux, des aveugles, des muets, des manchots, et plusieurs autres; lesquels on mit aux pieds de Jésus, et il les guérit.
31 Ẹnu ya ọ̀pọ̀ ènìyàn nígbà tí wọ́n rí àwọn odi tó ń sọ̀rọ̀, amúnkùn ún tó di alára pípé, arọ tí ó ń rìn àti àwọn afọ́jú tí ó ríran. Wọ́n sì ń fi ìyìn fún Ọlọ́run Israẹli.
De sorte que ces troupes s'étonnèrent de voir les muets parler, les manchots être sains, les boiteux marcher, et les aveugles voir; et elles glorifièrent le Dieu d'Israël.
32 Jesu pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sọ́dọ̀, ó wí pé, “Àánú àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe mí; nítorí wọ́n ti wà níhìn-ín pẹ̀lú mi fún ọjọ́ mẹ́ta gbáko báyìí. Wọn kò sì tún ní oúnjẹ mọ́. Èmi kò fẹ́ kí wọn padà lébi, nítorí òyì lè kọ́ wọn lójú ọ̀nà.”
Alors Jésus ayant appelé ses Disciples, dit: je suis ému de compassion envers cette multitude de gens, car il y a déjà trois jours qu'ils ne bougent d'avec moi, et ils n'ont rien à manger; et je ne veux pas les renvoyer à jeun, de peur que les forces ne leur manquent en chemin.
33 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì dá a lóhùn pé, “Níbo ni àwa yóò ti rí oúnjẹ ní ijù níhìn-ín yìí láti fi bọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn yìí?”
Et ses Disciples lui dirent: d'où pourrions-nous tirer dans ce désert assez de pains pour rassasier une si grande multitude?
34 Jesu sì béèrè pé, “Ìṣù àkàrà mélòó ni ẹ̀yin ní?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Àwa ní ìṣù àkàrà méje pẹ̀lú àwọn ẹja wẹ́wẹ́ díẹ̀.”
Et Jésus leur dit: combien avez-vous de pains? ils lui dirent: Sept, et quelque peu de petits poissons.
35 Jesu sì sọ fún gbogbo ènìyàn kí wọn jókòó lórí ilẹ̀.
Alors il commanda aux troupes de s'asseoir par terre.
36 Òun sì mú ìṣù àkàrà méje náà àti ẹja náà. Ó sì fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run, ó bù wọ́n sì wẹ́wẹ́, ó sì fi wọ́n fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀. Wọ́n sì pín in fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà.
Et ayant pris les sept pains et les poissons, il les rompit après avoir béni Dieu, et les donna à ses Disciples, et les Disciples au peuple.
37 Gbogbo wọn jẹ, wọ́n sì yó. Lẹ́yìn náà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì ṣa èyí tókù, ẹ̀kún agbọ̀n méje ni èyí tó ṣẹ́kù jẹ́.
Et ils mangèrent tous, et furent rassasiés; et on remporta du reste des pièces de pain sept corbeilles pleines.
38 Gbogbo wọn sì jẹ́ ẹgbàajì ọkùnrin láì kan àwọn obìnrin àti ọmọdé.
Or ceux qui avaient mangé étaient quatre mille hommes, sans compter les femmes et les petits enfants.
39 Lẹ́yìn náà, Jesu rán àwọn ènìyàn náà lọ sí ilé wọn, ó sì bọ́ sínú ọkọ̀, ó rékọjá lọ sí ẹkùn Magadani.
Et Jésus ayant donné congé aux troupes, monta sur une nacelle, et vint au territoire de Magdala.

< Matthew 15 >