< Mark 8 >

1 Ní ọjọ́ kan, bí ọ̀pọ̀ ènìyàn ti péjọ, kò sí oúnjẹ fún wọn mọ́ láti jẹ. Jesu pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
Na rĩrĩ, matukũ-inĩ macio kĩrĩndĩ kĩingĩ gĩkĩũngana rĩngĩ. Na tondũ gĩtiarĩ na kĩndũ gĩa kũrĩa-rĩ, Jesũ agĩĩta arutwo ake moke harĩ we, akĩmeera atĩrĩ,
2 Ó wí fún wọn pé, “Àánú ọ̀pọ̀ ènìyàn wọ̀nyí ṣe mí nítorí pé ó tó ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti wà níhìn-ín, kò sì sí ohun kan tí ó kù sílẹ̀ fún wọn láti jẹ.
“Nĩndĩraiguĩra andũ aya tha Nĩgũkorwo makoretwo hamwe na niĩ rĩu mĩthenya ĩtatũ na matirĩ na kĩndũ gĩa kũrĩa.
3 Bí mo bá sọ fún wọn láti máa lọ sí ilé wọn bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ebi, wọn yóò dákú lójú ọ̀nà, nítorí pé àwọn mìíràn nínú wọn ti ọ̀nà jíjìn wá.”
Ingĩmeera mainũke mahũũtiĩ mekũringĩkĩra njĩra, tondũ amwe ao moimĩte kũraya.”
4 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ béèrè pé, “Níbo ni a ó ti rí àkàrà tí ó tó láti fi bọ́ wọn nínú aṣálẹ̀ yìí?”
Nao arutwo makĩmũcookeria atĩrĩ, “Mũndũ angĩruta irio cia kũmahũũnia kũ gũkũ werũ-inĩ ũyũ?”
5 Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ìṣù àkàrà mélòó lẹ ní lọ́wọ́?” Wọ́n fèsì pé, “Ìṣù àkàrà méje.”
Jesũ akĩmooria atĩrĩ, “Mũrĩ na mĩgate ĩigana?” Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Tũrĩ na mĩgate mũgwanja.”
6 Nítorí náà, ó pàṣẹ fún àwọn ènìyàn náà láti jókòó lórí ilẹ̀. Ó sì mú odindi àkàrà méje náà, ó dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run, ó sì bù wọ́n sí wẹ́wẹ́, ó pín wọn fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti gbé ka iwájú àwọn ènìyàn, wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀.
Akĩĩra kĩrĩndĩ gĩikare thĩ. Nake akĩoya mĩgate ĩyo mũgwanja, na aarĩkia gũcookia ngaatho akĩenyũranga mĩgate ĩyo, akĩmĩnengera arutwo ake mahe andũ, nao magĩĩka o ũguo.
7 Wọ́n rí àwọn ẹja wẹ́wẹ́ díẹ̀ pẹ̀lú. Jesu tún dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run fún ìpèsè náà, ó sì pàṣẹ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti pín wọn fún àwọn ènìyàn náà.
O na nĩ maarĩ na tũthamaki tũnini tũtarĩ tũingĩ; agĩcookia ngaatho nĩ ũndũ watuo, na akĩĩra arutwo magaĩre andũ.
8 Gbogbo ọ̀pọ̀ ènìyàn náà ló jẹ àjẹyó àti àjẹtẹ́rùn. Lẹ́yìn èyí wọ́n kó àjẹkù ti ó kù jọ, agbọ̀n méje sì kún.
Nao makĩrĩa makĩhũũna. Thuutha ũcio arutwo makĩũngania cienyũ iria ciatigarĩte, ikĩiyũra ciondo mũgwanja.
9 Àwọn tí ó jẹ ẹ́ tó ìwọ̀n ẹgbàajì ènìyàn, ó sì rán wọn lọ.
Andũ arũme arĩa maarĩire maarĩ ta ngiri inya. Na aarĩkia kũmeera mathiĩ,
10 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, lẹ́yìn èyí, Jesu wọ inú ọkọ̀ ojú omi pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, wọ́n sì gúnlẹ̀ sí agbègbè Dalmanuta.
agĩtoonya gatarũ me na arutwo ake, magĩthiĩ bũrũri wa Dalumanutha.
11 Àwọn Farisi tọ Jesu wá, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí béèrè ìbéèrè lọ́wọ́ rẹ̀. Láti dán an wò, wọ́n béèrè fún àmì láti ọ̀run.
