< Matthew 13 >

1 Ní ọjọ́ kan náà, Jesu kúrò ní ilé, ó jókòó sí etí Òkun.
Azon a napon kiment Jézus a házból, és leült a tenger mellett.
2 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn péjọ sọ́dọ̀ rẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi bọ́ sínú ọkọ̀ ojú omi, ó jókòó, gbogbo ènìyàn sì dúró létí Òkun.
Nagy sokaság gyűlt köréje, akkora, hogy bement a hajóba leülni, az egész sokaság pedig a parton állt.
3 Nígbà náà ni ó fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ òwe bá wọn sọ̀rọ̀, wí pé, “Àgbẹ̀ kan jáde lọ gbin irúgbìn sínú oko rẹ̀.
Sokat beszélt nekik példázatokban: „Íme, kiment a magvető vetni,
4 Bí ó sì ti gbin irúgbìn náà, díẹ̀ bọ́ sí ẹ̀bá ọ̀nà, àwọn ẹyẹ sì wá, wọ́n sì jẹ ẹ́.
és amikor vetett, némely mag az útszélre esett, s jöttek a madarak, felkapdosták azt.
5 Díẹ̀ bọ́ sórí ilẹ̀ orí àpáta, níbi ti kò sí erùpẹ̀ púpọ̀. Àwọn irúgbìn náà sì dàgbàsókè kíákíá, nítorí erùpẹ̀ kò pọ̀ lórí wọn.
Némely pedig a köves helyre esett, ahol nem sok föld volt, és hamar kikelt, mivel nem volt mélyen a földben.
6 Ṣùgbọ́n nígbà tí oòrùn gòkè, oòrùn gbígbóná jó wọn, gbogbo wọn sì rọ, wọ́n kú nítorí wọn kò ni gbòǹgbò.
De amikor a nap felkelt, kiégett, és mivel nem volt gyökere, elszáradt.
7 Àwọn irúgbìn mìíràn bọ́ sí àárín ẹ̀gún, ẹ̀gún sì dàgbà, ó sì fún wọn pa.
Némelyek pedig tövisek közé estek, és a tövisek fölnövekedve megfojtották azt.
8 Ṣùgbọ́n díẹ̀ tó bọ́ sórí ilẹ̀ rere, ó sì so èso, òmíràn ọgọ́rùn-ún, òmíràn ọgọ́tọ̀ọ̀ta, òmíràn ọgbọọgbọ̀n, ni ìlọ́po èyí ti ó gbìn.
Némely pedig a jó földbe esett, és gyümölcsöt termett, némely százannyit, némely hatvanannyit, némely pedig harmincannyit.
9 Ẹni tí ó bá létí, kí ó gbọ́.”
Akinek van füle a hallásra, hallja meg!“
10 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n bí i pé, “Èéṣe tí ìwọ ń fi òwe bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀?”
A tanítványok odamentek hozzá, és ezt mondták neki: „Miért beszélsz hozzájuk példázatokban?“
11 Ó sì da wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin ni a ti fi fún láti mọ ohun ìjìnlẹ̀ ìjọba ọ̀run, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún wọn.
Ő pedig ezt felelte nekik: „Azért, mert nektek megadatott, hogy megértsétek a mennyek országának titkait, őnekik pedig nem adatott meg.
12 Ẹnikẹ́ni tí ó ní, òun ni a ó fún sí i, yóò sì ní lọ́pọ̀lọ́pọ̀. Ṣùgbọ́n lọ́wọ́ ẹni tí kò ní, ni a ó ti gbà èyí kékeré tí ó ní náà.
Mert akinek van, annak adatik, és bővölködik, de akinek nincs, attól az is elvétetik, amije van.
13 Ìdí nìyìí tí mo fi ń fi òwe bá wọn sọ̀rọ̀: “Ní ti rí rí, wọn kò rí; ní ti gbígbọ́ wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò sì yé wọn.
Azért szólok nekik példázatokban, mert látván nem látnak, és hallván nem hallanak, sem nem értenek.
14 Sí ara wọn ni a ti mú àsọtẹ́lẹ̀ wòlíì Isaiah ṣẹ: “‘Ní gbígbọ́ ẹ̀yin yóò gbọ́ ṣùgbọ́n kì yóò sì yé yín; ní rí rí ẹ̀yin yóò rí, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kì yóò sì mòye.
