< Matthew 11 >
1 Lẹ́yìn ìgbà tí Jesu sì ti parí ọ̀rọ̀ tí ó ń sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ méjìlá, ó ti ibẹ̀ rékọjá láti máa kọ́ni àti láti máa wàásù ní àwọn ìlú Galili gbogbo.
După ce a isprăvit Isus de a îndruma pe cei doisprezece ucenici ai Săi, a plecat de acolo ca să învețe și să propovăduiască în cetățile lor.
2 Nígbà tí Johanu gbọ́ ohun tí Kristi ṣe nínú ẹ̀wọ̀n, ó rán àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀
Ioan, auzind în temniță despre faptele lui Hristos, a trimis doi din ucenicii săi
3 láti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ṣe ìwọ ni ẹni tó ń bọ̀ wá tàbí kí a máa retí ẹlòmíràn?”
și I-a zis: “Tu ești Cel ce vine, sau trebuie să căutăm pe altul?”
4 Jesu dáhùn ó wí pé, “Ẹ padà lọ, ẹ sì sọ fún Johanu ohun tí ẹ̀yin gbọ́, àti èyí tí ẹ̀yin rí.
Isus le-a răspuns: “Mergeți și spuneți lui Ioan ce ați auzit și ce ați văzut:
5 Àwọn afọ́jú ń ríran, àwọn amúnkùn ún rìn, a ń wẹ àwọn adẹ́tẹ̀ mọ́ kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ wọn, àwọn adití ń gbọ́rọ̀, a ń jí àwọn òkú dìde, a sì ń wàásù ìyìnrere fún àwọn òtòṣì.
orbii își recapătă vederea, șchiopii umblă, leproșii sunt curățiți, surzii aud, morții înviază și săracilor li se vestește o veste bună.
6 Alábùkún fún ni ẹni tí kò rí ohun ìkọ̀sẹ̀ nípa mi.”
Ferice de cel care nu găsește în mine nici un prilej de poticnire.”
7 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu ti lọ tán, Jesu bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún ọ̀pọ̀ ènìyàn nípa ti Johanu: “Kí ni ẹ̀yin jáde lọ wò ní aginjù? Ewéko tí afẹ́fẹ́ ń mi?
Pe când se duceau aceștia, Isus a început să spună mulțimii despre Ioan: “Ce ați ieșit în pustie ca să vedeți? O trestie scuturată de vânt?
8 Bí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀, kí ni ẹ̀yin lọ òde lọ í wò? Ọkùnrin tí a wọ̀ ni aṣọ dáradára? Rárá àwọn ti ó wọ aṣọ dáradára wà ní ààfin ọba.
Dar voi ce ați ieșit să vedeți? Un om în haine moi? Iată, cei care poartă haine moi sunt în casele regilor.
9 Àní kí ní ẹ jáde láti lọ wò? Wòlíì? Bẹ́ẹ̀ ni, mo wí fún yín, ó sì ju wòlíì lọ.”
Dar tu de ce ai ieșit afară? Ca să vezi un profet? Da, vă spun, și chiar mai mult decât un profet.
10 Èyí ni ẹni tí a ti kọ̀wé rẹ̀ pé: “‘Èmi yóò rán ìránṣẹ́ mi síwájú rẹ, ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe níwájú rẹ.’
Căci acesta este Cel despre care este scris: “Iată, trimit înaintea feței tale pe trimisul Meu, care îți va pregăti calea înaintea ta”.
11 Lóòótọ́ ni mó wí fún yín, nínú àwọn tí a bí nínú obìnrin, kò sí ẹni tí ó tí í dìde tí ó ga ju Johanu onítẹ̀bọmi lọ, síbẹ̀ ẹni tí ó kéré jù ní ìjọba ọ̀run ni ó pọ̀jù ú lọ.
Adevărat vă spun că, dintre cei născuți din femei, nu s-a ridicat nimeni mai mare decât Ioan Botezătorul; totuși, cel mai mic în Împărăția Cerurilor este mai mare decât el.
12 Láti ìgbà ọjọ́ Johanu onítẹ̀bọmi títí di àkókò yìí ni ìjọba ọ̀run ti di à fi agbára wọ̀, àwọn alágbára ló ń fi ipá gbà á.
Din zilele lui Ioan Botezătorul și până acum, Împărăția Cerurilor suferă violențe și cei violenți o iau cu forța.
13 Nítorí náà gbogbo òfin àti wòlíì ni ó sọtẹ́lẹ̀ kí Johanu kí ó tó dé.
Căci toți profeții și Legea au profețit până la Ioan.
14 Bí ẹ̀yin yóò bá gbà á, èyí ni Elijah tó ń bọ̀ wá.
Dacă sunteți dispuși să-l primiți, acesta este Ilie, care va veni.
15 Ẹni tí ó bá ní etí, kí ó gbọ́.
Cine are urechi de auzit, să audă.
16 “Kí ni èmi ìbá fi ìran yìí wé? Ó dàbí àwọn ọmọ kékeré tí ń jókòó ní ọjà tí wọ́n sì ń ké pe àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn:
Dar cu ce să compar neamul acesta? Seamănă cu niște copii care stau în piețe, care strigă la tovarășii lor
17 “‘Àwa ń fun fèrè fún yín, ẹ̀yin kò jó; àwa kọrin ọ̀fọ̀ ẹ̀yin kò káàánú.’
