< Matthew 11 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí Jesu sì ti parí ọ̀rọ̀ tí ó ń sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ méjìlá, ó ti ibẹ̀ rékọjá láti máa kọ́ni àti láti máa wàásù ní àwọn ìlú Galili gbogbo.
And when Jesus had made an end of giving orders to his twelve disciples, He departed from thence to teach and preach in their cities.
2 Nígbà tí Johanu gbọ́ ohun tí Kristi ṣe nínú ẹ̀wọ̀n, ó rán àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀
Now when John heard in prison of the works of Christ,
3 láti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ṣe ìwọ ni ẹni tó ń bọ̀ wá tàbí kí a máa retí ẹlòmíràn?”
he sent two of his disciples to ask Him, Art thou He who was to come, or are we to expect another?
4 Jesu dáhùn ó wí pé, “Ẹ padà lọ, ẹ sì sọ fún Johanu ohun tí ẹ̀yin gbọ́, àti èyí tí ẹ̀yin rí.
And Jesus said to them in answer, Go and tell John the things which ye hear and see:
5 Àwọn afọ́jú ń ríran, àwọn amúnkùn ún rìn, a ń wẹ àwọn adẹ́tẹ̀ mọ́ kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ wọn, àwọn adití ń gbọ́rọ̀, a ń jí àwọn òkú dìde, a sì ń wàásù ìyìnrere fún àwọn òtòṣì.
the blind are restored to sight, and the lame walk; the lepers are cleansed, and the deaf hear; the dead are raised to life, and the poor have the gospel preached to them:
6 Alábùkún fún ni ẹni tí kò rí ohun ìkọ̀sẹ̀ nípa mi.”
and happy is the man who shall not be offended at any thing in me.
7 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu ti lọ tán, Jesu bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún ọ̀pọ̀ ènìyàn nípa ti Johanu: “Kí ni ẹ̀yin jáde lọ wò ní aginjù? Ewéko tí afẹ́fẹ́ ń mi?
And as they departed, Jesus took occasion to say to the people concerning John, What went ye out into the desert to see? a reed shaken by the wind?
8 Bí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀, kí ni ẹ̀yin lọ òde lọ í wò? Ọkùnrin tí a wọ̀ ni aṣọ dáradára? Rárá àwọn ti ó wọ aṣọ dáradára wà ní ààfin ọba.
But what went ye out to see? a man clad in fine attire? they that wear rich clothes are in the palaces of kings.
9 Àní kí ní ẹ jáde láti lọ wò? Wòlíì? Bẹ́ẹ̀ ni, mo wí fún yín, ó sì ju wòlíì lọ.”
But what did ye indeed go out to see? a prophet? Yes, verily, and one superior to a prophet.
10 Èyí ni ẹni tí a ti kọ̀wé rẹ̀ pé: “‘Èmi yóò rán ìránṣẹ́ mi síwájú rẹ, ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe níwájú rẹ.’
For this is he, of whom it is written, "Behold I send my messenger before thy face, who shall prepare thy way before thee."
11 Lóòótọ́ ni mó wí fún yín, nínú àwọn tí a bí nínú obìnrin, kò sí ẹni tí ó tí í dìde tí ó ga ju Johanu onítẹ̀bọmi lọ, síbẹ̀ ẹni tí ó kéré jù ní ìjọba ọ̀run ni ó pọ̀jù ú lọ.
For I assure you that in the whole human race there hath not risen a greater than John the baptist: though the lest in the kingdom of heaven is greater than he:
12 Láti ìgbà ọjọ́ Johanu onítẹ̀bọmi títí di àkókò yìí ni ìjọba ọ̀run ti di à fi agbára wọ̀, àwọn alágbára ló ń fi ipá gbà á.
and from the days of John the baptist to this time, the kingdom of heaven is as it were forced into, and the most pressing seize upon it with eagerness.
13 Nítorí náà gbogbo òfin àti wòlíì ni ó sọtẹ́lẹ̀ kí Johanu kí ó tó dé.
For all the prophets, and the law, did no more than prophesy, till John came:
14 Bí ẹ̀yin yóò bá gbà á, èyí ni Elijah tó ń bọ̀ wá.
and, if ye are willing to receive the truth, This is that Elias who was to come.
15 Ẹni tí ó bá ní etí, kí ó gbọ́.
He that hath ears to hear, let him hear.
