< Matthew 14 >

1 Ní àkókò náà ni Herodu ọba tetrarki gbọ́ nípa òkìkí Jesu,
W on czas usłyszał Herod Tetrarcha, wieść o Jezusie.
2 ó wí fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Dájúdájú Johanu onítẹ̀bọmi ni èyí, ó jíǹde kúrò nínú òkú. Ìdí nìyí tí ó fi ní agbára láti ṣiṣẹ́ ìyanu wọ̀nyí.”
I rzekł sługom swoim: Tenci jest Jan Chrzciciel; on to zmartwychwstał, i dlatego się cuda przez niego dzieją.
3 Nísinsin yìí Herodu ti mú Johanu, ó fi ẹ̀wọ̀n dè é, ó sì fi sínú túbú, nítorí Herodia aya Filipi arákùnrin rẹ̀,
Albowiem Herod pojmawszy Jana, związał go był i wsadził do więzienia dla Herodyjady, żony Filipa, brata swego.
4 nítorí Johanu onítẹ̀bọmi ti sọ fún Herodu pé, “Kò yẹ fún ọ láti fẹ́ obìnrin náà.”
Bo mu Jan mówił: Nie godzi ci się jej mieć.
5 Herodu fẹ́ pa Johanu, ṣùgbọ́n ó bẹ̀rù àwọn ènìyàn nítorí gbogbo ènìyàn gbàgbọ́ pé wòlíì ni.
Ale gdy go on chciał zabić, bał się ludu: albowiem go za proroka mieli.
6 Ní ọjọ́ àsè ìrántí ọjọ́ ìbí Herodu, ọmọ Herodia obìnrin jó dáradára, ó sì tẹ́ Herodu lọ́run gidigidi.
Gdy tedy obchodzono dzień narodzenia Herodowego, tańcowała córka Herodyjady w pośrodku gości, i podobała się Herodowi.
7 Nítorí náà ni ó ṣe fi ìbúra ṣe ìlérí láti fún un ní ohunkóhun ti ó bá béèrè fún.
Skąd pod przysięgą obiecał jej dać, czegobykolwiek żądała.
8 Pẹ̀lú ìmọ̀ràn láti ọ̀dọ̀ ìyá rẹ̀, ó béèrè pé, “Fún mi ni orí Johanu onítẹ̀bọmi nínú àwopọ̀kọ́”.
A ona przedtem będąc naprawiona od matki swojej, rzekła: Daj mi tu na misie głowę Jana Chrzciciela.
9 Inú ọba bàjẹ́ gidigidi, ṣùgbọ́n nítorí ìbúra rẹ̀ àti kí ojú má ba à tì í níwájú àwọn àlejò tó wà ba jẹ àsè, ó pàṣẹ pé kí wọ́n fún un gẹ́gẹ́ bí o ti fẹ́.
I zasmucił się król; ale dla przysięgi i dla spółsiedzących kazał jej dać.
10 Nítorí náà, a bẹ́ orí Johanu onítẹ̀bọmi nínú ilé túbú.
A posławszy kata, ściął Jana w więzieniu.
11 A sì gbé orí rẹ̀ jáde láti fi fún ọmọbìnrin náà nínú àwopọ̀kọ́, òun sì gbà á, ó gbé e tọ ìyá rẹ̀ lọ.
I przyniesiono głowę jego na misie, i oddano dzieweczce, i odniosła ją matce swojej.
12 Lẹ́yìn náà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu wá gba òkú rẹ̀, wọ́n sì sin ín. Wọ́n sì wá sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún Jesu.
A przyszedłszy uczniowie jego wzięli ciało i pogrzebli je, a szedłszy powiedzieli Jezusowi.
13 Nígbà tí Jesu gbọ́ ìròyìn ìṣẹ̀lẹ̀ náà, ó kúrò níbẹ̀, ó bá ọkọ̀ ojú omi lọ sí ibi kọ́lọ́fín kan ní èbúté láti dá wà níbẹ̀. Nígbà tí wọ́n gbọ́ èyí, ọ̀pọ̀ ènìyàn sì fi ẹsẹ̀ rìn tẹ̀lé e láti ọ̀pọ̀ ìlú wọn.
