< Mark 15 >

1 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀, àwọn olórí àlùfáà, àwọn àgbàgbà, àwọn olùkọ́ òfin àti gbogbo àjọ ìgbìmọ̀ fi ẹnu kò lórí ohun tí wọn yóò ṣe. Wọ́n sì de Jesu, wọ́n mú un lọ, wọ́n sì fi lé Pilatu lọ́wọ́.
And, straightway, early, when they had made, a council, the High-priest, with the Elders, and Scribes, and all the High-council, binding Jesus, led him away, and delivered him up unto Pilate.
2 Pilatu sì bi í léèrè, ó ni, “Ṣe ìwọ ni ọba àwọn Júù?” Jesu sì dáhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bi ìwọ ti wí náà ni.”
And Pilate questioned him—Art, thou, the king of the Jews? And, he, answering him, saith—Thou, sayest.
3 Àwọn olórí àlùfáà fi ẹ̀sùn ohun púpọ̀ kàn án.
And the High-priests began to accuse him, of many things.
4 Pilatu sì tún bi í léèrè pé, “Ṣe ìwọ kò dáhùn ni? Wo gbogbo ẹ̀sùn tí wọ́n fi kàn ọ.”
And, Pilate, again, was questioning him, [saying]—Answerest thou, nothing? See! of how many things, they are accusing thee!
5 Ṣùgbọ́n Jesu kò dalóhùn síbẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ ti ẹnu fi ya Pilatu.
But, Jesus, no further, answered, anything, so that Pilate began to marvel.
6 Ní báyìí, nígbà àjọ, gẹ́gẹ́ bí àṣà, òun a máa dá òǹdè kan sílẹ̀ fún wọn, ẹnikẹ́ni tí wọ́n bá béèrè fún.
Now, at feast time, he was wont to release unto them one prisoner, whom they were claiming.
7 Ọkùnrin kan wà tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Baraba. Wọ́n ti ju òun àti àwọn ọlọ̀tẹ̀ ẹgbẹ́ rẹ̀ sí ọgbà ẹ̀wọ̀n, nítorí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ìjọba, wọ́n sì pa ènìyàn nínú ìdìtẹ̀ wọn.
And there was the so-called Barabbas, with the rebels, bound, even with them who, in the rebellion, had committed, murder.
8 Ọ̀pọ̀ ènìyàn sì lọ bá Pilatu, wọ́n ní kí ó ṣe bí ó ti máa ń ṣe fún wọn ní ọdọọdún.
And, going up, the multitude began to be claiming—according as he was wont to do for them.
9 Pilatu béèrè lọ́wọ́ wọn wí pé, “Ṣe ẹ̀yin ń fẹ́ kí èmi dá ọba àwọn Júù sílẹ̀ fún yin?”
But, Pilate, answered them, saying—Will ye, I release unto you, the King of the Jews?
10 Òun mọ̀ pé nítorí ìlara ni àwọn olórí àlùfáà ṣe fà Jesu lé òun lọ́wọ́.
For he was getting to know that, for envy, had [the High-priests] delivered him up.
11 Nígbà náà ni àwọn olórí àlùfáà ru ọ̀pọ̀ ènìyàn sókè pé, kí ó kúkú dá Baraba sílẹ̀ fún wọn.
But, the High-priests, stirred up the multitude, that, rather Barabbas, he should release unto them.
12 Pilatu sì tún béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Kí ni ẹ̀yin ń fẹ́ kí èmi kí ó ṣe pẹ̀lú ẹni ti ẹ̀yin n pè ní ọba àwọn Júù?”
But, Pilate, again answering, was saying unto them—What then shall I do with him whom ye call, the King of the Jews?
13 Wọ́n sì tún kígbe sókè pé, “Kàn án mọ àgbélébùú!”
And, they, again, cried out—Crucify him!
14 Nígbà náà ni Pilatu bi wọn léèrè pé, “Èéṣe? Búburú kí ni ó ṣe?” Wọ́n sì kígbe sókè gidigidi wí pé, “Kàn án mọ́ àgbélébùú!”
But, Pilate, was saying unto them—Why! what, evil, hath he done? And, they, vehemently, cried out—Crucify him!
15 Pilatu sì ń fẹ́ ṣe èyí tí ó wu àwọn ènìyàn, ó dá Baraba sílẹ̀ fún wọn. Nígbà tí ó sì na Jesu tan o fà á lé wọn lọ́wọ́ láti kàn an mọ́ àgbélébùú.
And Pilate, being minded to do what would satisfy, the multitude, released unto them Barabbas, and delivered up Jesus, having scourged him, that he should be crucified.
16 Àwọn ọmọ-ogun sì fà á jáde lọ sínú ààfin (tí a ń pè ní Pretoriomu), wọ́n sì pe gbogbo ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ogun jọ.
