< Matthew 10 >

1 Jesu sì pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ méjìlá sí ọ̀dọ̀; ó fún wọn ní àṣẹ láti lé ẹ̀mí àìmọ́ jáde àti láti ṣe ìwòsàn ààrùn àti àìsàn gbogbo.
Puis, ayant appelé ses douze disciples, il leur donna le pouvoir de chasser les esprits impurs, et de guérir toute maladie et toute infirmité.
2 Orúkọ àwọn aposteli méjèèjìlá náà ni wọ̀nyí: ẹni àkọ́kọ́ ni Simoni ẹni ti a ń pè ni Peteru àti arákùnrin rẹ̀ Anderu; Jakọbu ọmọ Sebede àti arákùnrin rẹ̀ Johanu.
Or, voici les noms des douze Apôtres: Le premier est Simon, appelé Pierre, puis André, son frère; Jacques, fils de Zébédée, et Jean, son frère;
3 Filipi àti Bartolomeu; Tomasi àti Matiu agbowó òde; Jakọbu ọmọ Alfeu àti Taddeu;
Philippe et Barthélemi; Thomas et Matthieu, le publicain; Jacques, fils d'Alphée et Lebbée;
4 Simoni ọmọ ẹgbẹ́ Sealoti, Judasi Iskariotu, ẹni tí ó da Jesu.
Simon le zélateur, et Judas l'iscariot, celui qui livra Jésus.
5 Àwọn méjèèjìlá wọ̀nyí ni Jesu ran, ó sì pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe lọ sì ọ̀nà àwọn kèfèrí, ẹ má ṣe wọ̀ ìlú àwọn ará Samaria.
Ce sont là les douze que Jésus envoya en mission, après leur avoir donné ses instructions, en disant: «N'allez pas vers les Gentils, et n'entrez pas dans les villes des Samaritains;
6 Ẹ kúkú tọ̀ àwọn àgùntàn ilé Israẹli tí ó nù lọ.
allez plutôt vers les brebis perdues de la maison d'Israël.
7 Bí ẹ̀yin ti ń lọ, ẹ máa wàásù yìí wí pé, ‘Ìjọba ọ̀run kù sí dẹ̀dẹ̀.’
Partout, sur votre chemin, prêchez, et dites: «Le royaume des cieux est proche.»
8 Ẹ máa ṣe ìwòsàn fún àwọn aláìsàn, ẹ si jí àwọn òkú dìde, ẹ sọ àwọn adẹ́tẹ̀ di mímọ́, kí ẹ sì máa lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde. Ọ̀fẹ́ ni ẹ̀yin gbà á, ọ̀fẹ́ ni kí ẹ fi fún ni.
Guérissez les malades, rendez nets les lépreux, chassez les démons. Vous avez reçu gratuitement, donnez gratuitement.
9 “Ẹ má ṣe mú wúrà tàbí fàdákà tàbí idẹ sínú àpò ìgbànú yín,
Ne prenez ni or, ni argent, ni monnaie dans vos ceintures;
10 ẹ má ṣe mú àpò fún ìrìnàjò yín, kí ẹ má ṣe mú ẹ̀wù méjì, tàbí bàtà, tàbí ọ̀pá; oúnjẹ oníṣẹ́ yẹ fún un.
ni sac de voyage, ni deux tuniques, ni sandales, ni bâton; car l'ouvrier mérite sa nourriture.
11 Ìlúkílùú tàbí ìletòkíletò tí ẹ̀yin bá wọ̀, ẹ wá ẹni ti ó bá yẹ níbẹ̀ rí, níbẹ̀ ni kí ẹ sì gbé nínú ilé rẹ̀ títí tí ẹ̀yin yóò fi kúrò níbẹ̀.
En quelque ville ou village que vous entriez, informez-vous de quelque personne respectable, et demeurez chez elle jusqu'à ce que vous partiez.
12 Nígbà tí ẹ̀yin bá sì wọ ilé kan, ẹ kí i wọn.
En entrant, saluez ceux de la maison;
13 Bí ilé náà bá sì yẹ, kí àlàáfíà yín kí ó bà sórí rẹ̀; ṣùgbọ́n bí kò bá yẹ, kí àlàáfíà yín kí ó padà sọ́dọ̀ yín.
et, si cette maison est respectable, que votre paix vienne sur elle; mais si elle ne l'est pas, que votre paix revienne à vous.
14 Bí ẹnikẹ́ni tí kò bá sì gbà yín, tàbí tí kò gba ọ̀rọ̀ yín, ẹ gbọn eruku ẹ̀ṣẹ̀ yín sílẹ̀ tí ẹ bá ń kúrò ní ilé tàbí ìlú náà.
Si l’on ne vous reçoit pas, et même si l'on n'écoute pas vos paroles, sortez de cette maison ou de cette ville en secouant la poussière de vos pieds.
15 Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, yóò sàn fún ìlú Sodomu àti Gomorra ní ọjọ́ ìdájọ́ ju àwọn ìlú náà lọ.