To usłyszawszy Jezus, ustąpił stamtąd w łodzi na miejsce puste osobno; a usłyszawszy lud, szli za nim z miast pieszo.
14 Nígbà ti Jesu gúnlẹ̀, tí ó sì rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, inú rẹ̀ yọ́ sí wọn, ó sì mú àwọn aláìsàn láradá.
Wyszedłszy tedy Jezus ujrzał wielki lud, i użalił się ich, a uzdrawiał chore ich.
15 Nígbà ti ilẹ̀ ń ṣú lọ, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì wí pé, “Ibi yìí jìnnà sí ìlú ilẹ̀ sì ń ṣú lọ. Rán àwọn ènìyàn lọ sí àwọn ìletò kí wọ́n lè ra oúnjẹ jẹ.”
A gdy nadchodził wieczór, przystąpili do niego uczniowie jego, mówiąc: Puste jest to miejsce, a czas już przeminął; rozpuść ten lud, aby odszedłszy do miasteczek, kupili sobie żywności.
16 Ṣùgbọ́n Jesu fèsì pé, “Kò nílò kí wọ́n lọ kúrò. Ẹ fún wọn ní oúnjẹ.”
A Jezus im rzekł: Nie potrzeba im odchodzić, dajcie wy im co jeść.
17 Wọ́n sì dalóhùn pé, “Àwa kò ní ju ìṣù àkàrà márùn-ún àti ẹja méjì lọ níhìn-ín.”
Ale mu oni rzekli: Nie mamy tu, tylko pięć chlebów i dwie ryby.
18 Ó wí pé, “Ẹ mú wọn wá fún mi níhìn-ín yìí.”
A on rzekł: Przynieście mi je tu.
19 Lẹ́yìn náà, ó wí fún àwọn ènìyàn kí wọ́n jókòó lórí koríko. Lẹ́yìn náà, ó mú ìṣù àkàrà márùn-ún àti ẹja méjì. Ó gbé ojú rẹ̀ sí ọ̀run. Ó béèrè ìbùkún Ọlọ́run lórí oúnjẹ náà, Ó sì bù ú, ó sì fi àkàrà náà fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn láti pín in fún àwọn ènìyàn.
I rozkazawszy ludowi usiąść na trawie, wziął onych pięć chlebów i dwie ryby, a wejrzawszy w niebo, błogosławił, a łamiąc dawał uczniom chleby, a uczniowie ludowi.
20 Gbogbo wọn sì jẹ àjẹyó. Lẹ́yìn náà àwọn ọmọ-ẹ̀yìn kó àjẹkù jọ, ó kún agbọ̀n méjìlá.
I jedli wszyscy, a nasyceni byli; i zebrali, co zbywało ułomków, dwanaście koszów pełnych.
21 Iye àwọn ènìyàn ni ọjọ́ náà jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ọkùnrin, láìka àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé.
A tych, którzy jedli, było około pięciu tysięcy mężów, oprócz niewiast i dziatek.
22 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ lẹ́yìn èyí, Jesu wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kí wọ́n bọ sínú ọkọ̀ wọn, àti kí wọ́n máa kọjá lọ ṣáájú rẹ̀ sí òdìkejì. Òun náà dúró lẹ́yìn láti tú àwọn ènìyàn ká lọ sí ilé wọn.
A wnetże przymusił Jezus uczniów swoich, aby wstąpili w łódź, i uprzedzili go na drugą stronę, ażby rozpuścił lud.
23 Lẹ́yìn tí ó tú ìjọ ènìyàn ká tán, ó gun orí òkè lọ fúnra rẹ̀ láti lọ gba àdúrà. Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, òun wà nìkan níbẹ̀,
A rozpuściwszy lud, wstąpił na górę z osobna, aby się modlił; a gdy był wieczór, sam tam był.
24 ní àkókò yìí ọkọ̀ ojú omi náà ti rin jìnnà sí etí bèbè Òkun, tí ìjì omi ń tì í síwá sẹ́yìn, nítorí ìjì ṣe ọwọ́ òdì sí wọn.
