< Mark 5 >
1 Wọ́n lọ sí apá kejì adágún ní ẹ̀bá ilẹ̀ àwọn ará Gadara.
Un tie nonāca viņpus jūras, Gadariešu tiesā.
2 Bí Jesu sì ti ń ti inú ọkọ̀ ojú omi jáde. Ọkùnrin kan tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́ jáde ti ibojì wá pàdé rẹ̀.
Un Viņam no laivas izejot tūdaļ sastapās no kapiem cilvēks ar nešķīstu garu;
3 Ọkùnrin yìí ń gbé nínú ibojì, kò sí ẹni tí ó lè dè é mọ́, kódà ẹ̀wọ̀n kò le dè é.
Tam bija sava mītne kapos, un neviens viņu nevarēja ne ar ķēdēm saistīt.
4 Nítorí pé nígbà púpọ̀ ni wọ́n ti ń fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ dè é lọ́wọ́ àti ẹsẹ̀, tí ó sì ń já a dànù kúrò ni ẹsẹ̀ rẹ̀. Kò sí ẹnìkan tí ó ní agbára láti káwọ́ rẹ̀.
Jo tas ar pinekļiem un ķēdēm daudzkārt bija saistīts; bet viņš salauza tās ķēdes un sarāva tos pinekļus, un neviens to nespēja valdīt.
5 Tọ̀sán tòru láàrín àwọn ibojì àti ní àwọn òkè ni ó máa ń kígbe rara tí ó sì ń fi òkúta ya ara rẹ̀.
Un tas bija vienmēr naktīm un dienām kalnos un iekš kapiem, brēkdams un sevi ar akmeņiem sizdams.
6 Nígbà tí ó sì rí Jesu látòkèrè, ó sì sáré lọ láti pàdé rẹ̀. Ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
Bet Jēzu no tālienes ieraudzījis, tas skrēja un metās priekš Viņa zemē
7 Ó sì kígbe ní ohùn rara wí pé, “Kí ní ṣe tèmi tìrẹ, Jesu Ọmọ Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo? Mo fi Ọlọ́run bẹ̀ ọ́ má ṣe dá mi lóró.”
Un brēca ar stipru balsi un sacīja: “Kas man ar Tevi, Jēzu, Tu Dieva, Tā Visaugstākā, Dēls? No Dieva puses Tevi lūdzu, nemoki mani!”
8 Nítorí tí Ó wí fún un pé, “Jáde kúrò lára ọkùnrin náà, ìwọ ẹ̀mí àìmọ́!”
Jo Viņš uz to sacīja: “Izej, tu nešķīstais gars, no tā cilvēka.”
9 Jesu sì bi í léèrè pé, “Kí ni orúkọ rẹ?” Ẹ̀mí àìmọ́ náà sì dáhùn wí pé, “Ligioni, nítorí àwa pọ̀.”
Un Viņš tam jautāja: “Kāds tev vārds?” Un tas atbildēja sacīdams: “Vārds man leģions, jo mēs esam daudz.”
10 Nígbà náà ni ẹ̀mí àìmọ́ náà bẹ̀rẹ̀ sí í bẹ Jesu gidigidi, kí ó má ṣe rán àwọn jáde kúrò ní agbègbè náà.
Un tas Viņu ļoti lūdza, lai Viņš tos no tā apgabala neizdzītu.
11 Agbo ẹlẹ́dẹ̀ ńlá kan sì ń jẹ lẹ́bàá òkè.
Bet tur pie tā kalna bija liels cūku pulks ganos.
12 Àwọn ẹ̀mí àìmọ́ náà bẹ Jesu pé, “Rán wa lọ sínú àwọn ẹlẹ́dẹ̀ wọ̀n-ọn-nì kí àwa le è wọ inú wọn lọ.”
Un visi tie velni Viņu lūdza sacīdami: “Sūti mūs tais cūkās, ka tanīs ieskrienam.”
