< Mark 3 >

1 Nígbà tí Jesu wá sí Sinagọgu. Sì kíyèsi i ọkùnrin kan wà níbẹ̀, tí ọwọ́ rẹ̀ kan rọ.
Ni kabhele akajhingila mugati mu lisinagogi na m'ola jaajhele ni munu jhaapoozili kibhoko.
2 Àwọn kan nínú wọn sì ń wa ọ̀nà láti fi ẹ̀sùn kan Jesu. Nítorí náà, wọ́n ń ṣọ́ Ọ bí yóò mú un láradá ní ọjọ́ ìsinmi.
Baadhi jha bhanu bhankeseleleghe kwa bhuharibifu kulola Kama ibetakujobha ligono lya Sabato ili kwamba bhan'shtakiajhi.
3 Jesu wí fún ọkùnrin tí ọwọ́ rẹ̀ rọ náà pé, “Dìde dúró ní iwájú ìjọ ènìyàn.”
Yesu akan'jobhela munu jha apoozili kibhokho,” Jhinukayi na ujhemayi katikati jha bhumati obho.”
4 Nígbà náà ni Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ǹjẹ́ ó bá òfin mu ní ọjọ́ ìsinmi bóyá láti ṣe rere, tàbí láti ṣe búburú! Láti gbà ẹ̀mí là, tàbí pa á run?” Ṣùgbọ́n wọ́n dákẹ́ láìfèsì.
Kisha akabhajobhela bhanu, “Je ni halali kubhomba khenu kinofu ligono lya Sabato au kubhomba ghaghabelili kuj'ha gha haki; kuokola maisha, au kukoma?” Lakini bhakabakila kinunu.
5 Nígbà tí ó sì wo gbogbo wọn yíká pẹ̀lú ìbínú, ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí líle àyà wọn, ó sọ fún ọkùnrin náà pé, “Na ọwọ́ rẹ jáde.” Ó nà án jáde, ọwọ́ náà sì bọ̀ sípò padà pátápátá.
Akabhalanga kwa ligoga, akajhaihuzunika kwa ndabha j'ha bhubomolaji bhwa mioyo ghyabhene na akan'jobhela munu jhola, “Nyosiajhi kibhokho Kya jhobhi”. Akabhunyoosya ni Yesu akamponesya kibhokho Kya muene.
6 Lójúkan náà, àwọn Farisi jáde lọ, láti bá àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Herodu gbìmọ̀ pọ̀, bí wọn yóò ṣe pa Jesu.
Mafarisayo bhakalota kwibhala na mara bhakabhomba njama pamonga ni Maherode dhidi jha muene ili kun'koma.
7 Jesu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ yẹra kúrò níbẹ̀ lọ sí etí Òkun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn láti Galili àti Judea sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
Kisha Yesu pamonga ni bhanafunzi bha muene, bhakalota kubahari, ni bhumati mbaha bhwa bhanu ghwabhakesisi kuh'omela Galilaya ni Bhuyahudi
8 Nígbà tí wọ́n gbọ́ ìròyìn iṣẹ́ ìyanu tí ó ṣe, ọ̀pọ̀ ènìyàn sì tọ̀ ọ́ wá láti Judea, Jerusalẹmu àti Idumea, àti láti apá kejì odò Jordani àti láti ìhà Tire àti Sidoni.
ni kuh'omela Yerusalemu ni kuh'omela Idumaya ni palongolo jha Yorodani hi jirani jha Tiro ni Sidoni, bhumati mbaha, bhobhup'eliki khila khenu Kya abhombekai, bhahidili kwa muene.
9 Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn, Jesu sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti ṣètò ọkọ̀ ojú omi kékeré kan sílẹ̀ fún un láti lọ, láti lé àwọn èrò sẹ́yìn.
Na abhajobhili bhanafunzi bha muene kuandala bhuatu bhudebe kwa ndabha jha bhumati ili kwamba bhasihidi kun'komanila.
10 Nítorí tí ó mú ọ̀pọ̀ ènìyàn láradá, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn aláìsàn ló bí ara wọn lù ú láti fi ọwọ́ kàn án.
