< Matthew 15 >

1 Nígbà náà ní àwọn Farisi àti àwọn olùkọ́ òfin tọ Jesu wá láti Jerusalẹmu,
ⲁ̅ⲧⲟⲧⲉ ⲁⲩ⳿ⲓ ϩⲁ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ Ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛⲪⲁⲣⲓⲥⲉⲟⲥ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲥⲁϧ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ.
2 wọn béèrè pé, “Èéṣe tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ fi ń rú òfin àtayébáyé àwọn alàgbà? Nítorí tí wọn kò wẹ ọwọ́ wọn kí wọ́n tó jẹun!”
ⲃ̅ϫⲉ ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩ ⲛⲉⲕⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲥⲉⲉⲣⲡⲁⲣⲁⲃⲉⲛⲓⲛ ⳿ⲛϯⲡⲁⲣⲁⲇⲟⲥⲓⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓ⳿ⲡⲣⲉⲥⲃⲩⲧⲉⲣⲟⲥ ⳿ⲛⲥⲉⲓⲱⲓ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛⲛⲟⲩϫⲓϫ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁⲛ ⲉⲩⲛⲁⲟⲩⲉⲙ ⲱⲓⲕ.
3 Jesu sì dá wọn lóhùn pé, “Èéha ṣe tí ẹ̀yin fi rú òfin Ọlọ́run, nítorí àṣà yín?
ⲅ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ϩⲱⲧⲉⲛ ⲧⲉⲧ⳿ⲉⲛⲉⲣⲡⲁⲣⲁⲃⲉⲛⲓⲛ ⳿ⲛϯⲉⲛⲧⲟⲗⲏ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ ⲉⲑⲃⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲡⲁⲣⲁⲇⲟⲥⲓⲥ.
4 Nítorí Ọlọ́run wí pé, ‘Bọ̀wọ̀ fún Baba òun ìyá rẹ,’ àti pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ ọ̀rọ̀-òdì sí baba tàbí ìyá rẹ̀, ní láti kú.’
ⲇ̅ⲫϯ ⲅⲁⲣ ⲁϥϫⲟⲥ ϫⲉ ⲙⲁⲧⲁⲓ⳿ⲉ ⲡⲉⲕⲓⲱⲧ ⲛⲉⲙ ⲧⲉⲕⲙⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏⲉⲑⲛⲁϫⲉ ⲟⲩⲥⲁϫⲓ ⲉϥϩⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲥⲁ ⲡⲉϥⲓⲱⲧ ⲛⲉⲙ ⲧⲉϥⲙⲁⲩ ⲉϥ⳿ⲉⲙⲟⲩ ⳿ⲙ⳿ⲫⲙⲟⲩ.
5 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá wí fún baba tàbí ìyá rẹ̀ pé, ‘Ẹ̀bùn fún Ọlọ́run ni ohunkóhun tí ìwọ ìbá fi jèrè lára mi,’
ⲉ̅⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲇⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲫⲏⲉⲑⲛⲁϫⲟⲥ ⳿ⲙⲡⲉϥⲓⲱⲧ ⲓⲉ ⲧⲉϥⲙⲁⲩ ϫⲉ ⲟⲩⲧⲁⲓ⳿ⲟ ⳿ⲉ⳿ⲭⲛⲁϫⲉⲙϩⲏⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲓⲧⲟⲧ ⳿ⲛⲛⲉϥⲧⲁⲓ⳿ⲉ ⲡⲉϥⲓⲱⲧ ⲛⲉⲙ ⲧⲉϥⲙⲁⲩ.
6 tí Òun kò sì bọ̀wọ̀ fún baba tàbí ìyá rẹ̀, ó bọ́; bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin sọ òfin Ọlọ́run di asán nípa àṣà yín.
ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲁⲧⲉⲧⲉⲛⲕⲉⲣϥ ⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ ⲉⲑⲃⲉ ⲛⲉⲧⲉⲛⲡⲁⲣⲁⲇⲟⲥⲓⲥ.