A łódź już w pośrodku morza będąc, miotana była od wałów; albowiem był wiatr przeciwny.
25 Ní déédé ago mẹ́rin òwúrọ̀, Jesu tọ̀ wọ́n wá, ó ń rìn lórí omi.
Lecz o czwartej straży nocnej szedł do nich Jezus, chodząc po morzu.
26 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rí i tí ó ń rìn lójú omi, ẹ̀rù ba wọn gidigidi, wọ́n rò pé “iwin ni,” wọ́n kígbe tìbẹ̀rù tìbẹ̀rù.
A ujrzawszy go uczniowie po morzu chodzącego, zatrwożyli się, mówiąc: Obłuda to jest! i od bojaźni krzyknęli.
27 Lójúkan náà, Jesu wí fún wọn pé, “Ẹ mú ọkàn le! Èmi ni ẹ má ṣe bẹ̀rù.”
Lecz wnet rzekł do nich Jezus, mówiąc: Ufajcie! Jam ci to jest; nie bójcie się.
28 Peteru sì ké sí i pé, “Olúwa, bí ó bá jẹ́ pé ìwọ ni nítòótọ́, sọ pé kí n tọ̀ ọ́ wà lórí omi.”
A odpowiadając mu Piotr rzekł: Panie! Jeźliżeś ty jest, każ mi przyjść do ciebie po wodzie.
29 Jesu dá a lóhùn pé, “Ó dára, máa bọ̀ wá.” Nígbà náà ni Peteru sọ̀kalẹ̀ láti inú ọkọ̀. Ó ń rìn lórí omi lọ sí ìhà ọ̀dọ̀ Jesu.
A on rzekł: Pójdź! A Piotr, wystąpiwszy z łodzi, szedł po wodzie, aby przyszedł do Jezusa;
30 Nígbà tí ó rí afẹ́fẹ́ líle, ẹ̀rù bà á, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í rì. Ó kígbe lóhùn rara pé, “Gbà mí, Olúwa.”
Ale widząc wiatr gwałtowny, zląkł się; a gdy począł tonąć, zakrzyknął, mówiąc: Panie, ratuj mię!
31 Lójúkan náà, Jesu na ọwọ́ rẹ̀, ó dìímú, ó sì gbà á. Ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ṣiyèméjì ìwọ onígbàgbọ́ kékeré?”
A Jezus zaraz wyciągnąwszy rękę, uchwycił go i rzekł mu: O małowierny! przeczżeś wątpił?
32 Àti pé, nígbà ti wọ́n sì gòkè sínú ọkọ̀, ìjì náà sì dúró jẹ́ẹ́.
A gdy oni wstąpili w łódź, uciszył się wiatr.
33 Nígbà náà ni àwọn to wà nínú ọkọ̀ náà foríbalẹ̀ fún un wọ́n wí pé, “Nítòótọ́ Ọmọ Ọlọ́run ni ìwọ í ṣe.”
A ci, którzy byli w łodzi, przystąpiwszy pokłonili mu się, mówiąc: Prawdziwie jesteś Synem Bożym.
34 Nígbà tí wọn rékọjá sí apá kejì wọ́n gúnlẹ̀ sí Genesareti.
I przeprawiwszy się, przyszli do ziemi Gienezaret.
35 Nígbà tiwọn mọ̀ pé Jesu ni, wọn sì ránṣẹ́ sí gbogbo ìlú náà yíká. Wọ́n sì gbé gbogbo àwọn aláìsàn tọ̀ ọ́ wá.
A poznawszy go mężowie miejsca onego, posłali do wszystkiej onej okolicznej krainy; i przyniesiono do niego wszystkie, którzy się źle mieli.
36 Àwọn aláìsàn bẹ̀ ẹ́ pé kí ó gba àwọn láyè láti fi ọwọ́ kan ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀, gbogbo àwọn tí ó ṣe bẹ́ẹ̀ sì rí ìwòsàn.
I prosili go, aby się tylko podołku szaty jego dotykali; a którzykolwiek się dotknęli, uzdrowieni są.

< Matthew 14 >