< Matthew 14 >
1 Ní àkókò náà ni Herodu ọba tetrarki gbọ́ nípa òkìkí Jesu,
I taua wa ka rongo a Herora te tetaraki ki te rongo o Ihu,
2 ó wí fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Dájúdájú Johanu onítẹ̀bọmi ni èyí, ó jíǹde kúrò nínú òkú. Ìdí nìyí tí ó fi ní agbára láti ṣiṣẹ́ ìyanu wọ̀nyí.”
A ka mea ki ana pononga, Ko Hoani Kaiiriiri tenei; kua ara mai ia i te hunga mate; a na reira i mahi ai nga merekara i roto i a ia.
3 Nísinsin yìí Herodu ti mú Johanu, ó fi ẹ̀wọ̀n dè é, ó sì fi sínú túbú, nítorí Herodia aya Filipi arákùnrin rẹ̀,
I hopukia hoki a Hoani e Herora, a hereherea ana e ia, a maka ana ki te whare herehere, he mea hoki na Heroriaha, na te wahine a tona tuakana, a Piripi.
4 nítorí Johanu onítẹ̀bọmi ti sọ fún Herodu pé, “Kò yẹ fún ọ láti fẹ́ obìnrin náà.”
I mea hoki a Hoani ki a ia, E kore e tika kia riro ia i a koe.
5 Herodu fẹ́ pa Johanu, ṣùgbọ́n ó bẹ̀rù àwọn ènìyàn nítorí gbogbo ènìyàn gbàgbọ́ pé wòlíì ni.
A, i a ia e mea ana ki te whakamate i a ia, ka wehi i te mano; ki ta ratou hoki he poropiti ia.
6 Ní ọjọ́ àsè ìrántí ọjọ́ ìbí Herodu, ọmọ Herodia obìnrin jó dáradára, ó sì tẹ́ Herodu lọ́run gidigidi.
Otira i te taenga ki te ra whanau o Herora, ka kanikani te tamahine a Heroriaha i waenganui i a ratou, a ka ahuareka a Herora.
7 Nítorí náà ni ó ṣe fi ìbúra ṣe ìlérí láti fún un ní ohunkóhun ti ó bá béèrè fún.
Katahi ia ka mea ki a ia, oati rawa, kia hoatu ki a ia tana mea e tono ai.
8 Pẹ̀lú ìmọ̀ràn láti ọ̀dọ̀ ìyá rẹ̀, ó béèrè pé, “Fún mi ni orí Johanu onítẹ̀bọmi nínú àwopọ̀kọ́”.
Na, he mea whakakiki ia na tona whaea, ka mea, Homai ki konei ki ahau i runga i te rihi te matenga o Hoani Kaiiriiri.
9 Inú ọba bàjẹ́ gidigidi, ṣùgbọ́n nítorí ìbúra rẹ̀ àti kí ojú má ba à tì í níwájú àwọn àlejò tó wà ba jẹ àsè, ó pàṣẹ pé kí wọ́n fún un gẹ́gẹ́ bí o ti fẹ́.
Heoi ka pouri te kingi: otiia i whakaaro ia ki te oati, ki te hunga hoki e noho tahi ana me ia, a ka mea kia hoatu.
10 Nítorí náà, a bẹ́ orí Johanu onítẹ̀bọmi nínú ilé túbú.
Na ka tono tangata ia, a poutoa ana te matenga o Hoani i roto i te whare herehere.
11 A sì gbé orí rẹ̀ jáde láti fi fún ọmọbìnrin náà nínú àwopọ̀kọ́, òun sì gbà á, ó gbé e tọ ìyá rẹ̀ lọ.
A i mauria tona matenga i runga i te rihi, i hoatu ki te kotiro: kawea atu ana e ia ki tona whaea.
12 Lẹ́yìn náà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu wá gba òkú rẹ̀, wọ́n sì sin ín. Wọ́n sì wá sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún Jesu.
Na ka haere ana akonga, ka tango i te tinana, a tanumia ana e ratou, a haere ana, korero ana ki a Ihu.
13 Nígbà tí Jesu gbọ́ ìròyìn ìṣẹ̀lẹ̀ náà, ó kúrò níbẹ̀, ó bá ọkọ̀ ojú omi lọ sí ibi kọ́lọ́fín kan ní èbúté láti dá wà níbẹ̀. Nígbà tí wọ́n gbọ́ èyí, ọ̀pọ̀ ènìyàn sì fi ẹsẹ̀ rìn tẹ̀lé e láti ọ̀pọ̀ ìlú wọn.