7 Ẹ̀yin àgàbàgebè, ní òtítọ́ ni Wòlíì Isaiah sọtẹ́lẹ̀ nípa yín wí pé:
ⲍ̅ⲛⲓϣⲟⲃⲓ ⲕⲁⲗⲱⲥ ⲁϥⲉⲣ⳿ⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲉⲩⲓⲛ ϧⲁⲣⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛϫⲉ Ⲏ̇ⲥⲁ⳿ⲏⲁⲥ ⲡⲓ⳿ⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲏⲥ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ.
8 “‘Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń fi ẹnu lásán bu ọlá fún mi, ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnnà réré sí mi.
ⲏ̅ϫⲉ ⲡⲁⲓⲗⲁⲟⲥ ⲉⲣⲧⲓⲙⲁⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲟⲩ⳿ⲥⲫⲟⲧⲟⲩ ⲡⲟⲩϩⲏⲧ ⲇⲉ ⳿ϥⲟⲩ⳿ⲏⲟⲩ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲟⲓ.
9 Lásán ni ìsìn wọn; nítorí pé wọ́n ń fi òfin ènìyàn kọ́ ni ní ẹ̀kọ́.’”
ⲑ̅ⲉⲩⲉⲣⲥⲉⲃⲏⲥⲑⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲓ ⳿ⲉ⳿ⲫⲗⲏⲟⲩ ⲉⲩϯ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲛϩⲁⲛ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲛϩⲟⲛϩⲉⲛ ⳿ⲛⲣⲱⲙⲓ.
10 Jesu pe ọ̀pọ̀ ènìyàn wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, ó wí pé, “Ẹ tẹ́tí, ẹ sì jẹ́ kí nǹkan tí mo sọ yé yín.
ⲓ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲡⲓⲙⲏϣ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲥⲱⲧⲉⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲕⲁϯ.
11 Ènìyàn kò di aláìmọ́ nípa ohun tí ó wọ ẹnu ènìyàn, ṣùgbọ́n èyí tí ó ti ẹnu jáde wá ni ó sọ ní di aláìmọ́.”
ⲓ̅ⲁ̅ⲡⲉⲑⲛⲁϣⲉ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲣⲱϥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⲁⲛ ⲡⲉⲧⲥⲱϥ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲁⲗⲗⲁ ⲡⲉⲑⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲣⲱϥ ⲫⲁⲓ ⲡⲉⲧⲥⲱϥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ.
12 Nígbà náà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n wí fún un pé, “Ǹjẹ́ ìwọ mọ̀ pé inú bí àwọn Farisi lẹ́yìn tí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ tí ó sọ yìí?”
ⲓ̅ⲃ̅ⲧⲟⲧⲉ ⲁⲩ⳿ⲓ ϩⲁⲣⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⳿ⲕ⳿ⲉⲙⲓ ϫⲉ ⳿ⲉⲧⲁ ⲛⲓⲪⲁⲣⲓⲥⲉⲟⲥ ⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲡⲁⲓⲥⲁϫⲓ ⲁⲩⲉⲣ⳿ⲥⲕⲁⲛⲇⲁⲗⲓⲍⲉⲥⲑⲉ.
13 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Gbogbo igi tí Baba mi ti ń bẹ ni ọ̀run kò bá gbìn ni á ó fàtu tigbòǹgbò tigbòǹgbò,
ⲓ̅ⲅ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲁϥ⳿ⲉⲣⲟⲩ⳿ⲱ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⳿ϣϣⲏⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉⲧⲉ ⳿ⲙⲡⲉ ⲡⲁⲓⲱⲧ ⲉⲧϧⲉⲛ ⲛⲓⲫⲏⲟⲩ⳿ⲓ ϭⲱⲟⲩ ⲥⲉⲛⲁⲕⲟⲣϫⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲧⲟⲩⲛⲟⲩⲛⲓ.
14 ẹ fi wọ́n sílẹ̀; afọ́jú tí ń fi ọ̀nà han afọ́jú ni wọ́n. Bí afọ́jú bá sì ń fi ọ̀nà han afọ́jú, àwọn méjèèjì ni yóò jìn sí kòtò.”
