< Mark 3 >
1 Nígbà tí Jesu wá sí Sinagọgu. Sì kíyèsi i ọkùnrin kan wà níbẹ̀, tí ọwọ́ rẹ̀ kan rọ.
anantaraM yIzuH puna rbhajanagRhaM praviSTastasmin sthAnE zuSkahasta EkO mAnava AsIt|
2 Àwọn kan nínú wọn sì ń wa ọ̀nà láti fi ẹ̀sùn kan Jesu. Nítorí náà, wọ́n ń ṣọ́ Ọ bí yóò mú un láradá ní ọjọ́ ìsinmi.
sa vizrAmavArE tamarOgiNaM kariSyati navEtyatra bahavastam apavadituM chidramapEkSitavantaH|
3 Jesu wí fún ọkùnrin tí ọwọ́ rẹ̀ rọ náà pé, “Dìde dúró ní iwájú ìjọ ènìyàn.”
tadA sa taM zuSkahastaM manuSyaM jagAda madhyasthAnE tvamuttiSTha|
4 Nígbà náà ni Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ǹjẹ́ ó bá òfin mu ní ọjọ́ ìsinmi bóyá láti ṣe rere, tàbí láti ṣe búburú! Láti gbà ẹ̀mí là, tàbí pa á run?” Ṣùgbọ́n wọ́n dákẹ́ láìfèsì.
tataH paraM sa tAn papraccha vizrAmavArE hitamahitaM tathA hi prANarakSA vA prANanAza ESAM madhyE kiM karaNIyaM? kintu tE niHzabdAstasthuH|
5 Nígbà tí ó sì wo gbogbo wọn yíká pẹ̀lú ìbínú, ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí líle àyà wọn, ó sọ fún ọkùnrin náà pé, “Na ọwọ́ rẹ jáde.” Ó nà án jáde, ọwọ́ náà sì bọ̀ sípò padà pátápátá.
tadA sa tESAmantaHkaraNAnAM kAThinyAddhEtO rduHkhitaH krOdhAt cartudazO dRSTavAn taM mAnuSaM gaditavAn taM hastaM vistAraya, tatastEna hastE vistRtE taddhastO'nyahastavad arOgO jAtaH|
6 Lójúkan náà, àwọn Farisi jáde lọ, láti bá àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Herodu gbìmọ̀ pọ̀, bí wọn yóò ṣe pa Jesu.
atha phirUzinaH prasthAya taM nAzayituM hErOdIyaiH saha mantrayitumArEbhirE|
7 Jesu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ yẹra kúrò níbẹ̀ lọ sí etí Òkun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn láti Galili àti Judea sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
ataEva yIzustatsthAnaM parityajya ziSyaiH saha punaH sAgarasamIpaM gataH;
8 Nígbà tí wọ́n gbọ́ ìròyìn iṣẹ́ ìyanu tí ó ṣe, ọ̀pọ̀ ènìyàn sì tọ̀ ọ́ wá láti Judea, Jerusalẹmu àti Idumea, àti láti apá kejì odò Jordani àti láti ìhà Tire àti Sidoni.
tatO gAlIlyihUdA-yirUzAlam-idOm-yardannadIpArasthAnEbhyO lOkasamUhastasya pazcAd gataH; tadanyaH sOrasIdanOH samIpavAsilOkasamUhazca tasya mahAkarmmaNAM vArttaM zrutvA tasya sannidhimAgataH|
9 Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn, Jesu sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti ṣètò ọkọ̀ ojú omi kékeré kan sílẹ̀ fún un láti lọ, láti lé àwọn èrò sẹ́yìn.
tadA lOkasamUhazcEt tasyOpari patati ityAzagkya sa nAvamEkAM nikaTE sthApayituM ziSyAnAdiSTavAn|
10 Nítorí tí ó mú ọ̀pọ̀ ènìyàn láradá, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn aláìsàn ló bí ara wọn lù ú láti fi ọwọ́ kàn án.
