< Mark 6 >

1 Jesu fi ibẹ̀ sílẹ̀ lọ sí ìlú rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
A wyszedłszy stamtąd przyszedł do ojczyzny swojej, i szli za nim uczniowie jego.
2 Nígbà tí ó di ọjọ́ ìsinmi, ó lọ sí Sinagọgu láti kọ́ àwọn ènìyàn, ẹnu sì ya àwọn ènìyàn púpọ̀ tí ó gbọ́. Wọ́n wí pé, “Níbo ni ọkùnrin yìí gbé ti rí nǹkan wọ̀nyí? Irú ọgbọ́n kí ni èyí tí a fi fún un, tí irú iṣẹ́ ìyanu báyìí ń ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe?
A gdy przyszedł sabat, począł uczyć w bóżnicy, a wiele ich słuchając, zdumiewali się i mówili: Skądże temu to wszystko? a co to za mądrość, która mu jest dana, że się i takie mocy dzieją przez ręce jego?
3 Gbẹ́nàgbẹ́nà náà kọ́ yìí? Ọmọ Maria àti arákùnrin Jakọbu àti Josẹfu, Judasi àti Simoni? Àwọn arábìnrin rẹ̀ gbogbo ha kọ́ ni ó ń bá wa gbé níhìn-ín yìí?” Wọ́n sì kọsẹ̀ lára rẹ̀.
Izali ten nie jest cieśla, syn Maryi, i brat Jakóba, i Jozesa, i Judasa, i Szymona? Azaż tu nie masz i sióstr jego u nas? I gorszyli się z niego.
4 Nígbà náà, Jesu wí fún wọn pé, “A máa ń bu ọlá fún wòlíì níbi gbogbo àfi ní ìlú ara rẹ̀ àti láàrín àwọn ìdílé àti àwọn ẹbí òun pàápàá.”
Ale Jezus rzekł do nich: Nie jestci prorok beze czci, chyba w ojczyźnie swojej, a między pokrewnymi, i w domu swoim.
5 Nítorí àìgbàgbọ́ wọn, òun kò lè ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá láàrín wọn, àfi àwọn aláìsàn díẹ̀ tí ó gbé ọwọ́ lé lórí, tí wọ́n sì rí ìwòsàn.
I nie mógł tam uczynić żadnego cudu, oprócz iż niektóre chore, wkładając na nie ręce, uzdrowił.
6 Ẹnu si yà á nítorí àìgbàgbọ́ wọn. Lẹ́yìn náà, Jesu lọ sí àárín àwọn ìletò kéékèèké, ó sì ń kọ́ wọn.
A dziwował się niedowiarstwu ich, i obchodził okoliczne miasteczka, nauczając.
7 Ó sì pe àwọn méjìlá náà sọ́dọ̀ rẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí rán wọn lọ ní méjì méjì, Ó sì fi àṣẹ fún wọn lórí ẹ̀mí àìmọ́.
Tedy zwoławszy do siebie onych dwunastu, począł je po dwóch rozsyłać, i dał im moc nad duchami nieczystymi.
8 O sọ fún wọn pé, wọn kò gbọdọ̀ mú ohunkóhun lọ́wọ́, àfi ọ̀pá ìtìlẹ̀ wọn. Wọn kò gbọdọ̀ mú oúnjẹ, àpò ìgbànú, tàbí owó lọ́wọ́.
I rozkazał im, aby nic nie brali na drogę, jedno tylko laskę: ani taistry, ani chleba, ani w trzos pieniędzy;
9 Wọn kò tilẹ̀ gbọdọ̀ mú ìpààrọ̀ bàtà tàbí aṣọ lọ́wọ́.
Ale żeby się obuli w trzewiki, a nie obłoczyli dwóch sukien.
10 Jesu wí pé, “Ẹ dúró sí ilé kan ní ìletò kan. Ẹ má ṣe sípò padà láti ilé dé ilé, nígbà tí ẹ bá wà ní ìlú náà.
Zatem mówił do nich: Gdziekolwiek wnijdziecie w dom, tam zostańcie, póki byście stamtąd nie wyszli.
11 Ẹnikẹ́ni tí kò bá sì gbà yín, tí kò sì gbọ́rọ̀ yín, nígbà tí ẹ̀yin bá jáde kúrò níbẹ̀, ẹ gbọn eruku ẹsẹ̀ yín síbẹ̀ fún ẹ̀rí fún wọn.”