ⲓ̅ⲇ̅ⲭⲁⲩ ϩⲁⲛⲃⲉⲗⲗⲉⲩ ⲛⲉ ϭⲁⲩⲙⲱⲓⲧ ⳿ⲙⲃⲉⲗⲗⲉ ⳿ⲁⲣⲏⲟⲩ ⲟⲩⲃⲉⲗⲗⲉ ⲅⲁⲣ ⲉϥϭⲓⲙⲱⲓⲧ ϧⲁϫⲱϥ ⳿ⲛⲟⲩⲃⲉⲗⲗⲉ ϣⲁⲩϩⲉⲓ ⳿ⲉⲟⲩϣⲓⲕ ⳿ⲙ⳿ⲡⲃ̅.
15 Peteru wí, “Ṣe àlàyé òwe yìí fún wa.”
ⲓ̅ⲉ̅ⲁϥ⳿ⲉⲣⲟⲩ⳿ⲱ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ Ⲡⲉⲧⲣⲟⲥ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲃⲉⲗ ϯⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ ⲛⲁⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
16 Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéha ṣe tí ìwọ fi jẹ́ aláìmòye síbẹ̀”?
ⲓ̅ⲋ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲁⲕⲙⲏⲛ ϩⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲁⲛⲁⲧⲕⲁϯ.
17 “Ẹyin kò mọ̀ pé ohunkóhun tí ó gba ẹnu wọlé, yóò gba ti ọ̀nà oúnjẹ lọ, a yóò sì yà á jáde?
ⲓ̅ⲍ̅⳿ⲙⲡⲁⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ϫⲉ ⲉⲛⲭⲁⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉϣⲁⲩϣⲉ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲣⲱϥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ϣⲁⲩϣⲉⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲉϯⲛⲉϫⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲟⲩϩⲓⲧⲟⲩ ⳿ⲉⲛⲓⲙⲁ⳿ⲛϩⲉⲙⲥⲓ.
18 Ṣùgbọ́n ohun tí a ń sọ jáde láti ẹnu, inú ọkàn ni ó ti ń wá, èyí sì ni ó ń sọ ènìyàn di aláìmọ́.
ⲓ̅ⲏ̅ⲛⲏ ⲇⲉ ⲉⲑⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲣⲱϥ ⲉⲩⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲡⲓϩⲏⲧ ⲛⲁⲓ ⲡⲉⲧⲥⲱϥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ.
19 Ṣùgbọ́n láti ọkàn ni èrò búburú ti wá, bí ìpànìyàn, panṣágà, àgbèrè, olè jíjà, irọ́ àti ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́.
ⲓ̅ⲑ̅⳿ⲉϣⲁⲩ⳿ⲓ ⲅⲁⲣ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲓϩⲏⲧ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲙⲟⲕⲙⲉⲕ ⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⲛⲓϧⲱⲧⲉⲃ ⲛⲓⲙⲉⲧⲛⲱⲓⲕ ⲛⲓⲡⲟⲣⲛⲓ⳿ⲁ ⲛⲓϭⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⲛⲓⲙⲉⲧⲙⲉⲑⲣⲉ ⳿ⲛⲛⲟⲩϫ ⲛⲓϫⲉⲟⲩ⳿ⲁ.
20 Àwọn tí a dárúkọ wọ̀nyí ni ó ń sọ ènìyàn di aláìmọ́. Ṣùgbọ́n láti jẹun láì wẹ ọwọ́, kò lè sọ ènìyàn di aláìmọ́.”
ⲕ̅ⲛⲁⲓ ⲡⲉⲧⲥⲱϥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⲡⲓⲟⲩⲱⲙ ⲇⲉ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ⲉϣⲉⲛ ⲓⲁ ⲧⲟⲧ ⳿ⲛ⳿ϥⲥⲱϥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⲁⲛ.
21 Jesu sì ti ibẹ̀ kúrò lọ sí Tire àti Sidoni.
ⲕ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲁϥϣⲉⲛⲁϥ ⳿ⲉⲛⲓⲥⲁ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲧⲩⲣⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⳿ⲧⲤⲓⲇⲱⲛ.
