< Mark 3 >
1 Nígbà tí Jesu wá sí Sinagọgu. Sì kíyèsi i ọkùnrin kan wà níbẹ̀, tí ọwọ́ rẹ̀ kan rọ.
Ele entrou novamente na sinagoga, e estava lá um homem cuja mão estava murcha.
2 Àwọn kan nínú wọn sì ń wa ọ̀nà láti fi ẹ̀sùn kan Jesu. Nítorí náà, wọ́n ń ṣọ́ Ọ bí yóò mú un láradá ní ọjọ́ ìsinmi.
Eles o observavam, se ele iria curá-lo no dia de sábado, para que o acusassem.
3 Jesu wí fún ọkùnrin tí ọwọ́ rẹ̀ rọ náà pé, “Dìde dúró ní iwájú ìjọ ènìyàn.”
Ele disse ao homem cuja mão estava murcha: “Levante-se”.
4 Nígbà náà ni Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ǹjẹ́ ó bá òfin mu ní ọjọ́ ìsinmi bóyá láti ṣe rere, tàbí láti ṣe búburú! Láti gbà ẹ̀mí là, tàbí pa á run?” Ṣùgbọ́n wọ́n dákẹ́ láìfèsì.
Ele lhes disse: “É lícito no dia de sábado fazer o bem ou fazer o mal? Para salvar uma vida ou para matar?” Mas eles ficaram em silêncio.
5 Nígbà tí ó sì wo gbogbo wọn yíká pẹ̀lú ìbínú, ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí líle àyà wọn, ó sọ fún ọkùnrin náà pé, “Na ọwọ́ rẹ jáde.” Ó nà án jáde, ọwọ́ náà sì bọ̀ sípò padà pátápátá.
Quando ele havia olhado ao redor deles com raiva, sofrendo com o endurecimento de seus corações, disse ao homem: “Estenda sua mão”. Ele a estendeu, e sua mão foi restaurada tão saudável quanto a outra.
6 Lójúkan náà, àwọn Farisi jáde lọ, láti bá àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Herodu gbìmọ̀ pọ̀, bí wọn yóò ṣe pa Jesu.
Os fariseus saíram, e imediatamente conspiraram com os herodianos contra ele, como eles poderiam destruí-lo.
7 Jesu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ yẹra kúrò níbẹ̀ lọ sí etí Òkun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn láti Galili àti Judea sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
Jesus retirou-se para o mar com seus discípulos; e uma grande multidão o seguiu da Galiléia, da Judéia,
8 Nígbà tí wọ́n gbọ́ ìròyìn iṣẹ́ ìyanu tí ó ṣe, ọ̀pọ̀ ènìyàn sì tọ̀ ọ́ wá láti Judea, Jerusalẹmu àti Idumea, àti láti apá kejì odò Jordani àti láti ìhà Tire àti Sidoni.
de Jerusalém, de Iduméia, além do Jordão, e os que vinham dos arredores de Tiro e Sidom. Uma grande multidão, ouvindo as grandes coisas que ele fazia, veio até ele.
9 Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn, Jesu sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti ṣètò ọkọ̀ ojú omi kékeré kan sílẹ̀ fún un láti lọ, láti lé àwọn èrò sẹ́yìn.
Ele falou a seus discípulos que um barquinho deveria ficar perto dele por causa da multidão, para que eles não o pressionassem.
10 Nítorí tí ó mú ọ̀pọ̀ ènìyàn láradá, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn aláìsàn ló bí ara wọn lù ú láti fi ọwọ́ kàn án.
Pois ele havia curado muitos, para que todos os que tinham doenças o pressionassem para que o pudessem tocar.
11 Ìgbàkúgbà tí àwọn tí ó ni ẹ̀mí àìmọ́ bá ti fojú ri, wọ́n á wólẹ̀ níwájú rẹ̀. Wọn a sì kígbe lóhùn rara wí pé, “Ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run.”
Os espíritos imundos, sempre que o viam, caíam diante dele e gritavam: “Você é o Filho de Deus”!
12 Ṣùgbọ́n ó kìlọ̀ fún wọn gidigidi, kí wọn má ṣe fi òun hàn.
Ele os advertiu severamente que não deveriam dá-lo a conhecer.
13 Jesu gun orí òkè lọ, ó sì pe àwọn kan tí ó yàn láti wà pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá.
Ele subiu na montanha e chamou para si aqueles que ele queria, e eles foram até ele.
14 Ó yan àwọn méjìlá, kí wọn kí ó lè wà pẹ̀lú rẹ̀, àti kí ó lè rán wọn lọ láti wàásù
Ele indicou doze, para que estivessem com ele, e para que os enviasse a pregar
15 àti láti lágbára láti lé àwọn ẹ̀mí Èṣù jáde.
e ter autoridade para curar doenças e expulsar demônios:
16 Wọ̀nyí ni àwọn méjìlá náà tí ó yàn: Simoni (ẹni ti ó sọ àpèlé rẹ̀ ní Peteru),
Simão (a quem ele deu o nome de Pedro);
17 Jakọbu ọmọ Sebede àti Johanu arákùnrin rẹ̀ (àwọn ẹni tí Jesu sọ àpèlé wọ́n ní Boanaji, èyí tí ó túmọ̀ sí “àwọn ọmọ àrá”).