A którzykolwiek by was nie przyjęli, ani was słuchali, wyszedłszy stamtąd, otrząśnijcie proch z nóg waszych na świadectwo im; zaprawdę powiadam wam: Lżej będzie Sodomie i Gomorze w dzień sądny, niż miastu onemu.
12 Wọ́n jáde lọ láti wàásù ìrònúpìwàdà fún àwọn ènìyàn.
Tedy wyszedłszy kazali, aby ludzie pokutowali.
13 Wọ́n lé ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ẹ̀mí àìmọ́ jáde. Wọ́n sì ń fi òróró kun orí àwọn tí ara wọn kò dá, wọ́n sì mú wọn láradá.
I wyganiali wiele dyjabłów, i wiele chorych olejkiem mazali i uzdrawiali je.
14 Láìpẹ́, ọba Herodu gbọ́ nípa Jesu, nítorí níbi gbogbo ni a ti ń sọ̀rọ̀ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀. Ọba náà rò pé, “Johanu Onítẹ̀bọmi jíǹde kúrò nínú òkú, nítorí náà ni iṣẹ́ ìyanu ṣe ń ṣe láti ọwọ́ rẹ.”
A usłyszał o tem król Herod, (bo się imię jego stało rozsławione, ) i rzekł: Jan Chrzciciel zmartwychwstał, dlatego się cuda dzieją przez niego.
15 Àwọn mìíràn wí pé, “Elijah ní.” Àwọn mìíràn wí pé, “Wòlíì bí ọ̀kan lára àwọn àtijọ́ tó ti kú ló tún padà sáyé.”
A drudzy mówili: Elijasz to jest; drudzy zaś mówili: Prorok to jest, albo jako jeden z onych proroków.
16 Ṣùgbọ́n nígbà tí Herodu gbọ́ èyí, ó wí pé “Johanu tí mo tí bẹ́ lórí ni ó ti jíǹde kúrò nínú òkú.”
Co usłyszawszy Herod, rzekł: Ten jest Jan, któregom ja ściął, on zmartwychwstał.
17 Herodu fúnra rẹ̀ sá ti ránṣẹ́ mú Johanu, tìkára rẹ̀ sínú túbú nítorí Herodia aya Filipi arákùnrin rẹ̀ nítorí tí ó fi ṣe aya.
Albowiem tenże Herod posławszy pojmał Jana, i wsadził go do więzienia dla Herodyjady, żony Filipa, brata swego, iż ją był pojął za żonę.
18 Johanu sì ti wí fún Herodu pé, “Kò tọ́ sí ọ láti fi ìyàwó arákùnrin rẹ ṣe aya.”
Bo Jan mówił Herodowi: Nie godzi się mieć żony brata twego.
19 Nítorí náà ni Herodia ṣe ní sínú, òun sì fẹ́ pa á, ṣùgbọ́n kò le ṣe é.
A Herodyjas czyhała nań, i chciała go zabić, ale nie mogła;
20 Nítorí Herodu bẹ̀rù Johanu, ó sì mọ̀ ọ́n ni olóòtítọ́ ènìyàn àti ẹni mímọ́, ó sì ń tọ́jú rẹ̀. Nígbà tí Herodu ba gbọ́rọ̀ Johanu, ó máa ń dààmú síbẹ̀, ó sì fi ayọ̀ gbọ́rọ̀ rẹ̀.
Albowiem Herod obawiał się Jana, wiedząc, iż był mężem sprawiedliwym i świętym; i oglądał się nań, i słuchając go, wiele czynił i rad go słuchał.
21 Níkẹyìn Herodia rí ààyè. Àkókò yìí ni ọjọ́ ìbí Herodu, òun sì pèsè àsè ní ààfin ọba fún àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀: àwọn balógun àti àwọn ènìyàn pàtàkì ní Galili.
A gdy przyszedł dzień sposobny, którego Herod, obchodząc pamiątkę narodzenia swego, wieczerzą sprawił na książęta swoje i na hetmany i na przedniejsze z Galilei;
22 Nígbà náà, ni ọmọbìnrin Herodia wọlé láti jó. Inú Herodu àti àwọn àlejò rẹ̀ dùn tó bẹ́ẹ̀. Ọba sọ fún ọmọbìnrin náà pé, “Béèrè ohunkóhun tí ìwọ bá fẹ́ lọ́wọ́ mi, èmi ó sì fi fún ọ.”