22 Obìnrin kan láti Kenaani, tí ó ń gbé ibẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Ó ń bẹ̀bẹ̀, ó sì kígbe pé, “Olúwa, ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi; ọmọbìnrin mi ní ẹ̀mí èṣù ti ń dá a lóró gidigidi.”
ⲕ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲓⲥ ⲟⲩ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲛ ⲛⲏ⳿ⲁ ⲁⲥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲓϭⲓ⳿ⲏ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲥⲱϣ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲉⲥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲛⲁⲓ ϧⲁⲣⲟⲓ Ⲡⲁ⳪ ⳿ⲡϣⲏⲣⲓ ⳿ⲛⲆⲁⲩⲓⲇ ⲧⲁϣⲉⲣⲓ ⳿ⲧϩⲉⲙⲕⲏⲟⲩⲧ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲇⲉⲙⲱⲛ ⲛⲉⲙⲁⲥ.
23 Ṣùgbọ́n Jesu kò fún un ní ìdáhùn, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì gbà á níyànjú pé, “Lé obìnrin náà lọ, nítorí ó ń kígbe tọ̀ wá lẹ́yìn.”
ⲕ̅ⲅ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲉϥ⳿ⲉⲣⲟⲩ⳿ⲱ ⲛⲁⲥ ⳿ⲛⲟⲩⲥⲁϫⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲁⲩϯϩⲟ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲭⲁ ⲧⲁⲓ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϫⲉ ⳿ⲥⲱϣ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲥⲁⲙⲉⲛϩⲏⲛ.
24 Ó dáhùn pé, “Àgùntàn ilẹ̀ Israẹli tí ó nù nìkan ni a rán mi sí.”
ⲕ̅ⲇ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲁϥ⳿ⲉⲣⲟⲩ⳿ⲱ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⳿ⲙⲡⲟⲩⲧⲁⲟⲩⲟⲓ ϩⲁ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲉⲃⲏⲗ ⳿ⲉⲛⲓ⳿ⲉⲥⲱⲟⲩ ⲉⲧⲥⲱⲣⲉⲙ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲏⲓ ⳿ⲙⲠⲓ̅ⲥ̅ⲗ̅.
25 Obìnrin náà wá, ó wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó bẹ̀bẹ̀ sí i pé, “Olúwa ṣàánú fún mi.”
ⲕ̅ⲉ̅⳿ⲛⲑⲟⲥ ⲇⲉ ⲁⲥ⳿ⲓ ⲁⲥⲟⲩⲱϣⲧ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲉⲥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ Ⲡⲁ⳪ ⳿ⲁⲣⲓⲃⲟ⳿ⲏⲑⲓⲛ ⳿ⲉⲣⲟⲓ.
26 Ó sì dáhùn wí pé, “Kò tọ́ kí a gbé oúnjẹ àwọn ọmọ fún àwọn ajá.”
ⲕ̅ⲋ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲁϥ⳿ⲉⲣⲟⲩ⳿ⲱ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⲛⲁⲛⲉⲥ ⲁⲛ ⳿ⲉⲉⲗ ⳿ⲡⲱⲓⲕ ⳿ⲛⲛⲓϣⲏⲣⲓ ⳿ⲉⲧⲏⲓϥ ⳿ⲛⲛⲓⲟⲩϩⲱⲣ.
27 Obìnrin náà sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, síbẹ̀síbẹ̀ àwọn ajá a máa jẹ èrúnrún tí ó ti orí tábìlì olówó wọn bọ́ sílẹ̀.”
ⲕ̅ⲍ̅⳿ⲛⲑⲟⲥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁⲥ ϫⲉ ⲥⲉ Ⲡⲁ⳪ ⲕⲉ ⲅⲁⲣ ϣⲁⲣⲉ ⲛⲓⲕⲉⲟⲩϩⲱⲣ ⲟⲩⲱⲙ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲓⲗⲉϥⲗⲓϥⲓ ⲛⲏ⳿ⲉϣⲁⲩϩⲉⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲓ ϯ⳿ⲧⲣⲁⲡⲉⲍⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲟⲩϭⲓⲥⲉⲩ.