And, the soldiers, led him away, inside the court, which is a judgment-hall, —and called together the whole band;
17 Wọn sì fi aṣọ aláwọ̀ àlùkò wọ̀ ọ́, wọ́n hun adé ẹ̀gún, wọ́n sì fi dé e ní orí.
and they array him in purple, and set upon him, when they have plaited it; a crown of thorns, —
18 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí i kí ì wí pé, Kábíyèsí, ọba àwọn Júù.
and began to be saluting him—Joy to thee! King of the Jews!
19 Wọ́n sì fi ọ̀pá lù ú lórí, wọ́n sì tutọ́ sí i lára, wọ́n sì kúnlẹ̀ níwájú rẹ̀, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún un.
and were striking him on the head with a reed, and were spitting at him, —and, bowing their knees, were doing him homage.
20 Nígbà tí wọ́n sì fi ṣẹ̀sín tan, wọ́n sì bọ aṣọ elése àlùkò náà kúrò lára rẹ̀, wọ́n sì fi aṣọ rẹ̀ wọ̀ ọ́, wọ́n sì mú un jáde lọ láti kàn án mọ́ àgbélébùú.
And, when they had mocked him, they put off him, the purple, and put on him, his own garments. And they lead him forth, that they may crucify him.
21 Wọ́n rí ọkùnrin kan tí ń kọjá lọ. Simoni ará Kirene. Òun ni baba Aleksanderu àti Rufusi. Wọ́n sì mú un ní tipátipá pé, kí ó rú àgbélébùú Jesu.
And they impress a certain passer-by, Simon a Cyrenian, coming from a field, the father of Alexander and Rufus, —that he may carry his cross.
22 Wọ́n sì mú Jesu wá sí Gọlgọta (èyí tí ìtumọ̀ rẹ̀ ń jẹ́ Ibi Agbárí)
And they bring him unto the Golgotha place, which is, being translated, Skull-place.
23 Wọ́n sì fi myrri wáìnì tí a dàpọ̀ mọ́ òjìá fún un mu, ṣùgbọ́n òun kò gbà á.
And they would have given him, myrrhed wine, —who, however, received it not.
24 Wọ́n sì kàn án mọ́ àgbélébùú. Wọ́n sì pín aṣọ rẹ̀ láàrín ara wọn, wọ́n dìbò lórí àwọn aṣọ náà ni kí wọn bá à lè mọ èyí tí yóò jẹ́ ti olúkúlùkù.
And they crucify him, and part asunder his garments, casting a lot upon them—who should have anything.
25 Ní wákàtí kẹta ọjọ́ ni wọ́n kàn án mọ́ àgbélébùú.
And it was the third hour, and they crucified him.
26 Àkọlé ìfisùn tí wọ́n kọ sókè orí rẹ̀ ni: Ọba àwọn Júù.
And the inscription of his accusation, had been inscribed—THE KING OF THE JEWS.
27 Wọ́n sì kan àwọn olè méjì mọ́ àgbélébùú pẹ̀lú rẹ̀, ọ̀kan lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀, èkejì lọ́wọ́ òsì rẹ̀.
And, with him, they crucify, two robbers, one on his right hand, and one on his left.
29 Àwọn tí ń kọjá lọ sì ń fi ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n ń mi orí wọn pẹ̀lú, wọ́n sì ké pé, “Háà! Ìwọ tí yóò wó tẹmpili tí yóò sì tún un kọ́ láàrín ọjọ́ mẹ́ta,
And, the passers-by, were reviling him, shaking their heads, and saying—Aha! thou who wast pulling down the shrine, and building one in three days!
30 sọ̀kalẹ̀ láti orí àgbélébùú wá, kí o sì gba ara rẹ là!”
Save thyself, —coming down from the cross.
31 Bákan náà ni àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin fi í ṣẹ̀sín láàrín ara wọn, wọ́n wí pé, “Ó gba àwọn ẹlòmíràn là ṣùgbọ́n, ara rẹ̀ ni kò lè gbàlà.
Likewise, the High-priests also, mocking one to another, with the Scribes, were saying—Others, he saved, himself, he cannot save!
32 Jẹ́ kí Kristi, ọba Israẹli, sọ̀kalẹ̀ láti orí igi àgbélébùú wá nísinsin yìí kí àwa kí ó lè rí i, kí àwa kí ó sì lè gbàgbọ́.” Bákan náà, àwọn ti a kàn mọ́ àgbélébùú pẹ̀lú rẹ̀ sì ń kẹ́gàn rẹ̀.
The Christ, the King of Israel—let him come down now from the cross, that we may see and believe. And, they who had been crucified with him, were casting it in his teeth.
33 Nígbà tí ó di wákàtí kẹfà, òkùnkùn bo gbogbo ilẹ̀ títí di wákàtí kẹsànán.
And, when it was the sixth hour, darkness, came on all the land—until the ninth hour;
34 Ní wákàtí kẹsànán ni Jesu kígbe sókè ní ohùn rara, ó ní, “Eli, Eli, lama sabakitani?” (ìtumọ̀ èyí tí í ṣe, “Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí sílẹ̀?”).
and, at the ninth hour, Jesus, uttered a cry, with a loud voice—Eloi! Eloi! lama sabachthanei? which is, being translated—My God! [My God!] to what end, didst thou forsake me?