Kwa kujha aponisi bhingi, ili kila munu jha ajhele ni malombosi ajhele ni shauku jha kun'fikila ili an'kamulayi.
11 Ìgbàkúgbà tí àwọn tí ó ni ẹ̀mí àìmọ́ bá ti fojú ri, wọ́n á wólẹ̀ níwájú rẹ̀. Wọn a sì kígbe lóhùn rara wí pé, “Ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run.”
Popoha pala roho bhachafu bho bhikambona, bhabinili pasi mbele jha muene ni kuleta na bhajobhili, “Bhebhe ndo Mwana ghwa k'yara”.
12 Ṣùgbọ́n ó kìlọ̀ fún wọn gidigidi, kí wọn má ṣe fi òun hàn.
Akabhakuta kwa msisitizo bhasibhombi amanyikanikayi.
13 Jesu gun orí òkè lọ, ó sì pe àwọn kan tí ó yàn láti wà pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá.
Akalota panani pa kid'onda, na akabhakuta bha abhalondeghe, na bhakabhoka.
14 Ó yan àwọn méjìlá, kí wọn kí ó lè wà pẹ̀lú rẹ̀, àti kí ó lè rán wọn lọ láti wàásù
Akakabhachagula kumi ni bhabhele (abhakutili mitume), ili. kwamba bhajhelayi pamonga ni muene na abhwesiaghe kubhatuma kuhubiri,
15 àti láti lágbára láti lé àwọn ẹ̀mí Èṣù jáde.
ni kujha ni mamlaka gha kubhosya mapepo.
16 Wọ̀nyí ni àwọn méjìlá náà tí ó yàn: Simoni (ẹni ti ó sọ àpèlé rẹ̀ ní Peteru),
Na akabhachagula kumi ni bhabhele: Simoni, j'haampelili lihina lya Petro,
17 Jakọbu ọmọ Sebede àti Johanu arákùnrin rẹ̀ (àwọn ẹni tí Jesu sọ àpèlé wọ́n ní Boanaji, èyí tí ó túmọ̀ sí “àwọn ọmọ àrá”).
Yakobo mwana ghwa Zebedayo, ni Yohana ndongo munu Yakobo, j'haampelili lihina lya Bonagesi, abhu ndo bhana bha ngurumo,
18 Àti Anderu, Filipi, Bartolomeu, Matiu, Tomasi, Jakọbu ọmọ Alfeu, Taddeu, Simoni tí ń jẹ́ Sealoti
ni Andrea, Filipo, Bartholomayo, Mathayo, Tomaso, Yakobo mwana wa Alfayo, Thadayo, Simoni Mkananayo
19 àti Judasi Iskariotu, ẹni tí ó fi í hàn níkẹyìn.
ni Yuda Iskariote, ambaj'he an'saliti.
20 Nígbà náà ni Jesu sì wọ inú ilé kan, àwọn èrò sì tún kórajọ, tó bẹ́ẹ̀ tí Òun àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kò rí ààyè láti jẹun.
Kisha akalota kunyumba, ni bhumati bhwa bhanu bhakahida pamonga kabhele, hata bhasibhwesi kulya kabhele hata nkate.
21 Nígbà tí àwọn ẹbí rẹ̀ gbọ́ èyí, wọ́n wá láti mú un lọ ilé, nítorí tí wọn wí pé, “Orí rẹ̀ ti dàrú.”
Familia jha muene bho bhapeliki habari ejhu bhakalota kun'kamula, kwani bhajobhili, “Arukibhu ni kuhala”.
22 Àwọn olùkọ́ni ní òfin sọ̀kalẹ̀ wá láti Jerusalẹmu, wọ́n sì wí pé, “Ó ni Beelsebulu, olórí àwọn ẹ̀mí èṣù, ni ó sì fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde!”
Bhaandishi bhabhahidili kuh'oma Yerusalemu bhajobhili, “Apagewe ni Beelzebuli,” ni, “Kwan'tawala ghwa mapepo ibhosya mapepo”.
23 Jesu pè wọ́n, ó sì fi òwe bá wọn sọ̀rọ̀: “Báwo ni Èṣù ṣe lè lé èṣù jáde?
Yesu akabhakuta kwa muene ni kujobha nabhu kwa mifuanu, “Jinsi gani lisyetani kibhwesiayi kumbosya lisyetani?