13 Jesu fún wọn láààyè, àwọn ẹ̀mí àìmọ́ náà sì jáde kúrò lára ọkùnrin náà, wọ́n sì wọ inú àwọn ẹlẹ́dẹ̀ náà lọ. Agbo ẹlẹ́dẹ̀ náà tí ó tó ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún méjì sì túká lọ́gán, wọ́n sì sáré lọ ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè rọ́ sínú Òkun, wọ́n sì ṣègbé.
Un tūlīt Jēzus tiem to ļāva, un tie nešķīstie gari izgājuši ieskrēja tais cūkās; un tas cūku pulks no kraujas iegāzās jūrā (bet to bija pie divtūkstoš) un noslīka jūrā.
14 Àwọn olùtọ́jú ẹran wọ̀nyí sì sálọ sí àwọn ìlú ńlá àti ìlú kéékèèké, wọ́n sì ń tan ìròyìn náà ká bí wọ́n ti ń sáré. Àwọn ènìyàn sì tú jáde láti fojú gán-án-ní ohun náà tí ó ṣẹlẹ̀.
Un tie cūku gani bēga un stāstīja pilsētā un uz lauka; un tie izgāja raudzīt, kas bija noticis.
15 Nígbà tí wọ́n péjọ sọ́dọ̀ Jesu, wọ́n rí ọkùnrin náà, ẹni tí ó ní ẹ̀mí èṣù, tí ó jókòó níbẹ̀, ó wọ aṣọ ìyè rẹ sì bọ̀ sípò, ẹ̀rù sì bà wọ́n.
Un tie nāca pie Jēzus un ieraudzīja to velna apsēsto tur sēžam, apģērbtu un pie pilna prāta, to pašu, kam tas leģions bijis; un tie izbijās.
16 Àwọn tí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ṣojú wọn sì ń ròyìn rẹ̀ fún àwọn ènìyàn ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí ọkùnrin ẹlẹ́mìí àìmọ́, wọ́n si sọ nípa agbo ẹlẹ́dẹ̀ náà pẹ̀lú.
Un tie, kas to bija redzējuši, viņiem stāstīja, kā tam velna apsēstam bija noticis, un par tām cūkām.
17 Nígbà náà, àwọn èrò bẹ̀rẹ̀ sí ní bẹ Jesu pé kí ó fi agbègbè àwọn sílẹ̀.
Un tie sāka Viņu lūgt, lai no viņu robežām aizejot.
18 Bí Jesu ti ń wọ inú ọkọ̀ ojú omi lọ, ọkùnrin náà tí ó ti ní ẹ̀mí àìmọ́ tẹ́lẹ̀ bẹ̀ Ẹ́ pé kí òun lè bá a lọ.
Un kad Viņš kāpa laivā, tas velna apsēstais Viņu lūdza, ka pie Viņa varētu palikt.
19 Jesu kò gbà fún un, ṣùgbọ́n ó wí fún un pé, “Lọ sí ilé sí ọ̀dọ̀ àwọn ẹbí rẹ, kí o sì sọ fún wọn bí Ọlọ́run ti ṣe ohun ńlá fún ọ, àti bí ó sì ti ṣàánú fún ọ.”
Bet Jēzus to neļāva, bet uz to sacīja: “Ej savās mājās pie tiem savējiem un stāsti tiem, kādas lietas Tas Kungs tev darījis, un kā Viņš par tevi apžēlojies.”
20 Nítorí náà, ọkùnrin yìí padà lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí ròyìn ní Dekapoli nípa ohun ńlá tí Jesu ṣe fún un. Ẹnu sì ya gbogbo ènìyàn.
Un tas nogāja un sāka sludināt pa tām desmit pilsētām, ko Jēzus tam bija darījis, un visi brīnījās.
21 Nígbà tí Jesu sì ti inú ọkọ̀ rékọjá sí apá kejì Òkun, ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn péjọ yí i ká ní etí Òkun.
Un kad Jēzus atkal laivā bija pārcēlies uz otru malu, tad daudz ļaužu pie Viņa sapulcējās, un Viņš bija jūrmalā.