Nao Afarisai magĩũka na makĩambĩrĩria kũũria Jesũ ciũria. Makĩmwĩra aringe kĩama kuuma igũrũ no nĩkũmũgeria maamũgeragia.
12 Jesu mí kanlẹ̀, nígbà tí ó gbọ́ ìbéèrè wọn. Ó sì dáhùn wí pé, “Èéṣe tí ìran yìí fi ń wá àmì? Lóòótọ́ ni mo sọ fún un yín kò si àmì tí a ó fi fún ìran yín.”
Nake akĩhũmũka ihũmũka inene, akĩũria atĩrĩ, “Nĩkĩ gĩgũtũma rũciaro rũrũ rũũrie rũringĩrwo kĩama? Ngũmwĩra atĩrĩ na ma gũtirĩ kĩama rũkũringĩrwo.”
13 Nígbà náà ni ó padà sínú ọkọ̀ ojú omi ó fi àwọn ènìyàn sílẹ̀, ó sì rékọjá sí apá kejì Òkun náà.
Agĩcooka akĩmatiga, agĩtoonya gatarũ akĩringa mũrĩmo ũrĩa ũngĩ.
14 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ẹ̀yìn ti gbàgbé láti mú àkàrà tí yóò tó wọn ọ́n jẹ lọ́wọ́. Ẹyọ ìṣù àkàrà kan ṣoṣo ni ó wà nínú ọkọ̀ wọn.
Na rĩrĩ, arutwo nĩmariganĩirwo nĩ gũkuua mĩgate, tiga o mũgate ũmwe marĩ naguo gatarũ-inĩ.
15 Bí wọ́n sì ti ń rékọjá, Jesu kìlọ̀ fún wọn pé, “Ẹ máa ṣọ́ra nítorí ìwúkàrà àwọn Farisi àti ìwúkàrà Herodu.”
Nake Jesũ akĩmataara akĩmeera atĩrĩ, “Mwĩmenyererei. Mwĩhũgagei ndawa ya kũimbia mĩgate ya Afarisai na ya Herode.”
16 Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ronú èyí láàrín ara wọn wí pé, “Torí pé a kò mú àkàrà lọ́wọ́ ni?”
Nao makĩaranĩria ũhoro ũcio mũndũ na ũrĩa ũngĩ, makĩĩrana atĩrĩ, “Aratwĩra ũguo tondũ tũtirĩ na mĩgate.”
17 Jesu mọ ohun tí wọ́n sọ láàrín ara wọn, ó sì dá wọn lóhùn pé, “Èéṣe ti ẹ̀yin fi ń ṣe àròyé pé ẹ̀yin kò mú àkàrà lọ́wọ́? Ẹ̀yin kò kíyèsi i títí di ìsinsin yìí, ẹ kò sì ti mòye, àbí ọkàn yín le ni.
Jesũ aamenya ũrĩa meeranaga akĩmooria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ kĩratũma mwaranĩrie ũhoro wa kwaga mĩgate? Nginya rĩu mũtirĩ mũrataũkĩrwo o na kana mũkamenya? Nĩ kũũmia mũũmĩtie ngoro cianyu?
18 Ẹ̀yin ní ojú, ẹ kò fi ríran? Ẹ̀yin ni etí ẹ kò sí gbọ́ran? Ẹ̀yin kò sì rántí?
Anga mũrĩ na maitho na mũtionaga, na mũrĩ na matũ na mũtiiguaga? Kaĩ mũtararirikana?
19 Nígbà ti mo bu ìṣù àkàrà márùn-ún fún ẹgbẹ̀rún márùn-ún ènìyàn, agbọ̀n mélòó ni ó kún fún àjẹkù tí ẹ ṣàjọ?” Wọ́n wí pé, “Méjìlá.”
Rĩrĩa ndenyũrangĩire andũ arĩa ngiri ithano mĩgate ĩrĩa ĩtano-rĩ, nĩ ciondo ciigana muonganirie ciiyũrĩte cienyũ cia mĩgate?” Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Ciarĩ ciondo ikũmi na igĩrĩ.”
20 “Bákan náà, nígbà tí mo bọ́ ẹgbàajì pẹ̀lú ìṣù àkàrà méje, agbọ̀n mélòó ló kù sílẹ̀ lẹ́yìn àjẹyó àti àjẹtẹ́rùn wọn?” Wọ́n dáhùn pé, “Ó ku ẹ̀kún agbọ̀n méje.”
