< Mark 13 >

1 Bí Jesu ti ń jáde láti inú tẹmpili ní ọjọ́ náà, ọ̀kan nínú ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sọ fún un pé, “Olùkọ́, wo ilé ńlá tí ó dára wọ̀nyí. Sì wo òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ lára àwọn ògiri ilé náà.”
Kwathi ephuma ethempelini, omunye wabafundi bakhe wathi kuye: Mfundisi, khangela, amatshe anjani lezakhiwo ezinjani!
2 Jesu dáhùn pé, “Ìwọ rí ilé ńlá wọ̀nyí? Kì yóò sí òkúta kan tí a ó fi sílẹ̀ lórí èkejì tí a kì yóò wó lulẹ̀.”
UJesu wasephendula wathi kuye: Uyabona lezizakhiwo ezinkulu yini? Akusoze kutshiywe ilitshe phezu kwelitshe, elingasoze lidilizelwe phansi.
3 Bí Jesu si ti jókòó lórí òkè olifi tí ó kọjú sí tẹmpili, Peteru, Jakọbu, Johanu àti Anderu wà pẹ̀lú rẹ̀ níbẹ̀, wọ́n bi í léèrè ni ìkọ̀kọ̀ pé,
Esehlezi entabeni yeMihlwathi maqondana lethempeli, uPetro loJakobe loJohane loAndreya bambuza bebodwa,
4 “Sọ fún wa, nígbà wo ni nǹkan wọ̀nyí yóò ṣẹlẹ̀ sí tẹmpili náà? Kí ni yóò sì jẹ́ àmì nígbà tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò ṣẹ?”
bathi: Sitshele, lezizinto zizakuba nini? Lesibonakaliso siyini lapho sezizapheleliswa lezizinto zonke?
5 Jesu kìlọ̀ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tàn yín.
UJesu ebaphendula waseqala ukuthi: Qaphelani kungabi khona oliduhisayo.
6 Nítorí pé ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò wá ní orúkọ mi, wọn yóò wí pé, ‘Èmi ni Kristi,’ wọn yóò tan ọ̀pọ̀ ènìyàn jẹ.
Ngoba abanengi bazakuza ngebizo lami, besithi: Mina nginguye; futhi baduhise abanengi.
7 Nígbà tí ẹ̀yin bá ń gbọ́ ìró ogun àti ìdágìrì ogun, kí ẹ̀yin má ṣe jáyà, nítorí irú nǹkan wọ̀nyí kò le ṣe kí ó má ṣẹlẹ̀, ṣùgbọ́n òpin náà kì í ṣe ìgbà yìí.
Kodwa nxa lisizwa ngezimpi lamahungahunga ezimpi, lingethuki; ngoba kufanele kwenzeke; kodwa ukuphela kakukabi khona.
8 Orílẹ̀-èdè yóò dìde sí orílẹ̀-èdè, àti ìjọba sí ìjọba ilẹ̀ yóò máa jì ní ibi púpọ̀. Ìyàn yóò sì wà níbi gbogbo. Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni ìbẹ̀rẹ̀ ìpọ́njú tí ń bọ̀ níwájú.
Ngoba isizwe sizavukela isizwe, lombuso uvukele umbuso; njalo kuzakuba khona ukuzamazama komhlaba indawo ngendawo, njalo kuzakuba khona indlala lezinhlupheko; lezizinto ziyikuqala kwemihelo.
9 “Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn nǹkan wọ̀nyí bá bẹ̀rẹ̀ sí i ṣẹlẹ̀, ẹ kíyèsára! Nítorí ẹ̀yin yóò wà nínú ewu. Wọn yóò fà yín lọ ilé ẹjọ́ gbogbo. Wọn yóò fi ìyà jẹ yín nínú Sinagọgu wọn. Àwọn ènìyàn yóò fẹ̀sùn kàn yín níwájú àwọn baálẹ̀ àti níwájú àwọn ọba nítorí orúkọ mi, fún ẹ̀rí fún wọn.
Kodwa ziqapheleni lina; ngoba bazalinikela emiphakathini, lemasinagogeni lizatshaywa, lizalethwa laphambi kwababusi lamakhosi ngenxa yami, kube yibufakazi kubo.
10 Nítorí pé ẹ gbọdọ̀ kọ́kọ́ wàásù ìyìnrere náà fún gbogbo orílẹ̀-èdè kí òpin tó dé.
Kodwa ivangeli limele ukutshunyayelwa kuqala kuzo zonke izizwe.
11 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n bá ń fà yín lọ, tí wọ́n bá sì ń fi yín lé wọn lọ́wọ́, ẹ má ṣe ṣàníyàn ṣáájú ohun tí ẹ ó sọ. Ṣùgbọ́n ohun tí bá fi fún yín ní wákàtí náà, òun ni kí ẹ̀yin kí ó wí. Nítorí kì í ṣe ẹ̀yin ni ó ń wí, bí kò ṣe Ẹ̀mí Mímọ́.