yatO'nEkamanuSyANAmArOgyakaraNAd vyAdhigrastAH sarvvE taM spraSTuM parasparaM balEna yatnavantaH|
11 Ìgbàkúgbà tí àwọn tí ó ni ẹ̀mí àìmọ́ bá ti fojú ri, wọ́n á wólẹ̀ níwájú rẹ̀. Wọn a sì kígbe lóhùn rara wí pé, “Ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run.”
aparanjca apavitrabhUtAstaM dRSTvA taccaraNayOH patitvA prOcaiH prOcuH, tvamIzvarasya putraH|
12 Ṣùgbọ́n ó kìlọ̀ fún wọn gidigidi, kí wọn má ṣe fi òun hàn.
kintu sa tAn dRPham AjnjApya svaM paricAyituM niSiddhavAn|
13 Jesu gun orí òkè lọ, ó sì pe àwọn kan tí ó yàn láti wà pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá.
anantaraM sa parvvatamAruhya yaM yaM praticchA taM tamAhUtavAn tatastE tatsamIpamAgatAH|
14 Ó yan àwọn méjìlá, kí wọn kí ó lè wà pẹ̀lú rẹ̀, àti kí ó lè rán wọn lọ láti wàásù
tadA sa dvAdazajanAn svEna saha sthAtuM susaMvAdapracArAya prEritA bhavituM
15 àti láti lágbára láti lé àwọn ẹ̀mí Èṣù jáde.
sarvvaprakAravyAdhInAM zamanakaraNAya prabhAvaM prAptuM bhUtAn tyAjayitunjca niyuktavAn|
16 Wọ̀nyí ni àwọn méjìlá náà tí ó yàn: Simoni (ẹni ti ó sọ àpèlé rẹ̀ ní Peteru),
tESAM nAmAnImAni, zimOn sivadiputrO
17 Jakọbu ọmọ Sebede àti Johanu arákùnrin rẹ̀ (àwọn ẹni tí Jesu sọ àpèlé wọ́n ní Boanaji, èyí tí ó túmọ̀ sí “àwọn ọmọ àrá”).
yAkUb tasya bhrAtA yOhan ca AndriyaH philipO barthalamayaH,
18 Àti Anderu, Filipi, Bartolomeu, Matiu, Tomasi, Jakọbu ọmọ Alfeu, Taddeu, Simoni tí ń jẹ́ Sealoti
mathI thOmA ca AlphIyaputrO yAkUb thaddIyaH kinAnIyaH zimOn yastaM parahastESvarpayiSyati sa ISkariyOtIyayihUdAzca|
19 àti Judasi Iskariotu, ẹni tí ó fi í hàn níkẹyìn.
sa zimOnE pitara ityupanAma dadau yAkUbyOhanbhyAM ca binErigiz arthatO mEghanAdaputrAvityupanAma dadau|
20 Nígbà náà ni Jesu sì wọ inú ilé kan, àwọn èrò sì tún kórajọ, tó bẹ́ẹ̀ tí Òun àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kò rí ààyè láti jẹun.
anantaraM tE nivEzanaM gatAH, kintu tatrApi punarmahAn janasamAgamO 'bhavat tasmAttE bhOktumapyavakAzaM na prAptAH|
21 Nígbà tí àwọn ẹbí rẹ̀ gbọ́ èyí, wọ́n wá láti mú un lọ ilé, nítorí tí wọn wí pé, “Orí rẹ̀ ti dàrú.”
tatastasya suhRllOkA imAM vArttAM prApya sa hatajnjAnObhUd iti kathAM kathayitvA taM dhRtvAnEtuM gatAH|
22 Àwọn olùkọ́ni ní òfin sọ̀kalẹ̀ wá láti Jerusalẹmu, wọ́n sì wí pé, “Ó ni Beelsebulu, olórí àwọn ẹ̀mí èṣù, ni ó sì fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde!”
aparanjca yirUzAlama AgatA yE yE'dhyApakAstE jagadurayaM puruSO bhUtapatyAbiSTastEna bhUtapatinA bhUtAn tyAjayati|
23 Jesu pè wọ́n, ó sì fi òwe bá wọn sọ̀rọ̀: “Báwo ni Èṣù ṣe lè lé èṣù jáde?
tatastAnAhUya yIzu rdRSTAntaiH kathAM kathitavAn zaitAn kathaM zaitAnaM tyAjayituM zaknOti?
