< Matthew 14 >

1 Ní àkókò náà ni Herodu ọba tetrarki gbọ́ nípa òkìkí Jesu,
Husala ezyo, Uherode ahevwezye ihabari ya Yesu.
2 ó wí fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Dájúdájú Johanu onítẹ̀bọmi ni èyí, ó jíǹde kúrò nínú òkú. Ìdí nìyí tí ó fi ní agbára láti ṣiṣẹ́ ìyanu wọ̀nyí.”
Abhawozya ahoyi bhakwe, “Ono yu Yohana Umozyaji azyoshele afume whazimu. Eshi engovo ezyo zili hukwakwe.”
3 Nísinsin yìí Herodu ti mú Johanu, ó fi ẹ̀wọ̀n dè é, ó sì fi sínú túbú, nítorí Herodia aya Filipi arákùnrin rẹ̀,
Afwatanaje u Herode ali anemile u Yohana apinya na hutaje mwijela husababu ya Herodia, oshe wa Filipo okolo wakwe.
4 nítorí Johanu onítẹ̀bọmi ti sọ fún Herodu pé, “Kò yẹ fún ọ láti fẹ́ obìnrin náà.”
Afwatanaje u Yohana amozezye, “Sagashinza ahumweje umwene abhe shee wakwe.”
5 Herodu fẹ́ pa Johanu, ṣùgbọ́n ó bẹ̀rù àwọn ènìyàn nítorí gbogbo ènìyàn gbàgbọ́ pé wòlíì ni.
U Herode andiagojile ila ahogope abhantu husababu bhanolile u Yohana aje kuwe.
6 Ní ọjọ́ àsè ìrántí ọjọ́ ìbí Herodu, ọmọ Herodia obìnrin jó dáradára, ó sì tẹ́ Herodu lọ́run gidigidi.
Ila isala ninsiku zya papwe u Herode lwazyafiha umwale wa Herode ahanjile pakasi ya bhantu nahasongwezye u Herode.
7 Nítorí náà ni ó ṣe fi ìbúra ṣe ìlérí láti fún un ní ohunkóhun ti ó bá béèrè fún.
Katika ajibu shila shasobhe zezye hundapo aje anzahupele shoshonti shanzalabhe.
8 Pẹ̀lú ìmọ̀ràn láti ọ̀dọ̀ ìyá rẹ̀, ó béèrè pé, “Fún mi ni orí Johanu onítẹ̀bọmi nínú àwopọ̀kọ́”.
Baada yashauliwe nu maye wakwe, ayanjile, “Mpele ane epa pikombe itwe lya Yohana Umozi.”
9 Inú ọba bàjẹ́ gidigidi, ṣùgbọ́n nítorí ìbúra rẹ̀ àti kí ojú má ba à tì í níwájú àwọn àlejò tó wà ba jẹ àsè, ó pàṣẹ pé kí wọ́n fún un gẹ́gẹ́ bí o ti fẹ́.
Umwene ali na masikitiho humalawo gamwale, ila kwa ajili yindapo zyakwe, afwatanaje wonti bhabhaleho pashalye pamo numwene ayanjile aje lifanyishe.
10 Nítorí náà, a bẹ́ orí Johanu onítẹ̀bọmi nínú ilé túbú.
Atumile u Yohana aletwe afume whigeleza,
11 A sì gbé orí rẹ̀ jáde láti fi fún ọmọbìnrin náà nínú àwopọ̀kọ́, òun sì gbà á, ó gbé e tọ ìyá rẹ̀ lọ.
ili atemwe itwe lyakwe na litemwe pamwanya yisinia na apewe umwale na alitwale whamaye wakwe.
12 Lẹ́yìn náà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu wá gba òkú rẹ̀, wọ́n sì sin ín. Wọ́n sì wá sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún Jesu.
Tena abhanafunzi bhakwe bhenza awheje gula ombele na syele, baada yeli bhabhalile humozye u Yesu.
13 Nígbà tí Jesu gbọ́ ìròyìn ìṣẹ̀lẹ̀ náà, ó kúrò níbẹ̀, ó bá ọkọ̀ ojú omi lọ sí ibi kọ́lọ́fín kan ní èbúté láti dá wà níbẹ̀. Nígbà tí wọ́n gbọ́ èyí, ọ̀pọ̀ ènìyàn sì fi ẹsẹ̀ rìn tẹ̀lé e láti ọ̀pọ̀ ìlú wọn.