És beteljesedik rajtuk Ézsaiás jövendölése, amely ezt mondja: »Hallván halljatok, és ne értsetek, és látván lássatok, és ne ismerjetek!
15 Nítorí àyà àwọn ènìyàn yìí sébọ́ etí wọn sì wúwo láti gbọ́ ojú wọn ni wọ́n sì dì nítorí kí àwọn má ba à fi ojú wọn rí kí wọ́n má ba à fi etí wọn gbọ́ kí wọn má ba à fi àyà wọn mọ̀ òye, kí wọn má ba à yípadà, kí èmi ba à le mú wọn láradá.’
Mert megkövéredett e nép szíve, füleikkel nehezen hallottak, és szemeiket behunyták, hogy valami módon ne lássanak szemeikkel, ne halljanak füleikkel, és ne értsenek szívükkel, és meg ne térjenek, és meg ne gyógyítsam őket.«
16 Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ojú yín, nítorí wọ́n ríran, àti fún etí yín, nítorí ti wọ́n gbọ́.
A ti szemeitek boldogok, hogy látnak, és a ti füleitek, hogy hallanak.
17 Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì àti ènìyàn Ọlọ́run ti fẹ́ rí ohun tí ẹ̀yin ti rí, ki wọ́n sì gbọ́ ohun tí ẹ ti gbọ́, ṣùgbọ́n kò ṣe é ṣe fún wọn.
Mert bizony mondom néktek, hogy sok próféta és igaz kívánta látni, amiket ti láttok, és nem látták, és hallani, amiket ti hallotok, és nem hallották.
18 “Nítorí náà, ẹ fi etí sí ohun tí òwe afúnrúgbìn túmọ̀ sí,
Ti tehát halljátok meg a magvető példázatát!
19 nígbà tí ẹnikẹ́ni bá gbọ́ ọ̀rọ̀ nípa ìjọba ọ̀run ṣùgbọ́n tí kò yé e, lẹ́yìn náà èṣù á wá, a sì gba èyí tí a fún sí ọkàn rẹ̀ kúrò. Èyí ni irúgbìn ti a fún sí ẹ̀bá ọ̀nà.
Ha valaki hallja az igét a mennyeknek országáról, és nem érti, eljön a gonosz, és elkapja azt, ami az ő szívébe van elvetve. Ez az, amelyik az útfélre esett.
20 Ẹni tí ó sì gba irúgbìn tí ó bọ́ sí ilẹ̀ orí àpáta, ni ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà, lọ́gán, ó sì fi ayọ̀ gba ọ̀rọ̀ náà.
Amelyik pedig a köves helyre esett, az az, aki hallja az igét, és mindjárt örömmel fogadja,
21 Ṣùgbọ́n nítorí kò ní gbòǹgbò, ó wà fún ìgbà díẹ̀; nígbà tí wàhálà àti inúnibíni bá dìde nítorí ọ̀rọ̀ náà ní ojú kan náà yóò sì kọsẹ̀.
de nincs gyökere benne, hanem csak ideigvaló, mihelyst pedig nyomorgatás vagy üldözés támad az ige miatt, azonnal megbotránkozik.
22 Ẹni tí ó si gba irúgbìn tí ó bọ́ sí àárín ẹ̀gún ni ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà, ṣùgbọ́n àwọn àníyàn ayé yìí, ìtànjẹ, ọrọ̀ sì fún ọ̀rọ̀ náà pa, ọ̀rọ̀ náà kò so èso nínú rẹ̀. (aiōn g165)
Amelyik pedig a tövisek közé esett, az az, aki hallja az igét, de a világnak gondja és a gazdagságnak csalárdsága elfojtja az igét, és nem terem gyümölcsöt. (aiōn g165)
23 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó gba irúgbìn tí ó bọ́ sí orí ilẹ̀ rere ni ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà, tí ó sì yé e; òun sì so èso òmíràn ọgọ́rọ̀ọ̀rùn, òmíràn ọgọ́tọ̀ọ̀ta, òmíràn ọgbọọgbọ̀n.”
Amely pedig a jó földbe esett, az az, aki hallja is, és érti is az igét, gyümölcsöt is terem, némelyik százannyit, némelyik hatvanannyit, némelyik pedig harmincannyit.“
24 Jesu tún pa òwe mìíràn fún wọn: “Ìjọba ọ̀run dàbí àgbẹ̀ kan tí ó gbin irúgbìn rere sí oko rẹ̀,
Más példázatot is mondott nekik: „Hasonlatos a mennyek országa ahhoz az emberhez, aki földjébe jó magot vetett.