A gdy weszła córka onej Herodyjady i tańcowała, i podobała się Herodowi i spółsiedzącym, rzekł król do dzieweczki: Proś mię o co chcesz, a dam ci.
23 Ó sì búra fún un wí pé, “Ohunkóhun tí ìwọ bá fẹ́, ìbá à ṣe ìdajì ìjọba mi ni, èmi yóò fi fún ọ.”
I przysiągł jej: O cokolwiek byś mię prosiła, dam ci, aż do połowy królestwa mego.
24 Ó jáde lọ sọ fún ìyá rẹ̀ pé, “Kí ní kí ń béèrè?” Ó dáhùn pé, “Orí Johanu Onítẹ̀bọmi.”
Ona tedy wyszedłszy, rzekła matce swojej: O co mam prosić? A ona rzekła: O głowę Jana Chrzciciela.
25 Ọmọbìnrin yìí sáré padà wá sọ́dọ̀ Herodu ọba. Ó sì wí fún un pé, “Mo ń fẹ́ orí Johanu Onítẹ̀bọmi nísinsin yìí nínú àwopọ̀kọ́.”
A tak ona zaraz wszedłszy prędko do króla, prosiła mówiąc: Chcę, abyś mi teraz dał na misie głowę Jana Chrzciciela.
26 Inú ọba sì bàjẹ́ gidigidi, ṣùgbọ́n nítorí àwọn ìbúra rẹ, àti nítorí àwọn tí ó bá a jókòó pọ̀, kò sì fẹ́ kọ̀ fún un.
I zasmucił się król bardzo, wszakże dla przysięgi i dla spółsiedzących nie chciał jej odmówić.
27 Nítorí èyí, ọba rán ẹ̀ṣọ́ kan, ó fi àṣẹ fún un pé, kí ó gbé orí Johanu wá. Ọkùnrin náà sì lọ, ó bẹ́ Johanu lórí nínú túbú.
A zarazem posławszy król kata, rozkazał przynieść głowę jego.
28 Ó sì gbé orí Johanu wa nínú àwopọ̀kọ́. Ó sì gbé e fún ọmọbìnrin náà. Òun sì gbé e tọ ìyá rẹ̀ lọ.
A on poszedłszy ściął go w więzieniu, i przyniósł głowę jego na misie, a dał ją dzieweczce, a dzieweczka dała ją matce swojej.
29 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu gbọ́, wọ́n wá gbé òkú rẹ̀, wọ́n sì lọ tẹ́ ẹ sínú ibojì.
Co gdy usłyszeli uczniowie jego, przyszli i wzięli ciało jego, i położyli je w grobie.
30 Àwọn aposteli kó ara wọn jọ sí ọ̀dọ̀ Jesu, wọ́n sí ròyìn ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe àti ohun gbogbo tí wọ́n ti kọ́ni.
A Apostołowie zszedłszy się do Jezusa, opowiedzieli mu wszystko, i co czynili, i czego uczyli.
31 Nígbà tí Jesu rí i pé ọ̀pọ̀ ènìyàn ń lọ tí wọ́n sì ń bọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ààyè fún wọn láti jẹun, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí a kúrò láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn wọ̀nyí fún ìgbà díẹ̀, kí a sì sinmi.”
I rzekł im: Pójdźcie wy sami osobno na miejsce puste, a odpocznijcie trochę; bo ich wiele było, co przychodzili, i odchodzili, tak iż nie mieli wolnego czasu, żeby jedli.
32 Nítorí náà, wọ́n wọ ọkọ̀ ojú omi kúrò níbẹ̀ lọ sí ibi tí ó parọ́rọ́.
I odjechali w łodzi na miejsce puste osobno.
33 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ènìyàn ni o rí wọn nígbà tí wọ́n ń lọ. Àwọn wọ̀nyí sì tún wá láti ìlú ńlá gbogbo wọn sáré gba etí Òkun, wọ́n ṣáájú wọn gúnlẹ̀ ní èbúté.
A widząc je lud, że odjeżdżali, poznało go wiele ich, i zbieżeli się tam pieszo ze wszystkich miast, i poprzedzili je, i zgromadzili się do niego.