35 Nígbà tí àwọn kan nínú àwọn tí wọ́n dúró níbẹ̀ gbọ́, wọ́n sì wí pé, “Wò ó ó ń pe Elijah.”
And, some of the by-standers, having heard, were saying—See! Elijah, he calleth!
36 Nígbà náà ni ẹnìkan sáré lọ ki kànìnkànìn bọ inú ọtí kíkan, ó fi lé orí ọ̀pá, ó sì nà án sí Jesu kí ó lè mu ún. Ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a máa wò ó, bóyá Elijah yóò wá sọ̀ ọ́ kalẹ̀ wa.”
And one, running, filled a sponge with vinegar, and, putting it about a reed, was giving him to drink, saying—Stay! let us see whether Elijah is coming, to take him down!
37 Jesu sì tún kígbe sókè ni ohùn rara, ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́.
But, Jesus, sending out a loud voice, ceased to breathe.
38 Aṣọ ìkélé tẹmpili sì fàya sí méjì láti òkè dé ìsàlẹ̀.
And, the veil of the Temple, was rent into two, from top to bottom.
39 Nígbà tí balógun ọ̀rún tí ó dúró lẹ́gbẹ̀ ọ̀dọ̀ Jesu rí i tí ó kígbe sókè báyìí, tí ó sì jọ̀wọ́ èmí rẹ̀ lọ́wọ́, ó wí pé, “Lóòótọ́ Ọmọ Ọlọ́run ni ọkùnrin yìí í ṣe.”
Now the centurion, who was standing near, out over against him, seeing, that, thus, he ceased to breathe, said—Truly, this man, was God’s son!
40 Àwọn obìnrin kan wà níbẹ̀ pẹ̀lú, tí wọ́n ń wò ó láti òkèèrè. Maria Magdalene wà lára àwọn obìnrin náà, àti Maria ìyá Jakọbu kékeré àti ti Jose, àti Salome.
And there were, women also, from afar, looking on, —among whom were both Mary the Magdalene, and Mary the mother of James the Little and Joses, and Salome;
41 Àwọn wọ̀nyí, nígbà tí ó wà ní Galili máa ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, wọ́n a sì máa ṣe ìránṣẹ́ fún un àti ọ̀pọ̀ obìnrin mìíràn tí wọ́n sì bá a gòkè wá sí Jerusalẹmu.
who, when he was in Galilee, used to follow him, and minister unto him, —and many other women, who had come up with him unto Jerusalem.
42 Ọjọ́ yìí jẹ́ ọjọ́ ìpalẹ̀mọ́ (èyí tí i ṣe, ọjọ́ tó ṣáájú ọjọ́ ìsinmi). Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ náà sì ṣú,
And evening, already, having begun, since it was a preparation, that is, the eve of a Sabbath,
43 Josẹfu ará Arimatea wá, ọ̀kan pàtàkì nínú àwọn ọmọ ìgbìmọ̀, ẹni tí ń retí ìjọba Ọlọ́run, ó fi ìgboyà lọ sí iwájú Pilatu láti tọrọ òkú Jesu.
Joseph of Arimathaea, a noble counsellor, who, also himself, was awaiting the kingdom of God, came; and, venturing, went in unto Pilate, and claimed the body of Jesus.
44 Ẹnu ya Pilatu láti gbọ́ pé Jesu ti kú. Nítorí náà ó pe balógun ọ̀rún, ó sì bí i léèrè bóyá Jesu ti kú nítòótọ́.
But, Pilate, wondered whether, already, he was dead; and, calling near the centurion, questioned him—whether he had, already, died.
45 Nígbà tí balógun ọ̀rún náà sì fún Pilatu ni ìdánilójú pé Jesu ti kú, Pilatu jọ̀wọ́ òkú rẹ̀ fún Josẹfu.
And, getting to know from the centurion, he presented the corpse unto Joseph.
46 Josẹfu sì ti ra aṣọ ọ̀gbọ̀ wá. Ó sọ òkú Jesu kalẹ̀: ó sì fi aṣọ ọ̀gbọ̀ náà dì í. Ó sì tẹ́ ẹ sí inú ibojì, tí wọ́n gbẹ́ sí ara àpáta. Ó wá yí òkúta dí ẹnu ibojì náà.
And, buying a fine Indian cloth, he took him down, and wrapped him about with the cloth, and laid him in a tomb, which had been hewn out of a rock, —and rolled near a stone upon the door of the tomb.
47 Maria Magdalene àti Maria ìyá Jose ń wò ó bi Josẹfu ti n tẹ́ Jesu sí ibojì.
Now, Mary the Magdalene, and Mary the mother of Joses, were viewing how he had been laid.

< Mark 15 >