En vérité, je vous dis qu'au jour du jugement, le sort du pays de Sodome et de Gomorrhe sera plus supportable que celui de cette ville-là.
16 “Mò ń rán yín lọ gẹ́gẹ́ bí àgùntàn sáàrín ìkookò. Nítorí náà, kí ẹ ní ìṣọ́ra bí ejò, kí ẹ sì ṣe onírẹ̀lẹ̀ bí àdàbà.
Je vous envoie comme des brebis au milieu des loups; soyez donc prudents comme les serpents et simples comme les colombes.
17 Ẹ ṣọ́ra lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn nítorí wọn yóò fi yín le àwọn ìgbìmọ̀ ìgbèríko lọ́wọ́ wọn yóò sì nà yín nínú Sinagọgu.
Tenez-vous en garde contre les hommes, car ils vous livreront aux tribunaux, et ils vous fouetteront dans leurs synagogues.
18 Nítorí orúkọ mi, a ó mú yín lọ síwájú àwọn baálẹ̀ àti àwọn ọba, bí ẹlẹ́rìí sí wọn àti àwọn aláìkọlà.
On vous mènera devant les gouverneurs et devant les rois, à cause de moi, et vous rendrez témoignage devant eux et devant les Gentils.
19 Nígbà tí wọ́n bá mú yín, ẹ má ṣe ṣàníyàn ohun tí ẹ ó sọ tàbí bí ẹ ó ṣe sọ ọ́. Ní ojú kan náà ni a ó fi ohun tí ẹ̀yin yóò sọ fún yín.
Quand on vous livrera entre leurs mains, ne vous mettez pas en souci de la manière dont vous parlerez, ni de ce que vous direz; ce que vous devez dire, vous sera inspiré à l'heure même:
20 Nítorí pé kì í ṣe ẹ̀yin ni ó sọ ọ́, bí kò ṣe Ẹ̀mí Baba yín tí ń sọ̀rọ̀ nípasẹ̀ yín.
ce n'est pas vous qui parlez, c'est l'Esprit de votre Père, qui parle en vous.
21 “Arákùnrin yóò sì fi arákùnrin fún pípa. Baba yóò fi àwọn ọmọ rẹ̀ fún ikú pa. Àwọn ọmọ yóò ṣọ̀tẹ̀ sí òbí wọn, wọn yóò sì mú kí a pa wọ́n.
Le frère livrera son frère à la mort, et le père, son enfant; les enfants s'élèveront contre leurs pères et leurs mères, et les mettront à mort,
22 Gbogbo ènìyàn yóò sì kórìíra yín nítorí mi, ṣùgbọ́n gbogbo ẹni tí ó bá dúró ṣinṣin dé òpin ni a ó gbàlà.
et vous serez haïs de tous à cause de mon nom; mais celui qui persévérera jusqu’à la fin, sera sauvé.
23 Nígbà tí wọn bá ṣe inúnibíni sì i yín ní ìlú kan, ẹ sálọ sì ìlú kejì. Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹ̀yin kò tì í le la gbogbo ìlú Israẹli já tán kí Ọmọ Ènìyàn tó dé.
Quand on vous persécutera dans une ville, fuyez dans une autre. En vérité, je vous dis que vous n'aurez pas achevé de parcourir les villes d'Israël, que le Fils de l'homme sera venu.
24 “Akẹ́kọ̀ọ́ kì í ju olùkọ́ rẹ̀ lọ, bẹ́ẹ̀ ni ọmọ ọ̀dọ̀ kì í ju ọ̀gá rẹ̀ lọ.
Le disciple n'est pas au-dessus du maître, ni l'esclave au-dessus de son seigneur;
25 Ó tọ́ fún akẹ́kọ̀ọ́ láti dàbí olùkọ́ rẹ̀ àti fún ọmọ ọ̀dọ̀ láti rí bí ọ̀gá rẹ̀. Nígbà tí wọ́n bá pe baálé ilé ní Beelsebulu, mélòó mélòó ni ti àwọn ènìyàn ilé rẹ̀!
il suffit au disciple d'être traité comme son maître, et à l'esclave d'être traité comme son seigneur. S'ils ont appelé le maître de la maison Belzébuth, à combien plus forte raison appelleront-ils ainsi ses gens.
26 “Nítorí náà, ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí kò sí ohun tó ń bọ̀ tí kò ní í fi ara hàn, tàbí ohun tó wà ní ìkọ̀kọ̀ tí a kò ní mọ̀ ni gbangba.
Ne les craignez donc point, car il n'y a rien de caché qui ne se découvre, ni rien de secret qui ne finisse par être connu.
27 Ohun tí mo bá wí fún yín ní òkùnkùn, òun ni kí ẹ sọ ní ìmọ́lẹ̀. Èyí tí mo sọ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́ sì etí yín ni kí ẹ kéde rẹ́ lórí òrùlé.