25 ṣùgbọ́n ní òru ọjọ́ kan, nígbà tí ó sùn, ọ̀tá rẹ̀ wá sí oko náà ó sì gbin èpò sáàrín alikama, ó sì bá tirẹ̀ lọ.
De amikor az emberek aludtak, eljött az ellensége, konkolyt vetett a búza közé, és elment.
26 Nígbà tí alikama náà bẹ̀rẹ̀ sí dàgbà, tí ó sì so èso, nígbà náà ni èpò náà fi ara hàn.
Amikor pedig felnövekedett a vetés, és gyümölcsöt termett, akkor meglátszott a konkoly is.
27 “Àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ àgbẹ̀ náà wá, wọ́n sọ fún un pé, ‘Ọ̀gá, irúgbìn rere kọ́ ni ìwọ ha gbìn sí oko rẹ nì? Báwo ni èpò ṣe wà níbẹ̀ nígbà náà?’
A gazda szolgái ekkor odamentek hozzá, és ezt mondták neki: Uram, nem tiszta magot vetettél földedbe? Honnan van benne a konkoly?
28 “Ó sọ fún wọn pé, ‘Ọ̀tá ni ó ṣe èyí.’ “Àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tún bí i pé, ‘Ǹjẹ́ ìwọ ha fẹ́ kí a fa èpò náà tu kúrò?’
Ő pedig ezt mondta nekik: Valamelyik ellenség cselekedte azt. A szolgái ezt mondták neki: Akarod-e, hogy elmenjünk, és összeszedjük a konkolyt?
29 “Ó dá wọn lóhùn pé, ‘Rárá, nítorí bí ẹ̀yin bá ń tu èpò kúrò, ẹ ó tu alikama dànù pẹ̀lú rẹ̀.
Ő pedig azt mondta: Nem. Mert amikor összeszeditek a konkolyt, azzal együtt talán a búzát is kiszaggatjátok.
30 Ẹ jẹ́ kí àwọn méjèèjì máa dàgbà pọ̀, títí di àsìkò ìkórè. Èmi yóò sọ fún àwọn olùkórè náà láti kọ́kọ́ ṣa àwọn èpò kúrò kí wọ́n sì dìwọ́n ní ìtí, kí a sì sun wọn, kí wọ́n sì kó alikama sínú àká mi.’”
Hagyjátok, hogy együtt nőjön mindkettő az aratásig, és az aratás idején azt mondom majd az aratóknak: Szedjétek össze először a konkolyt, és kössétek kévébe, hogy elégessétek; a búzát pedig takarítsátok be csűrömbe.“
31 Jesu tún pa òwe mìíràn fún wọn: “Ìjọba ọ̀run dàbí èso hóró musitadi, èyí tí ọkùnrin kan mú tí ó gbìn sínú oko rẹ̀.
Más példázatot is mondott nekik: „Hasonlatos a mennyeknek országa a mustármaghoz, melyet fog az ember, és elvet a mezejébe.
32 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ èso tí ó kéré púpọ̀ láàrín èso rẹ̀, síbẹ̀ ó wá di ohun ọ̀gbìn tí ó tóbi jọjọ. Ó sì wá di igi tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì wá, wọ́n sì fi ẹ̀ka rẹ ṣe ibùgbé.”
Az kisebb ugyan minden magnál, de amikor felnő, nagyobb a veteményeknél, és fává lesz, úgyhogy reá szállnak az égi madarak, és fészket raknak ágain.“
33 Ó tún pa òwe mìíràn fún wọn: “Ìjọba ọ̀run dàbí ìwúkàrà tí obìnrin kan mú tí ó pò mọ́ ìyẹ̀fun púpọ̀ títí tí gbogbo rẹ fi di wíwú.”
Más példázatot is mondott nekik: „Hasonlatos a mennyeknek országa a kovászhoz, amelyet fog az asszony, három mérce lisztbe belekever, amitől az egész megkel.“
34 Òwe ni Jesu fi sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn, òwe ni ó fi bá wọn sọ gbogbo ọ̀rọ̀ tó sọ.