28 Jesu sì sọ fún obìnrin náà pé, “Ìgbàgbọ́ ńlá ni tìrẹ! A sì ti dáhùn ìbéèrè rẹ.” A sì mú ọmọbìnrin rẹ̀ láradá ní wákàtí kan náà.
ⲕ̅ⲏ̅ⲧⲟⲧⲉ ⲁϥ⳿ⲉⲣⲟⲩ⳿ⲱ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ⳿ⲱ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⲡⲉ ⲡⲉⲛⲁϩϯ ⲉϥ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⲛⲉ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲉⲧⲉⲟⲩⲁϣϥ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥⲟⲩϫⲁⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲧⲉⲥϣⲉⲣⲓ ⲓⲥϫⲉⲛ ϯⲟⲩⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ.
29 Jesu ti ibẹ̀ lọ sí Òkun Galili. Ó gun orí òkè, o sì jókòó níbẹ̀.
ⲕ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲟⲩ⳿ⲱⲧⲉⲃ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ⲥⲕⲉⲛ ⳿ⲫⲓⲟⲙ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲄⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϣⲉⲛⲁϥ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲟⲩⲧⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϩⲉⲙⲥⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲡⲉ.
30 Ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn sì tọ̀ ọ́ wá, àti àwọn arọ, afọ́jú, amúnkùn ún, odi àti ọ̀pọ̀ àwọn aláìsàn mìíràn. Wọ́n gbé wọn kalẹ̀ lẹ́sẹ̀ Jesu. Òun sì mú gbogbo wọn láradá.
ⲗ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩ⳿ⲓ ϩⲁⲣⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛⲛⲓϣϯ ⳿ⲙⲙⲏϣ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛ ϩⲁⲛϭⲁⲗⲉⲩ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲃⲉⲗⲗⲉⲩ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲕⲟⲩⲣ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛϫⲁϭ ⲉⲩ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲕⲉⲙⲏϣ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϩⲓⲧⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ϧⲁ ⲛⲉϥϭⲁⲗⲁⲩϫ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲉⲣⲫⲁϧⲣⲓ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ.
31 Ẹnu ya ọ̀pọ̀ ènìyàn nígbà tí wọ́n rí àwọn odi tó ń sọ̀rọ̀, amúnkùn ún tó di alára pípé, arọ tí ó ń rìn àti àwọn afọ́jú tí ó ríran. Wọ́n sì ń fi ìyìn fún Ọlọ́run Israẹli.
ⲗ̅ⲁ̅ϩⲱⲥⲧⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲙⲏϣ ⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ⲉⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲛⲓ⳿ⲉⲃⲱⲟⲩ ⲉⲩⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲓϭⲁⲗⲉⲩ ⲉⲩⲙⲟϣⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲃⲉⲗⲗⲉⲩ ⲉⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲙⲃⲟⲗ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲕⲟⲩⲣ ⲉⲩⲥⲱⲧⲉⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩϯ⳿ⲱⲟⲩ ⳿ⲙⲪϯ ⳿ⲙⲠⲓ̅ⲥ̅ⲗ̅.
32 Jesu pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sọ́dọ̀, ó wí pé, “Àánú àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe mí; nítorí wọ́n ti wà níhìn-ín pẹ̀lú mi fún ọjọ́ mẹ́ta gbáko báyìí. Wọn kò sì tún ní oúnjẹ mọ́. Èmi kò fẹ́ kí wọn padà lébi, nítorí òyì lè kọ́ wọn lójú ọ̀nà.”
ⲗ̅ⲃ̅Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲇⲉ ⳿ⲉⲧⲁϥⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ϯϣⲉⲛϩⲏⲧ ϧⲁ ⲡⲁⲓⲙⲏϣ ϫⲉ ⲓⲥ ⲅ̅ ⳿ⲛ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲥⲉⲭⲏ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲙⲁ ⲛⲉⲙⲏⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲟⲩⲛⲁⲟⲩⲟⲙϥ ⲟⲩⲟϩ ϯⲟⲩⲱϣ ⲁⲛ ⳿ⲉⲭⲁⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ⲉϣⲉⲛⲟⲩⲱⲙ ϫⲉ ⳿ⲛⲛⲟⲩⲃⲱⲗ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓ ⲡⲓⲙⲱⲓⲧ.