22 Ọ̀kan nínú àwọn olórí Sinagọgu tí à ń pè ni Jairu wá sọ́dọ̀ Jesu, nígbà tí ó sì rí i, ó wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
Un redzi, tad nāca viens no tiem baznīcas priekšniekiem, Jaīrus ar vārdu; un Viņu redzēdams, tas krita Viņam pie kājām,
23 Ó sì bẹ̀ ẹ́ gidigidi pé, “Ọmọbìnrin mi wà lójú ikú, mo bẹ̀ ọ́, wá fi ọwọ́ rẹ lé e, kí ara rẹ̀ lè dá, kí ó sì yè.”
Un Viņu ļoti lūdza sacīdams: “Mana meitiņa guļ uz nāvi, lūdzams, nāc un uzliec tai rokas, ka viņa top vesela un dzīvo.”
24 Jesu sì ń bá a lọ. Ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn sì ń tọ̀ Ọ́ lẹ́yìn.
Un Viņš ar to nogāja. Un daudz ļaužu Viņam gāja pakaļ un Viņu spieda.
25 Obìnrin kan sì wà láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, tí ó ti ní ìsun ẹ̀jẹ̀ fún odidi ọdún méjìlá.
Un tur bija viena sieva, tai jau divpadsmit gadus bija asinssērga.
26 Ẹni tí ojú rẹ̀ sì ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpọ́njú lọ́dọ̀ ọ̀pọ̀ àwọn oníṣègùn, tí ó sì ti ná gbogbo ohun tí ó ní, síbẹ̀ kàkà kí ó san, ó ń burú sí i.
Un tā daudz bija cietusi no daudz ārstiem un visu savu nabadzību iztērējusi un nekādu palīdzību nebija atradusi, bet tā sērga bija vēl niknāka palikusi.
27 Nígbà tí ó sì gbúròó iṣẹ́ ìyanu tí Jesu ṣe, ìdí nìyìí tí ó fi wá sẹ́yìn rẹ̀, láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn, ó sì fọwọ́ kan aṣọ rẹ̀.
Šī par Jēzu dzirdējusi nāca ļaužu pulkā no aizmugures un aizskāra Viņa drēbes.
28 Nítorí ti ó rò ní ọkàn rẹ̀ pé, “Bí mo bá sá à lè fi ọwọ́ kan aṣọ rẹ̀, ara mi yóò dá.”
Jo tā sacīja: “Ja vien Viņa drēbes aizskaršu, tad tapšu vesela.”
29 Ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì gbẹ lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, òun sì mọ̀ lára rẹ̀ pé, a mú òun láradá kúrò nínú ààrùn náà.
Un tūdaļ viņas asins avots izsīka; un viņa noprata pie savām miesām, ka no tās kaites bija dziedināta.
30 Lọ́gán, Jesu sì mọ̀ nínú ara rẹ̀ pé agbára jáde lára òun. Ó yípadà láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn, ó sì béèrè, “Ta ni ó fi ọwọ́ kan aṣọ mi?”
Un Jēzus tūdaļ pie Sevis nomanīdams, ka spēks no Viņa izgājis, apgriezās uz tiem ļaudīm un sacīja: “Kas Manas drēbes aizskāris?”
31 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ rí ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ó rọ̀gbà yí ọ ká, ìwọ sì tún ń béèrè ẹni tí ó fi ọwọ́ kàn ọ́?”
Un Viņa mācekļi uz Viņu sacīja: “Tu redzi, ka tie ļaudis Tev virsū mācās, un Tu saki: kas Mani aizskāris?”
32 Síbẹ̀, Jesu bẹ̀rẹ̀ sí wò yíká láti rí ẹni náà, tí ó fi ọwọ́ kan òun.
Un Viņš skatījās apkārt, to ieraudzīt, kas to bija darījusi.
33 Nígbà náà, obìnrin náà kún fún ìbẹ̀rù àti ìwárìrì nítorí ó ti mọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ lára òun. Ó sì kúnlẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì sọ gbogbo òtítọ́ fún un.
Bet tā sieva bīdamies un drebēdama zināja, kas pie viņas bija noticis, nāca un krita Viņa priekšā pie zemes un Viņam visu to patiesību izteica.
