< Mark 16 >

1 Nígbà tí ọjọ́ ìsinmi sì kọjá, Maria Magdalene, Maria ìyá Jakọbu, àti Salome mú òróró olóòórùn dídùn wá kí wọn bá à le fi kun Jesu lára.
And when the sabbath was past, Mary the Magdalene, and Mary the mother of James, and Salome, bought spices, that they might come and anoint him.
2 Ní kùtùkùtù ọjọ́ kìn-ín-ní ọ̀sẹ̀, wọ́n wá sí ibi ibojì nígbà tí oòrùn bẹ̀rẹ̀ sí yọ,
And very early on the first day of the week, they came to the tomb at the rising of the sun.
3 wọn sì ń bi ara wọn léèrè pé, “Ta ni yóò yí òkúta náà kúrò ní ẹnu ibojì fún wa?”
And they said to one another, Who will roll away for us the stone from the door of the tomb?
4 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọn sì wò ó, wọ́n rí i pé a ti yí òkúta tí ó tóbi gidigidi náà kúrò.
And looking up they see that the stone had been rolled back; for it was very large.
5 Nígbà tí wọ́n sì wo inú ibojì náà, wọ́n rí ọ̀dọ́mọkùnrin kàn tí ó wọ aṣọ funfun, ó jókòó ní apá ọ̀tún, ẹnu sì yà wọn.
And they entered the tomb, and saw a young man sitting on the right side, clothed in a long white garment; and they were affrighted.
6 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má bẹ̀rù: ẹ̀yin ń wá Jesu tí Nasareti, tí a kàn mọ́ àgbélébùú. Ó jíǹde! Kò sí níhìn-ín yìí mọ́, ẹ wo ibi tí wọ́n gbé tẹ́ ẹ sí.
But he saith to them, Be not affrighted; ye seek Jesus the Nazarene who was crucified; he hath risen; he is not here; behold the place where they laid him.
7 Ṣùgbọ́n ẹ lọ sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ títí kan Peteru wí pé, ‘Òun ti ń lọ síwájú yín sí Galili. Ibẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti rí i, gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ fún yín.’”
But go, tell his disciples and Peter, that he is going before you into Galilee; there ye will see him, as he said to you.
8 Wọ́n sáré jáde lọ kánkán, kúrò ní ibi ibojì náà, nítorí tí wọ́n wárìrì; ẹ̀rù sì bà wọn gidigidi; wọn kò wí ohunkóhun fún ẹnikẹ́ni, nítorí ẹ̀rù bá wọ́n.
And they went out, and fled from the tomb; for trembling and amazement had seized them, and they said nothing to any one; for they were terrified.
9 (note: The most reliable and earliest manuscripts do not include Mark 16:9-20.) Nígbà tí Jesu jíǹde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ní ọjọ́ kìn-ín-ní ọ̀sẹ̀, ó kọ́ fi ara hàn fun Maria Magdalene, ni ara ẹni tí ó ti lé ẹ̀mí Èṣù méje jáde.
(note: The most reliable and earliest manuscripts do not include Mark 16:9-20.) (The remaining twelve verses, according to Tischendorf and others, made originally no part of Mark's Gospel. As the passage was added very early, however, since it is referred to by Irenaeus in the latter part of the second century, it is here given, as an appendix.) [[And having risen early, on the first day of the week, he appeared first to Mary the Magdalene, out of whom he had cast seven demons.
10 Òun sì lọ sọ fún àwọn tí ó ti ń bá a gbé, bí wọn ti ń gbààwẹ̀, tí wọ́n sì ń sọkún.
She went and reported it to those who had been with him, who were mourning and weeping.
11 Àti àwọn, nígbà tí wọ́n sì gbọ́ pé Jesu wa láààyè, àti pé, òun ti rí i, wọn kò gbàgbọ́.
And they, when they heard that he was alive, and had been seen by her, did not believe.
12 Lẹ́yìn èyí, ó sì fi ara hàn fún àwọn méjì ní ọ̀nà mìíràn, bí wọ́n ti ń rìn ní ọ̀nà, tí wọ́n sì ń lọ sí ìgbèríko.
After this, he manifested himself in another form to two of them as they walked, going into the country.
13 Nígbà tí wọ́n sì mọ ẹni tí i ṣe, wọ́n sì lọ ròyìn fún àwọn ìyókù, síbẹ̀, àwọn ìyókù kò gbà wọ́n gbọ́.
And they went and reported it to the rest; and even them they did not believe.
14 Lẹ́yìn náà, Jesu fi ara rẹ̀ hàn fún àwọn mọ́kànlá níbi tí wọ́n ti ń jẹun papọ̀; Ó sì bá wọn wí fún àìgbàgbọ́ àti ọkàn líle wọn, nítorí wọn kò gba ẹ̀rí àwọn tí ó ti rí i lẹ́yìn àjíǹde rẹ̀ gbọ́.
Afterward he manifested himself to the eleven themselves, as they were reclining at table, and upbraided them with their unbelief and hardness of heart, because they did not believe those who had seen him after he had risen.
15 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sí gbogbo ayé, kí ẹ sì máa wàásù ìyìnrere mi fún gbogbo ẹ̀dá.
And he said to them, Go ye into all the world, and preach the glad tidings to the whole creation.
16 Ẹni tí ó bá gbàgbọ́, tí a sì tẹ̀bọmi yóò là. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá kọ̀ tí kò gbàgbọ́ yóò jẹ̀bi.
He that believeth and is baptized will be saved; but he that doth not believe will be condemned.
17 Àmì wọ̀nyí yóò sì máa bá àwọn tí ó gbàgbọ́ lọ. Ní orúkọ mi ni wọ́n yóò máa lé ẹ̀mí èṣù jáde. Wọn yóò máa fi èdè tuntun sọ̀rọ̀.
And these signs will accompany believers: In my name they will cast out demons; they will speak with new tongues;
18 Wọn yóò sì gbé ejò lọ́wọ́, bí wọ́n bá sì jẹ májèlé kò nípa wọ́n lára rárá. Wọ́n yóò gbé ọwọ́ lé àwọn aláìsàn, ara wọn yóò sì dá.”
they will take up serpents; and if they drink any deadly thing, it will not hurt them; they will lay their hands on the sick, and they will recover.
19 Nígbà tí Jesu Olúwa sì ti bá wọn sọ̀rọ̀ báyìí tan, á gbé e lọ sí ọ̀run, ó sì jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.
So then, the Lord, after he had spoken to them, was taken up into heaven, and sat down on the right hand of God;
20 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì jáde lọ. Wọ́n ń wàásù káàkiri. Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú wọn, ó sì ń fi ìdí ọ̀rọ̀ rẹ̀ múlẹ̀ nípa àwọn àmì tí ó tẹ̀lé e.
and they went forth, and preached every where, the Lord working with them, and confirming the word by the signs which followed it.]]

< Mark 16 >