“Na rĩrĩa ndenyũrangĩire andũ arĩa ngiri inya mĩgate ĩrĩa mũgwanja-rĩ, nĩ ciondo ciigana muonganirie ciiyũrĩte cienyũ cia mĩgate?” Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Ciarĩ ciondo mũgwanja.”
21 Ó sì wí fún wọn pé, “Èéha ti ṣe tí kò fi yé yin?”
Akĩmooria atĩrĩ, “Kaĩ mũtarĩ mũrataũkĩrwo nĩ ũhoro nginya rĩu?”
22 Nígbà tí wọ́n dé Betisaida, àwọn ènìyàn kan mú afọ́jú kan wá sọ́dọ̀ rẹ̀. Wọ́n bẹ̀ ẹ́ kí ó fi ọwọ́ kàn án, kí ó sì wò ó sàn.
Na maakinya Bethisaida, andũ amwe makĩmũrehera mũndũ warĩ mũtumumu, na magĩthaitha Jesũ amũhutie.
23 Jesu fa ọkùnrin náà lọ́wọ́, ó sì mú un jáde lọ sí ẹ̀yìn ìlú. Ó tu itọ́ sí i lójú. Ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ lé ojú náà. Ó sì bi í léèrè pé, “Ǹjẹ́ ìwọ lè rí ohunkóhun nísinsin yìí?”
Akĩnyiita mũndũ ũcio mũtumumu guoko, akĩmuumia na nja ya itũũra. Na aarĩkia kũmũtuĩra mata maitho na kũmũigĩrĩra moko, Jesũ akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ kũrĩ kĩndũ ũroona?”
24 Ọkùnrin náà wo àyíká rẹ̀, ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa, mo rí àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n n kò rí wọn kedere, wọ́n n rìn kiri bí àgékù igi.”
Nake agĩtiira maitho, akiuga atĩrĩ, “Nĩndĩrona andũ; no ngoona mahaana ta mĩtĩ magĩthiĩ.”
25 Nígbà náà, Jesu tún gbé ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì lé àwọn ojú ọkùnrin náà, bí ọkùnrin náà sì ti ranjú mọ́ ọn, a dá ìran rẹ̀ padà, ó sì rí gbogbo nǹkan kedere.
O rĩngĩ Jesũ akĩigĩrĩra mũndũ ũcio moko maitho. Hĩndĩ ĩyo maitho make makĩhingũka, agĩcooka kuona na akĩona indo ciothe wega.
26 Jesu sì rán an sí àwọn ẹbí rẹ̀. Ó kìlọ̀ fún un pé, “Má ṣe lọ sí ìlú, kí o má sì sọ fún ẹnikẹ́ni ní ìlú.”
Jesũ akĩmwĩra atĩrĩ, “Inũka, na ndũgatoonye itũũra-inĩ.”
27 Nísinsin yìí, Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kúrò ní Galili. Wọ́n sì jáde lọ sí àwọn abúlé ní agbègbè Kesarea-Filipi. Bí wọ́n ti ń lọ lọ́nà, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ta ni àwọn ènìyàn ń fi mí pè?”
Jesũ na arutwo ake magĩthiĩ na mbere o nginya tũtũũra-inĩ tũrĩa twarigiicĩirie Kaisarea-Filipi. Na me njĩra-inĩ akĩmooria atĩrĩ, “Andũ moigaga niĩ nĩ niĩ ũ?”
28 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn náà dáhùn pé, “Àwọn kan rò pé ìwọ ni Johanu Onítẹ̀bọmi, àwọn mìíràn sọ pé, ìwọ ni Elijah tàbí àwọn wòlíì mìíràn ni ó tún padà wá sáyé.”
Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Amwe moigaga wee nĩwe Johana Mũbatithania; angĩ makoiga wee nĩwe Elija; o na angĩ moigaga wee ũrĩ ũmwe wa anabii.”
29 Ó sì bi wọ́n pé, “Ta ni ẹ̀yin ń fi mí pè?” Peteru dáhùn pé, “Ìwọ ni Kristi náà.”
Nake akĩmooria atĩrĩ, “Inyuĩ na inyuĩ muugaga atĩa? Muugaga niĩ nĩ niĩ ũ?” Petero akĩmũcookeria atĩrĩ, “Wee nĩwe Kristũ.”
30 Ṣùgbọ́n Jesu kìlọ̀ fún wọn, kí wọn má sọ èyí fún ẹnikẹ́ni.
Nake Jesũ akĩmakaania matikeere mũndũ o na ũrĩkũ ũhoro wake.