34 Bí Jesu ti ń sọ̀kalẹ̀ láti inú ọkọ̀ náà, ó bá ọ̀pọ̀ ènìyàn bí i tí àtẹ̀yìnwá, tí wọ́n ti ń dúró dè e. Ó káàánú fún wọn, nítorí wọ́n dàbí àgùntàn tí kò ní olùtọ́jú. Ó sì kọ́ wọn ni ọ̀pọ̀ nǹkan tí ó yẹ kí wọ́n mọ̀.
A wyszedłszy Jezus ujrzał wielki lud, i użalił się ich, iż byli jako owce nie mające pasterza, i począł ich nauczać wiele rzeczy.
35 Nígbà tí ọjọ́ sì ti bù lọ tán, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n wí fún un pé, ibi aṣálẹ̀ ni ìbí yìí, ọjọ́ sì bù lọ tán.
A gdy już czas mijał, przystąpiwszy do niego uczniowie jego, rzekli: To miejsce jest puste, a już czas mija.
36 “Rán àwọn ènìyàn wọ̀nyí láti lọ sí àwọn abúlé àti ìlú láti ra oúnjẹ fún ara wọn.”
Rozpuść je, aby poszedłszy do okolicznych wsi i miasteczek, nakupili sobie chleba; bo nie mają, coby jedli.
37 Ṣùgbọ́n Jesu sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ẹ fún wọn ní oúnjẹ.” Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn wí fún pé, “Èyí yóò ná wa tó owó iṣẹ́ ọ̀yà oṣù mẹ́jọ, ṣe kí a lọ fi èyí ra àkàrà fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn yìí láti jẹ.”
A on odpowiadając, rzekł im: Dajcie wy im jeść. I rzekli mu: Szedłszy kupimy za dwieście groszy chleba, a damy im jeść?
38 Jesu tún béèrè pé, “Ìṣù àkàrà mélòó ni ẹ̀yin ni lọ́wọ́? Ẹ lọ wò ó.” Wọ́n padà wá jíṣẹ́ pé, “Ìṣù àkàrà márùn-ún àti ẹja méjì.”
A on im rzekł: Wieleż chleba macie? Idźcie, a dowiedzcie się. A oni dowiedziawszy się, powiedzieli: Pięcioro, i dwie ryby.
39 Nígbà náà ni Jesu sọ fún ọ̀pọ̀ ènìyàn náà kí a mú wọn jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ lórí koríko.
Tedy im kazał wszystkie gromadami posadzić na zielonej trawie.
40 Lẹ́sẹ̀kan náà, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í jókòó, ní àádọ́ta tàbí ọgọọgọ́rùn-ún.
I usiedli rząd podle rządu, tu po stu, tu zaś po pięćdziesiąt.
41 Nígbà tí ó sì mú ìṣù àkàrà márùn-ún àti ẹja méjì náà, ó gbé ojú rẹ̀ sókè ọ̀run. Ó dúpẹ́ fún oúnjẹ náà, ó bù wọ́n sí wẹ́wẹ́, ó fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti gbé e kalẹ̀ síwájú àwọn ènìyàn náà àti àwọn ẹja méjì náà ni ó pín fún gbogbo wọn.
A wziąwszy one pięć chlebów, i one dwie ryby, wejrzawszy w niebo, błogosławił. I połamał one chleby i dawał uczniom swoim, aby kładli przed nie; i one dwie ryby rozdzielił między wszystkie.
42 Gbogbo wọn sì jẹ àjẹyó.
I jedli wszyscy, i nasyceni byli.
43 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì kó agbọ̀n méjìlá tí ó kún fún àjẹkù àkàrà àti ti ẹja pẹ̀lú.
I zebrali ułomków, dwanaście koszów pełnych, i z onych ryb.
44 Àwọn tí ó sì jẹ́ àkàrà náà tó ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún márùn-ún ọkùnrin.
A było tych, którzy jedli chleby, około pięciu tysięcy mężów.
45 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ lẹ́yìn èyí, Jesu pàṣẹ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti padà sínú ọkọ̀ kí wọn sì ṣáájú rékọjá sí Betisaida. Níbẹ̀ ni òun yóò ti wà pẹ̀lú wọn láìpẹ́. Nítorí òun fúnra a rẹ̀ yóò dúró sẹ́yìn láti rí i pé àwọn ènìyàn túká lọ ilé wọn.