Ce que je vous dis dans les ténèbres, dites-le au grand jour; et ce que je vous dis à l'oreille, publiez-le sur les toits.
28 Ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn tí ó le pa ara nìkan; ṣùgbọ́n tí wọn kò lè pa ẹ̀mí. Ẹ bẹ̀rù Ẹni tí ó le pa ẹ̀mí àti ara run ní ọ̀run àpáàdì. (Geenna g1067)
Ne craignez pas ceux qui tuent le corps, et qui ne peuvent tuer l'âme; craignez plutôt celui qui peut faire périr l'âme et le corps dans la Géhenne. (Geenna g1067)
29 Ológoṣẹ́ méjì kọ́ ni à ń tà ní owó idẹ wẹ́wẹ́ kan? Síbẹ̀ kò sí ọ̀kan nínú wọn tí yóò ṣubú lu ilẹ̀ lẹ́yìn Baba yin.
Ne donne-t-on pas deux passereaux pour un sou? et pourtant il n'en tombe pas un à terre sans la volonté de votre Père;
30 Àti pé gbogbo irun orí yín ni a ti kà pé.
les cheveux mêmes de votre tête sont tous comptés.
31 Nítorí náà, ẹ má ṣe fòyà; ẹ̀yin ní iye lórí ju ọ̀pọ̀ ológoṣẹ́ lọ.
Ne craignez donc point; vous valez plus qu'un grand nombre de passereaux.
32 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́wọ́ mi níwájú ènìyàn, òun náà ni èmi yóò jẹ́wọ́ rẹ̀ níwájú Baba mi ní ọ̀run.
Ainsi, quiconque me confessera devant les hommes, je le confesserai aussi devant mon Père qui est dans les cieux;
33 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá sẹ́ mí níwájú àwọn ènìyàn, òun náà ni èmi náà yóò sọ wí pé n kò mọ̀ níwájú Baba mi ní ọ̀run.
mais quiconque me reniera devant les hommes, je le renierai aussi devant mon Père qui est dans les cieux.
34 “Ẹ má ṣe rò pé mo mú àlàáfíà wá sí ayé, Èmi kò mú àlàáfíà wá bí kò ṣe idà.
«Ne pensez pas que je sois venu apporter la paix sur la terre; je suis venu apporter, non la paix, mais l'épée:
35 Nítorí èmi wá láti ya “‘ọmọkùnrin ní ipa sí baba rẹ̀, ọmọbìnrin ní ipa sí ìyá rẹ̀, àti aya ọmọ sí ìyakọ rẹ.
je suis venu mettre le fils contre son père, la fille contre sa mère, et la belle-fille contre sa belle-mère;
36 Ará ilé ènìyàn ni yóò sì máa ṣe ọ̀tá rẹ̀.’
on aura pour ennemis, les gens de sa propre maison.
37 “Ẹni tí ó bá fẹ́ baba rẹ̀ tàbí ìyá rẹ̀ jù mí lọ, kò yẹ ní tèmi, ẹni tí ó ba fẹ́ ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin rẹ̀ jù mí lọ, kò yẹ ní tèmi.
Celui qui aime son père ou sa mère plus que moi, n'est pas digne de moi; celui qui aime son fils ou sa fille plus que moi, n'est pas digne de moi;
38 Ẹni tí kò bá gbé àgbélébùú rẹ̀ kí ó tẹ̀lé mi kò yẹ ní tèmi.
et celui qui ne prend pas sa croix et ne me suit pas, n'est pas digne de moi.
39 Ẹni tí ó bá wa ẹ̀mí rẹ̀ yóò sọ ọ́ nù, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá sọ ẹ̀mí rẹ̀ nú nítorí tèmi ni yóò rí i.
Celui qui sauvera sa vie, la perdra, et celui qui perdra sa vie à cause de moi, la retrouvera.
40 “Ẹni tí ó bá gbà yín, ó gbà mí, ẹni tí ó bá sì gbà mí gba ẹni tí ó rán mi.
Qui vous reçoit, me reçoit, et qui me reçoit, reçoit celui qui m'a envoyé.
41 Ẹni tí ó ba gba wòlíì, nítorí pé ó jẹ́ wòlíì yóò jẹ èrè wòlíì, ẹni tí ó bá sì gba olódodo nítorí ti ó jẹ́ ènìyàn olódodo, yóò jẹ èrè olódodo.
Celui qui reçoit un prophète, en qualité de prophète, recevra une récompense de prophète; celui qui reçoit un juste, en qualité de juste, recevra une récompense de juste;
42 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fi ago omi tútù fún ọ̀kan nínú àwọn onírẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí mu nítorí tí ó jẹ́ ọmọ-ẹ̀yìn mi, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kò ní pàdánù èrè rẹ̀.”
et n'eût-on donné qu'un verre d'eau froide à l'un de ces petits, parce qu'il est mon disciple, je vous dis en vérité, qu'on ne perdra point sa récompense.»

< Matthew 10 >