Mindezeket példázatokban mondta Jézus a sokaságnak, és példázat nélkül semmit sem mondott nekik,
35 Kí ọ̀rọ̀ tí a ti ẹnu àwọn wòlíì sọ lé wá sí ìmúṣẹ pé: “Èmi yóò ya ẹnu mi láti fi òwe sọ̀rọ̀. Èmi yóò sọ àwọn ohun tí ó fi ara sin láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé wá.”
hogy beteljesedjék, amit a próféta mondott: „Megnyitom a számat példázatokra, és feltárom, amik e világ alapítása óta rejtve vannak.“
36 Lẹ́yìn náà ó sì fi ọ̀pọ̀ ènìyàn sílẹ̀ lóde, ó wọ ilé lọ. Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọn wí pé, “Ṣàlàyé òwe èpò inú oko fún wa.”
Ekkor elbocsátotta Jézus a sokaságot, és bement a házba. Tanítványai odamentek hozzá, és ezt mondták: „Magyarázd meg nekünk a szántóföld konkolyáról szóló példázatot!“
37 Ó sì dá wọn lóhùn pé, “Ọmọ Ènìyàn ni ẹni tí ó ń fúnrúgbìn rere.
Ő pedig így felelt nekik: „Aki a jó magot veti, az az Emberfia,
38 Ayé ni oko náà; irúgbìn rere ni àwọn ènìyàn ti ìjọba ọ̀run. Èpò ni àwọn ènìyàn tí wọ́n jẹ́ ti èṣù,
a szántóföld pedig a világ, a jó mag az Isten országának fiai, a konkoly pedig a gonosznak fiai.
39 ọ̀tá tí ó gbin àwọn èpò sáàrín alikama ni èṣù. Ìkórè ni òpin ayé, àwọn olùkórè sì ní àwọn angẹli. (aiōn g165)
Az ellenség, aki a konkolyt vetette, az ördög; az aratás pedig a világ vége, az aratók pedig az angyalok. (aiōn g165)
40 “Gẹ́gẹ́ bí a ti kó èpò jọ, tí a sì sun ún nínú iná, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni yóò rí ní ìgbẹ̀yìn ayé. (aiōn g165)
Ahogyan összegyűjtik a konkolyt és megégetik, úgy lesz a világ végén. (aiōn g165)
41 Ọmọ Ènìyàn yóò ran àwọn angẹli rẹ̀, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tó ń mú ni dẹ́ṣẹ̀ kúrò ní ìjọba rẹ̀ àti gbogbo ènìyàn búburú.
Az Emberfia elküldi angyalait, és az országából összegyűjtenek minden botránkozást okozót és mindenkit, aki gonoszságot cselekedett,
42 Wọn yóò sì sọ wọ́n sí inú iná ìléru, níbi ti ẹkún òun ìpayínkeke yóò gbé wà.
és tüzes kemencébe vetik őket: ott lesz sírás és fogcsikorgatás.
43 Nígbà náà ni àwọn olódodo yóò máa ràn bí oòrùn ní ìjọba Baba wọn. Ẹni tí ó bá létí, jẹ́ kí ó gbọ́.
Akkor az igazak fénylenek, mint a nap Atyjuk országában. Akinek van füle a hallásra, hallja meg!
44 “Ìjọba ọ̀run sì dàbí ìṣúra kan tí a fi pamọ́ sínú oko. Nígbà tí ọkùnrin kan rí i ó tún fi í pamọ́. Nítorí ayọ̀ rẹ̀, ó ta gbogbo ohun ìní rẹ̀, ó ra oko náà.
„Ismét hasonlatos a mennyek országa a szántóföldben elrejtett kincshez, amelyet megtalált az ember, elrejti, örömében elmegy, eladja mindenét, amije van, és megveszi azt a szántóföldet.
45 “Bákan náà ni ìjọba ọ̀run dàbí oníṣòwò kan tí ó ń wá òkúta olówó iyebíye láti rà.
Ismét hasonlatos a mennyek országa a kereskedőhöz, aki igazgyöngyöket keres.
46 Nígbà tí ó rí ọ̀kan tí ó ni iye lórí, ó lọ láti ta gbogbo ohun ìní rẹ̀ láti le rà á.
Amikor egy drágagyöngyöt talál, mindenételadja, amije van, és megveszi azt.
47 “Bákan náà, a sì tún lè fi ìjọba ọ̀run wé àwọ̀n kan tí a jù sínú odò, ó sì kó onírúurú ẹja.