Tiago, filho de Zebedeu; e João, irmão de Tiago (a quem ele chamou de Boanerges, que significa Filhos do Trovão);
18 Àti Anderu, Filipi, Bartolomeu, Matiu, Tomasi, Jakọbu ọmọ Alfeu, Taddeu, Simoni tí ń jẹ́ Sealoti
André; Filipe; Bartolomeu; Mateus; Tomé; Tiago, filho de Alfeu; Tadeu; Simão, o Zelote;
19 àti Judasi Iskariotu, ẹni tí ó fi í hàn níkẹyìn.
e Judas Iscariotes, que também o traiu. Depois ele entrou em uma casa.
20 Nígbà náà ni Jesu sì wọ inú ilé kan, àwọn èrò sì tún kórajọ, tó bẹ́ẹ̀ tí Òun àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kò rí ààyè láti jẹun.
A multidão se reuniu novamente, de modo que não podiam nem mesmo comer pão.
21 Nígbà tí àwọn ẹbí rẹ̀ gbọ́ èyí, wọ́n wá láti mú un lọ ilé, nítorí tí wọn wí pé, “Orí rẹ̀ ti dàrú.”
Quando seus amigos o ouviram, saíram para apreendê-lo; pois disseram: “Ele é louco”.
22 Àwọn olùkọ́ni ní òfin sọ̀kalẹ̀ wá láti Jerusalẹmu, wọ́n sì wí pé, “Ó ni Beelsebulu, olórí àwọn ẹ̀mí èṣù, ni ó sì fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde!”
Os escribas que desceram de Jerusalém disseram: “Ele tem Belzebu”, e “Pelo príncipe dos demônios ele expulsa os demônios”.
23 Jesu pè wọ́n, ó sì fi òwe bá wọn sọ̀rọ̀: “Báwo ni Èṣù ṣe lè lé èṣù jáde?
Ele os convocou e lhes disse em parábolas: “Como Satanás pode expulsar Satanás?
24 Bí ìjọba kan bá yapa sí ara rẹ̀, ìjọba náà yóò wó lulẹ̀.
Se um reino está dividido contra si mesmo, esse reino não pode permanecer de pé.
25 Bákan náà, bí ilé kan bá sì yapa sí ara rẹ, ilé náà kí yóò le è dúró.
Se uma casa está dividida contra si mesma, essa casa não pode permanecer de pé.
26 Bí Èṣù bá sì dìde sí ara rẹ̀, tí ó sì yapa, òun kí yóò le è dúró ṣùgbọ́n òpin rẹ̀ yóò dé.
Se Satanás se levantou contra si mesmo, e está dividido, ele não pode permanecer de pé, mas tem um fim.
27 Kò sí ẹni tí ó le wọ ilé ọkùnrin alágbára kan lọ, kí ó sì kó o ní ẹrù lọ, bí kò ṣe pé ó kọ́kọ́ de ọkùnrin alágbára náà ní okùn, nígbà náà ni yóò lè kó ẹrù ní ilé rẹ̀.
Mas ninguém pode entrar na casa do homem forte para saquear, a menos que ele primeiro amarre o homem forte; então ele saqueará sua casa.
28 Lóòótọ́ ní mo wí fún yín, gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ni a ó dáríjì àwọn ọmọ ènìyàn, àti gbogbo ọ̀rọ̀-òdì.
“Certamente vos digo que todos os pecados dos descendentes dos homens serão perdoados, incluindo suas blasfêmias com as quais eles podem blasfemar;
29 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí Ẹ̀mí Mímọ́, kì yóò rí ìdáríjì títí ayé, ṣùgbọ́n ó wà nínú ewu ẹ̀bi àìnípẹ̀kun.” (aiōn , aiōnios )
mas quem quer que blasfeme contra o Espírito Santo nunca tem perdão, mas está sujeito à condenação eterna”. (aiōn , aiōnios )
30 Òun sọ eléyìí fún wọn, nítorí tí wọ́n sọ pé, “Nípa agbára ẹ̀mí àìmọ́ ló ń ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.”
- porque eles disseram: “Ele tem um espírito impuro”.
31 Nígbà náà ni àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìyá wá, wọ́n dúró lóde, wọ́n sì ránṣẹ́ sí i, wọ́n ń pè é.
Sua mãe e seus irmãos vieram e, parados do lado de fora, mandaram chamá-lo.
32 Àwọn ènìyàn tí wọ́n jókòó lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Ìyá àti àwọn arákùnrin rẹ wà lóde.”
Uma multidão estava sentada ao seu redor e lhe disseram: “Eis que sua mãe, seus irmãos e suas irmãs estão lá fora procurando por você”.
33 Ṣùgbọ́n ó dá wọn lóhùn wí pé, “Ta ni í ṣe ìyá mi tàbí àwọn arákùnrin mi?”
Ele lhes respondeu: “Quem são minha mãe e meus irmãos?”
34 Ó sì wò gbogbo àwọn tí ó jókòó lọ́dọ̀ rẹ̀ yíká, ó sì wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìyá mi àti àwọn arákùnrin mi.
Olhando ao redor daqueles que se sentaram ao seu redor, ele disse: “Eis minha mãe e meus irmãos!
35 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run, òun ni arákùnrin mi àti arábìnrin mi àti ìyá mi.”
Pois quem faz a vontade de Deus é meu irmão, minha irmã e minha mãe”.