34 Jesu sì wí fún un pé, “Ọmọbìnrin, ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá. Máa lọ ní àlàáfíà, ìwọ sì ti sàn nínú ààrùn rẹ.”
Bet Viņš uz to sacīja: “Mana meita, tava ticība tev palīdzējusi. Ej ar mieru un paliec vesela no tavas kaites.”
35 Bí Jesu sì ti ń ba obìnrin náà sọ̀rọ̀, àwọn ìránṣẹ́ dé láti ilé Jairu olórí Sinagọgu wá, wọ́n wí fún un pé, ọmọbìnrin rẹ ti kú, àti pé kí wọn má ṣe yọ Jesu lẹ́nu láti wá, nítorí ó ti pẹ́ jù.
Viņam to vēl runājot, kādi no tā baznīcas priekšnieka nāca un sacīja: “Tava meita jau nomirusi, ko tu To Mācītāju vēl apgrūtini.”
36 Ṣùgbọ́n bi Jesu ti gbọ́ ọ̀rọ̀ náà, ó wí fún Jairu pé, “Má bẹ̀rù, sá à gbàgbọ́ nìkan.”
Bet Jēzus to vārdu, ko tie teica, dzirdējis, sacīja uz to baznīcas priekšnieku: “Nebīsties, tici vien!”
37 Nígbà náà, Jesu dá ọ̀pọ̀ ènìyàn náà dúró. Kò sì jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tẹ̀lé òun lẹ́yìn lọ ilé Jairu, bí kò ṣe Peteru, Jakọbu àti Johanu arákùnrin Jakọbu.
Un Viņš neļāva nevienam Sev līdz iet kā vien Pēterim un Jēkabam un Jānim, Jēkaba brālim.
38 Nígbà tí wọ́n dé ibẹ̀, Jesu rí i pé gbogbo nǹkan ti dàrú. Ilé kún fún àwọn tí ń sọkún, àti àwọn tí ń pohùnréré ẹkún.
Un Viņš nāca tā baznīcas priekšnieka namā un redzēja troksni un ļaudis daudz raudam un kaucam.
39 Ó wọ inú ilé lọ, o sì bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀, ó béèrè pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń sọkún tí ẹ sì ń pohùnréré ẹkún? Ọmọbìnrin náà kò kú, ó sùn lásán ni.”
Un Viņš iegājis uz tiem sacīja: “Ko jūs dariet troksni un raudiet? Tas bērns nav miris, bet guļ.”
40 Wọ́n sì fi í rẹ́rìn-ín. Ṣùgbọ́n ó sọ fún gbogbo wọn láti bọ́ síta, ó mú baba àti ìyá ọmọ náà, àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ mẹ́ta. Ó sì wọ inú yàrá tí ọmọbìnrin náà gbé dùbúlẹ̀ sí.
Un tie Viņu izsmēja. Bet Viņš visus izdzina un ņēma pie Sevis tā bērna tēvu un māti un tos, kas līdz ar Viņu bija, un iegāja, kur tas bērns gulēja.
41 Ó gbá a ní ọwọ́ mú, ó sì wí pé, “Talita kuumi” (tí ó túmọ̀ sí “Ọmọdébìnrin, dìde dúró!”).
Un Viņš satvēra tā bērna roku un sacīja uz to: “Talita, kūmi!” Tas ir tulkots: “Meitiņa, Es tev saku, celies augšām!”
42 Lẹ́sẹ̀kan náà, ọmọbìnrin náà sì dìde. Ó sì ń rìn, ẹ̀rù sì bà wọ́n, ẹnu sì ya àwọn òbí rẹ̀ gidigidi.
Un tā meitiņa tūlīt cēlās un staigāja; jo tā bija divpadsmit gadus veca. Un tie iztrūcinājās ar lielu iztrūcināšanos.
43 Jesu sì kìlọ̀ fún wọn gidigidi pé kí wọn má ṣe sọ ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀. Ó sì wí fún wọn kí wọn fún ọmọbìnrin náà ní oúnjẹ.
Un Viņš tiem stipri piekodināja, ka neviens to nedabūtu zināt, un lika tai dot ēst.