33 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì dá a lóhùn pé, “Níbo ni àwa yóò ti rí oúnjẹ ní ijù níhìn-ín yìí láti fi bọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn yìí?”
ⲗ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲉ ⲛⲓⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ϫⲉ Ⲁⲛⲛⲁϫⲉⲙ ⲧⲁⲓ⳿ⲏⲡⲓ ⳿ⲛⲱⲓⲕ ⲑⲱⲛ ϩⲓ ⲡⲁⲓⲙⲁ ⳿ⲛϣⲁϥⲉ ϩⲱⲥⲧⲉ ⳿ⲉ⳿ⲧⲥⲓ ⳿ⲉⲡⲁⲓⲙⲏϣ.
34 Jesu sì béèrè pé, “Ìṣù àkàrà mélòó ni ẹ̀yin ní?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Àwa ní ìṣù àkàrà méje pẹ̀lú àwọn ẹja wẹ́wẹ́ díẹ̀.”
ⲗ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲟⲩⲟⲛⲧⲉⲧⲉⲛ ⲟⲩⲏⲣ ⳿ⲛⲱⲓⲕ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲍ̅ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲕⲟⲩϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉⲃⲧ.
35 Jesu sì sọ fún gbogbo ènìyàn kí wọn jókòó lórí ilẹ̀.
ⲗ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥϩⲟⲛϩⲉⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲙⲏϣ ⲉⲑⲣⲟⲩⲣⲱⲧⲉⲃ ϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲓⲕⲁϩⲓ.
36 Òun sì mú ìṣù àkàrà méje náà àti ẹja náà. Ó sì fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run, ó bù wọ́n sì wẹ́wẹ́, ó sì fi wọ́n fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀. Wọ́n sì pín in fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà.
ⲗ̅ⲋ̅ⲁϥϭⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲍ̅ ⳿ⲛⲱⲓⲕ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲧⲉⲃⲧ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ⲥⲙⲟⲩ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲁϥⲫⲁϣⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲧⲏⲓⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲛⲓⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲇⲉ ⲁⲩϯ ⳿ⲛⲛⲓⲙⲏϣ.
37 Gbogbo wọn jẹ, wọ́n sì yó. Lẹ́yìn náà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì ṣa èyí tókù, ẹ̀kún agbọ̀n méje ni èyí tó ṣẹ́kù jẹ́.
ⲗ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲟⲩⲱⲙ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲁⲩⲥⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲉⲗ ⳿ⲡϩⲟⲩ⳿ⲟ ⳿ⲛⲛⲓⲗⲁⲕϩ ⲁⲩⲙⲁϩ ⲍ̅ ⳿ⲙⲃⲓⲣ.
38 Gbogbo wọn sì jẹ́ ẹgbàajì ọkùnrin láì kan àwọn obìnrin àti ọmọdé.
ⲗ̅ⲏ̅ⲛⲏ ⲇⲉ ⳿ⲉⲛⲁⲩⲟⲩⲱⲙ ⲛⲁⲩⲉⲣ ⲇ̅ ⳿ⲛϣⲟ ⳿ⲛⲣⲱⲙⲓ ⲭⲱⲣⲓⲥ ⳿ⲁⲗⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ.
39 Lẹ́yìn náà, Jesu rán àwọn ènìyàn náà lọ sí ilé wọn, ó sì bọ́ sínú ọkọ̀, ó rékọjá lọ sí ẹkùn Magadani.
ⲗ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲭⲁ ⲛⲓⲙⲏϣ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁϥ⳿ⲁⲗⲏⲓ ⳿ⲉⲡⲓϫⲟⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲛⲓϭⲓ⳿ⲏ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲙⲁⲅⲇⲁⲗⲁⲛ

< Matthew 15 >