Nape Uyesu lwahevwa ega, ajitenga afume isehemu ela azubha mukasi yimashua abhala esehemu yijitenjile. Umuda empoga lwayanya whali, bhafwatile lwimanama afume humijini.
14 Nígbà ti Jesu gúnlẹ̀, tí ó sì rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, inú rẹ̀ yọ́ sí wọn, ó sì mú àwọn aláìsàn láradá.
Tena u Yesu ahenzele whilongolela lyawo alola empoga ingosi. Abhalolela enkombo na hubhaponyle impongo zyawo.
15 Nígbà ti ilẹ̀ ń ṣú lọ, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì wí pé, “Ibi yìí jìnnà sí ìlú ilẹ̀ sì ń ṣú lọ. Rán àwọn ènìyàn lọ sí àwọn ìletò kí wọ́n lè ra oúnjẹ jẹ.”
Ishalyabhela yakamiliha, abhanafunzi bhahenza hukwakwe na yanje, “Ene sehemu yijangwa ni siku tayari lishilile. Bhatabhanye amakutano ili bhabhale muvijiji ni bhakale ishalye kwa ajili yawo.
16 Ṣùgbọ́n Jesu fèsì pé, “Kò nílò kí wọ́n lọ kúrò. Ẹ fún wọn ní oúnjẹ.”
Ila Yesu ayanjile, “Sagabhali ni haja yabhalebhewo. Bhapeli amwe ishalye”
17 Wọ́n sì dalóhùn pé, “Àwa kò ní ju ìṣù àkàrà márùn-ún àti ẹja méjì lọ níhìn-ín.”
Bhamozya, “Epa tilinago amabumunda gasanu neswe zebhele tu.”'
18 Ó wí pé, “Ẹ mú wọn wá fún mi níhìn-ín yìí.”
U Yesu ayanga, “Galeti huline.”
19 Lẹ́yìn náà, ó wí fún àwọn ènìyàn kí wọ́n jókòó lórí koríko. Lẹ́yìn náà, ó mú ìṣù àkàrà márùn-ún àti ẹja méjì. Ó gbé ojú rẹ̀ sí ọ̀run. Ó béèrè ìbùkún Ọlọ́run lórí oúnjẹ náà, Ó sì bù ú, ó sì fi àkàrà náà fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn láti pín in fún àwọn ènìyàn.
Tena u Yesu ayiwozya empoga akhale pansi yimasole. Ayega amabumunda gasanu neswe zebhele. Ayenya humwanya, asaya nabudulanye amabumunda abhapela abhanafunzi. Abhanafunzi bhayipela empoga.
20 Gbogbo wọn sì jẹ àjẹyó. Lẹ́yìn náà àwọn ọmọ-ẹ̀yìn kó àjẹkù jọ, ó kún agbọ̀n méjìlá.
Bhalya wonti bhihuta. Tena bhavikusanya ivipande vyonti vishalye nameme iviseje kumi navibhele.
21 Iye àwọn ènìyàn ni ọjọ́ náà jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ọkùnrin, láìka àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé.
Bhala bhabhaliye bhabhakadiliya aje abhalume elfu zisanu bila yabhazye abhashe na bhana.
22 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ lẹ́yìn èyí, Jesu wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kí wọ́n bọ sínú ọkọ̀ wọn, àti kí wọ́n máa kọjá lọ ṣáájú rẹ̀ sí òdìkejì. Òun náà dúró lẹ́yìn láti tú àwọn ènìyàn ká lọ sí ilé wọn.
Mara heka abhawozya abhanafunzi bhinjile mukasi yimashuwa, isala ezyo umwene abhalaga empoga bhabhaje bhewo.
23 Lẹ́yìn tí ó tú ìjọ ènìyàn ká tán, ó gun orí òkè lọ fúnra rẹ̀ láti lọ gba àdúrà. Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, òun wà nìkan níbẹ̀,
Lwabhalaga empoga bhabhala bhene, azubha pamwanya yigamba apute mwene. Isala lwayali yilyabhela alihoho mwene.