și spun: 'Noi am cântat la flaut pentru voi și voi n-ați dansat. Noi am plâns pentru voi, iar voi nu v-ați plâns'.
18 Nítorí Johanu wá kò bá a yín jẹ bẹ́ẹ̀ ni kò mu, ẹ̀yin sì wí pé, ‘Ó ní ẹ̀mí èṣù.’
Căci Ioan nu a venit nici să mănânce, nici să bea, și ei spun: “Are un demon”.
19 Ọmọ Ènìyàn wá bá a yín jẹun, ó sì bá yin mu, wọ́n wí pé, ‘Ọ̀jẹun àti ọ̀mùtí; ọ̀rẹ́ àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.’ Ṣùgbọ́n a dá ọgbọ́n láre nípa ìṣe rẹ̀.”
Fiul Omului a venit mâncând și bând și ei spun: 'Iată un om gurmand și un bețiv, prietenul vameșilor și al păcătoșilor!'. Dar înțelepciunea este justificată de copiii ei.”
20 Nígbà náà ni Jesu bẹ̀rẹ̀ sí í bá ìlú tí ó ti ṣe ọ̀pọ̀ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ wí, nítorí wọn kò ronúpìwàdà.
Apoi a început să denunțe cetățile în care se săvârșiseră cele mai multe din faptele lui mărețe, pentru că nu se pocăiseră.
21 Ó wí pé, “Ègbé ni fún ìwọ Korasini, ègbé ni fún ìwọ Betisaida! Ìbá ṣe pé a ti ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu tí a ṣe nínú yín ní a ṣe ni Tire àti Sidoni, àwọn ènìyàn wọn ìbá ti ronúpìwàdà ti pẹ́ nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú.
“Vai de tine, Corazin! Vai de tine, Betsaida! Pentru că, dacă în Tir și în Sidon s-ar fi făcut în Tir și în Sidon lucrările mărețe care s-au făcut în voi, s-ar fi pocăit demult în sac și cenușă.
22 Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, yóò sàn fún Tire àti Sidoni ní ọjọ́ ìdájọ́ jù fún yín.
Dar vă spun că, în ziua judecății, va fi mai ușor de suportat pentru Tir și Sidon decât pentru voi.
23 Àti ìwọ Kapernaumu, a ó ha gbé ọ ga sókè ọ̀run? Rárá, a ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ sí ipò òkú. Nítorí, ìbá ṣe pé a ti ṣe iṣẹ́ ìyanu tí a ṣe nínú rẹ ní Sodomu, òun ìbá wà títí di òní. (Hadēs )
Tu, Capernaum, care te-ai înălțat la cer, te vei coborî în Hades. Căci, dacă s-ar fi făcut în Sodoma lucrările mărețe care s-au făcut în voi, ar fi rămas până astăzi. (Hadēs )
24 Lóòótọ́ yóò sàn fún ilẹ̀ Sodomu ní ọjọ́ ìdájọ́ jù fún ìwọ lọ.”
Dar Eu vă spun că, în ziua judecății, va fi mai ușor de suportat pentru țara Sodomei decât pentru voi.”
25 Nígbà náà ni Jesu wí pé, “Mo yìn ọ Baba, Olúwa ọ̀run àti ayé, nítorí ìwọ ti fi òtítọ́ yìí pamọ́ fún àwọn tó jẹ́ ọlọ́gbọ́n àti amòye, Ìwọ sì ti fi wọ́n hàn fún àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.
În vremea aceea, Isus a răspuns: “Îți mulțumesc, Tată, Doamne al cerului și al pământului, că ai ascuns aceste lucruri de cei înțelepți și pricepuți și le-ai descoperit copiilor.
26 Bẹ́ẹ̀ ni, Baba, nítorí ó wù ọ́ láti ṣe bẹ́ẹ̀.
Da, Tată, pentru că așa a fost bineplăcut înaintea Ta.
27 “Ohun gbogbo ni Baba mi ti fi sí ìkáwọ́ mi. Kò sí ẹni tí ó mọ ọmọ bí kò ṣe Baba, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnikẹ́ni tí ó mọ Baba, bí kò ṣe ọmọ, àti àwọn tí ọmọ yan láti fi ara hàn fún.
Toate lucrurile mi-au fost predate de Tatăl meu. Nimeni nu-L cunoaște pe Fiul, în afară de Tatăl; și nimeni nu-L cunoaște pe Tatăl, în afară de Fiul și de cel căruia Fiul vrea să i-L dezvăluie.
28 “Ẹ wá sọ́dọ̀ mi gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣiṣẹ́ tí a sì di ẹrù wíwúwo lé lórí, èmi yóò sì fún yín ní ìsinmi.
“Veniți la Mine, voi toți cei osteniți și împovărați, și Eu vă voi da odihnă.
29 Ẹ gbé àjàgà mi wọ̀. Ẹ kọ́ ẹ̀kọ́ lọ́dọ̀ mi nítorí onínútútù àti onírẹ̀lẹ̀ ọkàn ni èmi, ẹ̀yin yóò sì ri ìsinmi fún ọkàn yín.
Luați jugul Meu asupra voastră și învățați de la Mine, căci Eu sunt blând și smerit cu inima; și veți găsi odihnă pentru sufletele voastre.
30 Nítorí àjàgà mi rọrùn ẹrù mi sì fúyẹ́.”
Căcijugul Meu este ușor și povara Mea este ușoară.”