24 Bí ìjọba kan bá yapa sí ara rẹ̀, ìjọba náà yóò wó lulẹ̀.
kinjcana rAjyaM yadi svavirOdhEna pRthag bhavati tarhi tad rAjyaM sthiraM sthAtuM na zaknOti|
25 Bákan náà, bí ilé kan bá sì yapa sí ara rẹ, ilé náà kí yóò le è dúró.
tathA kasyApi parivArO yadi parasparaM virOdhI bhavati tarhi sOpi parivAraH sthiraM sthAtuM na zaknOti|
26 Bí Èṣù bá sì dìde sí ara rẹ̀, tí ó sì yapa, òun kí yóò le è dúró ṣùgbọ́n òpin rẹ̀ yóò dé.
tadvat zaitAn yadi svavipakSatayA uttiSThan bhinnO bhavati tarhi sOpi sthiraM sthAtuM na zaknOti kintUcchinnO bhavati|
27 Kò sí ẹni tí ó le wọ ilé ọkùnrin alágbára kan lọ, kí ó sì kó o ní ẹrù lọ, bí kò ṣe pé ó kọ́kọ́ de ọkùnrin alágbára náà ní okùn, nígbà náà ni yóò lè kó ẹrù ní ilé rẹ̀.
aparanjca prabalaM janaM prathamaM na baddhA kOpi tasya gRhaM pravizya dravyANi luNThayituM na zaknOti, taM badvvaiva tasya gRhasya dravyANi luNThayituM zaknOti|
28 Lóòótọ́ ní mo wí fún yín, gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ni a ó dáríjì àwọn ọmọ ènìyàn, àti gbogbo ọ̀rọ̀-òdì.
atOhEtO ryuSmabhyamahaM satyaM kathayAmi manuSyANAM santAnA yAni yAni pApAnIzvaranindAnjca kurvvanti tESAM tatsarvvESAmaparAdhAnAM kSamA bhavituM zaknOti,
29 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí Ẹ̀mí Mímọ́, kì yóò rí ìdáríjì títí ayé, ṣùgbọ́n ó wà nínú ewu ẹ̀bi àìnípẹ̀kun.” (aiōn , aiōnios )
kintu yaH kazcit pavitramAtmAnaM nindati tasyAparAdhasya kSamA kadApi na bhaviSyati sOnantadaNPasyArhO bhaviSyati| (aiōn , aiōnios )
30 Òun sọ eléyìí fún wọn, nítorí tí wọ́n sọ pé, “Nípa agbára ẹ̀mí àìmọ́ ló ń ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.”
tasyApavitrabhUtO'sti tESAmEtatkathAhEtOH sa itthaM kathitavAn|
31 Nígbà náà ni àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìyá wá, wọ́n dúró lóde, wọ́n sì ránṣẹ́ sí i, wọ́n ń pè é.
atha tasya mAtA bhrAtRgaNazcAgatya bahistiSThanatO lOkAn prESya tamAhUtavantaH|
32 Àwọn ènìyàn tí wọ́n jókòó lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Ìyá àti àwọn arákùnrin rẹ wà lóde.”
tatastatsannidhau samupaviSTA lOkAstaM babhASirE pazya bahistava mAtA bhrAtarazca tvAm anvicchanti|
33 Ṣùgbọ́n ó dá wọn lóhùn wí pé, “Ta ni í ṣe ìyá mi tàbí àwọn arákùnrin mi?”
tadA sa tAn pratyuvAca mama mAtA kA bhrAtarO vA kE? tataH paraM sa svamIpOpaviSTAn ziSyAn prati avalOkanaM kRtvA kathayAmAsa
34 Ó sì wò gbogbo àwọn tí ó jókòó lọ́dọ̀ rẹ̀ yíká, ó sì wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìyá mi àti àwọn arákùnrin mi.
pazyataitE mama mAtA bhrAtarazca|
35 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run, òun ni arákùnrin mi àti arábìnrin mi àti ìyá mi.”
yaH kazcid IzvarasyESTAM kriyAM karOti sa Eva mama bhrAtA bhaginI mAtA ca|