Kodwa nxa belidonsa belinikela, lingakhathaleli ngaphambili elizakukhuluma, linganakani; kodwa loba yini elizayinikwa ngalelohola, ikhulumeni; ngoba kakusini elikhulumayo, kodwa uMoya oyiNgcwele.
12 “Arákùnrin yóò máa fi ẹ̀sùn kan arákùnrin rẹ̀, tí yóò sì yọrí sí ikú. Baba yóò máa ṣe ikú pa ọmọ rẹ̀. Àwọn ọmọ yóò máa dìtẹ̀ sí òbí wọn. Àní, àwọn ọmọ pẹ̀lú yóò máa ṣe ikú pa òbí wọn.
Futhi umfowabo uzanikela umfowabo ekufeni, loyise umntwana; labantwana bazavukela abazali, besebebabulala;
13 Àwọn ènìyàn yóò kórìíra yín nítorí tí ẹ jẹ́ tèmi. Ṣùgbọ́n ẹni tó bá fi ara da ìyà títí dé òpin tí kò sì kọ̀ mí sílẹ̀ òun ni yóò rí ìgbàlà.
njalo lizazondwa yibo bonke ngenxa yebizo lami; kodwa ophikelelayo kuze kube sekupheleni, nguye ozasindiswa.
14 “Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìríra ìsọdahoro, tí ó dúró níbí tí kò yẹ (ẹnikẹ́ni tí ó bá kà á kí ó yé e), nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ni Judea sálọ sí orí òkè.
Kodwa nxa libona amanyala encithakalo, akhulunywa nguDaniyeli umprofethi, emi lapho angafanele khona (ofundayo kaqedisise), khona labo abaseJudiya kababalekele ezintabeni;
15 Kí ẹni ti ń bẹ lórí ilé má ṣe sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ilé, bẹ́ẹ̀ ni kí ó má sì ṣe wọ inú rẹ̀, láti mú ohunkóhun jáde nínú ilé rẹ̀.
lophezu kophahla lwendlu angehleli endlini, angangeni ukuthatha ulutho endlini yakhe;
16 Kí ẹni tí ó wà lóko má ṣe padà sẹ́yìn láti wá mú aṣọ rẹ̀.
losemasimini angabuyeli emuva, ukuyathatha isembatho sakhe.
17 Ègbé ní fún àwọn tí ó lóyún, àti fún obìnrin tí ń fún ọ́mọ lọ́mú ní ọjọ́ wọ̀nyí.
Kodwa maye kwabakhulelweyo labamunyisayo ngalezonsuku!
18 Kí ẹ sì máa gbàdúrà pé èyí ṣẹlẹ̀ ní àkókò òtútù.
Kodwa khulekani ukuthi ukubaleka kwenu kungabi sebusika.
19 Nítorí ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì yóò jẹ́ àkókò ìpọ́njú, irú èyí tí kò ì ṣẹlẹ̀ láti ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀dá Ọlọ́run. Irú rẹ̀ kò sì ni ṣẹlẹ̀ mọ́.
Ngoba ngalezonsuku kuzakuba khona ukuhlupheka, okungazanga kube khona kusukela ekuqaleni kokudaliweyo uNkulunkulu akudalayo kuze kube khathesi, lokungasoze kwaba khona.
20 “Àfi tí Olúwa bá gé àkókò ìjìyà náà kúrú, ẹyọ ẹ̀mí kan ní ayé kì yóò là. Ṣùgbọ́n nítorí àwọn tí Ọlọ́run yàn, ni yóò ṣe dín àwọn ọjọ́ náà kù.
Njalo uba iNkosi ibingazifinyezanga lezonsuku, bekungesindiswe nyama; kodwa ngenxa yabakhethiweyo, ebakhethileyo, izifinyezile insuku.
21 Nígbà náà, bí ẹnikẹ́ni bá sọ fún un yín pé, ‘Ẹ wò ó, Kristi wa níbi yìí!’ tàbí, sọ fún un yín pé, ‘Ẹ wò ó, ó wà lọ́hùn ún nì!’ Ẹ má ṣe gbà wọ́n gbọ́.
Langalesosikhathi nxa umuntu esithi kini: Khangelani, nangu uKristu; kumbe: Khangelani, ulaphayana; lingakholwa;
22 Nítorí àwọn èké Kristi àti àwọn wòlíì èké ni yóò wá, wọn yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu tí yóò tan ènìyàn jẹ hàn. Bí ó bá ṣe é ṣe, wọn yóò tan àwọn àyànfẹ́ pàápàá jẹ.
ngoba kuzavuka okristu bamanga labaprofethi bamanga, besebesenza izibonakaliso lezimangaliso, ukuduhisa, nxa kungenzeka, labakhethiweyo.
23 Nítorí náà, ẹ ṣọ́ra. Mo ti kìlọ̀ fún un yín ṣáájú tó!
Kodwa qaphelani lina; khangelani, sengilitshelile konke ngaphambili.
24 “Ṣùgbọ́n ni ọjọ́ wọ̀nyí lẹ́yìn ìpọ́njú tí mo sọ yìí, “‘oòrùn yóò ṣókùnkùn, òṣùpá kò ní tan ìmọ́lẹ̀ rẹ̀.