24 ní àkókò yìí ọkọ̀ ojú omi náà ti rin jìnnà sí etí bèbè Òkun, tí ìjì omi ń tì í síwá sẹ́yìn, nítorí ìjì ṣe ọwọ́ òdì sí wọn.
Ila eshi imashua lwayali pahati yibahari yayumbaga husababu yimawimbi kwani inkongu yali yimpisho.
25 Ní déédé ago mẹ́rin òwúrọ̀, Jesu tọ̀ wọ́n wá, ó ń rìn lórí omi.
Katika uusiku wi zamu ya nne u Yesu abhasojeleye ajenda pamwanya yemenze.
26 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rí i tí ó ń rìn lójú omi, ẹ̀rù ba wọn gidigidi, wọ́n rò pé “iwin ni,” wọ́n kígbe tìbẹ̀rù tìbẹ̀rù.
Isala abhanafunzi bhakwe lwabhanola ajenda pamwanya yi bahari, bhahogope nayanje, “Yuzimu ka,” na zuvye isauti katika ihali yiwoga.
27 Lójúkan náà, Jesu wí fún wọn pé, “Ẹ mú ọkàn le! Èmi ni ẹ má ṣe bẹ̀rù.”
U Yesu abhawozya heka, ayanga, “Jipelaji umoyo! Nene! mugajihogope.”
28 Peteru sì ké sí i pé, “Olúwa, bí ó bá jẹ́ pé ìwọ ni nítòótọ́, sọ pé kí n tọ̀ ọ́ wà lórí omi.”
U Petro anjibu whayanje, “Gosi, nkesho wewe, mbozye enenze huliwe pamwanya yimenze.”
29 Jesu dá a lóhùn pé, “Ó dára, máa bọ̀ wá.” Nígbà náà ni Peteru sọ̀kalẹ̀ láti inú ọkọ̀. Ó ń rìn lórí omi lọ sí ìhà ọ̀dọ̀ Jesu.
U Yesu ayanga, “Enza.” Esho Upetro afuma mukasi yimashua na ajenda pamwanya yimenze abhale wha Yesu.
30 Nígbà tí ó rí afẹ́fẹ́ líle, ẹ̀rù bà á, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í rì. Ó kígbe lóhùn rara pé, “Gbà mí, Olúwa.”
Ila u Petro lwalola amawimbi, ahogope, na whande adwine, pansi, akwizya husauti nayanje, “Gosi, nokole!”
31 Lójúkan náà, Jesu na ọwọ́ rẹ̀, ó dìímú, ó sì gbà á. Ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ṣiyèméjì ìwọ onígbàgbọ́ kékeré?”
Digana Yesu anyosya inyobhe yakwe amosya u Petro, na humozye, “Awe wilweteho udodo, yenu ulinamashaka?”
32 Àti pé, nígbà ti wọ́n sì gòkè sínú ọkọ̀, ìjì náà sì dúró jẹ́ẹ́.
Epo u Yesu nu Petro bhahinjiye mumashua, inkongu yaleshile avugule.
33 Nígbà náà ni àwọn to wà nínú ọkọ̀ náà foríbalẹ̀ fún un wọ́n wí pé, “Nítòótọ́ Ọmọ Ọlọ́run ni ìwọ í ṣe.”
Abhanafunzi mmashua bhansayile u Yesu na yanje, “Lyoli awe wamwana wa Ngolobhi.”
34 Nígbà tí wọn rékọjá sí apá kejì wọ́n gúnlẹ̀ sí Genesareti.
Na lwabhafwemela, bhafishile panse yi Genesareti.
35 Nígbà tiwọn mọ̀ pé Jesu ni, wọn sì ránṣẹ́ sí gbogbo ìlú náà yíká. Wọ́n sì gbé gbogbo àwọn aláìsàn tọ̀ ọ́ wá.
Na bhantu bhi sehemu ela lwabhamanya u Yesu, bhatumile uujumbe kila sehemu zipembeni nahunete kila wabhinile.
36 Àwọn aláìsàn bẹ̀ ẹ́ pé kí ó gba àwọn láyè láti fi ọwọ́ kan ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀, gbogbo àwọn tí ó ṣe bẹ́ẹ̀ sì rí ìwòsàn.
Bhamozezye aje bhawezye aguse ikunjo limwenda gwakwe, na bhinji bhabhagubile bhaponilwe.

< Matthew 14 >