24 Bí ìjọba kan bá yapa sí ara rẹ̀, ìjọba náà yóò wó lulẹ̀.
Kama bhufalme bhugawanyiki bhwene, bhufalme obhu ghwibhwesya lepi kujhema.
25 Bákan náà, bí ilé kan bá sì yapa sí ara rẹ, ilé náà kí yóò le è dúró.
Kama nyumba jhigabhwanyiki jhiene, jhibhwesya lepi kujhema.
26 Bí Èṣù bá sì dìde sí ara rẹ̀, tí ó sì yapa, òun kí yóò le è dúró ṣùgbọ́n òpin rẹ̀ yóò dé.
Kama lisyetani libeta kujhinuka kinyume kyake liene, libhwesya lepi kujhema, na kubetakujha lifikili mwisho bhwake.
27 Kò sí ẹni tí ó le wọ ilé ọkùnrin alágbára kan lọ, kí ó sì kó o ní ẹrù lọ, bí kò ṣe pé ó kọ́kọ́ de ọkùnrin alágbára náà ní okùn, nígbà náà ni yóò lè kó ẹrù ní ilé rẹ̀.
Lakini ajhelepi hata mmonga jhaibhwesya kujhingila mugati mu nyumba jha munu mwenye nghofu ni kuheja fenu fya muene bila kunfunga mwenye nghofu hoti, na Kisha ni kubhonganiya Kya kijhele mu nyumba.
28 Lóòótọ́ ní mo wí fún yín, gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ni a ó dáríjì àwọn ọmọ ènìyàn, àti gbogbo ọ̀rọ̀-òdì.
Bhukweli nikabhajobhela, dhambi syoha. sya bhana bha bhanu sibetakusamehebhwa, pamonga ni kufufulibhwa ambasyo bhitamka,
29 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí Ẹ̀mí Mímọ́, kì yóò rí ìdáríjì títí ayé, ṣùgbọ́n ó wà nínú ewu ẹ̀bi àìnípẹ̀kun.” (aiōn g165, aiōnios g166)
lakini jhejhioha jhaibeta kun'situ Roho Mtakatifu ibetalepi kusamehebhwa kamwe bali ajhele ni hatia jha dhambi jha milele”. (aiōn g165, aiōnios g166)
30 Òun sọ eléyìí fún wọn, nítorí tí wọ́n sọ pé, “Nípa agbára ẹ̀mí àìmọ́ ló ń ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.”
Yesu alijobhili ele kwa ndabha bhajobhaghe, “Ajhe ni roho bhachafu”.
31 Nígbà náà ni àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìyá wá, wọ́n dúró lóde, wọ́n sì ránṣẹ́ sí i, wọ́n ń pè é.
Kisha nyinamunu ni bhalongomunu bhakahida ni kujhema kwibhala. Bhakan'tuma munu kun'kuta.
32 Àwọn ènìyàn tí wọ́n jókòó lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Ìyá àti àwọn arákùnrin rẹ wà lóde.”
Ni bhumati bhwa bhanu bhwabhujhele bhutamili karibu nu muene bhakan'jobhela, “Nyinu aku ni bhalongobhu bhajhe kwibhala, na bhikulonda bhebhe”.
33 Ṣùgbọ́n ó dá wọn lóhùn wí pé, “Ta ni í ṣe ìyá mi tàbí àwọn arákùnrin mi?”
Akabhajibu, “Niani nyina bhangu ni ndongobhangu?”
34 Ó sì wò gbogbo àwọn tí ó jókòó lọ́dọ̀ rẹ̀ yíká, ó sì wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìyá mi àti àwọn arákùnrin mi.
Akabhalanga bhabhatamili bhan'syonguiki ni kujobha, Lakini, Langayi, abha ndo bha nyina bhangu ni bhalongobhangu!
35 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run, òun ni arákùnrin mi àti arábìnrin mi àti ìyá mi.”
Jhejhioha j'haibhomba mapenzi gha K'yara, munu oj'hu ndo ndongobhangu, ndo nd'ombo bhangu, ni nyina bhangu”.

< Mark 3 >