Kodwa ngalezonsuku, emva kwalokhokuhlupheka, ilanga lizafiphazwa, lenyanga kayiyikupha ukukhanya kwayo,
25 Àwọn ìràwọ̀ pẹ̀lú yóò já lulẹ̀ láti ojú ọ̀run, àti agbára tí ń bẹ ní ọ̀run ni a ó sì mì tìtì.’
lenkanyezi zezulu zizabe zisiwa, lamandla asemazulwini azazanyazanyiswa.
26 “Nígbà náà ni gbogbo ayé yóò sì rí i tí èmi Ọmọ Ènìyàn yóò máa bọ̀ wá láti inú àwọsánmọ̀ pẹ̀lú agbára àti ògo ńlá.
Khona-ke bezabona iNdodana yomuntu isiza emayezini ilamandla amakhulu lenkazimulo,
27 Nígbà náà ni yóò sì rán àwọn angẹli rẹ̀ láti kó àwọn àyànfẹ́ ní gbogbo ayé jọ láti orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé láti ìkangun ayé títí dé ìkangun ọ̀run.
khona-ke izathuma ingilosi zayo, ibisiqoqa abakhethiweyo bayo emimoyeni yomine, kusukela emkhawulweni womhlaba kuze kube semkhawulweni wezulu.
28 “Nísinsin yìí, ẹ kọ́ òwe lára igi ọ̀pọ̀tọ́, nígbà tí ẹ̀ka rẹ bá ń yọ tuntun, tí ó bá sì ń rú ewé, èyí fihàn pé àkókò ẹ̀rùn ti dé.
Fundani-ke umfanekiso emkhiweni; nxa ugatsha lwawo selusiba buthakathaka, luhlume amahlamvu, liyazi ukuthi ihlobo seliseduze;
29 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, nígbà tí ẹ ba ri àwọn ohun wọ̀nyí ti n ṣẹlẹ̀, kí ẹ mọ̀ pé ó súnmọ́ etílé tán, bi ìgbà tí ó wà lẹ́yìn ìlẹ̀kùn.
ngokunjalo lani, nxa libona lezizinto zisenzeka, yazini ukuthi kuseduze kuseminyango.
30 Lóòótọ́ ni mo wí fún un yín, ìran yìí kì yóò rékọjá títí a ó fi mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí ṣẹ.
Ngiqinisile ngithi kini: Lesisizukulwana asisoze sidlule, zize zenzeke izinto zonke lezi.
31 Ọ̀run àti ayé yóò kọjá lọ, ṣùgbọ́n àwọn ọ̀rọ̀ mi dúró dájú títí ayé àìnípẹ̀kun.
Kuzadlula izulu lomhlaba; kodwa amazwi ami awasoze adlule.
32 “Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó mọ ọjọ́ tàbí wákàtí tí nǹkan wọ̀nyí yóò ṣẹlẹ̀. Àwọn angẹli ọ̀run pàápàá kò mọ̀. Àní, èmi pẹ̀lú kò mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe baba nìkan.
Kodwa lolosuku lalelohola kakho owaziyo ngakho, ngitsho lengilosi ezisezulwini, ngitsho leNdodana, ngaphandle kukaBaba.
33 Ẹ máa ṣọ́ra, ẹ dúró wámú, kí ẹ sì máa gbàdúrà, nítorí ẹ̀yin kò mọ ìgbà tí àkókò ná yóò dé.
Qaphelani, lilinde likhuleke; ngoba kalazi ukuthi isikhathi sinini.
34 Ó dà bí ọkùnrin kan tí ó lọ sí ìrìnàjò tí ó jìnnà rere, ẹni tí ó fi ilé rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì fi àṣẹ fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti iṣẹ́ tí ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò ṣe, ó sì fi àṣẹ fún ẹni tó dúró lẹ́nu-ọ̀nà láti máa ṣọ́nà.
Njengomuntu owasuka elizweni lakibo watshiya indlu yakhe, wanika inceku zakhe amandla, kuleyo laleyo umsebenzi wayo, walaya umlindisango ukuthi alinde.
35 “Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ẹ̀yin pẹ̀lú ní láti máa fi ìrètí ṣọ́nà, nítorí pé ẹ kò mọ àkókò tí baálé ilé yóò dé. Bóyá ní ìrọ̀lẹ́ ni o, tàbí ní ọ̀gànjọ́ òru, tàbí nígbà tí àkùkọ máa ń kọ, tàbí ní òwúrọ̀.
Ngakho lindani; ngoba kalazi ukuthi inkosi yendlu izafika nini, kusihlwa, loba phakathi kobusuku, loba ekukhaleni kweqhude, loba emadabukakusa;
36 Àti wí pé nígbà tí ó bá dé lójijì, kó má ṣe bá yín lójú oorun.
hlezi ifike ilijume, ilifice lilele.
37 Ohun tí mo wí fún un yín, mo wí fun gbogbo ènìyàn: ‘Ẹ máa ṣọ́nà!’”
Lalokhu engikutsho kini ngikutsho kubo bonke: Lindani.

< Mark 13 >