31 Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí kọ́ wọn, pé, Ọmọ Ènìyàn kò le ṣàìmá jìyà ohun púpọ̀, a ó sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀ láti ọwọ́ àwọn àgbàgbà, àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin, a ó sì pa á, lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta yóò sì jíǹde.
Ningĩ Jesũ akĩambĩrĩria kũmaruta atĩ Mũrũ wa Mũndũ no nginya one mathĩĩna maingĩ na aregwo nĩ athuuri, na athĩnjĩri-Ngai arĩa anene o na arutani a watho, na atĩ no nginya ooragwo, na thuutha wa mĩthenya ĩtatũ ariũke.
32 Jesu bá wọn sọ̀rọ̀ yìí, láìfi ohunkóhun pamọ́ fún wọn, ṣùgbọ́n Peteru pe Jesu sẹ́yìn, ó sì bẹ̀rẹ̀ si bá a wí.
Aaririe ũhoro ũcio atekũhitha, nake Petero akĩmũtwara keheri-inĩ, akĩambĩrĩria kũmũkaania.
33 Jesu yípadà, ó wo àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀. Ó sì wí fún Peteru pẹ̀lú ìtara pé, “Kúrò lẹ́yìn mi Satani, nítorí ìwọ kò ro ohun tí Ọlọ́run bí kò ṣe ohun tí ènìyàn.”
No Jesũ akĩĩhũgũra akĩrora arutwo ake, na agĩkũũma Petero, akiuga atĩrĩ, “Cooka thuutha wakwa, Shaitani! Wee ndwĩciiragia maũndũ moimĩte kũrĩ Ngai, tiga o maũndũ marĩa moimĩte kũrĩ andũ.”
34 Nígbà náà ni Jesu pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ àti ọ̀pọ̀ ènìyàn láti bá wọn sọ̀rọ̀, ó wí fún wọn pé, “Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ tọ̀ mí lẹ́yìn, kí ó sẹ́ ara rẹ̀, kí ó si gbé àgbélébùú rẹ̀, kí ó si máa tọ̀ mi lẹ́yìn.
Agĩcooka agĩĩta kĩrĩndĩ hamwe na arutwo ake moke harĩ we, akĩmeera atĩrĩ, “Mũndũ o wothe ũngĩenda kũnũmĩrĩra, no nginya eerege we mwene, na akuue mũtharaba wake anũmĩrĩre.
35 Nítorí ẹni tó bá gbìyànjú láti gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là, yóò sọ ọ́ nù. Iye àwọn tí ó sọ ẹ̀mí wọn nù nìkan nítorí í tèmi àti nítorí ìyìnrere, òun náà ni yóò gbà á là.
Nĩgũkorwo ũrĩa wothe wendaga kũhonokia muoyo wake nĩ kũũrwo akoorwo nĩguo, no ũrĩa wothe ũkoorwo nĩ muoyo wake nĩ ũndũ wakwa na nĩ ũndũ wa Ũhoro-ũrĩa-Mwega, nĩakaũhonokia.
36 Nítorí èrè kí ni ó jẹ́ fún ẹni tí ó jèrè gbogbo ayé, tí ó sọ ẹ̀mí rẹ̀ nù?
Mũndũ angĩĩguna nakĩ angĩĩgwatĩra thĩ yothe, no orwo nĩ muoyo wake?
37 Tàbí kí ni ènìyàn yóò fi ṣe pàṣípàrọ̀ ẹ̀mí rẹ̀?
Kana nĩ kĩĩ mũndũ angĩkũũrania na muoyo wake?
38 Nítorí náà, bí ẹnikẹ́ni bá tijú àti gbà mí tàbí ọ̀rọ̀ mi nínú ìran panṣágà àti ẹlẹ́ṣẹ̀ yìí, tí ó kún fún àìgbàgbọ́ àti ẹ̀ṣẹ̀ báyìí, Ọmọ Ènìyàn yóò tijú rẹ̀ nígbà tí ó bá padà dé nínú ògo Baba rẹ̀, pẹ̀lú àwọn angẹli mímọ́.”
Mũndũ o wothe ũngĩconoka nĩ ũndũ wakwa na aconoke nĩ ũndũ wa ciugo ciakwa hĩndĩ ĩno ya rũciaro rũrũ rwa ũtharia na rwa mehia, o nake Mũrũ wa Mũndũ nĩakamũconokera rĩrĩa agaacooka arĩ na riiri wa Ithe, arĩ na araika arĩa atheru.”

< Mark 8 >