Na, i te rongonga o Ihu, ka haere atu ia i reira ra te kaipuke ki te koraha, ki te wahi motu ke: a, no ka rongo te mano, ka aru i a ia ra uta i roto i nga pa.
14 Nígbà ti Jesu gúnlẹ̀, tí ó sì rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, inú rẹ̀ yọ́ sí wọn, ó sì mú àwọn aláìsàn láradá.
A ka puta atu a Ihu, ka kite i te huihuinga nui, ka aroha ia ki a ratou, a whakaorangia ana e ia o ratou turoro.
15 Nígbà ti ilẹ̀ ń ṣú lọ, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì wí pé, “Ibi yìí jìnnà sí ìlú ilẹ̀ sì ń ṣú lọ. Rán àwọn ènìyàn lọ sí àwọn ìletò kí wọ́n lè ra oúnjẹ jẹ.”
A, no ka ahiahi, ka haere atu ana akonga ki a ia, ka mea, He wahi koraha tenei, kua heke noa atu te ra; tonoa atu te mano, kia haere ai ratou ki nga kainga ki te hoko kai ma ratou.
16 Ṣùgbọ́n Jesu fèsì pé, “Kò nílò kí wọ́n lọ kúrò. Ẹ fún wọn ní oúnjẹ.”
Ano ra ko Ihu ki a ratou, Kahore he mea e haere ai ratou; ma koutou e hoatu he kai ma ratou.
17 Wọ́n sì dalóhùn pé, “Àwa kò ní ju ìṣù àkàrà márùn-ún àti ẹja méjì lọ níhìn-ín.”
Ka mea ratou ki a ia, Heoi ano a matou i konei, e rima nga taro, e rua hoki nga ika.
18 Ó wí pé, “Ẹ mú wọn wá fún mi níhìn-ín yìí.”
Na ka mea ia, Mauria mai ki konei ki ahau.
19 Lẹ́yìn náà, ó wí fún àwọn ènìyàn kí wọ́n jókòó lórí koríko. Lẹ́yìn náà, ó mú ìṣù àkàrà márùn-ún àti ẹja méjì. Ó gbé ojú rẹ̀ sí ọ̀run. Ó béèrè ìbùkún Ọlọ́run lórí oúnjẹ náà, Ó sì bù ú, ó sì fi àkàrà náà fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn láti pín in fún àwọn ènìyàn.
Na ka mea ia ki te mano kia noho ki runga i te tarutaru, ka mau i nga taro e rima, i nga ika hoki e rua, ka titiro ki runga ki te rangi, ka whakapai, ka whawhati, a hoatu ana e ia nga taro ki nga akonga, a na nga akonga ki te mano.
20 Gbogbo wọn sì jẹ àjẹyó. Lẹ́yìn náà àwọn ọmọ-ẹ̀yìn kó àjẹkù jọ, ó kún agbọ̀n méjìlá.
A kai katoa ana ratou, a ka makona: a kotahi tekau ma rua nga kete i kohia ake e ratou, ki tonu i nga whatiwhatinga i toe.
21 Iye àwọn ènìyàn ni ọjọ́ náà jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ọkùnrin, láìka àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé.
Ko te hunga i kai ra me te mea e rima mano nga tane, haunga nga wahine me nga tamariki.
22 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ lẹ́yìn èyí, Jesu wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kí wọ́n bọ sínú ọkọ̀ wọn, àti kí wọ́n máa kọjá lọ ṣáájú rẹ̀ sí òdìkejì. Òun náà dúró lẹ́yìn láti tú àwọn ènìyàn ká lọ sí ilé wọn.
Na akiaki tonu a Ihu i ana akonga kia eke ki te kaipuke, kia whakawhiti i mua i a ia ki tawahi, i a ia e tuku ana i nga mano kia haere.
23 Lẹ́yìn tí ó tú ìjọ ènìyàn ká tán, ó gun orí òkè lọ fúnra rẹ̀ láti lọ gba àdúrà. Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, òun wà nìkan níbẹ̀,
A, ka oti te mano te tuku, ka kake ia ki runga ki te maunga ki te wahi motu ke ki te inoi: na kua ahiahi, a ko ia anake i reira.