Szintén hasonlatos a mennyeknek országa a tengerbe vetett hálóhoz, amely mindenféle fajta halat összefog.
48 Nígbà tí àwọ̀n náà sì kún, àwọn apẹja fà á sókè sí etí bèbè Òkun, wọ́n jókòó, wọ́n sì ṣa àwọn èyí tí ó dára sínú apẹ̀rẹ̀, ṣùgbọ́n wọ́n da àwọn tí kò dára nù.
Miután megtelik, kivonják a partra a halászok, és leülve, a jókat edényekbe gyűjtik, a hitványakat pedig kidobják.
49 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni yóò rí ní ìgbẹ̀yìn ayé. Àwọn angẹli yóò wá láti ya àwọn ènìyàn búburú kúrò lára àwọn olódodo. (aiōn g165)
Így lesz a világnak végén is: Eljönnek majd az angyalok, és kiválasztják a gonoszakat az igazak közül. (aiōn g165)
50 Wọn ó sì ju àwọn ènìyàn búburú sínú iná ìléru náà, ní ibi ti ẹkún àti ìpayínkeke yóò gbé wà.”
És tüzes kemencébe vetik őket, ott lesz sírás és fogcsikorgatás.“
51 Jesu bí wọn léèrè pé, “Ǹjẹ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí yé yín.” Wọ́n dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, ó yé wa.”
Azután Jézus ezt kérdezte tőlük: „Megértettétek mindezeket?“Azok ezt mondták: „Megértettük, Uram.“
52 Ó wí fún wọn pé, “Nítorí náà ni olúkúlùkù olùkọ́ òfin tí ó ti di ọmọ-ẹ̀yìn ní ìjọba ọ̀run ṣe dàbí ọkùnrin kan tí í ṣe baálé ilé, tí ó mú ìṣúra tuntun àti èyí tí ó ti gbó jáde láti inú yàrá ìṣúra rẹ̀.”
Ő pedig ezt mondta nekik: „Ezért minden írástudó, aki ismeri a mennyek országáról szóló tanítást, hasonlatos az olyan gazdához, aki ót és újat hoz elő éléskamrájából.“
53 Lẹ́yìn ti Jesu ti parí òwe wọ̀nyí, ó ti ibẹ̀ kúrò.
És történt, hogy amikor Jézus elmondta ezeket a példázatokat, elment onnan.
54 Ó wá sí ìlú òun tìkára rẹ̀, níbẹ̀ ni ó ti ń kọ́ àwọn ènìyàn nínú Sinagọgu, ẹnu sì yà wọ́n. Wọ́n béèrè pé, “Níbo ni ọkùnrin yìí ti mú ọgbọ́n yìí àti iṣẹ́ ìyanu wọ̀nyí wá?
És hazájába érve, tanította őket a zsinagógában, úgy, hogy álmélkodtak, és ezt mondták: „Honnan van ebben ez a bölcsesség és az erő?
55 Kì í ha ṣe ọmọ gbẹ́nàgbẹ́nà ni èyí bí? Ìyá rẹ̀ ha kọ́ ni à ń pè ní Maria bí? Arákùnrin rẹ̀ ha kọ́ ni Jakọbu, Josẹfu, Simoni àti Judasi bí?
Nem ő annak az ácsmesternek a fia? Nem az ő anyját hívják Máriának, és az ő testvéreit Jakabnak, Józsefnek, Simonnak és Júdásnak?
56 Àwọn arábìnrin rẹ̀ gbogbo ha kọ́ ni ó ń bá wa gbé níhìn-ín yìí, nígbà náà níbo ni ọkùnrin yìí ti rí àwọn nǹkan wọ̀nyí?”
És nővérei is nem mind közöttünk élnek? Honnan vette mindezeket?“
57 Inú bí wọn sí i. Ṣùgbọ́n Jesu wí fún wọn pé, “Wòlíì a máa lọ́lá ní ibòmíràn, àfi ní ilé ara rẹ̀ àti ní ìlú ara rẹ̀ nìkan ni wòlíì kò ti lọ́lá.”
És megbotránkoztak őbenne. Jézus pedig ezt mondta nekik: „A prófétának csak az ő hazájában és házában nincs tisztessége.“
58 Nítorí náà kò ṣe iṣẹ́ ìyanu kankan níbẹ̀, nítorí àìnígbàgbọ́ wọn.
Nem is tett ott sok csodát a hitetlenségük miatt.

< Matthew 13 >