I wnet przymusił ucznie swoje, aby wstąpili w łódź, i uprzedzili go na drugą stronę ku Betsaidzie, ażby on rozpuścił lud.
46 Lẹ́yìn náà, ó lọ sórí òkè láti lọ gbàdúrà.
A odprawiwszy je, odszedł na górę, aby się modlił.
47 Nígbà tí ó di alẹ́, ọkọ̀ wà láàrín Òkun, òun nìkan sì wà lórí ilẹ̀.
A gdy był wieczór, była łódź w pośród morza, a on sam był na ziemi.
48 Ó rí i wí pé àwọn ọmọ-ẹ̀yìn wà nínú wàhálà púpọ̀ ní wíwa ọkọ̀ náà nítorí ti ìjì líle ṣe ọwọ́ òdì sí wọn, nígbà tí ó sì dì ìwọ̀n ìṣọ́ kẹrin òru, ó tọ̀ wọ́n wá, ó ń rìn lórí omi Òkun, òun sì fẹ́ ré wọn kọjá,
I widział, że się spracowali, wiosłami robiąc; (bo wiatr mieli przeciwny, ) a tak około czwartej straży nocnej przyszedł do nich, chodząc po morzu, i chciał je wyminąć.
49 ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí i tí ó ń rìn, wọ́n rò pé iwin ni. Wọ́n sì kígbe sókè lóhùn rara,
Ale oni ujrzawszy go chodzącego po morzu, mniemali, żeby była obłuda, i krzyknęli:
50 nítorí gbogbo wọn ni ó rí i, tí ẹ̀rù sì bà wọ́n. Ṣùgbọ́n òun sọ̀rọ̀ sí wọn lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ pé, “Ẹ mú ọkàn le! Èmi ni. Ẹ má bẹ̀rù.”
(Bo go wszyscy widzieli, i wylękli się.) Ale zaraz przemówił do nich, i rzekł im: Ufajcie, jam jest; nie bójcie się!
51 Nígbà náà ni ó gòkè sínú ọkọ̀ pẹ̀lú wọn, ìjì líle náà sì dáwọ́ dúró. Ẹ̀rù sì bà wọ́n rékọjá gidigidi, ẹnu sì yà wọ́n.
I wstąpił do nich w łódź, i uciszył się wiatr; a oni się sami w sobie nader zdumiewali i dziwowali.
52 Wọn kò sá tó ni òye iṣẹ́ ìyanu ti ìṣù àkàrà, nítorí ti ọkàn wọn yigbì.
Bo nie zrozumieli z strony chlebów, gdyż serce ich było zdrętwiało.
53 Lẹ́yìn tí wọ́n la Òkun náà kọjá, wọ́n gúnlẹ̀ sí Genesareti. Wọ́n sì so ọkọ̀ sí èbúté.
A przeprawiwszy się przyszli do ziemi Gienezaret i przybili się do brzegu.
54 Wọ́n jáde kúrò nínú ọkọ̀. Àwọn ènìyàn tó wà níbẹ̀ rí Jesu, wọ́n sì dá a mọ̀ ọ́n.
A gdy wyszli z łodzi, zaraz ci, co go poznali,
55 Wéré, wọ́n ròyìn dídé rẹ̀, gbogbo àwọn ènìyàn sáré gbé gbogbo àwọn aláìsàn lórí àkéte wọn wá pàdé rẹ̀.
Obieżawszy wszystkę onę okoliczną krainę, poczęli nosić na łożach tych, którzy się źle mieli, gdziekolwiek usłyszeli o nim, że tam jest.
56 Ní ibi gbogbo tí ó sì dé, yálà ní abúlé, ìlú ńlá tàbí àrọ́ko, ń ṣe ni wọ́n ń kó àwọn aláìsàn pàdé rẹ̀ ní àárín ọjà. Wọ́n sì ń bẹ̀ ẹ́ kí ó jẹ́ kí wọn fi ọwọ́ kan etí aṣọ rẹ̀, gbogbo àwọn tí wọ́n sì fi ọwọ́ kàn án ni a mú láradá.
A gdziekolwiek on wszedł do miasteczek, albo do miast, albo do wsi, kładli niemocne po ulicach, i prosili go, aby się tylko dotykali podołka szaty jego; a ile się go ich dotknęli, byli uzdrowieni.

< Mark 6 >