16 “Kí ni èmi ìbá fi ìran yìí wé? Ó dàbí àwọn ọmọ kékeré tí ń jókòó ní ọjà tí wọ́n sì ń ké pe àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn:
But to what shall I compare this generation? they are like children sitting in the market-places,
17 “‘Àwa ń fun fèrè fún yín, ẹ̀yin kò jó; àwa kọrin ọ̀fọ̀ ẹ̀yin kò káàánú.’
and calling to their companions, and saying "We have sung and ye have not danced; we have mourned, and ye have not lamented:"
18 Nítorí Johanu wá kò bá a yín jẹ bẹ́ẹ̀ ni kò mu, ẹ̀yin sì wí pé, ‘Ó ní ẹ̀mí èṣù.’
for John came neither eating nor drinking as others do, and they say, He is beside himself:
19 Ọmọ Ènìyàn wá bá a yín jẹun, ó sì bá yin mu, wọ́n wí pé, ‘Ọ̀jẹun àti ọ̀mùtí; ọ̀rẹ́ àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.’ Ṣùgbọ́n a dá ọgbọ́n láre nípa ìṣe rẹ̀.”
the Son of man came eating and drinking like other men, and they call Him a gluttonous man, and a wine-bibber, and a friend of publicans and sinners. But wisdom is justified by her children.
20 Nígbà náà ni Jesu bẹ̀rẹ̀ sí í bá ìlú tí ó ti ṣe ọ̀pọ̀ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ wí, nítorí wọn kò ronúpìwàdà.
Then began He to upbraid the cities, in which most of his miracles were wrought; because they did not repent.
21 Ó wí pé, “Ègbé ni fún ìwọ Korasini, ègbé ni fún ìwọ Betisaida! Ìbá ṣe pé a ti ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu tí a ṣe nínú yín ní a ṣe ni Tire àti Sidoni, àwọn ènìyàn wọn ìbá ti ronúpìwàdà ti pẹ́ nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú.
Wo unto thee, Chorazin; wo unto thee, Bethsaida: for if the miracles wrought among you had been done in Tyre and Sidon, they would have repented long ago in sackcloth and ashes:
22 Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, yóò sàn fún Tire àti Sidoni ní ọjọ́ ìdájọ́ jù fún yín.
therefore I tell you, it shall be more tolerable for Tyre and Sidon in the day of judgement, than for you.
23 Àti ìwọ Kapernaumu, a ó ha gbé ọ ga sókè ọ̀run? Rárá, a ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ sí ipò òkú. Nítorí, ìbá ṣe pé a ti ṣe iṣẹ́ ìyanu tí a ṣe nínú rẹ ní Sodomu, òun ìbá wà títí di òní. (Hadēs g86)
And thou, Capernaum, which art exalted even to heaven, shalt be cast down to hell: for if the miracles, which have been wrought in thee, had been wrought in Sodom, it would have remained unto this day. (Hadēs g86)
24 Lóòótọ́ yóò sàn fún ilẹ̀ Sodomu ní ọjọ́ ìdájọ́ jù fún ìwọ lọ.”
Moreover I tell you, that it shall be more tolerable for the land of Sodom in the day of judgement, than for thee.
25 Nígbà náà ni Jesu wí pé, “Mo yìn ọ Baba, Olúwa ọ̀run àti ayé, nítorí ìwọ ti fi òtítọ́ yìí pamọ́ fún àwọn tó jẹ́ ọlọ́gbọ́n àti amòye, Ìwọ sì ti fi wọ́n hàn fún àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.
And upon this occasion Jesus opened his mouth and said, "I thank thee, O Father, Lord of heaven and earth, that thou hast hid these things from the wise and knowing, and hast revealed them to babes:
26 Bẹ́ẹ̀ ni, Baba, nítorí ó wù ọ́ láti ṣe bẹ́ẹ̀.
even so, Father, for it was thy good pleasure that so it should be."
27 “Ohun gbogbo ni Baba mi ti fi sí ìkáwọ́ mi. Kò sí ẹni tí ó mọ ọmọ bí kò ṣe Baba, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnikẹ́ni tí ó mọ Baba, bí kò ṣe ọmọ, àti àwọn tí ọmọ yan láti fi ara hàn fún.
All things are delivered to me by my Father: and no one knoweth the Son, but the Father; nor does any one know the Father, but the Son, and he to whom the Son is pleased to reveal Him.
28 “Ẹ wá sọ́dọ̀ mi gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣiṣẹ́ tí a sì di ẹrù wíwúwo lé lórí, èmi yóò sì fún yín ní ìsinmi.
Come unto me therefore all ye who are labouring and oppressed, and I will give you ease.
29 Ẹ gbé àjàgà mi wọ̀. Ẹ kọ́ ẹ̀kọ́ lọ́dọ̀ mi nítorí onínútútù àti onírẹ̀lẹ̀ ọkàn ni èmi, ẹ̀yin yóò sì ri ìsinmi fún ọkàn yín.
Take but my yoke upon you, and learn of me, (for I am meek and lowly in heart, ) and ye shall find refreshment to your souls:
30 Nítorí àjàgà mi rọrùn ẹrù mi sì fúyẹ́.”
for my yoke is easy, and my burthen is light.

< Matthew 11 >