24 ní àkókò yìí ọkọ̀ ojú omi náà ti rin jìnnà sí etí bèbè Òkun, tí ìjì omi ń tì í síwá sẹ́yìn, nítorí ìjì ṣe ọwọ́ òdì sí wọn.
Na, tera te kaipuke te akina ra e te ngaru i waenga moana: i he hoki te hau.
25 Ní déédé ago mẹ́rin òwúrọ̀, Jesu tọ̀ wọ́n wá, ó ń rìn lórí omi.
A i te wha o nga mataaratanga o te po ka haere a Ihu ki a ratou, i haere maori i runga i te moana.
26 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rí i tí ó ń rìn lójú omi, ẹ̀rù ba wọn gidigidi, wọ́n rò pé “iwin ni,” wọ́n kígbe tìbẹ̀rù tìbẹ̀rù.
A, i te kitenga o nga akonga i a ia e haere ana i runga i te moana, ka ihiihi, ka mea, He wairua; ka aue i te wehi.
27 Lójúkan náà, Jesu wí fún wọn pé, “Ẹ mú ọkàn le! Èmi ni ẹ má ṣe bẹ̀rù.”
Na kua hohoro te korero a Ihu ki a ratou, te mea, Kia manawanui, ko ahau tenei; aua e wehi.
28 Peteru sì ké sí i pé, “Olúwa, bí ó bá jẹ́ pé ìwọ ni nítòótọ́, sọ pé kí n tọ̀ ọ́ wà lórí omi.”
Na ka whakahoki a Pita ki a ia, ka mea, E te Ariki, ki te mea ko koe tena, kiia mai ahau kia haere atu ki a koe i runga i te wai.
29 Jesu dá a lóhùn pé, “Ó dára, máa bọ̀ wá.” Nígbà náà ni Peteru sọ̀kalẹ̀ láti inú ọkọ̀. Ó ń rìn lórí omi lọ sí ìhà ọ̀dọ̀ Jesu.
Na ka mea ia, Haere mai. A ka marere atu a Pita i te kaipuke, ka haere i runga i te wai, kia tae ai ki a Ihu.
30 Nígbà tí ó rí afẹ́fẹ́ líle, ẹ̀rù bà á, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í rì. Ó kígbe lóhùn rara pé, “Gbà mí, Olúwa.”
Otira ka kite ia i te hau e kaha ana, ka wehi; a ka timata te totohu, ka karanga ake, ka mea, Ahau, e te Ariki, whakaorangia.
31 Lójúkan náà, Jesu na ọwọ́ rẹ̀, ó dìímú, ó sì gbà á. Ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ṣiyèméjì ìwọ onígbàgbọ́ kékeré?”
Hohoro tonu te totoro o te ringa o Ihu, ka hopu i a ia, ka mea ki a ia, E te tangata whakapono iti, he aha koe i ngakau rua ai?
32 Àti pé, nígbà ti wọ́n sì gòkè sínú ọkọ̀, ìjì náà sì dúró jẹ́ẹ́.
Ano ka eke raua ki te kaipuke, mutu pu te hau.
33 Nígbà náà ni àwọn to wà nínú ọkọ̀ náà foríbalẹ̀ fún un wọ́n wí pé, “Nítòótọ́ Ọmọ Ọlọ́run ni ìwọ í ṣe.”
Na ka haere mai te hunga i runga i te kaipuke, ka koropiko ki a ia, ka mea, He pono ko te Tama koe a te Atua.
34 Nígbà tí wọn rékọjá sí apá kejì wọ́n gúnlẹ̀ sí Genesareti.
A, i to ratou whitinga atu, ka tae ki te whenua o Kenehareta.
35 Nígbà tiwọn mọ̀ pé Jesu ni, wọn sì ránṣẹ́ sí gbogbo ìlú náà yíká. Wọ́n sì gbé gbogbo àwọn aláìsàn tọ̀ ọ́ wá.
A, ka mohio nga tangata o taua wahi ki a ia, ka tono tangata puta noa i nga wahi tutata katoa o reira, hei kawe mai i nga turoro katoa ki a ia;
36 Àwọn aláìsàn bẹ̀ ẹ́ pé kí ó gba àwọn láyè láti fi ọwọ́ kan ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀, gbogbo àwọn tí ó ṣe bẹ́ẹ̀ sì rí ìwòsàn.
Ka inoi ki a ia kia pa kau ratou ki te taniko o tona kakahu; a ora ake nga tangata katoa i pa.